< Numbers 35 >

1 Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní Jordani tí ó rékọjá láti Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
Господ говори още на Моисея в моавските полета при Иордан срещу Ерихон, казвайки:
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti fún àwọn Lefi ní ilẹ̀ láti gbé lára ogún tí àwọn ọmọ Israẹli yóò jogún. Kí ẹ sì fún wọn ní ilẹ̀ lára pápá oko tútù, káàkiri ìlú.
Заповядай на израилтяните да дадат на левитите от наследственото си притежание градове, в които да се зеселят; дайте на левитите и пасбища около градовете им.
3 Nígbà náà, wọn yóò ní ìlú tí wọn yóò gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn, ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú gbogbo ìní wọn.
Градовете да им служат за живеене, а пасбищата да им служат за говедата им, за имота им и за всичките им животни.
4 “Ilẹ̀ pápá oko tútù káàkiri ìlú tí ẹ ó fi fún àwọn ọmọ Lefi, wíwọ̀n rẹ̀ yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ (1,500 ẹsẹ̀ bàtà) láti ògiri ìlú náà.
Пасбищата около градовете, които ще дадете на левитите, да се простират хиляда лакътя навън от градската стена наоколо.
5 Lẹ́yìn ìlú náà, wọn ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́ lápá ibi ìhà ìlà-oòrùn, ẹgbẹ̀rún méjì ẹsẹ̀ bàtà ní ìhà gúúsù, ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà àríwá, kí ìlú náà sì wà ní àárín. Wọn yóò ní agbègbè yìí gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ pápá oko tútù fún ìlú náà.
Да измерите извън града, на източната страна, две хиляди лакътя, на южната страна две хиляди лакътя, на западната страна две хиляди лакътя, северната страна две хиляди лакътя, а градът да бъде в средата. Такива да бъдат пасбищата около градовете им.
6 “Mẹ́fà lára ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ ìlú ààbò, tí ẹni tí ó bá pa ènìyàn yóò sá sí. Ní àfikún, ẹ fún wọn ní méjìlélógójì ìlú sí i.
И градовете, които ще дадете на левитите, да бъдат шест града за прибягване, които да определите, за да може да прибягва там убиецът; и на тях да притурите още четиридесет и два града.
7 Ní gbogbo rẹ̀, kí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi ní méjìdínláàádọ́ta ìlú lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
Всичките градове, които ще дадете на левитите, да бъдат четиридесет и осем града; дайте ги заедно с пасбищата им.
8 Ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi láti ara ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli jogún, olúkúlùkù kí ó fi nínú ìlú rẹ̀ fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní rẹ̀ tí ó ní. Gba púpọ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní púpọ̀ àti díẹ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní díẹ̀.”
И когато дадете градовете от притежанието на израилтяните, от многото градове дайте много, а от малкото - дайте малко; всяко племе да даде на левитите от градовете си според наследството, което е наследило.
9 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
Господ говори още на Моисея казвайки:
10 “Sọ̀rọ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn: ‘Nígbà tí ẹ bá rékọjá odò Jordani sí Kenaani,
Говори на израилтяните, казвайки им: Когато минете през Иордан в Ханаанската земя,
11 yan àwọn ìlú kan láti jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìlú ààbò fún yín, kí apani tó pa ènìyàn ní àìmọ̀ máa sálọ síbẹ̀.
тогава да си определите градове, които да ви бъдат градове за прибежище, за да може да прибягва там убиецът, който убие човек по погрешка.
12 Wọn yóò jẹ́ ibi ìsásí kúrò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san, kí ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn má ba à kú kí ó tó dúró níwájú àwọn ìjọ àwọn ènìyàn ní ìdájọ́.
Те да ви бъдат градове за избягване от сродника - мъздовъздател, за да се не убие убиецът преди да се представи на съд пред обществото.
13 Mẹ́fà nínú ìlú tí ẹ ó fi fún wọn yóò jẹ́ ìlú ààbò fún yín.
От градовете, които ще дадете, шест да ви бъдат градове за прибягване.
14 Yan ìlú mẹ́ta ní ìhà ti Jordani, kí ẹ sì yan ìlú mẹ́ta ní ìhà Kenaani tí yóò máa jẹ́ ìlú ìsásí.
Три града да дадете оттатък Иордан, и три града да дадете в Ханаанската земя, да бъдат градове за прибягване.
15 Ìlú mẹ́fà yìí yóò jẹ́ ìlú ìsásí fún àwọn ọmọ Israẹli, fún àjèjì àti ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbé láàrín wọn, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn ní àìmọ̀ sálọ síbẹ̀.
Тия шест града да бъдат прибежище за израилтяните и за чужденеца, и за онзи, който е пришелец помежду им, за да може да прибягват там всеки, който би убил човек по погрешка.
16 “‘Bí ọkùnrin kan bá fi ohun èlò irin lu ènìyàn tí ó kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa, apànìyàn náà.
Ако някой удари някого с желязно оръдие, та умре, убиец е; убиецът непременно да се умъртви.
17 Tàbí tí ènìyàn bá mú òkúta tí ó lè pa ènìyàn lọ́wọ́ tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa apànìyàn náà.
Ако го е ударил с камък из ръката си, от който може да умре, та умре, убиец е; убиецът непременно да се умъртви.
18 Tàbí tí ènìyàn bá mú ohun èlò igi ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì lẹ̀ ẹ́ pa ènìyàn, tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni; pípa ní a ó pa apànìyàn náà.
