< Numbers 35 >
1 Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní Jordani tí ó rékọjá láti Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
I PAN powiedział do Mojżesza na równinach Moabu, nad Jordanem, [naprzeciw] Jerycha:
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti fún àwọn Lefi ní ilẹ̀ láti gbé lára ogún tí àwọn ọmọ Israẹli yóò jogún. Kí ẹ sì fún wọn ní ilẹ̀ lára pápá oko tútù, káàkiri ìlú.
Rozkaż synom Izraela, aby dali Lewitom ze swej dziedzicznej posiadłości miasta na zamieszkanie, dacie Lewitom też pastwiska dokoła ich miast.
3 Nígbà náà, wọn yóò ní ìlú tí wọn yóò gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn, ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú gbogbo ìní wọn.
Będą mieli miasta na mieszkanie, a ich pastwiska będą dla ich bydła, dla ich dobytku i dla wszystkich ich zwierząt.
4 “Ilẹ̀ pápá oko tútù káàkiri ìlú tí ẹ ó fi fún àwọn ọmọ Lefi, wíwọ̀n rẹ̀ yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ (1,500 ẹsẹ̀ bàtà) láti ògiri ìlú náà.
Pastwiska miast, które dacie Lewitom, będą rozciągać się na tysiąc łokci wokół murów miasta.
5 Lẹ́yìn ìlú náà, wọn ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́ lápá ibi ìhà ìlà-oòrùn, ẹgbẹ̀rún méjì ẹsẹ̀ bàtà ní ìhà gúúsù, ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà àríwá, kí ìlú náà sì wà ní àárín. Wọn yóò ní agbègbè yìí gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ pápá oko tútù fún ìlú náà.
Odmierzycie również poza miastem dwa tysiące łokci po stronie wschodniej, po stronie południowej też dwa tysiące łokci, także po stronie zachodniej dwa tysiące łokci i po stronie północnej dwa tysiące łokci, a miasto będzie w środku. To będą pastwiska ich miast.
6 “Mẹ́fà lára ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ ìlú ààbò, tí ẹni tí ó bá pa ènìyàn yóò sá sí. Ní àfikún, ẹ fún wọn ní méjìlélógójì ìlú sí i.
A spośród tych miast, które dacie Lewitom, sześć będzie miastami schronienia, które przekażecie, aby mógł tam uciec zabójca. Oprócz nich dacie im czterdzieści dwa miasta.
7 Ní gbogbo rẹ̀, kí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi ní méjìdínláàádọ́ta ìlú lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Wszystkich miast, które dacie Lewitom, będzie czterdzieści osiem wraz z ich pastwiskami.
8 Ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi láti ara ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli jogún, olúkúlùkù kí ó fi nínú ìlú rẹ̀ fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní rẹ̀ tí ó ní. Gba púpọ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní púpọ̀ àti díẹ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní díẹ̀.”
A miasta, które im dacie, [będą pochodziły] z posiadłości synów Izraela; od liczniejszego dacie więcej, a od mniej licznego dacie mniej; każdy da Lewitom ze swoich miast stosownie do otrzymanego dziedzictwa.
9 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
Potem PAN powiedział do Mojżesza:
10 “Sọ̀rọ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn: ‘Nígbà tí ẹ bá rékọjá odò Jordani sí Kenaani,
Przemów do synów Izraela i powiedz im: Gdy przejdziecie przez Jordan do ziemi Kanaan;
11 yan àwọn ìlú kan láti jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìlú ààbò fún yín, kí apani tó pa ènìyàn ní àìmọ̀ máa sálọ síbẹ̀.
Wyznaczcie sobie miasta, które będą dla was miastami schronienia, aby mógł tam uciec zabójca, który zabił kogoś nieumyślnie.
12 Wọn yóò jẹ́ ibi ìsásí kúrò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san, kí ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn má ba à kú kí ó tó dúró níwájú àwọn ìjọ àwọn ènìyàn ní ìdájọ́.
