< Numbers 36 >

1 Àwọn olórí ìdílé Gileadi, ọmọkùnrin Makiri ọmọ Manase tí ó wá láti ara ìdílé ìran Josẹfu wá, wọ́n sì sọ̀rọ̀ níwájú Mose àti àwọn olórí, àwọn ìdílé Israẹli.
Wtedy przystąpili naczelnicy spośród ojców synów Gileada, syna Makira, syna Manassesa, z domów Józefa, i mówili przed Mojżeszem i przed książętami, naczelnikami ojców synów Izraela:
2 Wọ́n sọ pé, “Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún olúwa mi láti fi ilẹ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ogún nípa kèké ṣíṣẹ́. Ó pa á láṣẹ fún ọ láti fi ogún Selofehadi arákùnrin wa fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀.
PAN nakazał memu panu rozdzielić ziemię w dziedzictwo synom Izraela przez losowanie; mojemu panu rozkazano też przez PANA dać dziedzictwo naszego brata Selofchada jego córkom.
3 Wàyí, tí wọn bá fẹ́ ọkùnrin láti ẹ̀yà Israẹli mìíràn; nígbà náà a ó gba ogún un wọn kúrò nínú ogún ìran wa, a ó sì fi kún ogún ẹ̀yà tí a fẹ́ wọn sí. Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gbà á kúrò nínú ìpín ilẹ̀ ogún ti wa.
Jeśli więc któryś z synów [innego] pokolenia synów Izraela pojmie je [za żony], to ich dziedzictwo zostanie odjęte od dziedzictwa naszych ojców i przyłączone do dziedzictwa pokolenia, do którego będą należeć; w ten sposób nasze dziedzictwo się zmniejszy.
4 Nígbà tí ọdún ìdásílẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli bá dé, a ó pa ogún wọn pọ̀ mọ́ ẹ̀yà tí wọ́n fẹ́ wọn sí, a ó sì gba ogún ẹ̀yà wọn kúrò lọ́wọ́ baba ńlá wọn.”
A gdy nadejdzie rok jubileuszowy dla synów Izraela, wtedy ich dziedzictwo zostanie przyłączone do dziedzictwa pokolenia, do którego będą należeć; i tak ich dziedzictwo zostanie odjęte od dziedzictwa pokolenia naszych ojców.
5 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa, Mose pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ohun ti ẹ̀yà àwọn ìran Josẹfu ń sọ tọ̀nà.
Wtedy Mojżesz rozkazał synom Izraela zgodnie ze słowem PANA: Słusznie mówi pokolenie synów Józefa.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ fún àwọn ọmọbìnrin Selofehadi: wọ́n lè fẹ́ ẹni tí ọkàn wọn fẹ́, kìkì pé wọ́n fẹ́ nínú ẹ̀yà ìdílé baba wọn.
Oto co PAN rozkazał w sprawie córek Selofchada: Niech wychodzą za mąż, za kogo chcą, ale mogą wyjść tylko za kogoś z domu pokolenia swoich ojców;
7 Kò sí ogún kan ní Israẹli tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà mìíràn, nítorí gbogbo ọmọ Israẹli ni yóò fi ilẹ̀ ogún ẹ̀yà tí wọ́n jogún láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn pamọ́.
Aby dziedzictwo synów Izraela nie było przenoszone z [jednego] pokolenia na [drugie] pokolenie. Każdy bowiem z synów Izraela ma pozostać przy dziedzictwie pokolenia swoich ojców.
8 Gbogbo ọmọbìnrin tí ó bá jogún ilẹ̀ nínú ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ fẹ́ ènìyàn nínú ẹ̀yà ìdílé baba rẹ̀, kí gbogbo ọmọ Israẹli lè ní ìpín nínú ogún baba wọn.
I każda córka, która posiada dziedzictwo w jakimś pokoleniu synów Izraela, wyjdzie za mąż za kogoś z domu pokolenia swego ojca, aby synowie Izraela dziedziczyli, każdy dziedzictwo swoich ojców.
9 Kò sí ogún kankan tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà òmíràn, nítorí olúkúlùkù ẹ̀yà ọmọ Israẹli gbọdọ̀ tọ́jú ilẹ̀ tí ó jogún.”
Dziedzictwo bowiem nie będzie przenoszone z [jednego] pokolenia na drugie pokolenie, lecz każde z pokoleń synów Izraela ma pozostać przy swoim dziedzictwie.
10 Nígbà náà, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
Jak PAN rozkazał Mojżeszowi, tak uczyniły córki Selofchada.
11 Nítorí pé a gbé Mahila, Tirsa, Hogla, Milka, àti Noa, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ní ìyàwó fún àwọn ọmọ arákùnrin baba wọn.
Bo Machla, Tirsa, Chogla, Milka i Noa, córki Selofchada, wyszły za mąż za synów swoich stryjów.
12 Wọ́n fẹ́ ọkọ nínú ìdílé ìran Manase, ọmọ Josẹfu ogún wọn kù nínú ìdílé àti ẹ̀yà baba wọn.
Wyszły za mąż w rodzinach synów Manassesa, syna Józefa; w ten sposób ich dziedzictwo pozostało przy pokoleniu domu ich ojca.
13 Wọ̀nyí ni àṣẹ àti ìdájọ́ tí Olúwa ti ipasẹ̀ Mose fún àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani létí Jeriko.
To są przykazania i prawa, które PAN nakazał synom Izraela przez Mojżesza na równinach Moabu, nad Jordanem, [naprzeciw] Jerycha.

< Numbers 36 >