< Numbers 5 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Angraeng mah Mosi khaeah,
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn ó lé ẹnikẹ́ni tó bá ní ẹ̀tẹ̀, ìtújáde ara ní oríṣìíríṣìí tàbí ẹni tó jẹ́ aláìmọ́ nípa fífọwọ́ kan òkú.
Ngansae man kami, kahoih thai ai takpum nathaih tawn kami hoi kaciim ai kadueh qok sui Israel kaminawk loe ataihaih ahmuen tasa bangah suem ah;
3 Irú ẹni bẹ́ẹ̀ yálà ọkùnrin tàbí obìnrin, ẹ lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó kí wọn má ba à ba ibùdó wọn jẹ́ níbi tí èmi ń gbé láàrín wọn.”
ka ohhaih ahmuen amhnongsak han ai ah, to baktih nathaih tawn kami loe nongpa maw, nongpata maw ohhaih im tasa bangah suem ah, tiah a naa.
4 Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀; wọ́n lé wọn jáde kúrò nínú ibùdó. Wọn ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún Mose.
Angraeng mah Mosi khaeah thuih ih lok baktih toengah, Israel kaminawk mah sak o; to baktih nathaih tawn kami loe ohhaih ahmuen tasa bangah a suek o.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
Angraeng mah Mosi khaeah,
6 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli: ‘Nígbà tí ọkùnrin kan tàbí obìnrin kan bá ṣẹ̀ ara wọn lọ́nà kan tàbí òmíràn, tí wọ́n sì ṣe àìṣòótọ́ sí Olúwa, ẹni náà jẹ̀bi.
Israel kaminawk khaeah hae tiah thui paeh; kaminawk mah sak o ih zaehaih to nongpa mah maw, nongpata mah maw, Angraeng hmaa ah oep om ai ah sak o pazae pongah, to kami to zaehaih tawn nahaeloe,
7 Ó gbọdọ̀ jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ tí ó sẹ̀. Ó gbọdọ̀ san ẹ̀san rẹ̀ ní ojú owó, kí ó sì fi ìdámárùn-ún rẹ̀ lé e, kí ó sì fi fún ẹni tí òun jẹ̀bi rẹ̀.
to kaminawk mah sak o ih zaehaih to taphong han oh; a sakpazae o pongah, a sakpazae o ih kami khaeah ahmuen pangato thungah ahmuen maeto thap ueloe, rong pae boih tih.
8 Ṣùgbọ́n bí irú ẹni bẹ́ẹ̀ kò bá ní ìbátan tí ó súnmọ́ ọn tí ó lè ṣe àtúnṣe àṣìṣe rẹ̀ náà fún, àtúnṣe náà jẹ́ ti Olúwa, ẹ sì gbọdọ̀ ko fún àlùfáà pẹ̀lú àgbò tí a fi ṣe ètùtù fún ẹni náà.
Toe kami maeto mah a sakpazae ih hmuen pongah, rong ih hmuen talawkkung om ai nahaeloe, to rong ih hmuen to Angraeng ih hmuen ah suek moe, qaima khaeah paek han oh; to pacoengah anih zaehaih loih thai hanah angbawnhaih sak hanah tuu tae to paek han oh.
9 Gbogbo ọrẹ ohun mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli bá mú wá fún àlùfáà jẹ́ tirẹ̀.
Israel kaminawk mah qaima han sin ih ciimcai hmuennawk boih loe anih ih hmuen ah om tih.
10 Ọrẹ ohun mímọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan jẹ́ ti òun nìkan, ṣùgbọ́n ohunkóhun tó bá fún àlùfáà yóò jẹ́ ti àlùfáà.’”
Kami boih mah kaciim ah sin ih hmuennawk loe, anih ih hmuen ah om tih; kami mah qaima han paek ih tangqumnawk doeh anih ih hmuen ah om tih, tiah thuih paeh, tiah a naa.
11 Olúwa sọ fún Mose wí pé,
To pacoengah Angraeng mah Mosi khaeah,
12 “Bá àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀ kí o sọ fún wọn pé, ‘Bí ìyàwó ọkùnrin kan bá yapa tó sì ṣe àìṣòótọ́ sí i,
Israel kaminawk han hae tiah lokthui paeh; kami maeto ih zu loe oep om ai pongah, loklam amkhraeng ving moe, a sava nuiah zaehaih a sak;
13 nípa mímú kí ọkùnrin mìíràn bá a lòpọ̀ tí ó sì fi èyí pamọ́ fún ọkọ rẹ̀, tí a kò si gbá a mú nínú ìwà àìmọ́ rẹ̀ (nítorí pé kò sí ẹlẹ́rìí àti pé wọn kò ká a mọ́ nígbà tí ó ń dẹ́ṣẹ̀ náà).