Te miasta będą dla was miastami schronienia przed mścicielem, aby zabójca nie poniósł śmierci, zanim nie stanie przed zgromadzeniem na sąd.
13 Mẹ́fà nínú ìlú tí ẹ ó fi fún wọn yóò jẹ́ ìlú ààbò fún yín.
A z miast, które oddacie, sześć będzie dla was miastami schronienia.
14 Yan ìlú mẹ́ta ní ìhà ti Jordani, kí ẹ sì yan ìlú mẹ́ta ní ìhà Kenaani tí yóò máa jẹ́ ìlú ìsásí.
Trzy miasta dacie z tej strony Jordanu, a trzy miasta dacie w ziemi Kanaan; będą one miastami schronienia.
15 Ìlú mẹ́fà yìí yóò jẹ́ ìlú ìsásí fún àwọn ọmọ Israẹli, fún àjèjì àti ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbé láàrín wọn, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn ní àìmọ̀ sálọ síbẹ̀.
Tych sześć miast będzie schronieniem dla synów Izraela, dla obcego i dla przybysza, który mieszka wśród was, aby mógł tam uciec każdy, kto by zabił człowieka nieumyślnie.
16 “‘Bí ọkùnrin kan bá fi ohun èlò irin lu ènìyàn tí ó kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa, apànìyàn náà.
Jeśli jednak uderzy go przedmiotem żelaznym, tak że ten umrze, jest mordercą. Morderca poniesie śmierć.
17 Tàbí tí ènìyàn bá mú òkúta tí ó lè pa ènìyàn lọ́wọ́ tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa apànìyàn náà.
Jeśli uderzy go kamieniem, który ma w ręce i którym można zabić, a ten umrze, jest mordercą. Morderca poniesie śmierć.
18 Tàbí tí ènìyàn bá mú ohun èlò igi ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì lẹ̀ ẹ́ pa ènìyàn, tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni; pípa ní a ó pa apànìyàn náà.
Albo jeśli uderzy go ręcznym przedmiotem drewnianym, którym można zabić, a ten umrze, jest mordercą. Morderca poniesie śmierć.
19 Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà; tí ó bá bá a, yóò pa á.
Mściciel krwi sam zabije tego mordercę. Gdziekolwiek go spotka, sam go zabije.
20 Tí ẹnikẹ́ni tí ó bá ń yan odì pẹ̀lú ìríra tí ẹlòmíràn tàbí ju nǹkan sí i pẹ̀lú èrò, tí ó sì kú.
Jeśli z nienawiści popchnie go albo rzuci w niego czymś z zasadzki, a ten umrze;
21 Tàbí pẹ̀lú ìjà gbangba lù ú pẹ̀lú ìkùùkuu tí ó sì kú, pípa ni a ó pa ẹni bẹ́ẹ̀; apànìyàn ni. Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà tí ó bá bá a.
Albo jeśli z wrogości uderzy go ręką, a ten umrze, to ten, który uderzył, poniesie śmierć, bo jest mordercą. Mściciel krwi zabije mordercę, gdziekolwiek go spotka.
22 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá fi nǹkan gún un lójijì láìṣọ̀ta, tàbí tí ó sọ ohunkóhun lù ú láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ ṣe
Lecz jeśli niespodziewanie i bez wrogości go popchnie albo rzuci w niego czymkolwiek bez zasadzki;
23 tàbí, láìri, ju òkúta sí tí ó lè pa á, tí ó sì kú, nígbà tí kì í ṣe ọ̀tá rẹ̀, láti ṣe é léṣe.
Albo jeśli nie widząc, upuści na niego jakiś kamień, którym można zabić, a ten umrze, chociaż nie był jego wrogiem ani nie szukał jego krzywdy;
24 Àwọn àpéjọ gbọdọ̀ dájọ́ láàrín rẹ̀ àti olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà.
Wtedy zgromadzenie rozsądzi pomiędzy tym, który zabił, a między mścicielem krwi według tych praw.
