< Numbers 4 >

1 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
And Jehovah spoke to Moses and to Aaron, saying,
2 “Ka iye àwọn ọmọ Kohati láàrín àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
Take the sum of the sons of Kohath from among the sons of Levi, after their families, according to their fathers' houses,
3 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń ṣiṣẹ́ nínú àgọ́ ìpàdé.
from thirty years old and upward even unto fifty years old, all that enter into the service, to do the work in the tent of meeting.
4 “Wọ̀nyí ni iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Kohati nínú àgọ́ àjọ, láti tọ́jú àwọn ohun èlò mímọ́ jùlọ.
This shall be the service of the sons of Kohath in the tent of meeting: it is most holy.
5 Nígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò wọ inú rẹ̀, wọn yóò sí aṣọ ìbòrí rẹ̀, wọn yóò sì fi bo àpótí ẹ̀rí.
And when the camp setteth forward, Aaron and his sons shall go in, and they shall take down the veil of separation and cover the ark of testimony with it;
6 Wọn yóò sì fi awọ ewúrẹ́ bò ó, lórí awọ ewúrẹ́ yìí ni wọn ó tẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
and shall put thereon a covering of badgers' skin, and shall spread over it a cloth wholly of blue, and shall put its staves [to it].
7 “Lórí tábìlì àkàrà ìfihàn ni kí wọn ó na aṣọ aláró kan sí, kí wọn kí ó sì fi àwopọ̀kọ́ sórí rẹ̀, àti ṣíbí àti àwokòtò àti ìgò fún ọrẹ ohun mímu; àti àkàrà ìgbà gbogbo ní kí ó wà lórí rẹ̀.
And upon the table of shewbread they shall spread a cloth of blue; and put thereon the dishes, and the cups, and the bowls, and goblets of the drink-offering; and the continual bread shall be thereon.
8 Lórí gbogbo nǹkan wọ̀nyí ni wọn yóò da, wọn ó tún fi awọ ewúrẹ́ bò ó, wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
And they shall spread upon them a cloth of scarlet, and cover it with a covering of badgers' skin, and shall put its staves [to it].
9 “Kí wọn kí ó sì mú aṣọ aláwọ̀ aláró kan, kí wọn kí ó sì fi bo ọ̀pá fìtílà àti fìtílà rẹ̀, àti alumagaji rẹ̀, àti àwo alumagaji rẹ̀, àti gbogbo ohun èlò òróró rẹ̀, èyí tí wọ́n fi ń ṣe iṣẹ́ rẹ̀.
And they shall take a cloth of blue, and cover the candlestick of the light, and its lamps, and its snuffers, and its snuff-trays, and all the oil vessels thereof, wherewith they perform its service;
10 Kí wọn ó fi awọ ẹran yí fìtílà àti gbogbo ohun èlò rẹ, kí wọn kí ó sì gbé e lé orí férémù tí wọn yóò fi gbé e.
and they shall put it and all the utensils thereof within a covering of badgers' skin, and shall put it upon a pole.
11 “Ní orí pẹpẹ wúrà ni kí wọn ó tẹ́ aṣọ aláró kan sí, wọn yóò sì fi awọ seali bò ó, kí wọ́n sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
And upon the golden altar they shall spread a cloth of blue, and cover it with a covering of badgers' skin, and shall put its staves [to it].
12 “Kí wọn kó gbogbo ohun èlò tí wọ́n ń lò fún iṣẹ́ ìsìn ní ibi mímọ́, kí wọn ó fi aṣọ aláwọ̀ búlúù yìí, kí wọn ó sì fi awọ seali bò ó, kí wọn ó sì fi gbé wọn ka orí férémù.
And they shall take all the instruments of service, wherewith they serve in the sanctuary, and put them in a cloth of blue, and cover them with a covering of badgers' skin, and shall put them upon a pole.
13 “Kí wọn ó kó eérú kúrò lórí pẹpẹ idẹ, kí wọn ó sì tẹ́ aṣọ aláwọ̀ àlùkò lé e lórí.
And they shall cleanse the altar of the ashes, and spread a purple cloth thereon;
14 Nígbà náà ni kí wọn ó kó gbogbo ohun èlò fún iṣẹ́ ìsìn níbi pẹpẹ, títí dórí àwo iná, fọ́ọ̀kì ẹran, ọkọ́ eérú àti àwokòtò. Kí wọn ó fi awọ ewúrẹ́ bo gbogbo rẹ̀, kí wọn ó sì fi òpó rẹ̀ bọ ààyè rẹ̀.
and they shall put upon it all the utensils thereof, wherewith they perform service about it: the firepans, the forks, and the shovels, and the bowls, — all the utensils of the altar; and they shall spread upon it a covering of badgers' skin, and put its staves [to it].
