< Numbers 4 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
And YHWH speaks to Moses and to Aaron, saying,
2 “Ka iye àwọn ọmọ Kohati láàrín àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
“Take a census of the sons of Kohath from the midst of the sons of Levi, by their families, by the house of their fathers;
3 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
from a son of thirty years and upward, even until a son of fifty years, everyone going in to the host, to do work in the Tent of Meeting.
4 “Wọ̀nyí ni iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Kohati nínú àgọ́ àjọ, láti tọ́jú àwọn ohun èlò mímọ́ jùlọ.
This [is] the service of the sons of Kohath in the Tent of Meeting [for] the most holy things:
5 Nígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sí aṣọ ìbòrí rẹ̀, wọn yóò sì fi bo àpótí ẹ̀rí.
when Aaron and his sons have come in, in the journeying of the camp, and have taken down the veil of the hanging, and have covered the Ark of the Testimony with it,
6 Wọn yóò sì fi awọ ewúrẹ́ bò ó, lórí awọ ewúrẹ́ yìí ni wọn ó tẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
then they have put a covering of tachash skin on it, and have spread a garment completely of blue above, and have placed its poles.
7 “Lórí tábìlì àkàrà ìfihàn ni kí wọn ó na aṣọ aláró kan sí, kí wọn kí ó sì fi àwopọ̀kọ́ sórí rẹ̀, àti ṣíbí àti àwokòtò àti ìgò fún ọrẹ ohun mímu; àti àkàrà ìgbà gbogbo ní kí ó wà lórí rẹ̀.
And they spread a garment of blue over the table of the presence, and have put the dishes, and the spoons, and the bowls, and the cups of the drink-offering on it, and the bread of continuity is on it,
8 Lórí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọn yóò da, wọn ó tún fi awọ ewúrẹ́ bò ó, wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
and they have spread a garment of scarlet over them, and have covered it with a covering of tachash skin, and have placed its poles,
9 “Kí wọn kí ó sì mú aṣọ aláwọ̀ aláró kan, kí wọn kí ó sì fi bo ọ̀pá fìtílà àti fìtílà rẹ̀, àti alumagaji rẹ̀, àti àwo alumagaji rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò òróró rẹ̀, èyí tí wọ́n fi ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀.
and have taken a garment of blue, and have covered the lampstand of the lamp, and its lights, and its snuffers, and its snuff-dishes, and all its oil vessels with which they minister to it;
10 Kí wọn ó fi awọ ẹran yí fìtílà àti gbogbo ohun èlò rẹ, kí wọn kí ó sì gbé e lé orí férémù tí wọn yóò fi gbé e.
and they have put it and all its vessels into a covering of tachash skin, and have put [it] on the bar.
11 “Ní orí pẹpẹ wúrà ni kí wọn ó tẹ́ aṣọ aláró kan sí, wọn yóò sì fi awọ seali bò ó, kí wọ́n sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
And they spread a garment of blue over the golden altar, and have covered it with a covering of tachash skin, and have placed its poles,
12 “Kí wọn kó gbogbo ohun èlò tí wọ́n ń lò fún iṣẹ́ ìsìn ní ibi mímọ́, kí wọn ó fi aṣọ aláwọ̀ búlúù yìí, kí wọn ó sì fi awọ seali bò ó, kí wọn ó sì fi gbé wọn ka orí férémù.
and have taken all the vessels of ministry with which they minister in the holy place, and have put [them] into a garment of blue, and have covered them with a covering of tachash skin, and have put [them] on the bar,
13 “Kí wọn ó kó eérú kúrò lórí pẹpẹ idẹ, kí wọn ó sì tẹ́ aṣọ aláwọ̀ àlùkò lé e lórí.
and have removed the ashes of the altar, and have spread a garment of purple over it,
14 Nígbà náà ni kí wọn ó kó gbogbo ohun èlò fún iṣẹ́ ìsìn níbi pẹpẹ, títí dórí àwo iná, fọ́ọ̀kì ẹran, ọkọ́ eérú àti àwokòtò. Kí wọn ó fi awọ ewúrẹ́ bo gbogbo rẹ̀, kí wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
and have put on it all its vessels with which they minister on it—the censers, the hooks, and the shovels, and the bowls, all the vessels of the altar—and have spread a covering of tachash skin on it, and have placed its poles.
