< Numbers 4 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Jehova akĩĩra Musa na Harũni atĩrĩ:
2 “Ka iye àwọn ọmọ Kohati láàrín àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
“Thĩinĩ wa Alawii-rĩ, tarai rũhonge rwa Akohathu kũringana na mbarĩ ciao na nyũmba ciao.
3 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
Mũtare arũme othe a ũkũrũ wa kuuma mĩaka mĩrongo ĩtatũ nginya mĩaka mĩrongo ĩtano arĩa mokaga gũtungata wĩra-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo.
4 “Wọ̀nyí ni iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Kohati nínú àgọ́ àjọ, láti tọ́jú àwọn ohun èlò mímọ́ jùlọ.
“Ũyũ nĩguo wĩra wa Akohathu thĩinĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo: wĩra wao nĩ kũmenyerera indo iria theru mũno.
5 Nígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sí aṣọ ìbòrí rẹ̀, wọn yóò sì fi bo àpótí ẹ̀rí.
Rĩrĩa kambĩ ĩgũthaama-rĩ, Harũni na ariũ ake marĩtoonyaga thĩinĩ wa hema ĩyo makaruta gĩtambaya gĩa gũcuurio gĩa kũhakania na makahumbĩra ithandũkũ rĩa Ũira nakĩo.
6 Wọn yóò sì fi awọ ewúrẹ́ bò ó, lórí awọ ewúrẹ́ yìí ni wọn ó tẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
Ningĩ marĩhumbĩre na gĩthii kĩa njũũa cia pomboo, na maare gĩtambaya kĩa rangi wa bururu mũtheri igũrũ rĩacio, na matoonyie mĩtĩ ya kũrĩkuua handũ hayo.
7 “Lórí tábìlì àkàrà ìfihàn ni kí wọn ó na aṣọ aláró kan sí, kí wọn kí ó sì fi àwopọ̀kọ́ sórí rẹ̀, àti ṣíbí àti àwokòtò àti ìgò fún ọrẹ ohun mímu; àti àkàrà ìgbà gbogbo ní kí ó wà lórí rẹ̀.
“Nao maare gĩtambaya kĩa rangi wa bururu igũrũ rĩa metha ya mĩgate ĩrĩa ĩigagwo mbere ya Jehova, na mamĩigĩrĩre thaani, na thaani, nene na mbakũri, na ndigithũ cia magongona ma kũnyuuo; na mĩgate ĩrĩa ĩigagwo hau hĩndĩ ciothe ĩikare o hau igũrũ.
8 Lórí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọn yóò da, wọn ó tún fi awọ ewúrẹ́ bò ó, wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
Macooke maigĩrĩre gĩtambaya kĩa rangi wa gakarakũ igũrũ rĩa indo icio na ningĩ mahumbĩre gĩtambaya kĩu na njũũa cia pomboo, na matoonyie mĩtĩ ya kũrĩkuua handũ hayo.
9 “Kí wọn kí ó sì mú aṣọ aláwọ̀ aláró kan, kí wọn kí ó sì fi bo ọ̀pá fìtílà àti fìtílà rẹ̀, àti alumagaji rẹ̀, àti àwo alumagaji rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò òróró rẹ̀, èyí tí wọ́n fi ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀.
“Ningĩ moe gĩtambaya kĩa rangi wa bururu, mahumbĩre mũtĩ ũrĩa wa kũigĩrĩrwo matawa marĩa mamũrĩkaga, hamwe na matawa maguo, na magathĩ ma gũtinia ndaambĩ, na thaani cia mũrarĩ wa ndaambĩ, na ndigithũ cia gwĩkĩrwo maguta ma matawa macio.
10 Kí wọn ó fi awọ ẹran yí fìtílà àti gbogbo ohun èlò rẹ, kí wọn kí ó sì gbé e lé orí férémù tí wọn yóò fi gbé e.
Ningĩ makũnje mũtĩ ũcio na indo ciaguo ciothe ciohetwo na gĩthii kĩa njũũa cia pomboo, na macigĩrĩre igũrũ rĩa gĩkuui gĩacio.
11 “Ní orí pẹpẹ wúrà ni kí wọn ó tẹ́ aṣọ aláró kan sí, wọn yóò sì fi awọ seali bò ó, kí wọ́n sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
“Nĩ maare gĩtambaya kĩa rangi wa bururu igũrũ rĩa kĩgongona gĩa thahabu, na makĩhumbĩre na gĩthii kĩa njũũa cia pomboo, na matoonyie mĩtĩ ĩrĩa ya gũgĩkuua handũ hayo.