15 “Lẹ́yìn tí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ti parí bíbo ibi mímọ́ àti gbogbo ohun èlò ibi mímọ́, nígbà tí àgọ́ bá sì ṣetán láti tẹ̀síwájú, kí àwọn ọmọ Kohati bọ́ síwájú láti gbé e, ṣùgbọ́n wọn kò gbọdọ̀ fọwọ́ kan ohun mímọ́ kankan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀ wọn ó kú. Àwọn ọmọ Kohati ni yóò gbé gbogbo ohun tó wà nínú àgọ́ ìpàdé.
And when Aaron and his sons have ended covering the sanctuary, and all the utensils of the sanctuary, when the camp setteth forward, then afterwards the sons of Kohath shall come to carry it; but they shall not touch the holy things, lest they die. This is what the sons of Kohath have to carry in the tent of meeting.
16 “Iṣẹ́ Eleasari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni ṣíṣe àbojútó òróró fìtílà, tùràrí dídùn, ẹbọ ohun jíjẹ ìgbà gbogbo àti òróró ìtasórí. Kí ó jẹ́ alábojútó gbogbo ohun tó jẹ mọ́ àgọ́ àti gbogbo ohun tó wà nínú rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò ibi mímọ́.”
And Eleazar the son of Aaron the priest shall have the oversight of the oil for the light, and the fragrant incense, and the continual oblation, and the anointing oil, — the oversight of the whole tabernacle, and of all that is therein, over the sanctuary, and over its furniture.
17 Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
And Jehovah spoke to Moses and to Aaron, saying,
18 “Rí i pé a kò gé ẹ̀yà Kohati kúrò lára àwọn ọmọ Lefi.
Ye shall not cut off the families of the Kohathites from among the Levites,
19 Nítorí kí wọ́n lè yè, kí wọ́n má ba à kú nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ tòsí àwọn ohun mímọ́ jùlọ: Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni kí ó wọ ibi mímọ́ láti pín iṣẹ́ oníkálùkù àti àwọn ohun tí wọn yóò gbé.
but this shall ye do unto them, that they may live, and not die, when they draw near unto the most holy things: Aaron and his sons shall go in, and appoint them every one to his service and to his burden;
20 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Kohati kò gbọdọ̀ wọlé láti wo àwọn ohun mímọ́, bó tilẹ̀ jẹ́ ìṣẹ́jú kan, bí wọ́n bá ṣe bẹ́ẹ̀, wọn yóò kú.”
but they shall not go in and see for a moment the holy things, lest they die.
21 Olúwa sọ fún Mose pé,
And Jehovah spoke to Moses, saying,
22 “Tún ka iye àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
Take also the sum of the sons of Gershon, according to their fathers' houses, after their families.
23 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
From thirty years old and upward to fifty years old shalt thou number them; every one that cometh to labour in the work, to perform the service in the tent of meeting.
24 “Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni, bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ àti ní ẹrù rírù.
This shall be the service of the families of the Gershonites, in serving, and in carrying:
25 Àwọn ni yóò máa ru àwọn aṣọ títa ti àgọ́, ti àgọ́ ìpàdé àti ìbòrí rẹ̀, àti awọ ewúrẹ́ tí a fi bò ó, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
they shall carry the curtains of the tabernacle, and the tent of meeting, its covering, and the covering of badgers' skin that is above upon it, and the curtain of the entrance to the tent of meeting,
26 aṣọ títa ti àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí àgbàlá, okùn àti àwọn ohun èlò iṣẹ́ ìsìn, àti ohun gbogbo tí à ń lò fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn ó máa sìn. Àwọn ọmọ Gerṣoni ni yóò ṣe gbogbo ohun tó bá yẹ pẹ̀lú àwọn nǹkan wọ̀nyí.
and the hangings of the court, and the curtain of the entrance, of the gate of the court, which surroundeth the tabernacle and the altar, and the cords thereof, and all the instruments of their service; and all that is to be done for these things shall they perform.
27 Gbogbo iṣẹ́ ìsìn àwọn ọmọ Gerṣoni yálà ni iṣẹ́ ṣíṣe tàbí ní ẹrù rírù ni, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni yóò máa darí wọn; ìwọ ni kí o sì yàn ẹrù tí oníkálùkù yóò rù fún un.
At the commandment of Aaron and his sons shall be all the service of the sons of the Gershonites, in all their carrying, and in all their service; and ye shall appoint unto them in charge all their carrying.
28 Èyí ni iṣẹ́ ìdílé àwọn Gerṣoni ni àgọ́ ìpàdé Itamari, ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ni yóò sì jẹ alábojútó iṣẹ́ wọn.
This is the service of the families of the sons of Gershon in the tent of meeting, and their charge shall be under the hand of Ithamar the son of Aaron the priest.
29 “Ka iye àwọn ọmọ Merari nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn.