15 “Lẹ́yìn tí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ti parí bíbo ibi mímọ́ àti gbogbo ohun èlò ibi mímọ́, nígbà tí àgọ́ bá sì ṣetán láti tẹ̀síwájú, kí àwọn ọmọ Kohati bọ́ síwájú láti gbé e, ṣùgbọ́n wọn kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan ohun mímọ́ kankan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀ wọn ó kú. Àwọn ọmọ Kohati ni yóò gbé gbogbo ohun tó wà nínú àgọ́ ìpàdé.
And Aaron has finished—his sons also—covering the holy place, and all the vessels of the holy place, in the journeying of the camp, and afterward the sons of Kohath come in to carry [it], and they do not come to the holy thing, lest they have died; these [things are] the burden of the sons of Kohath in the Tent of Meeting.
16 “Iṣẹ́ Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni ṣíṣe àbojútó òróró fìtílà, tùràrí dídùn, ẹbọ ohun jíjẹ ìgbà gbogbo àti òróró ìtasórí. Kí ó jẹ́ alábojútó gbogbo ohun tó jẹ mọ́ àgọ́ àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò ibi mímọ́.”
And the oversight of Eleazar, son of Aaron the priest, [is] the oil of the lamp, and the spice-incense, and the present of continuity, and the anointing oil, the oversight of all the Dwelling Place and of all that [is] in it, in the sanctuary and in its vessels.”
17 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
And YHWH speaks to Moses and to Aaron, saying,
18 “Rí i pé a kò gé ẹ̀yà Kohati kúrò lára àwọn ọmọ Lefi.
“You do not cut off the tribe of the families of the Kohathite from the midst of the Levites;
19 Nítorí kí wọ́n lè yè, kí wọ́n má ba à kú nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ tòsí àwọn ohun mímọ́ jùlọ: Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni kí ó wọ ibi mímọ́ láti pín iṣẹ́ oníkálùkù àti àwọn ohun tí wọn yóò gbé.
but do this for them, and they have lived and do not die in their drawing near [to] the Holy of Holies: Aaron and his sons go in, and have set them, each man to his service, and to his burden,
20 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Kohati kò gbọdọ̀ wọlé láti wo àwọn ohun mímọ́, bó tilẹ̀ jẹ́ ìṣẹ́jú kan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kú.”
and they do not go in to see when the holy thing is swallowed, lest they have died.”
21 Olúwa sọ fún Mose pé,
And YHWH speaks to Moses, saying,
22 “Tún ka iye àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
“Also take a census of the sons of Gershon by the house of their fathers, by their families;
23 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
from a son of thirty years and upward, until a son of fifty years, you number them—everyone who is going in to serve the host, to do the service in the Tent of Meeting.
24 “Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni, bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ àti ní ẹrù rírù.
This [is] the service of the families of the Gershonite, to serve and for burden:
25 Àwọn ni yóò máa ru àwọn aṣọ títa ti àgọ́, ti àgọ́ ìpàdé àti ìbòrí rẹ̀, àti awọ ewúrẹ́ tí a fi bò ó, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
and they have carried the curtains of the Dwelling Place, and the Tent of Meeting, its covering, and the covering of the tachash [skin] which [is] on it above, and the veil at the opening of the Tent of Meeting,
26 aṣọ títa ti àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí àgbàlá, okùn àti àwọn ohun èlò iṣẹ́ ìsìn, àti ohun gbogbo tí à ń lò fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn ó máa sìn. Àwọn ọmọ Gerṣoni ni yóò ṣe gbogbo ohun tó bá yẹ pẹ̀lú àwọn nǹkan wọ̀nyí.
and the hangings of the court, and the veil at the opening of the gate of the court which [is] by the Dwelling Place, and by the altar all around, and their cords, and all the vessels of their service, and all that is made for them—and they have served.
27 Gbogbo iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Gerṣoni yálà ni iṣẹ́ ṣíṣe tàbí ní ẹrù rírù ni, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóò máa darí wọn; ìwọ ni kí o sì yàn ẹrù tí oníkálùkù yóò rù fún un.
By the command of Aaron and his sons is all the service of the sons of the Gershonite, in all their burden and in all their service; and you have laid a charge on them concerning the charge of all their burden.
28 Èyí ni iṣẹ́ ìdílé àwọn Gerṣoni ni àgọ́ ìpàdé Itamari, ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni yóò sì jẹ alábojútó iṣẹ́ wọn.
