< Numbers 4 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Le Seigneur parla encore à Moïse et à Aaron, disant:
2 “Ka iye àwọn ọmọ Kohati láàrín àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
Fais le dénombrement des fils de Caath d’entre les Lévites, selon leurs familles et leurs maisons,
3 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
Depuis trente ans et au dessus, jusqu’à cinquante ans, de tous ceux qui entrent, pour se tenir et servir dans le tabernacle d’alliance.
4 “Wọ̀nyí ni iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Kohati nínú àgọ́ àjọ, láti tọ́jú àwọn ohun èlò mímọ́ jùlọ.
Voici la fonction des fils de Caath: C’est dans le tabernacle et le Saint des saints
5 Nígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sí aṣọ ìbòrí rẹ̀, wọn yóò sì fi bo àpótí ẹ̀rí.
Qu’entreront Aaron et ses fils, quand le camp devra être levé, et ils ôteront le voile qui est suspendu devant la porte, et ils en envelopperont l’arche du témoignage,
6 Wọn yóò sì fi awọ ewúrẹ́ bò ó, lórí awọ ewúrẹ́ yìí ni wọn ó tẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
Et ils le couvriront encore d’une couverture de peaux violettes, et ils étendront par-dessus un drap tout d’hyacinthe, et ils introduiront les leviers.
7 “Lórí tábìlì àkàrà ìfihàn ni kí wọn ó na aṣọ aláró kan sí, kí wọn kí ó sì fi àwopọ̀kọ́ sórí rẹ̀, àti ṣíbí àti àwokòtò àti ìgò fún ọrẹ ohun mímu; àti àkàrà ìgbà gbogbo ní kí ó wà lórí rẹ̀.
Ils envelopperont aussi la table de proposition d’un drap d’hyacinthe, et ils mettront avec elle les encensoirs, les petits mortiers, les tasses et les coupes pour faire les libations; et les pains seront toujours sur elle;
8 Lórí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọn yóò da, wọn ó tún fi awọ ewúrẹ́ bò ó, wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
Et ils étendront par-dessus un drap d’écarlate qu’ils couvriront encore d’une couverture de peaux violettes, et ils y introduiront les leviers.
9 “Kí wọn kí ó sì mú aṣọ aláwọ̀ aláró kan, kí wọn kí ó sì fi bo ọ̀pá fìtílà àti fìtílà rẹ̀, àti alumagaji rẹ̀, àti àwo alumagaji rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò òróró rẹ̀, èyí tí wọ́n fi ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀.
Ils prendront de plus un drap d’hyacinthe dont ils couvriront le chandelier avec ses lampes, ses pincettes, ses mouchettes et tous les vases d’huile qui sont nécessaires pour entretenir les lampes.
10 Kí wọn ó fi awọ ẹran yí fìtílà àti gbogbo ohun èlò rẹ, kí wọn kí ó sì gbé e lé orí férémù tí wọn yóò fi gbé e.
Et sur toutes ces choses ils poseront une couverture de peaux violettes, et ils introduiront les leviers.
11 “Ní orí pẹpẹ wúrà ni kí wọn ó tẹ́ aṣọ aláró kan sí, wọn yóò sì fi awọ seali bò ó, kí wọ́n sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
Et l’autel d’or aussi, ils l’envelopperont d’un drap d’hyacinthe, et ils étendront par-dessus une couverture de peaux violettes, et ils y introduiront les leviers.
12 “Kí wọn kó gbogbo ohun èlò tí wọ́n ń lò fún iṣẹ́ ìsìn ní ibi mímọ́, kí wọn ó fi aṣọ aláwọ̀ búlúù yìí, kí wọn ó sì fi awọ seali bò ó, kí wọn ó sì fi gbé wọn ka orí férémù.
Tous les vases avec lesquels se fait le service dans le sanctuaire, ils les envelopperont dans un drap d’hyacinthe, et ils étendront par-dessus une couverture de peaux violettes, et ils introduiront les leviers.
13 “Kí wọn ó kó eérú kúrò lórí pẹpẹ idẹ, kí wọn ó sì tẹ́ aṣọ aláwọ̀ àlùkò lé e lórí.
Mais ils nettoieront aussi l’autel de ses cendres, et ils l’envelopperont dans un drap de pourpre,
14 Nígbà náà ni kí wọn ó kó gbogbo ohun èlò fún iṣẹ́ ìsìn níbi pẹpẹ, títí dórí àwo iná, fọ́ọ̀kì ẹran, ọkọ́ eérú àti àwokòtò. Kí wọn ó fi awọ ewúrẹ́ bo gbogbo rẹ̀, kí wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
Et ils y mettront avec lui tous les vases dont ils se servent pour son ministère, c’est-à-dire les brasiers, les fourchettes, les tridents, les crocs et les pelles. Ils couvriront ensemble tous les vases de l’autel d’une couverture de peaux violettes, et ils introduiront les leviers.
