< Numbers 35 >

1 Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní Jordani tí ó rékọjá láti Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise în câmpiile lui Moab, lângă Iordan, aproape de Ierihon, spunând:
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti fún àwọn Lefi ní ilẹ̀ láti gbé lára ogún tí àwọn ọmọ Israẹli yóò jogún. Kí ẹ sì fún wọn ní ilẹ̀ lára pápá oko tútù, káàkiri ìlú.
Poruncește copiilor lui Israel, ca ei să dea leviților din moștenirea stăpânirii lor, cetăți pentru a locui în ele; și să dați de asemenea leviților împrejurimile cetăților lor, de jur împrejurul lor.
3 Nígbà náà, wọn yóò ní ìlú tí wọn yóò gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn, ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú gbogbo ìní wọn.
Și vor avea cetățile pentru a locui în ele; și împrejurimile vor fi pentru vitele lor și pentru bunurile lor și pentru toate animalele lor.
4 “Ilẹ̀ pápá oko tútù káàkiri ìlú tí ẹ ó fi fún àwọn ọmọ Lefi, wíwọ̀n rẹ̀ yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ (1,500 ẹsẹ̀ bàtà) láti ògiri ìlú náà.
Și împrejurimile cetăților, pe care să le dați leviților, se vor întinde de la zidul cetății în afară, o mie de coți de jur împrejur.
5 Lẹ́yìn ìlú náà, wọn ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́ lápá ibi ìhà ìlà-oòrùn, ẹgbẹ̀rún méjì ẹsẹ̀ bàtà ní ìhà gúúsù, ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà àríwá, kí ìlú náà sì wà ní àárín. Wọn yóò ní agbègbè yìí gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ pápá oko tútù fún ìlú náà.
Și să măsurați din afara cetății pe latura de est, două mii de coți, și pe latura de sud, două mii de coți, și pe latura de vest, două mii de coți, și pe latura de nord, două mii de coți; și cetatea să fie în mijloc; acestea să le fie împrejurimile cetăților.
6 “Mẹ́fà lára ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ ìlú ààbò, tí ẹni tí ó bá pa ènìyàn yóò sá sí. Ní àfikún, ẹ fún wọn ní méjìlélógójì ìlú sí i.
Și printre cetățile pe care să le dați leviților să fie șase cetăți de scăpare, pe care să le rânduiți pentru ucigașul de oameni, ca să poată fugi acolo; și lor să le adăugați patruzeci și două de cetăți.
7 Ní gbogbo rẹ̀, kí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi ní méjìdínláàádọ́ta ìlú lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Astfel, toate cetățile pe care să le dați leviților să fie patruzeci și opt de cetăți; pe ele să le dați împreună cu împrejurimile lor.
8 Ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi láti ara ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli jogún, olúkúlùkù kí ó fi nínú ìlú rẹ̀ fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní rẹ̀ tí ó ní. Gba púpọ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní púpọ̀ àti díẹ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní díẹ̀.”
Și cetățile pe care să le dați să fie din stăpânirea copiilor lui Israel; de la cei ce au multe să dați multe; dar de la cei ce au puține să dați puține; fiecare să dea dintre cetățile sale leviților, conform moștenirii sale pe care o moștenește.
9 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
Și DOMNUL i-a vorbit lui Moise, spunând:
10 “Sọ̀rọ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn: ‘Nígbà tí ẹ bá rékọjá odò Jordani sí Kenaani,
Vorbește copiilor lui Israel și spune-le: Când veți fi trecut peste Iordan în țara lui Canaan;
11 yan àwọn ìlú kan láti jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìlú ààbò fún yín, kí apani tó pa ènìyàn ní àìmọ̀ máa sálọ síbẹ̀.
Atunci să vă rânduiți cetăți care să fie cetăți de scăpare pentru voi; ca ucigașul să poată fugi acolo, cel ce ucide vreo persoană, fără intenție.
12 Wọn yóò jẹ́ ibi ìsásí kúrò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san, kí ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn má ba à kú kí ó tó dúró níwájú àwọn ìjọ àwọn ènìyàn ní ìdájọ́.