The sons of Merari: after their families, according to their fathers' houses shalt thou number them;
30 Ka gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
from thirty years old and upward even to fifty years old shalt thou number them, every one that entereth into the labour, to perform the service of the tent of meeting.
31 Iṣẹ́ tí wọn yóò sì máa ṣe nínú àgọ́ ìpàdé nìyìí: gbígbẹ́ àwọn férémù àgọ́, pákó ìdábùú rẹ̀, òpó àti ihò òpó rẹ̀,
And this shall be the charge of their burden, according to all their service in the tent of meeting: the boards of the tabernacle, and the bars thereof, and the pillars thereof, and bases thereof,
32 pẹ̀lú gbogbo òpó tó yí àgbàlá ká àti ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn, kí o sì yan ohun tí oníkálùkù yóò rù fún un.
and the pillars of the court round about, and their bases, and their pegs, and their cords, all their instruments, according to all their service; and by name ye shall number to them the materials which are their charge to carry.
33 Èyí ni iṣẹ́ ìsìn ìdílé àwọn ọmọ Merari, bí wọn yóò ti máa ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé lábẹ́ àkóso Itamari ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà.”
This is the service of the families of the sons of Merari, according to all their service in the tent of meeting, under the hand of Ithamar the son of Aaron the priest.
34 Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn olórí ìjọ ènìyàn ka àwọn ọmọ Kohati nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
And Moses and Aaron and the princes of the assembly numbered the sons of the Kohathites after their families, and according to their fathers' houses,
35 Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún gbogbo àwọn tó ń wá ṣiṣẹ́ ní Àgọ́ ìpàdé.
from thirty years old and upward even to fifty years old, every one that entered into the labour, for service in the tent of meeting.
36 Iye wọn nípa ìdílé jẹ́ ẹgbẹ̀rìnlá ó dín làádọ́ta.
And those that were numbered of them according to their families were two thousand seven hundred and fifty.
37 Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Kohati tó ń ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé; tí Mose àti Aaroni kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
These are they that were numbered of the families of the Kohathites, every one that served in the tent of meeting, whom Moses and Aaron numbered according to the commandment of Jehovah through Moses.
38 Wọ́n ka àwọn ọmọ Gerṣoni nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
And those that were numbered of the sons of Gershon, after their families, and according to their fathers' houses,
39 Gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, gbogbo àwọn tó lè ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
from thirty years old and upward even to fifty years old, every one that entered into the labour, for service in the tent of meeting,
40 Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá ó lé ọgbọ̀n.
even those that were numbered of them, after their families, according to their fathers' houses, were two thousand six hundred and thirty.
41 Èyí jẹ́ àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Gerṣoni, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé. Mose àti Aaroni ṣe bí àṣẹ Olúwa.
These are they that were numbered of the families of the sons of Gershon, all that served in the tent of meeting, whom Moses and Aaron numbered according to the commandment of Jehovah.
42 Wọ́n ka àwọn ọmọ Merari nípa ìdílé àti ilé baba wọn.
And those that were numbered of the families of the sons of Merari, after their families, according to their fathers' houses,
43 Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta ọdún, àwọn tó ṣiṣẹ́ ní àgọ́ ìpàdé.
from thirty years old and upward even to fifty years old, every one that entered into the labour, for service in the tent of meeting,
44 Iye wọn nípa ìdílé àti ilé baba wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rìndínlógún.
even those that were numbered of them according to their families, were three thousand two hundred.
45 Èyí ni àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Merari. Mose àti Aaroni kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose.
These are they that were numbered of the families of the sons of Merari, whom Moses and Aaron numbered according to the commandment of Jehovah through Moses.
46 Gbogbo àwọn tí a kà nínú àwọn ọmọ Lefi, ti Mose àti Aaroni àti àwọn olórí Israẹli kà, nípa ìdílé wọn àti gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
All those that were numbered of the Levites, whom Moses and Aaron and the princes of Israel numbered, after their families and according to their fathers' houses,
47 Gbogbo ọkùnrin láti ọmọ ọgbọ̀n ọdún títí dé àádọ́ta, àwọn tó ń ṣiṣẹ́ ìsìn tó sì ń ru àwọn ẹrù inú Àgọ́ ìpàdé.
from thirty years old and upward even to fifty years old, every one that came to serve [in] the work of the service, and [in] the work of carrying, in the tent of meeting,
48 Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbẹ̀tàlá lé lẹ́gbàarin ó dín ogún.
even those that were numbered of them, were eight thousand five hundred and eighty.
49 Wọ́n yan iṣẹ́ àti àwọn ohun tí ẹni kọ̀ọ̀kan yóò máa gbé fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
According to the commandment of Jehovah they were numbered by Moses, every one for his service, and for his burden, and numbered by him, as Jehovah had commanded Moses.

< Numbers 4 >