15 “Lẹ́yìn tí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ti parí bíbo ibi mímọ́ àti gbogbo ohun èlò ibi mímọ́, nígbà tí àgọ́ bá sì ṣetán láti tẹ̀síwájú, kí àwọn ọmọ Kohati bọ́ síwájú láti gbé e, ṣùgbọ́n wọn kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan ohun mímọ́ kankan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀ wọn ó kú. Àwọn ọmọ Kohati ni yóò gbé gbogbo ohun tó wà nínú àgọ́ ìpàdé.
Or, lorsque Aaron et ses fils auront enveloppé le sanctuaire et tous ses vases, au lever du camp, les fils de Caath entreront pour les porter ainsi enveloppés; mais ils ne toucheront point les vases du sanctuaire, de peur qu’ils ne meurent. Telles sont dans le tabernacle d’alliance les charges des fils de Caath,
16 “Iṣẹ́ Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni ṣíṣe àbojútó òróró fìtílà, tùràrí dídùn, ẹbọ ohun jíjẹ ìgbà gbogbo àti òróró ìtasórí. Kí ó jẹ́ alábojútó gbogbo ohun tó jẹ mọ́ àgọ́ àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò ibi mímọ́.”
Au-dessus desquels sera Eléazar, fils d’Aaron, le prêtre, au soin de qui appartient l’huile pour entretenir les lampes, le parfum de composition, le sacrifice perpétuel, l’huile de l’onction et tout ce qui appartient au service du tabernacle et de tous les vases qui sont dans le tabernacle.
17 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
Le Seigneur parla encore à Moïse et à Aaron, disant:
18 “Rí i pé a kò gé ẹ̀yà Kohati kúrò lára àwọn ọmọ Lefi.
Ne détruisez point le peuple de Caath du milieu des Lévites;
19 Nítorí kí wọ́n lè yè, kí wọ́n má ba à kú nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ tòsí àwọn ohun mímọ́ jùlọ: Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni kí ó wọ ibi mímọ́ láti pín iṣẹ́ oníkálùkù àti àwọn ohun tí wọn yóò gbé.
Mais faites ceci pour eux, afin qu’ils vivent et qu’ils ne meurent point, s’ils touchent le Saint des saints. Aaron et ses fils entreront, et ils disposeront eux-mêmes les ouvrages de tous séparément, et ils partageront ce que chacun doit porter.
20 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Kohati kò gbọdọ̀ wọlé láti wo àwọn ohun mímọ́, bó tilẹ̀ jẹ́ ìṣẹ́jú kan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kú.”
Que les autres ne voient nullement avec curiosité ce qui est dans le sanctuaire, avant qu’il soit enveloppé, autrement ils mourront.
21 Olúwa sọ fún Mose pé,
Le Seigneur parla encore à Moïse, disant:
22 “Tún ka iye àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
Fais aussi le dénombrement des enfants de Gerson, selon leurs maisons, leurs familles et leur parenté,
23 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
Depuis trente ans et au-dessus jusqu’à cinquante ans. Dénombre tous ceux qui entrent et qui servent dans le tabernacle d’alliance.
24 “Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni, bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ àti ní ẹrù rírù.
L’office de la famille des Gersonites est,
25 Àwọn ni yóò máa ru àwọn aṣọ títa ti àgọ́, ti àgọ́ ìpàdé àti ìbòrí rẹ̀, àti awọ ewúrẹ́ tí a fi bò ó, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
Qu’ils portent les rideaux du tabernacle et le toit d’alliance, l’autre couverture, puis la couverture violette qui est par-dessus tout, et le voile qui est suspendu à l’entrée du tabernacle d’alliance;
26 aṣọ títa ti àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí àgbàlá, okùn àti àwọn ohun èlò iṣẹ́ ìsìn, àti ohun gbogbo tí à ń lò fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn ó máa sìn. Àwọn ọmọ Gerṣoni ni yóò ṣe gbogbo ohun tó bá yẹ pẹ̀lú àwọn nǹkan wọ̀nyí.
Les rideaux du parvis et le voile de l’entrée, qui est devant le tabernacle. Tout ce qui appartient à l’autel, les cordages et les vases de service,
27 Gbogbo iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Gerṣoni yálà ni iṣẹ́ ṣíṣe tàbí ní ẹrù rírù ni, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóò máa darí wọn; ìwọ ni kí o sì yàn ẹrù tí oníkálùkù yóò rù fún un.
Au commandement d’Aaron et de ses fils, les fils de Gerson le porteront, et chacun saura à quelle charge il doit être soumis.
