< Numbers 36 >
1 Àwọn olórí ìdílé Gileadi, ọmọkùnrin Makiri ọmọ Manase tí ó wá láti ara ìdílé ìran Josẹfu wá, wọ́n sì sọ̀rọ̀ níwájú Mose àti àwọn olórí, àwọn ìdílé Israẹli.
Og de Øverste for Fædrenehusene i Gileads Børns Slægt, hans, som var en Søn af Makir, Manasse Søn, af Josefs Børns Slægt, gik frem, og de talede for Mose Ansigt og for Fyrsternes Ansigt, dem, som vare de Øverste for Fædrenehusene blandt Israels Børn,
2 Wọ́n sọ pé, “Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún olúwa mi láti fi ilẹ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ogún nípa kèké ṣíṣẹ́. Ó pa á láṣẹ fún ọ láti fi ogún Selofehadi arákùnrin wa fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀.
og de sagde: Herren har budet min Herre at give Israels Børn Landet til Arv ved Lod; og min Herre er befalet af Herren at give vor Broder Zelafehads Arv til hans Døtre;
3 Wàyí, tí wọn bá fẹ́ ọkùnrin láti ẹ̀yà Israẹli mìíràn; nígbà náà a ó gba ogún un wọn kúrò nínú ogún ìran wa, a ó sì fi kún ogún ẹ̀yà tí a fẹ́ wọn sí. Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gbà á kúrò nínú ìpín ilẹ̀ ogún ti wa.
men blive de en af de Sønner, som høre til de andre Israels Børns Stammer, til Hustruer, da vil deres Arv gaa bort fra vore Fædres Arv og lægges til den Stamme, som de gaa over til, og gaa bort fra vor Arvs Lod;
4 Nígbà tí ọdún ìdásílẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli bá dé, a ó pa ogún wọn pọ̀ mọ́ ẹ̀yà tí wọ́n fẹ́ wọn sí, a ó sì gba ogún ẹ̀yà wọn kúrò lọ́wọ́ baba ńlá wọn.”
og naar det bliver Jubelaar for Israels Børn, da lægges deres Arv til den Stammes Arv, som de gik over til; og dermed vil deres Arv gaa bort fra vore Fædres Stammes Arv.
5 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa, Mose pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ohun ti ẹ̀yà àwọn ìran Josẹfu ń sọ tọ̀nà.
Og Mose bød Israels Børn efter Herrens Mund og sagde: Josefs Børns Stamme taler ret.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ fún àwọn ọmọbìnrin Selofehadi: wọ́n lè fẹ́ ẹni tí ọkàn wọn fẹ́, kìkì pé wọ́n fẹ́ nínú ẹ̀yà ìdílé baba wọn.
Dette er det Ord, som Herren byder om Zelafehads Døtre og siger: De maa vorde dem til Hustruer, som synes gode for deres Øjne, kun at de vorde dem til Hustruer, som ere af deres Fædres Stammes Slægtskab,
7 Kò sí ogún kan ní Israẹli tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà mìíràn, nítorí gbogbo ọmọ Israẹli ni yóò fi ilẹ̀ ogún ẹ̀yà tí wọ́n jogún láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn pamọ́.
at Israels Børns Arv ej skal komme omkring fra en Stamme til en anden; men hver iblandt Israels Børn skal hænge ved sine Fædres Stammes Arv.
8 Gbogbo ọmọbìnrin tí ó bá jogún ilẹ̀ nínú ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ fẹ́ ènìyàn nínú ẹ̀yà ìdílé baba rẹ̀, kí gbogbo ọmọ Israẹli lè ní ìpín nínú ogún baba wọn.
Og hver Datter af Israels Børns Stammer, som arver nogen Arv, skal vorde en af sin Faders Stammes Slægtskab til Hustru, paa det Israels Børn kunne arve hver sine Fædres Arv,
9 Kò sí ogún kankan tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà òmíràn, nítorí olúkúlùkù ẹ̀yà ọmọ Israẹli gbọdọ̀ tọ́jú ilẹ̀ tí ó jogún.”
og at en Arv ikke skal komme omkring fra en Stamme til en anden Stamme; men Israels Børns Stammer skulle hænge hver ved sin Arv.
10 Nígbà náà, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
Som Herren havde befalet Mose, saa gjorde Zelafehads Døtre.
11 Nítorí pé a gbé Mahila, Tirsa, Hogla, Milka, àti Noa, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ní ìyàwó fún àwọn ọmọ arákùnrin baba wọn.
Og Mahela, Tirza og Hogla og Milka og Noa, Zelafehads Døtre, bleve deres Farbroders Sønners Hustruer.
12 Wọ́n fẹ́ ọkọ nínú ìdílé ìran Manase, ọmọ Josẹfu ogún wọn kù nínú ìdílé àti ẹ̀yà baba wọn.
Dem, som vare af Manasse Børns, Josefs Søns, Slægter, bleve de til Hustruer, og deres Arv blev hos deres Faders Slægtskabs Stamme.
13 Wọ̀nyí ni àṣẹ àti ìdájọ́ tí Olúwa ti ipasẹ̀ Mose fún àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani létí Jeriko.
Disse ere de Bud og de Love, som Herren bød ved Mose for Israels Børn paa Moabiternes slette Marker, ved Jordanen over for Jeriko.