Și acestea să vă fie cetăți pentru scăpare din fața răzbunătorului; ca ucigașul să nu moară, până ce nu stă înaintea adunării, în judecată.
13 Mẹ́fà nínú ìlú tí ẹ ó fi fún wọn yóò jẹ́ ìlú ààbò fún yín.
Și din aceste cetăți, pe care le veți da, să fie șase cetăți de scăpare.
14 Yan ìlú mẹ́ta ní ìhà ti Jordani, kí ẹ sì yan ìlú mẹ́ta ní ìhà Kenaani tí yóò máa jẹ́ ìlú ìsásí.
Să dați trei cetăți de această parte a Iordanului și trei cetăți să dați în țara lui Canaan, care să fie cetăți de scăpare.
15 Ìlú mẹ́fà yìí yóò jẹ́ ìlú ìsásí fún àwọn ọmọ Israẹli, fún àjèjì àti ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbé láàrín wọn, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn ní àìmọ̀ sálọ síbẹ̀.
Aceste șase cetăți să fie de scăpare, deopotrivă pentru copiii lui Israel și pentru străinul și pentru cel ce locuiește temporar printre voi; ca fiecare om, care ucide fără intenție vreo persoană, să poată fugi acolo.
16 “‘Bí ọkùnrin kan bá fi ohun èlò irin lu ènìyàn tí ó kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa, apànìyàn náà.
Și dacă el îl lovește cu o unealtă de fier, încât acela moare, el este un ucigaș; ucigașul negreșit să fie dat morții.
17 Tàbí tí ènìyàn bá mú òkúta tí ó lè pa ènìyàn lọ́wọ́ tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa apànìyàn náà.
Și dacă îl lovește aruncând o piatră, de care poate muri și moare, el este ucigaș; ucigașul negreșit să fie dat morții.
18 Tàbí tí ènìyàn bá mú ohun èlò igi ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì lẹ̀ ẹ́ pa ènìyàn, tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni; pípa ní a ó pa apànìyàn náà.
Sau dacă îl lovește cu o armă de mână din lemn, de care poate muri și moare, el este ucigaș; ucigașul negreșit să fie dat morții.
19 Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà; tí ó bá bá a, yóò pa á.
Însuși răzbunătorul sângelui să ucidă pe ucigaș; când îl întâlnește, să îl ucidă.
20 Tí ẹnikẹ́ni tí ó bá ń yan odì pẹ̀lú ìríra tí ẹlòmíràn tàbí ju nǹkan sí i pẹ̀lú èrò, tí ó sì kú.
Iar dacă din ură îl împinge, sau aruncă ceva în el, stând la pândă, ca el să moară;
21 Tàbí pẹ̀lú ìjà gbangba lù ú pẹ̀lú ìkùùkuu tí ó sì kú, pípa ni a ó pa ẹni bẹ́ẹ̀; apànìyàn ni. Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà tí ó bá bá a.
Sau în dușmănie îl lovește cu mâna sa, încât acela moare; cel ce l-a lovit să fie negreșit dat morții, pentru că este un ucigaș; răzbunătorul sângelui să ucidă pe ucigaș, când îl întâlnește.
22 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá fi nǹkan gún un lójijì láìṣọ̀ta, tàbí tí ó sọ ohunkóhun lù ú láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ ṣe
Dar dacă îl împinge pe neașteptate fără dușmănie, sau a aruncat ceva lucru asupra lui, fără a sta la pândă,
23 tàbí, láìri, ju òkúta sí tí ó lè pa á, tí ó sì kú, nígbà tí kì í ṣe ọ̀tá rẹ̀, láti ṣe é léṣe.
Sau cu vreo piatră de care un om poate muri, dar nevăzându-l și aruncând-o asupra lui, încât acela moare și nu era dușmanul lui, nici nu a căutat vătămarea lui,
24 Àwọn àpéjọ gbọdọ̀ dájọ́ láàrín rẹ̀ àti olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà.