12 “Kí wọn kó gbogbo ohun èlò tí wọ́n ń lò fún iṣẹ́ ìsìn ní ibi mímọ́, kí wọn ó fi aṣọ aláwọ̀ búlúù yìí, kí wọn ó sì fi awọ seali bò ó, kí wọn ó sì fi gbé wọn ka orí férémù.
“Ningĩ moe indo ciothe iria ihũthagĩrwo ũtungata-inĩ wa handũ-harĩa-haamũre, macikũnje na gĩtambaya kĩa rangi wa bururu, macihumbĩre na gĩthii kĩa njũũa cia pomboo, na maciigĩrĩre igũrũ rĩa gĩkuui gĩacio.
13 “Kí wọn ó kó eérú kúrò lórí pẹpẹ idẹ, kí wọn ó sì tẹ́ aṣọ aláwọ̀ àlùkò lé e lórí.
“Ningĩ nĩ marute mũhu kuuma kĩgongona-inĩ gĩa gĩcango, na maare gĩtambaya kĩa rangi wa ndathi igũrũ rĩakĩo.
14 Nígbà náà ni kí wọn ó kó gbogbo ohun èlò fún iṣẹ́ ìsìn níbi pẹpẹ, títí dórí àwo iná, fọ́ọ̀kì ẹran, ọkọ́ eérú àti àwokòtò. Kí wọn ó fi awọ ewúrẹ́ bo gbogbo rẹ̀, kí wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
Ningĩ maigĩrĩre indo ciothe iria ihũthagĩrwo gũtungata kĩgongona-inĩ, nacio nĩ hamwe na ngĩo cia mwaki, na njibe, na icakũri, na mbakũri cia kũminjaminjĩria. Igũrũ rĩakĩo nĩ maare gĩthii kĩa njũũa cia pomboo na matoonyie mĩtĩ ya gũgĩkuua handũ hayo.
15 “Lẹ́yìn tí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ti parí bíbo ibi mímọ́ àti gbogbo ohun èlò ibi mímọ́, nígbà tí àgọ́ bá sì ṣetán láti tẹ̀síwájú, kí àwọn ọmọ Kohati bọ́ síwájú láti gbé e, ṣùgbọ́n wọn kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan ohun mímọ́ kankan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀ wọn ó kú. Àwọn ọmọ Kohati ni yóò gbé gbogbo ohun tó wà nínú àgọ́ ìpàdé.
“Thuutha wa Harũni na ariũ ake kũrĩĩkia kũhumbĩra indo ciothe theru o na indo ciothe nyamũre, na rĩrĩa andũ a kambĩ mehaarĩria gũthaama-rĩ, ariũ a Akohathu nao moke makuue indo icio. No matikanahutie indo icio nyamũre matigakue. Akohathu acio nĩo magaakuua indo iria irĩ thĩinĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo.
16 “Iṣẹ́ Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni ṣíṣe àbojútó òróró fìtílà, tùràrí dídùn, ẹbọ ohun jíjẹ ìgbà gbogbo àti òróró ìtasórí. Kí ó jẹ́ alábojútó gbogbo ohun tó jẹ mọ́ àgọ́ àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò ibi mímọ́.”
“Eleazaru mũrũ wa Harũni, ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, nĩwe ũrĩmenyagĩrĩra maguta ma gwakia tawa, na ũbumba ũrĩa ũnungaga wega, na mũtu ũrĩa ũrutagwo hĩndĩ ciothe, o na maguta marĩa maitanagĩrĩrio. Nĩwe ũrĩmenyagĩrĩra Hema-ĩyo-Nyamũre ĩrĩ yothe na indo iria ciothe irĩ thĩinĩ wayo, nĩcio indo iria nyamũre ciĩkĩrĩtwo kuo, na indo cia wĩra.”
17 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Jehova akĩĩra Musa na Harũni atĩrĩ,
18 “Rí i pé a kò gé ẹ̀yà Kohati kúrò lára àwọn ọmọ Lefi.
“Menyererai mbarĩ cia mũhĩrĩga wa Akohathu matikaneherio kuuma kũrĩ Alawii.
19 Nítorí kí wọ́n lè yè, kí wọ́n má ba à kú nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ tòsí àwọn ohun mímọ́ jùlọ: Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni kí ó wọ ibi mímọ́ láti pín iṣẹ́ oníkálùkù àti àwọn ohun tí wọn yóò gbé.
Nĩguo matũũre muoyo na matikae gũkua rĩrĩa mangĩkuhĩrĩria indo iria theru mũno-rĩ, mekagĩrei ũũ: Harũni na ariũ ake nĩo marĩtoonyaga handũ harĩa hatheru, na makagaĩra o mũndũ wĩra wake na kĩrĩa egũkuua.