28 Èyí ni iṣẹ́ ìdílé àwọn Gerṣoni ni àgọ́ ìpàdé Itamari, ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni yóò sì jẹ alábojútó iṣẹ́ wọn.
Tel est l’emploi de la famille des Gersonites dans le tabernacle d’alliance; et ils seront sous la main d’Ithamar, fils d’Aaron le prêtre.
29 “Ka iye àwọn ọmọ Merari nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
Tu recenseras aussi les fils de Mérari selon leurs maisons et les familles de leurs pères,
30 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
Depuis trente ans et au-dessus jusqu’à cinquante ans, tous ceux qui entrent pour l’office de leur ministère, et le service de l’alliance de témoignage.
31 Iṣẹ́ tí wọn yóò sì máa ṣe nínú àgọ́ ìpàdé nìyìí: gbígbẹ́ àwọn férémù àgọ́, pákó ìdábùú rẹ̀, òpó àti ihò òpó rẹ̀,
Voici leurs charges: ils porteront les ais du tabernacle, ses leviers, ses colonnes et leurs soubassements,
32 pẹ̀lú gbogbo òpó tó yí àgbàlá ká àti ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn, kí o sì yan ohun tí oníkálùkù yóò rù fún un.
Et aussi les colonnes autour du parvis avec leurs soubassements, leurs pieux et leurs cordages. Ils prendront le compte de tous les vases et des autres objets, et c’est ainsi qu’ils les porteront.
33 Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Merari, bí wọn yóò ti máa ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé lábẹ́ àkóso Itamari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà.”
Tel est l’office des familles des Mérarites et leur ministère dans le tabernacle d’alliance; et ils sont sous la main d’Ithamar, fils d’Aaron, le prêtre.
34 Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn olórí ìjọ ènìyàn ka àwọn ọmọ Kohati nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
Moïse donc, Aaron et les princes de la synagogue recensèrent les fils de Caath, selon leur parenté et les maisons de leurs pères,
35 Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní Àgọ́ ìpàdé.
Depuis trente ans et au-dessus jusqu’à cinquante ans, tous ceux qui entrent au service du tabernacle d’alliance;
36 Iye wọn nípa ìdílé jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlá ó dín làádọ́ta.
Et il s’en trouva deux mille sept cent cinquante.
37 Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé; tí Mose àti Aaroni kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
C’est là le nombre du peuple de Caath qui entrent dans le tabernacle d’alliance: Moïse et Aaron les dénombrèrent, selon la parole du Seigneur, par l’entremise de Moïse.
38 Wọ́n ka àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
Les fils de Gerson aussi furent dénombrés selon leur parenté et les maisons de leurs pères,
39 Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, gbogbo àwọn tó lè ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
Depuis trente ans et au-dessus, jusqu’à cinquante ans, tous ceux qui entrent pour servir dans le tabernacle d’alliance;
40 Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá ó lé ọgbọ̀n.
Et il s’en trouva deux mille six cent trente.
41 Èyí jẹ́ àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Gerṣoni, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé. Mose àti Aaroni ṣe bí àṣẹ Olúwa.
C’est là le peuple des Gersonites, que dénombrèrent Moïse et Aaron, selon la parole du Seigneur.
42 Wọ́n ka àwọn ọmọ Merari nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
Ensuite furent dénombrés les fils de Mérari selon leur parenté et les maisons de leurs pères,
43 Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
Depuis trente ans et au-dessus, jusqu’à cinquante ans, tous ceux qui entrent pour accomplir les rites du tabernacle d’alliance;
44 Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún.
Et il s’en trouva trois mille deux cents.
45 Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Merari. Mose àti Aaroni kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
Tel est le nombre des fils de Mérari que recensèrent Moïse et Aaron, selon l’ordre du Seigneur, par l’entremise de Moïse.
46 Gbogbo àwọn tí a kà nínú àwọn ọmọ Lefi, ti Mose àti Aaroni àti àwọn olórí Israẹli kà, nípa ìdílé wọn àti gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
Tous ceux qui furent recensés d’entre les Lévites, et que firent recenser par leurs noms, Moïse, Aaron et les princes d’Israël, selon leur parenté et les maisons de leurs pères,
47 Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, àwọn tó ń ṣiṣẹ́ ìsìn tó sì ń ru àwọn ẹrù inú Àgọ́ ìpàdé.
Depuis trente ans et au-dessus, jusqu’à cinquante ans, entrant pour le service du tabernacle et pour porter les fardeaux,
48 Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá lé lẹ́gbàarin ó dín ogún.
Furent en tout huit mille cinq cent quatre-vingts.
49 Wọ́n yan iṣẹ́ àti àwọn ohun tí ẹni kọ̀ọ̀kan yóò máa gbé fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
C’est selon la parole du Seigneur que Moïse les recensa, chacun selon son office et ses charges, comme lui avait ordonné le Seigneur.

< Numbers 4 >