< Numbers 35 >

1 Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní Jordani tí ó rékọjá láti Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahvé parla à Moïse dans les plaines de Moab, près du Jourdain, à Jéricho, et dit:
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti fún àwọn Lefi ní ilẹ̀ láti gbé lára ogún tí àwọn ọmọ Israẹli yóò jogún. Kí ẹ sì fún wọn ní ilẹ̀ lára pápá oko tútù, káàkiri ìlú.
« Ordonne aux enfants d'Israël de donner aux Lévites des villes à habiter sur leur héritage. Tu donneras aux Lévites des pâturages pour les villes qui les entourent.
3 Nígbà náà, wọn yóò ní ìlú tí wọn yóò gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn, ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú gbogbo ìní wọn.
Ils auront les villes pour y habiter. Leurs pâturages seront destinés à leur bétail, à leurs biens et à tous leurs animaux.
4 “Ilẹ̀ pápá oko tútù káàkiri ìlú tí ẹ ó fi fún àwọn ọmọ Lefi, wíwọ̀n rẹ̀ yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ (1,500 ẹsẹ̀ bàtà) láti ògiri ìlú náà.
« Les pâturages des villes que vous donnerez aux Lévites partiront de l'enceinte de la ville et s'étendront en dehors sur mille coudées tout autour.
5 Lẹ́yìn ìlú náà, wọn ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́ lápá ibi ìhà ìlà-oòrùn, ẹgbẹ̀rún méjì ẹsẹ̀ bàtà ní ìhà gúúsù, ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà àríwá, kí ìlú náà sì wà ní àárín. Wọn yóò ní agbègbè yìí gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ pápá oko tútù fún ìlú náà.
Vous mesurerez à l'extérieur de la ville, à l'est, deux mille coudées, au sud, deux mille coudées, à l'ouest, deux mille coudées, au nord, deux mille coudées, la ville étant au milieu. Telles seront les terres de pâturage de leurs villes.
6 “Mẹ́fà lára ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ ìlú ààbò, tí ẹni tí ó bá pa ènìyàn yóò sá sí. Ní àfikún, ẹ fún wọn ní méjìlélógójì ìlú sí i.
« Les villes que tu donneras aux Lévites seront les six villes de refuge que tu donneras au meurtrier de l'homme pour qu'il s'y réfugie. En plus de celles-ci, tu donneras quarante-deux villes.
7 Ní gbogbo rẹ̀, kí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi ní méjìdínláàádọ́ta ìlú lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Toutes les villes que tu donneras aux Lévites seront quarante-huit villes, avec leurs pâturages.
8 Ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi láti ara ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli jogún, olúkúlùkù kí ó fi nínú ìlú rẹ̀ fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní rẹ̀ tí ó ní. Gba púpọ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní púpọ̀ àti díẹ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní díẹ̀.”
En ce qui concerne les villes que tu donneras en propriété aux enfants d'Israël, tu prendras beaucoup sur le grand nombre et peu sur le petit nombre. Chacun, selon l'héritage qu'il aura reçu, donnera une partie de ses villes aux Lévites. »
9 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahvé parla à Moïse et dit:
10 “Sọ̀rọ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn: ‘Nígbà tí ẹ bá rékọjá odò Jordani sí Kenaani,
Parle aux enfants d'Israël et dis-leur: « Lorsque vous aurez passé le Jourdain pour entrer dans le pays de Canaan,
11 yan àwọn ìlú kan láti jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìlú ààbò fún yín, kí apani tó pa ènìyàn ní àìmọ̀ máa sálọ síbẹ̀.
vous vous désignerez des villes qui seront pour vous des villes de refuge, afin que le meurtrier qui tue quelqu'un involontairement puisse s'y réfugier.
12 Wọn yóò jẹ́ ibi ìsásí kúrò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san, kí ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn má ba à kú kí ó tó dúró níwájú àwọn ìjọ àwọn ènìyàn ní ìdájọ́.
