< Numbers 36 >

1 Àwọn olórí ìdílé Gileadi, ọmọkùnrin Makiri ọmọ Manase tí ó wá láti ara ìdílé ìran Josẹfu wá, wọ́n sì sọ̀rọ̀ níwájú Mose àti àwọn olórí, àwọn ìdílé Israẹli.
Joseph acaeng, Manasseh capa Makir, Makir capa Gilead imthung takoh lu koeknawk to angzoh o moe, Mosi, zaehoikungnawk hoi Israel imthung takoh lu koeknawk khaeah lokthuih o;
2 Wọ́n sọ pé, “Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún olúwa mi láti fi ilẹ̀ yìí fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ogún nípa kèké ṣíṣẹ́. Ó pa á láṣẹ fún ọ láti fi ogún Selofehadi arákùnrin wa fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀.
nihcae mah, Kaicae ih angraeng Mosi mah taham khethaih cung to vah moe, Israel kaminawk Kanaan prae toepsak hanah, Angraeng mah lokpaek boeh; Angraeng mah kaicae angraeng khaeah kaicae ih amnawk Zelophehad ih canunawk hanah qawk paek han ih kawng doeh a thuih boeh.
3 Wàyí, tí wọn bá fẹ́ ọkùnrin láti ẹ̀yà Israẹli mìíràn; nígbà náà a ó gba ogún un wọn kúrò nínú ogún ìran wa, a ó sì fi kún ogún ẹ̀yà tí a fẹ́ wọn sí. Bẹ́ẹ̀ ni a ó sì gbà á kúrò nínú ìpín ilẹ̀ ogún ti wa.
Nihcae loe kalah Israel acaengnawk khaeah sava sah o nahaeloe, ampanawk mah toep o ih qawk thung hoiah nihcae ih qawk to la o ueloe, sava sakhaih acaeng kaminawk ih qawk ah om tih; to tiah kaicae ih qawk to la o tih boeh.
4 Nígbà tí ọdún ìdásílẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli bá dé, a ó pa ogún wọn pọ̀ mọ́ ẹ̀yà tí wọ́n fẹ́ wọn sí, a ó sì gba ogún ẹ̀yà wọn kúrò lọ́wọ́ baba ńlá wọn.”
Israel caanawk ih Jubili to phak naah, nihcae ih qawk loe nihcae sava sakhaih acaengnawk ih qawk ah om tih, to tiah kam panawk khae hoi hak ih acaeng qawk to la o tih, tiah a naa o.
5 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa, Mose pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ohun ti ẹ̀yà àwọn ìran Josẹfu ń sọ tọ̀nà.
To naah Angraeng mah thuih ih lok baktih toengah, Mosi mah Israel kaminawk khaeah, Joseph ih caanawk mah thuih o ih lok loe amsoem.
6 Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ fún àwọn ọmọbìnrin Selofehadi: wọ́n lè fẹ́ ẹni tí ọkàn wọn fẹ́, kìkì pé wọ́n fẹ́ nínú ẹ̀yà ìdílé baba wọn.
Zelophehad ih canunawk hanah Angraeng mah thuih ih lok loe hae tiah oh; nihcae loe a koeh o koek ih kami khaeah sava sah o nasoe; toe ampa ih acaengnawk khae khue ah sava sak o han oh.
7 Kò sí ogún kan ní Israẹli tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà mìíràn, nítorí gbogbo ọmọ Israẹli ni yóò fi ilẹ̀ ogún ẹ̀yà tí wọ́n jogún láti ọ̀dọ̀ baba ńlá wọn pamọ́.
To pongah Israel acaeng thung ih qawk doeh acaeng maeto hoi maeto khaeah paqoi han om ai; Israel kaminawk boih ampanawk khae hoiah toep o ih qawk to pakuem o han oh.
8 Gbogbo ọmọbìnrin tí ó bá jogún ilẹ̀ nínú ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ fẹ́ ènìyàn nínú ẹ̀yà ìdílé baba rẹ̀, kí gbogbo ọmọ Israẹli lè ní ìpín nínú ogún baba wọn.
Kawbaktih Israel acaeng thungah doeh qawktoep canunawk loe, ampa ih acaeng thungah ni sava sak o han oh; to tiah Israel kaminawk boih mah ampanawk ih qawk to toep o tih.
9 Kò sí ogún kankan tí ó gbọdọ̀ kọjá láti ẹ̀yà kan sí ẹ̀yà òmíràn, nítorí olúkúlùkù ẹ̀yà ọmọ Israẹli gbọdọ̀ tọ́jú ilẹ̀ tí ó jogún.”
Qawk ah toep ih hmuen to acaeng maeto hoi maeto khaeah paqoi o hmah; Israel acaeng boih mah angmacae ih qawk to pakuem o han oh, tiah a thuih pae.
10 Nígbà náà, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
Angraeng mah Mosi khaeah thuih ih lok baktih toengah, Zelophehad canunawk mah sak o.
11 Nítorí pé a gbé Mahila, Tirsa, Hogla, Milka, àti Noa, àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ní ìyàwó fún àwọn ọmọ arákùnrin baba wọn.
Zelophehad canu, Mahlah, Tirzah, Hoglah, Milkah hoi Noah cae loe, ampa amnawk ih capanawk khaeah sava sak o.
12 Wọ́n fẹ́ ọkọ nínú ìdílé ìran Manase, ọmọ Josẹfu ogún wọn kù nínú ìdílé àti ẹ̀yà baba wọn.
Nihcae loe Joseph capa Manasseh ih caanawk khaeah sava sak o, to tiah nihcae ih qawk loe ampanawk ih acaeng thungah oh poe.
13 Wọ̀nyí ni àṣẹ àti ìdájọ́ tí Olúwa ti ipasẹ̀ Mose fún àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani létí Jeriko.
Hae loe Jeriko vangpui zaeh, Jordan vapui taengah kaom, Moab azawn ah, Angraeng mah Mosi patohhaih rang hoiah Israel kaminawk khaeah thuih ih lokpaekhaih hoi lokcaekhaih ah oh.

< Numbers 36 >