< Numbers 36 >

1 Àwọn olórí ìdílé Gileadi, ọmọkùnrin Makiri ọmọ Manase tí ó wá láti ara ìdílé ìran Josẹfu wá, wọ́n sì sọ̀rọ̀ níwájú Mose àti àwọn olórí, àwọn ìdílé Israẹli.
Kwasekusondela inhloko zaboyise zensendo zabantwana bakoGileyadi indodana kaMakiri indodana kaManase, abosendo lwabantwana bakoJosefa, zakhuluma phambi kukaMozisi laphambi kweziphathamandla, inhloko zaboyise babantwana bakoIsrayeli,
2 Wọ́n sọ pé, “Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún olúwa mi láti fi ilẹ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ogún nípa kèké ṣíṣẹ́. Ó pa á láṣẹ fún ọ láti fi ogún Selofehadi arákùnrin wa fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀.
zathi: INkosi yalaya inkosi yami ukuthi iphe abantwana bakoIsrayeli ilizwe njengelifa ngenkatho; futhi inkosi yami yalaywa yiNkosi ukuthi inike ilifa likaZelofehadi umfowethu kumadodakazi akhe.
3 Wàyí, tí wọn bá fẹ́ ọkùnrin láti ẹ̀yà Israẹli mìíràn; nígbà náà a ó gba ogún un wọn kúrò nínú ogún ìran wa, a ó sì fi kún ogún ẹ̀yà tí a fẹ́ wọn sí. Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gbà á kúrò nínú ìpín ilẹ̀ ogún ti wa.
Uba esendela kwenye yamadodana ezizwe zabantwana bakoIsrayeli, ilifa lawo lizasuswa elifeni labobaba, lengezelelwe elifeni lalesosizwe azakuba ngawaso; ngalokho lizasuswa kunkatho yelifa lethu.
4 Nígbà tí ọdún ìdásílẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli bá dé, a ó pa ogún wọn pọ̀ mọ́ ẹ̀yà tí wọ́n fẹ́ wọn sí, a ó sì gba ogún ẹ̀yà wọn kúrò lọ́wọ́ baba ńlá wọn.”
Lalapho kuzakuba lijubili labantwana bakoIsrayeli, ilifa lawo lizakwengezelelwa elifeni lalesosizwe azakuba ngawaso; ngalokho ilifa lawo lizasuswa elifeni lesizwe sabobaba.
5 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa, Mose pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ohun ti ẹ̀yà àwọn ìran Josẹfu ń sọ tọ̀nà.
UMozisi waselaya abantwana bakoIsrayeli ngokomlomo weNkosi esithi: Isizwe sabantwana bakoJosefa sikhulume kuhle.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ fún àwọn ọmọbìnrin Selofehadi: wọ́n lè fẹ́ ẹni tí ọkàn wọn fẹ́, kìkì pé wọ́n fẹ́ nínú ẹ̀yà ìdílé baba wọn.
Le yinto iNkosi eyilayileyo mayelana lamadodakazi kaZelofehadi isithi: Kawendele kulabo abahle emehlweni awo, kodwa kawendele osendweni lwesizwe sikayise.
7 Kò sí ogún kan ní Israẹli tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà mìíràn, nítorí gbogbo ọmọ Israẹli ni yóò fi ilẹ̀ ogún ẹ̀yà tí wọ́n jogún láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn pamọ́.
Ngalokho ilifa labantwana bakoIsrayeli kalingabhodi lisuke esizweni liye esizweni, ngoba abantwana bakoIsrayeli bazanamathela, ngulowo lalowo elifeni lesizwe saboyise.
8 Gbogbo ọmọbìnrin tí ó bá jogún ilẹ̀ nínú ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ fẹ́ ènìyàn nínú ẹ̀yà ìdílé baba rẹ̀, kí gbogbo ọmọ Israẹli lè ní ìpín nínú ogún baba wọn.
Layileyo laleyo indodakazi edla ilifa esizweni sabantwana bakoIsrayeli izakwendela komunye wosendo wesizwe sikayise, ukuze abantwana bakoIsrayeli badle ilifa, omunye lomunye ilifa laboyise.
9 Kò sí ogún kankan tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà òmíràn, nítorí olúkúlùkù ẹ̀yà ọmọ Israẹli gbọdọ̀ tọ́jú ilẹ̀ tí ó jogún.”
Ngalokho ilifa kaliyikubhoda lisuke esizweni liye kwesinye isizwe, ngoba izizwe zabantwana bakoIsrayeli zizanamathela, ngulowo lalowo elifeni lakhe.
10 Nígbà náà, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
Njengokulaya kweNkosi kuMozisi enza njalo amadodakazi kaZelofehadi;
11 Nítorí pé a gbé Mahila, Tirsa, Hogla, Milka, àti Noa, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ní ìyàwó fún àwọn ọmọ arákùnrin baba wọn.
ngoba uMahla, uTiriza, loHogila, loMilka, loNowa, amadodakazi kaZelofehadi, endela emadodaneni abafowabo bakayise.
12 Wọ́n fẹ́ ọkọ nínú ìdílé ìran Manase, ọmọ Josẹfu ogún wọn kù nínú ìdílé àti ẹ̀yà baba wọn.
Endela kunsendo zabantwana bakoManase indodana kaJosefa, lelifa lawo lahlala esizweni sosendo lukayise.
13 Wọ̀nyí ni àṣẹ àti ìdájọ́ tí Olúwa ti ipasẹ̀ Mose fún àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani létí Jeriko.
Le yimilayo lezahlulelo iNkosi eyazilaya abantwana bakoIsrayeli ngesandla sikaMozisi emagcekeni akoMowabi eJordani eJeriko.

< Numbers 36 >