20 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Kohati kò gbọdọ̀ wọlé láti wo àwọn ohun mímọ́, bó tilẹ̀ jẹ́ ìṣẹ́jú kan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kú.”
No ariũ a Kohathu matikanatoonye thĩinĩ kuona indo iria theru o na hanini, nĩguo matigaakue.”
21 Olúwa sọ fún Mose pé,
Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
22 “Tún ka iye àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
“Tara Agerishoni o nao kũringana na nyũmba ciao na mbarĩ ciao.
23 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
Ũtare arũme othe a ũkũrũ wa kuuma mĩaka mĩrongo ĩtatũ nginya mĩaka mĩrongo ĩtano arĩa mokaga gũtungata wĩra-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo.
24 “Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni, bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ àti ní ẹrù rírù.
“Ũyũ nĩguo ũtungata wa mbarĩ cia Agerishoni rĩrĩa mekũruta wĩra na gũkuua mĩrigo:
25 Àwọn ni yóò máa ru àwọn aṣọ títa ti àgọ́, ti àgọ́ ìpàdé àti ìbòrí rẹ̀, àti awọ ewúrẹ́ tí a fi bò ó, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
Nĩo marĩkuuaga itambaya cia gũcuurio cia Hema-ĩrĩa-Nyamũre, na Hema-ya-Gũtũnganwo, na indo cia kũmĩhumbĩra, o na gĩthii kĩa njũũa cia pomboo cia kũmĩhumbĩra na igũrũ, na itambaya cia gũcuurio cia itoonyero rĩa Hema-ya-Gũtũnganwo,
26 aṣọ títa ti àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí àgbàlá, okùn àti àwọn ohun èlò iṣẹ́ ìsìn, àti ohun gbogbo tí à ń lò fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn ó máa sìn. Àwọn ọmọ Gerṣoni ni yóò ṣe gbogbo ohun tó bá yẹ pẹ̀lú àwọn nǹkan wọ̀nyí.
na itambaya cia gũcuurio iria cia kũirigĩra nja ĩrĩa ĩthiũrũrũkĩirie Hema-ĩyo-Nyamũre na kĩgongona, na gĩtambaya gĩa gũcuurio gĩa itoonyero-inĩ, na mĩhĩndo na indo ciothe itũmagĩrwo ũtungata-inĩ wayo. Agerishoni acio nĩo marĩrutaga wĩra wothe ũrĩa wagĩrĩire kũrutwo na indo icio.
27 Gbogbo iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Gerṣoni yálà ni iṣẹ́ ṣíṣe tàbí ní ẹrù rírù ni, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóò máa darí wọn; ìwọ ni kí o sì yàn ẹrù tí oníkálùkù yóò rù fún un.
Ũtungata wao wothe, ũrĩ wa gũkuua mĩrigo kana wa kũruta wĩra ũngĩ, ũrĩĩrutagwo ũtongoretio nĩ Harũni na ariũ ake. Nĩ inyuĩ mũrĩmagayagĩra wĩra wao wa kĩrĩa gĩothe marĩkuuaga.
28 Èyí ni iṣẹ́ ìdílé àwọn Gerṣoni ni àgọ́ ìpàdé Itamari, ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni yóò sì jẹ alábojútó iṣẹ́ wọn.
Ũcio nĩguo ũtungata wa mbarĩ ya Agerishoni Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo. Wĩra wao ũrĩĩrutagwo ũtongoretio nĩ Ithamaru mũrũ wa Harũni, ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai.
29 “Ka iye àwọn ọmọ Merari nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
“Tara Amerari kũringana na mbarĩ na nyũmba ciao.
30 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
Tara arũme othe a ũkũrũ wa kuuma mĩaka mĩrongo ĩtatũ nginya mĩaka mĩrongo ĩtano arĩa mokaga gũtungata wĩra-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo.
31 Iṣẹ́ tí wọn yóò sì máa ṣe nínú àgọ́ ìpàdé nìyìí: gbígbẹ́ àwọn férémù àgọ́, pákó ìdábùú rẹ̀, òpó àti ihò òpó rẹ̀,
Ũyũ nĩguo wĩra wao ũrĩa marĩrutaga magĩtungata Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo: wĩra wao nĩ gũkuuaga buremu cia Hema-ĩyo-Nyamũre, na mĩgĩĩko yayo, na itugĩ na itina ciacio,
32 pẹ̀lú gbogbo òpó tó yí àgbàlá ká àti ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn, kí o sì yan ohun tí oníkálùkù yóò rù fún un.
o ũndũ ũmwe na itugĩ iria ciirigĩte nja hamwe na itina ciacio, na higĩ cia hema na mĩhĩndo, na indo ciothe ciacio na kĩndũ gĩothe gĩkonainie na kũruta wĩra ũcio. Gayagĩra o mũndũ indo iria agĩrĩirwo nĩ gũkuua.
