< Numbers 36 >

1 Àwọn olórí ìdílé Gileadi, ọmọkùnrin Makiri ọmọ Manase tí ó wá láti ara ìdílé ìran Josẹfu wá, wọ́n sì sọ̀rọ̀ níwájú Mose àti àwọn olórí, àwọn ìdílé Israẹli.
Tada pristupe obiteljski glavari od roda sinova Gileada, sina Makirova, sina Manašeova, jednoga roda Josipovih sinova, te pred Mojsijem i starješinama, glavarima obitelji,
2 Wọ́n sọ pé, “Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún olúwa mi láti fi ilẹ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ogún nípa kèké ṣíṣẹ́. Ó pa á láṣẹ fún ọ láti fi ogún Selofehadi arákùnrin wa fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀.
reknu: “Jahve je naredio našemu gospodaru da kockom dade ovu zemlju u baštinu Izraelcima; nadalje, našem je gospodaru naredio Jahve da baštinu našega brata Selofhada dade njegovim kćerima.
3 Wàyí, tí wọn bá fẹ́ ọkùnrin láti ẹ̀yà Israẹli mìíràn; nígbà náà a ó gba ogún un wọn kúrò nínú ogún ìran wa, a ó sì fi kún ogún ẹ̀yà tí a fẹ́ wọn sí. Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gbà á kúrò nínú ìpín ilẹ̀ ogún ti wa.
Ali ako se one udaju za koga iz drugog izraelskoga plemena, onda će njihova baština biti otrgnuta od naše djedovske baštine i biti priključena baštini plemena kojemu one pripadnu. Tako će se okrnjiti baština koja kockom pripadne nama.
4 Nígbà tí ọdún ìdásílẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli bá dé, a ó pa ogún wọn pọ̀ mọ́ ẹ̀yà tí wọ́n fẹ́ wọn sí, a ó sì gba ogún ẹ̀yà wọn kúrò lọ́wọ́ baba ńlá wọn.”
A kada nastupi jubilej Izraelcima, baština će se tih žena dodati baštini plemena kojemu pripadnu. Tako će njihova baština biti oduzeta od baštine našega pradjedovskog plemena.”
5 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa, Mose pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ohun ti ẹ̀yà àwọn ìran Josẹfu ń sọ tọ̀nà.
I po zapovijedi Jahvinoj Mojsije naredi Izraelcima: “Pleme Josipovih sinova pravo govori.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ fún àwọn ọmọbìnrin Selofehadi: wọ́n lè fẹ́ ẹni tí ọkàn wọn fẹ́, kìkì pé wọ́n fẹ́ nínú ẹ̀yà ìdílé baba wọn.
Ovo naređuje Jahve za Selofhadove kćeri: Neka se one udaju za onoga koji im se učini dobar, samo neka se udaju u rod svoga očinskoga plemena.
7 Kò sí ogún kan ní Israẹli tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà mìíràn, nítorí gbogbo ọmọ Israẹli ni yóò fi ilẹ̀ ogún ẹ̀yà tí wọ́n jogún láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn pamọ́.
Baština Izraelaca ne smije se prenositi iz jednoga plemena u drugo; i svaki Izraelac mora ostati privezan uz pradjedovsku baštinu svoga plemena.
8 Gbogbo ọmọbìnrin tí ó bá jogún ilẹ̀ nínú ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ fẹ́ ènìyàn nínú ẹ̀yà ìdílé baba rẹ̀, kí gbogbo ọmọ Israẹli lè ní ìpín nínú ogún baba wọn.
Zato se svaka djevojka koja steče baštinu u izraelskim plemenima mora udati za nekoga u plemenu kojemu pripada rod joj očev, tako da bi svaki Izraelac sačuvao baštinu svoga oca.
9 Kò sí ogún kankan tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà òmíràn, nítorí olúkúlùkù ẹ̀yà ọmọ Israẹli gbọdọ̀ tọ́jú ilẹ̀ tí ó jogún.”
Tako se baština neće prenositi iz jednoga plemena u drugo, nego će svako izraelsko pleme prianjati uza svoju baštinu.”
10 Nígbà náà, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
Kako je Jahve Mojsiju naredio, tako su i učinile kćeri Selofhadove:
11 Nítorí pé a gbé Mahila, Tirsa, Hogla, Milka, àti Noa, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ní ìyàwó fún àwọn ọmọ arákùnrin baba wọn.
Mahla, Tirsa, Hogla, Milka i Noa, kćeri Selofhadove, udaše se za sinove svojih stričeva.
12 Wọ́n fẹ́ ọkọ nínú ìdílé ìran Manase, ọmọ Josẹfu ogún wọn kù nínú ìdílé àti ẹ̀yà baba wọn.
Kako su se udale u rod potomstva Manašea, Josipova sina, njihova je baština ostala u plemenu kojemu pripadaše rod im očev.
13 Wọ̀nyí ni àṣẹ àti ìdájọ́ tí Olúwa ti ipasẹ̀ Mose fún àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani létí Jeriko.
To su zapovijedi i zakoni koje je Jahve preko Mojsija izdao Izraelcima na Moapskim poljanama uz Jordan, nasuprot Jerihonu.

< Numbers 36 >