This [is] the service of the families of the sons of the Gershonite in the Tent of Meeting; and their charge [is] under the hand of Ithamar son of Aaron the priest.
29 “Ka iye àwọn ọmọ Merari nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
The sons of Merari, by their families, by the house of their fathers—you number them;
30 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
from a son of thirty years and upward even to a son of fifty years, you number them—everyone who is going in to the host, to do the service of the Tent of Meeting.
31 Iṣẹ́ tí wọn yóò sì máa ṣe nínú àgọ́ ìpàdé nìyìí: gbígbẹ́ àwọn férémù àgọ́, pákó ìdábùú rẹ̀, òpó àti ihò òpó rẹ̀,
And this [is] the charge of their burden, of all their service in the Tent of Meeting: the boards of the Dwelling Place, and its bars, and its pillars, and its sockets,
32 pẹ̀lú gbogbo òpó tó yí àgbàlá ká àti ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn, kí o sì yan ohun tí oníkálùkù yóò rù fún un.
and the pillars of the court all around, and their sockets, and their pins, and their cords, of all their vessels, and of all their service; and you number the vessels of the charge of their burden by name.
33 Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Merari, bí wọn yóò ti máa ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé lábẹ́ àkóso Itamari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà.”
This [is] the service of the families of the sons of Merari, for all their service, in the Tent of Meeting, by the hand of Ithamar son of Aaron the priest.”
34 Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn olórí ìjọ ènìyàn ka àwọn ọmọ Kohati nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
And Moses numbers—Aaron also, and the princes of the congregation—the sons of the Kohathite, by their families, and by the house of their fathers,
35 Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní Àgọ́ ìpàdé.
from a son of thirty years and upward even to a son of fifty years, everyone who is going in to the host, for service in the Tent of Meeting,
36 Iye wọn nípa ìdílé jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlá ó dín làádọ́ta.
and their numbered ones, by their families, are two thousand seven hundred and fifty.
37 Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé; tí Mose àti Aaroni kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
These [are] those numbered of the families of the Kohathite, everyone who is serving in the Tent of Meeting, whom Moses and Aaron numbered by the command of YHWH, by the hand of Moses.
38 Wọ́n ka àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
And those numbered of the sons of Gershon, by their families, and by the house of their fathers,
39 Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, gbogbo àwọn tó lè ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
from a son of thirty years and upward even to a son of fifty years, everyone who is going in to the host, for service in the Tent of Meeting,
40 Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá ó lé ọgbọ̀n.
even their numbered ones, by their families, by the house of their fathers, are two thousand and six hundred and thirty.
41 Èyí jẹ́ àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Gerṣoni, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé. Mose àti Aaroni ṣe bí àṣẹ Olúwa.
These [are] those numbered of the families of the sons of Gershon, everyone who is serving in the Tent of Meeting, whom Moses and Aaron numbered by the command of YHWH.
42 Wọ́n ka àwọn ọmọ Merari nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
And those numbered of the families of the sons of Merari, by their families, by the house of their fathers,
43 Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
from a son of thirty years and upward even to a son of fifty years, everyone who is going in to the host, for service in the Tent of Meeting,
44 Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún.
even their numbered ones, by their families, are three thousand and two hundred.
45 Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Merari. Mose àti Aaroni kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
These [are] those numbered of the families of the sons of Merari, whom Moses and Aaron numbered by the command of YHWH, by the hand of Moses.
46 Gbogbo àwọn tí a kà nínú àwọn ọmọ Lefi, ti Mose àti Aaroni àti àwọn olórí Israẹli kà, nípa ìdílé wọn àti gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
All those numbered, whom Moses numbered—Aaron also, and the princes of Israel—of the Levites, by their families, and by the house of their fathers,
47 Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, àwọn tó ń ṣiṣẹ́ ìsìn tó sì ń ru àwọn ẹrù inú Àgọ́ ìpàdé.
from a son of thirty years and upward even to a son of fifty years, everyone who is going in to do the work of the service, even the service of burden in the Tent of Meeting,
48 Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá lé lẹ́gbàarin ó dín ogún.
even their numbered ones are eight thousand and five hundred and eighty;
49 Wọ́n yan iṣẹ́ àti àwọn ohun tí ẹni kọ̀ọ̀kan yóò máa gbé fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
he has numbered them by the command of YHWH, by the hand of Moses, each man by his service, and by his burden, with his numbered ones, as YHWH has commanded Moses.

< Numbers 4 >