Ces villes vous serviront de refuge contre le vengeur, afin que le meurtrier ne meure pas avant de se présenter devant l'assemblée pour être jugé.
13 Mẹ́fà nínú ìlú tí ẹ ó fi fún wọn yóò jẹ́ ìlú ààbò fún yín.
Les villes que vous donnerez seront pour vous six villes de refuge.
14 Yan ìlú mẹ́ta ní ìhà ti Jordani, kí ẹ sì yan ìlú mẹ́ta ní ìhà Kenaani tí yóò máa jẹ́ ìlú ìsásí.
Vous donnerez trois villes au-delà du Jourdain, et vous donnerez trois villes dans le pays de Canaan. Ce seront des villes de refuge.
15 Ìlú mẹ́fà yìí yóò jẹ́ ìlú ìsásí fún àwọn ọmọ Israẹli, fún àjèjì àti ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbé láàrín wọn, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn ní àìmọ̀ sálọ síbẹ̀.
Ces six villes serviront de refuge aux enfants d'Israël, à l'étranger et à celui qui habite au milieu d'eux, afin que quiconque tue quelqu'un involontairement puisse s'y réfugier.
16 “‘Bí ọkùnrin kan bá fi ohun èlò irin lu ènìyàn tí ó kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa, apànìyàn náà.
"'Mais s'il l'a frappé avec un instrument de fer, au point qu'il soit mort, c'est un meurtrier. Le meurtrier sera puni de mort.
17 Tàbí tí ènìyàn bá mú òkúta tí ó lè pa ènìyàn lọ́wọ́ tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa apànìyàn náà.
S'il l'a frappé à la main avec une pierre qui puisse faire mourir un homme, et que celui-ci soit mort, c'est un meurtrier. Le meurtrier sera puni de mort.
18 Tàbí tí ènìyàn bá mú ohun èlò igi ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì lẹ̀ ẹ́ pa ènìyàn, tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni; pípa ní a ó pa apànìyàn náà.
Ou bien, s'il le frappe à la main avec une arme de bois, qui puisse tuer un homme, et que celui-ci meure, c'est un meurtrier. Le meurtrier sera puni de mort.
19 Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà; tí ó bá bá a, yóò pa á.
Le vengeur du sang fera mourir lui-même le meurtrier. Quand il le rencontrera, il le mettra à mort.
20 Tí ẹnikẹ́ni tí ó bá ń yan odì pẹ̀lú ìríra tí ẹlòmíràn tàbí ju nǹkan sí i pẹ̀lú èrò, tí ó sì kú.
S'il l'a bousculé par haine, ou s'il lui a lancé quelque chose en le guettant, au point qu'il soit mort,
21 Tàbí pẹ̀lú ìjà gbangba lù ú pẹ̀lú ìkùùkuu tí ó sì kú, pípa ni a ó pa ẹni bẹ́ẹ̀; apànìyàn ni. Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà tí ó bá bá a.
ou s'il l'a frappé de sa main par hostilité, au point qu'il soit mort, celui qui l'a frappé sera puni de mort. C'est un meurtrier. Le vengeur du sang mettra à mort le meurtrier quand il le rencontrera.
22 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá fi nǹkan gún un lójijì láìṣọ̀ta, tàbí tí ó sọ ohunkóhun lù ú láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ ṣe
"'Mais s'il l'a poussé brusquement sans hostilité, ou s'il a lancé sur lui quelque chose sans le guetter,
23 tàbí, láìri, ju òkúta sí tí ó lè pa á, tí ó sì kú, nígbà tí kì í ṣe ọ̀tá rẹ̀, láti ṣe é léṣe.
ou avec une pierre quelconque, par laquelle un homme peut mourir, sans le voir, et qu'il l'a jetée sur lui de telle sorte qu'il est mort, et qu'il n'était pas son ennemi et ne cherchait pas à lui faire du mal,
24 Àwọn àpéjọ gbọdọ̀ dájọ́ láàrín rẹ̀ àti olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà.
alors la congrégation jugera entre le frappeur et le vengeur du sang selon ces ordonnances.