25 Àpéjọ gbọdọ̀ dá ààbò bo ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn, kí a sì rán an padà lọ sí ìlú ìsásí tí ó ti wá. Ó gbọdọ̀ dúró níbẹ̀ títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú, ẹni tí a fi àmì òróró yàn.
I zgromadzenie wybawi zabójcę z rąk mściciela krwi; zgromadzenie też przekaże go miastu schronienia, do którego uciekł. Tam będzie mieszkał aż do śmierci najwyższego kapłana, namaszczonego olejem świętym.
26 “‘Ṣùgbọ́n ti ẹni tí a fi sùn kan bá jáde kọjá ààlà ìlú ìsásí tí ó sá sí.
Lecz jeśli zabójca wyjdzie poza granice swojego miasta schronienia, do którego uciekł;
27 Tí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ sì ri ní ìta ìlú náà, olùgbẹ̀san lè pa ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn láìjẹ̀bi ẹ̀sùn ìpànìyàn.
I mściciel trafi tam na niego poza granicą jego miasta schronienia, i zabije zabójcę, to nie będzie winien krwi.
28 Ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn gbọdọ̀ dúró nínú ìlú ìsásí títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú; lẹ́yìn ikú olórí àlùfáà, ni ó tó lè padà sí ibi tí dúkìá rẹ̀ wà.
[Ten] bowiem ma mieszkać w swoim mieście schronienia aż do śmierci najwyższego kapłana. Lecz po śmierci najwyższego kapłana zabójca może wrócić do ziemi swojej posiadłości.
29 “‘Wọ̀nyí ni ó jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún yín ní ìran yín tó ń bọ̀, ní ibikíbi tí ẹ bá ń gbé.
To będzie dla was ustawa prawna przez wszystkie wasze pokolenia, we wszystkich waszych domach.
30 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn gbọdọ̀ kú gẹ́gẹ́ bí apànìyàn lórí ìjẹ́rìí àwọn ènìyàn. Ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo. Kì yóò jẹ́rìí sí ẹnìkan láti pa.
Ktokolwiek zabije człowieka, to na podstawie zeznania świadków zostanie zabity zabójca. Lecz jeden świadek nie może świadczyć przeciwko komuś, by [skazać] go na śmierć.
31 “‘Má ṣe gba ohun ìràpadà fún ẹ̀mí apànìyàn, tí ó jẹ̀bi kí ó kú. Ṣùgbọ́n pípa ni kí a pa á.
Nie weźmiecie też okupu za życie zabójcy, który zasługuje na śmierć. Musi ponieść śmierć.
32 “‘Má ṣe gba ìràsílẹ̀ fún ẹnikẹ́ni tí ó bá lọ sí ìlú ìsásí, pe kí ó padà máa gbé ní ilẹ̀ tirẹ̀ kí ó tó di ìgbà ikú olórí àlùfáà.
Nie weźmiecie też okupu od tego, który uciekł do swojego miasta schronienia, aby mógł wrócić i zamieszkać w swojej ziemi, zanim umrze kapłan;
33 “‘Má ṣe sọ ilẹ̀ tí ẹ wà di àìmọ́. Ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sọ ilẹ̀ náà di àìmọ́. Àtúnṣe kì yóò sí fún ilẹ̀ tí a ti ta ẹ̀jẹ̀ lé lórí, àyàfi ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó ta á sílẹ̀.
Abyście nie bezcześcili ziemi, w której będziecie, gdyż krew bezcześci ziemię; a ziemia nie może być inaczej oczyszczona od przelanej w niej krwi jak tylko krwią tego, który ją przelał.
34 Má ṣe sọ di àìmọ́, ilẹ̀ tí ẹ ń gbé, àti èyí tí mo ń gbé, nítorí Èmi Olúwa ń gbé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.’”
Nie zanieczyszczajcie więc ziemi, w której mieszkacie, w której przebywam też ja. Ja bowiem [jestem] PAN, który przebywa wśród synów Izraela.