Atunci adunarea să judece între ucigaș și răzbunătorul sângelui conform acestor judecăți;
25 Àpéjọ gbọdọ̀ dá ààbò bo ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn, kí a sì rán an padà lọ sí ìlú ìsásí tí ó ti wá. Ó gbọdọ̀ dúró níbẹ̀ títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú, ẹni tí a fi àmì òróró yàn.
Și adunarea să elibereze pe ucigaș din mâna răzbunătorului sângelui și adunarea să îl întoarcă la cetatea lui de scăpare, unde fugise; și el să locuiască în ea până la moartea marelui preot, care a fost uns cu untdelemnul sfânt.
26 “‘Ṣùgbọ́n ti ẹni tí a fi sùn kan bá jáde kọjá ààlà ìlú ìsásí tí ó sá sí.
Dar dacă ucigașul va ieși vreodată în afara granițelor cetății sale de scăpare, unde fugise;
27 Tí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ sì ri ní ìta ìlú náà, olùgbẹ̀san lè pa ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn láìjẹ̀bi ẹ̀sùn ìpànìyàn.
Și răzbunătorul sângelui îl găsește în afara granițelor cetății sale de scăpare și răzbunătorul sângelui ucide pe ucigaș, el nu va fi vinovat de sânge;
28 Ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn gbọdọ̀ dúró nínú ìlú ìsásí títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú; lẹ́yìn ikú olórí àlùfáà, ni ó tó lè padà sí ibi tí dúkìá rẹ̀ wà.
Deoarece trebuia să rămână în cetatea lui de scăpare până la moartea marelui preot; dar după moartea marelui preot, ucigașul se va întoarce în pământul stăpânirii sale.
29 “‘Wọ̀nyí ni ó jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún yín ní ìran yín tó ń bọ̀, ní ibikíbi tí ẹ bá ń gbé.
Astfel aceste lucruri vă vor fi drept statut de judecată prin generațiile voastre, în toate locuințele voastre.
30 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn gbọdọ̀ kú gẹ́gẹ́ bí apànìyàn lórí ìjẹ́rìí àwọn ènìyàn. Ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo. Kì yóò jẹ́rìí sí ẹnìkan láti pa.
Oricine ucide vreo persoană, ucigașul să fie dat morții după gura martorilor; dar un singur martor nu va mărturisi împotriva vreunei persoane pentru a face ca acela să moară.
31 “‘Má ṣe gba ohun ìràpadà fún ẹ̀mí apànìyàn, tí ó jẹ̀bi kí ó kú. Ṣùgbọ́n pípa ni kí a pa á.
Mai mult, să nu luați preț de răscumpărare pentru viața ucigașului, cel vinovat de moarte; ci el negreșit să fie dat morții.
32 “‘Má ṣe gba ìràsílẹ̀ fún ẹnikẹ́ni tí ó bá lọ sí ìlú ìsásí, pe kí ó padà máa gbé ní ilẹ̀ tirẹ̀ kí ó tó di ìgbà ikú olórí àlùfáà.
Și să nu luați preț de răscumpărare pentru cel fugit la cetatea lui de scăpare, ca el să poată veni din nou să locuiască în țară, până la moartea preotului.
33 “‘Má ṣe sọ ilẹ̀ tí ẹ wà di àìmọ́. Ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sọ ilẹ̀ náà di àìmọ́. Àtúnṣe kì yóò sí fún ilẹ̀ tí a ti ta ẹ̀jẹ̀ lé lórí, àyàfi ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó ta á sílẹ̀.
Astfel să nu murdăriți țara în care sunteți, pentru că sângele pângărește țara; și țara nu poate fi curățată de sângele care este vărsat în ea, decât prin sângele celui ce l-a vărsat.
34 Má ṣe sọ di àìmọ́, ilẹ̀ tí ẹ ń gbé, àti èyí tí mo ń gbé, nítorí Èmi Olúwa ń gbé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.’”
Nu pângăriți de aceea țara pe care o veți locui, în care eu locuiesc, pentru că eu DOMNUL locuiesc în mijlocul copiilor lui Israel.

< Numbers 35 >