kami maeto mah to nongpata to iih haih, toe a sava khaeah thui ai ah angphat; to nongpata loe ciim ai boeh, toe anih hnukung om ai pongah, mi mah doeh a sak ih zaehaih to naeh thai ai,
14 Ṣùgbọ́n tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkọ rẹ̀ dé bi pé ó ń funra sí ìyàwó rẹ̀ yìí tí ìyàwó rẹ̀ sì wà ní àìmọ́ nítòótọ́, tàbí tí ẹ̀mí owú bá bà lé ọkùnrin kan tó sì ń jowú ìyàwó rẹ̀ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó wà ní mímọ́,
toe sava mah a zu loe ciim ai boeh, tiah oep vawthaih to tawnh maw, to tih ai boeh loe a zu nuiah palunghaenghaih a tawnh, toe anih ih zu loe amhnonghaih tidoeh om ai to mah a sava mah anih nuiah palunghaenghaih tawn nahaeloe,
15 nígbà náà ni ọkùnrin yìí yóò mú ìyàwó rẹ̀ lọ sọ́dọ̀ àlùfáà. Ọkùnrin náà yóò sì mú ọrẹ tí a yàn fún obìnrin náà, ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n efa ìyẹ̀fun barle. Kò gbọdọ̀ da òróró sí i, bẹ́ẹ̀ ni kò gbọdọ̀ fi tùràrí dídùn sí i nítorí pé ẹbọ ohun jíjẹ fún owú ni, èyí ti n mú ẹ̀ṣẹ̀ wá sí ìrántí.
a sava mah a zu to qaima khaeah caeh haih ueloe, barli takaw dip ephah hato thungah maeto a zu ih zae angbawnhaih sak hanah sin tih; takaw dip nuiah situi bawh mak ai, a nuiah hmuihoih doeh thlaek mak ai; to baktih angbawnhaih loe zu nuiah palunghaeng pongah, sak ih angbawnhaih ah oh moe, zaehaih panoek hanah sak ih angbawnhaih ah doeh oh.
16 “‘Àlùfáà yóò sì mú un wá síwájú Olúwa.
Qaima mah to nongpata to caeh haih ueloe, Angraeng hmaa ah angdoesak tih;
17 Àlùfáà yóò sì bu erùpẹ̀ ilẹ̀ àgọ́ sínú omi mímọ́ tó bù láti ìkòkò amọ̀.
to naah qaima mah kaciim tui to long laom thungah lawn ueloe, anih mah kahni imthung ih maiphu to lak pacoengah, tui thungah phuih tih.
18 Lẹ́yìn èyí, àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì tú irun orí obìnrin náà lé e lọ́wọ́, èyí ni ẹbọ ohun jíjẹ ti owú, àlùfáà fúnra rẹ̀ yóò sì gbé omi kíkorò tí ń mú ègún lọ́wọ́.
Qaima mah nongpata to Angraeng hmaa ah angdoesak ueloe, nongpata ih lu to khuk pae hmoek tih; nongpata nuiah palunghaeng pongah zaehaih panoek hanah sak ih angbawnhaih takaw dip to a ban ah pasumsak tih; qaima mah tangoenghaih kaomsak thaih tui kakhaa to a ban ah sin tih.
19 Àlùfáà yóò sì mú obìnrin náà búra, yóò wí pé, “Bí ọkùnrin mìíràn kò bá bá ọ lòpọ̀, tí ó kò sì yapa, tí o kò sì di aláìmọ́ níwọ̀n ìgbà tí ó wà lábẹ́ àṣẹ ọkọ rẹ̀, a jẹ́ pé omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí kò ní ṣe ọ́ níbi.
Qaima mah nongpata to, Kaw baktih nongpa hoiah doeh na iip ai, oep om ai loklam ah doeh nam khraeng ai moe, na sava laep ah kalah nongpa hoiah takpum amhnonghaih to na sah ai nahaeloe, hae ih tangoenghaih kaomsak thaih tui kakhaa hae na nuiah pha hmah nasoe, tiah thui tih.
20 Ṣùgbọ́n tí ìwọ bá ti yapa kúrò lọ́dọ̀ ọkọ rẹ, tí o bá ti ba ara rẹ jẹ́ nípa jíjẹ́ kí ọkùnrin tí kì í ṣe ọkọ rẹ bá ọ lòpọ̀,”
Toe na sava nuiah oep thok ai ah na oh moe, kalah nongpa hoiah loklam nam khraeng ving; na sava nuiah kalah nongpa hoiah na iih moe, na takpum to amhnong boeh nahaeloe,
21 nígbà náà ni àlùfáà yóò mú obìnrin náà búra, yóò sọ fún obìnrin náà pé, “Kí Olúwa sọ ọ́ di ẹni ègún àti ẹni ìbáwí láàrín àwọn ènìyàn rẹ nípa mímú kí itan rẹ jẹrà, kí ikùn rẹ̀ sì wú.
qaima mah nang loe nangmah ih kaminawk salakah, Angraeng mah na phaih to zaeksak ueloe, na zok doeh bawksak tih, to tiah nang loe tangoenghaih zok kami ah na om tih, tiah nongpata khaeah thuih pae pacoengah, nongpata to tangoenghaih lok akamsak tih;
22 Ǹjẹ́ kí omi yìí tí ń mú ègún wá wọ inú ara rẹ, kí ó mú ikùn rẹ̀ wú, kí ó sì mú itan rẹ̀ jẹrà dànù.” “‘Obìnrin náà yóò sì wí pé, “Àmín. Bẹ́ẹ̀ ni kó rí.”
tangoenghaih kaomsak hae tui kakhaa hae na zok thungah akun naah, na phaih to zaeksak ueloe, na zok doeh baawk tih, tiah thui pae tih. To naah nongpata mah, Amen, to tiah om nasoe, tiah thui tih.