33 Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Merari, bí wọn yóò ti máa ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé lábẹ́ àkóso Itamari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà.”
Ũcio nĩguo ũtungata wa mbarĩ ya Amerari rĩrĩa marĩrutaga wĩra Hema-inĩ-ya-Gũtũnganwo, matongoretio nĩ Ithamaru mũrũ wa Harũni, ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai.”
34 Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn olórí ìjọ ènìyàn ka àwọn ọmọ Kohati nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
Na rĩrĩ, Musa, na Harũni, na atongoria a kĩrĩndĩ nĩmatarire Akohathu acio kũringana na mbarĩ na nyũmba ciao.
35 Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní Àgọ́ ìpàdé.
Arũme othe a ũkũrũ wa kuuma mĩaka mĩrongo ĩtatũ nginya mĩaka mĩrongo ĩtano arĩa mookire gũtungata wĩra-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo,
36 Iye wọn nípa ìdílé jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlá ó dín làádọ́ta.
matarĩtwo na mbarĩ ciao, maarĩ andũ 2,750
37 Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé; tí Mose àti Aaroni kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
Ũcio nĩguo warĩ mũigana wa andũ othe arĩa maarĩ a mbarĩ cia Akohathu arĩa maatungataga thĩinĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo. Musa na Harũni maamatarire kũringana na ũrĩa Jehova aathĩte Musa.
38 Wọ́n ka àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
Agerishoni maatarirwo kũringana na mbarĩ na nyũmba ciao.
39 Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, gbogbo àwọn tó lè ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
Arũme othe a ũkũrũ wa kuuma mĩaka mĩrongo ĩtatũ nginya mĩaka mĩrongo ĩtano arĩa mookire gũtungata wĩra-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo,
40 Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá ó lé ọgbọ̀n.
matarĩtwo na mbarĩ na nyũmba ciao, maarĩ andũ 2,630.
41 Èyí jẹ́ àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Gerṣoni, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé. Mose àti Aaroni ṣe bí àṣẹ Olúwa.
Ũcio nĩguo warĩ mũigana wa mbarĩ cia Agerishoni arĩa maatungataga thĩinĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo. Musa na Harũni maamatarire kũringana na watho wa Jehova.
42 Wọ́n ka àwọn ọmọ Merari nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
Amerari maatarirwo kũringana na mbarĩ na nyũmba ciao.
43 Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
Arũme othe a ũkũrũ wa kuuma mĩaka mĩrongo ĩtatũ nginya mĩaka mĩrongo ĩtano arĩa mookire gũtungata wĩra-inĩ wa Hema-ya-Gũtũnganwo,
44 Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún.
matarĩtwo na mbarĩ ciao, maarĩ andũ 3,200.
45 Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Merari. Mose àti Aaroni kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
Ũcio nĩguo warĩ mũigana wa mbarĩ cia Amerari. Musa na Harũni maamatarire kũringana na ũrĩa Jehova aathĩte Musa.
46 Gbogbo àwọn tí a kà nínú àwọn ọmọ Lefi, ti Mose àti Aaroni àti àwọn olórí Israẹli kà, nípa ìdílé wọn àti gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
Nĩ ũndũ ũcio, Musa na Harũni na atongoria a Isiraeli magĩtara Alawii othe kũringana na mbarĩ ciao na nyũmba ciao.
47 Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, àwọn tó ń ṣiṣẹ́ ìsìn tó sì ń ru àwọn ẹrù inú Àgọ́ ìpàdé.
Arũme othe a ũkũrũ wa kuuma mĩaka mĩrongo ĩtatũ nginya mĩaka mĩrongo ĩtano arĩa mookire kũruta wĩra wa gũtungata na gũkuua Hema-ya-Gũtũnganwo,
48 Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá lé lẹ́gbàarin ó dín ogún.
mũigana wao warĩ andũ 8,580.
49 Wọ́n yan iṣẹ́ àti àwọn ohun tí ẹni kọ̀ọ̀kan yóò máa gbé fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Kũringana na watho wa Jehova ũrĩa aathĩte Musa, mũndũ o mũndũ nĩagayagĩrwo wĩra wake, na akeerwo kĩrĩa egũkuua. Ũguo nĩguo maatarirwo, o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa.

< Numbers 4 >