25 Àpéjọ gbọdọ̀ dá ààbò bo ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn, kí a sì rán an padà lọ sí ìlú ìsásí tí ó ti wá. Ó gbọdọ̀ dúró níbẹ̀ títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú, ẹni tí a fi àmì òróró yàn.
L'assemblée délivrera le meurtrier de la main du vengeur du sang, et l'assemblée le rétablira dans sa ville de refuge, où il s'était enfui. Il y restera jusqu'à la mort du grand prêtre, qui a été oint de l'huile sainte.
26 “‘Ṣùgbọ́n ti ẹni tí a fi sùn kan bá jáde kọjá ààlà ìlú ìsásí tí ó sá sí.
"'Mais si le meurtrier dépasse le périmètre de la ville de refuge où il s'est enfui,
27 Tí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ sì ri ní ìta ìlú náà, olùgbẹ̀san lè pa ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn láìjẹ̀bi ẹ̀sùn ìpànìyàn.
si le vengeur du sang le trouve en dehors du périmètre de la ville de refuge et que le vengeur du sang tue le meurtrier, il ne sera pas coupable de meurtre,
28 Ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn gbọdọ̀ dúró nínú ìlú ìsásí títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú; lẹ́yìn ikú olórí àlùfáà, ni ó tó lè padà sí ibi tí dúkìá rẹ̀ wà.
car il aurait dû rester dans sa ville de refuge jusqu'à la mort du grand prêtre. Mais après la mort du grand prêtre, le meurtrier retournera dans le pays qu'il possède.
29 “‘Wọ̀nyí ni ó jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún yín ní ìran yín tó ń bọ̀, ní ibikíbi tí ẹ bá ń gbé.
"'Ces choses seront pour vous une loi et une ordonnance à travers vos générations dans toutes vos habitations.
30 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn gbọdọ̀ kú gẹ́gẹ́ bí apànìyàn lórí ìjẹ́rìí àwọn ènìyàn. Ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo. Kì yóò jẹ́rìí sí ẹnìkan láti pa.
"'Si quelqu'un tue une personne, le meurtrier sera tué sur la base du témoignage des témoins; mais un témoin ne pourra pas témoigner seul contre une personne pour qu'elle meure.
31 “‘Má ṣe gba ohun ìràpadà fún ẹ̀mí apànìyàn, tí ó jẹ̀bi kí ó kú. Ṣùgbọ́n pípa ni kí a pa á.
"'Tu ne prendras pas de rançon pour la vie d'un meurtrier qui est coupable de mort. Il sera mis à mort.
32 “‘Má ṣe gba ìràsílẹ̀ fún ẹnikẹ́ni tí ó bá lọ sí ìlú ìsásí, pe kí ó padà máa gbé ní ilẹ̀ tirẹ̀ kí ó tó di ìgbà ikú olórí àlùfáà.
"'Tu ne prendras pas de rançon pour celui qui s'est réfugié dans sa ville de refuge, afin qu'il revienne habiter dans le pays avant la mort du prêtre.
33 “‘Má ṣe sọ ilẹ̀ tí ẹ wà di àìmọ́. Ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sọ ilẹ̀ náà di àìmọ́. Àtúnṣe kì yóò sí fún ilẹ̀ tí a ti ta ẹ̀jẹ̀ lé lórí, àyàfi ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó ta á sílẹ̀.
"'Vous ne souillerez donc pas la terre où vous habitez, car le sang souille la terre. On ne peut faire pour la terre l'expiation du sang qui y est versé, que par le sang de celui qui l'a versé.
34 Má ṣe sọ di àìmọ́, ilẹ̀ tí ẹ ń gbé, àti èyí tí mo ń gbé, nítorí Èmi Olúwa ń gbé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.’”
Vous ne souillerez pas le pays que vous habitez, où j'habite, car moi, Yahvé, j'habite au milieu des enfants d'Israël.'"

< Numbers 35 >