23 “‘Nígbà náà ni àlùfáà yóò kọ ègún yìí sínú ìwé kíká, yóò sì sìn ín sínú omi kíkorò náà.
Hae tangoenghaih lok loe qaima mah cabu thungah tarik ueloe, kakhaa tui hoiah phrae let tih;
24 Àlùfáà yóò sì mú kí obìnrin náà mu omi kíkorò tí ń mú ègún wá yìí, omi náà yóò wọ inú rẹ̀ yóò sì fa ìrora kíkorò fún obìnrin náà bí ó bá jẹ̀bi.
qaima mah tangoenghaih kaomsak kakhaa tui to nongpata hanah naesak tih; nongpata ih zok thungah tangoenghaih kaomsak tui kakhaa akun naah, paroeai khaa pae tih.
25 Àlùfáà yóò gba ọrẹ ohun jíjẹ owú náà lọ́wọ́ rẹ̀, yóò fì í síwájú Olúwa, yóò sì mú iná sórí pẹpẹ.
To pacoengah qaima mah to nongpata ban ah sinsak ih palunghaeng pongah sak ih angbawnhaih takaw dip to la ueloe, Angraeng hmaa ah ahaek pacoengah, hmaicam nuiah suem tih.
26 Àlùfáà yóò bu ẹ̀kúnwọ́ kan nínú ọrẹ ohun jíjẹ náà, yóò sun ún lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìrántí lẹ́yìn tí ó ti mú kí obìnrin náà mu omi.
Qaima mah zaehaih panoek han sak ih angbawnhaih takaw dip to ban tangsum maeto la ueloe, hmaicam nuiah hmai hoiah thlaek tih; to pacoengah to tui to nongpata hanah naesak tih.
27 Bí ó bá ti mú obìnrin yìí mu omi náà, bí ó bá sì jẹ́ pé obìnrin náà ti ba ara rẹ̀ jẹ́, tí ó sì ṣe àìṣòótọ́ sí ọkọ rẹ̀, omi tí ń mú ègún wá, yóò wọ ara rẹ̀, yóò fa ìrora kíkorò fún un, ikùn rẹ̀ yóò wú, itan rẹ̀ yóò sì jẹrà dànù, yóò sì di ẹni ègún láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
To nongpata mah angmah ih sava nuiah zaehaih to sah moe, ciim ai boeh nahaeloe, tangoenghaih lokkam ih baktih toengah omsakkung tui kakhaa to naek naah, zok thungah tui to paroeai khaa tih; to naah a phaih to zaek ueloe, a zok doeh baawk tih; to naah to nongpata loe angmah ih kaminawk salakah tangoenghaih zok kami ah om tih.
28 Ṣùgbọ́n tó bá jẹ́ pé obìnrin náà kò ba ara rẹ̀ jẹ́, tó sì jẹ́ mímọ́, yóò bọ́ nínú ẹ̀bi, yóò sì le bímọ.
Toe nongpata loe ciimcai moe, amhnonghaih tidoeh om ai nahaeloe, anih loe zaehaih tawn ai pongah, caa sah let tih.
29 “‘Èyí ni òfin owú jíjẹ nígbà tí obìnrin tó wà lábẹ́ ọkọ bá ṣe a ṣe má ṣe, tí ó bá ba ara rẹ̀ jẹ́,
Hae loe zu mah oep kaom ai ah, kalah nongpa hoi loklam amkhraeng ving moe, sava nuiah ciimcai ai ah khosak naah maw, palunghaenghaih tawnh naah maw,
30 tàbí nígbà tí ẹ̀mí owú jíjẹ bá bà lé ọkùnrin kan nítorí pé ó funra sí ìyàwó rẹ̀. Àlùfáà yóò mú obìnrin náà dúró níwájú Olúwa yóò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí òfin ti wí fún un.
to tih ai boeh loe nongpa mah a zu nuiah palunghaenghaih tawnh naah maw, patoh ih kaalok ah oh; sava mah a zu nuiah palunghaenghaih tawnh naah, qaima mah nongpata to Angraeng hmaa ah angdoesak ueloe, hae ih kaalok baktih toengah nongpata to lokcaek tih.
31 Ara ọkọ rẹ̀ mọ́ nínú ẹ̀ṣẹ̀ yìí ṣùgbọ́n obìnrin náà yóò ru ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.’”
To tiah sava loe zaehaih ciim ueloe, nongpata loe a zaehaih pongah danpaekhaih to zok tih, tiah thui paeh, tiah a naa.

< Numbers 5 >