Или ако го е ударил с дървено оръжие в ръката си, от което може да умре, та умре, убиец е; убиецът непременно да се умъртви.
19 Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà; tí ó bá bá a, yóò pa á.
Мъздовъздателят за кръвта сам да умъртви убиеца; когато го срещне, да го умъртви.
20 Tí ẹnikẹ́ni tí ó bá ń yan odì pẹ̀lú ìríra tí ẹlòmíràn tàbí ju nǹkan sí i pẹ̀lú èrò, tí ó sì kú.
И ако го тласне от омраза, или из засада хвърли нещо върху него, та умре,
21 Tàbí pẹ̀lú ìjà gbangba lù ú pẹ̀lú ìkùùkuu tí ó sì kú, pípa ni a ó pa ẹni bẹ́ẹ̀; apànìyàn ni. Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà tí ó bá bá a.
или от омраза го удари с ръката си, та умре, тоя, който го е ударил, непременно да се умъртви убиец е; мъздовъздателят за кръвта да умъртви убиеца, когато го срещне.
22 “‘Ṣùgbọ́n bí ó bá fi nǹkan gún un lójijì láìṣọ̀ta, tàbí tí ó sọ ohunkóhun lù ú láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ ṣe
Но ако го тласне внезапно, без да го е намразил, или хвърли нещо върху него без да го е причаквал,
23 tàbí, láìri, ju òkúta sí tí ó lè pa á, tí ó sì kú, nígbà tí kì í ṣe ọ̀tá rẹ̀, láti ṣe é léṣe.
или ако, без да види, направи да падне на него някакъв камък, от който може да умре, та умре, без да му е бил неприятел, или да е искал да му стори зло,
24 Àwọn àpéjọ gbọdọ̀ dájọ́ láàrín rẹ̀ àti olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà.
тогава обществото да отсъди между убиеца и мъздовъздателя за кръвта според тия съдби;
25 Àpéjọ gbọdọ̀ dá ààbò bo ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn, kí a sì rán an padà lọ sí ìlú ìsásí tí ó ti wá. Ó gbọdọ̀ dúró níbẹ̀ títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú, ẹni tí a fi àmì òróró yàn.
и обществото да избави убиеца от ръката на мъздовъздателя за кръвта, и обществото да го върне в града, гдето бе прибягнал за прибежище; и той да живее в него до смъртта на първосвещеника, който е помазан със светото миро.
26 “‘Ṣùgbọ́n ti ẹni tí a fi sùn kan bá jáde kọjá ààlà ìlú ìsásí tí ó sá sí.
Но ако убиецът излезе кога да е вън от пределите на прибежищния град, в който бе прибягнал,
27 Tí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ sì ri ní ìta ìlú náà, olùgbẹ̀san lè pa ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn láìjẹ̀bi ẹ̀sùn ìpànìyàn.
и мъздовъздателят за кръвта го намери вън от пределите на прибежищния град, и мъздовъздателят за кръвта умъртви убиеца, тоя няма да бъде виновен за кръвопролитие;
28 Ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn gbọdọ̀ dúró nínú ìlú ìsásí títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú; lẹ́yìn ikú olórí àlùfáà, ni ó tó lè padà sí ibi tí dúkìá rẹ̀ wà.
защото убиецът трябваше да стои в прибежищния си град до смъртта на първосвещеника. А след смъртта на първосвещеника нека се върне убиецът в земята, която му е притежание.
29 “‘Wọ̀nyí ni ó jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún yín ní ìran yín tó ń bọ̀, ní ibikíbi tí ẹ bá ń gbé.
Това да ви бъде съдебен закон във всичките ви поколения по всичките ви заселища.
30 “‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn gbọdọ̀ kú gẹ́gẹ́ bí apànìyàn lórí ìjẹ́rìí àwọn ènìyàn. Ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo. Kì yóò jẹ́rìí sí ẹnìkan láti pa.
Който убие някого, тоя убиец да се умъртви при думите на свидетели: обаче не бива само един свидетел да свидетелствува против някого, за да се умъртви.
31 “‘Má ṣe gba ohun ìràpadà fún ẹ̀mí apànìyàn, tí ó jẹ̀bi kí ó kú. Ṣùgbọ́n pípa ni kí a pa á.
Нито да взимате някакъв откуп за живота на убиеца, който като виновен заслужава смърт; но непременно той да се умъртви.
32 “‘Má ṣe gba ìràsílẹ̀ fún ẹnikẹ́ni tí ó bá lọ sí ìlú ìsásí, pe kí ó padà máa gbé ní ilẹ̀ tirẹ̀ kí ó tó di ìgbà ikú olórí àlùfáà.
Да не взимате откуп и за онзи, който е прибягнал в прибежищен град, за да се върне да живее на мястото си преди смъртта на свещеника.
33 “‘Má ṣe sọ ilẹ̀ tí ẹ wà di àìmọ́. Ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sọ ilẹ̀ náà di àìmọ́. Àtúnṣe kì yóò sí fún ilẹ̀ tí a ti ta ẹ̀jẹ̀ lé lórí, àyàfi ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó ta á sílẹ̀.
Така няма да оскверните земята, в която се намирате; защото кръвта, тя е, която осквернява земята; и земята не може да се очисти от кръвта, която се е проляла на нея, освен с кръвта на онзи, който я е пролял.
34 Má ṣe sọ di àìmọ́, ilẹ̀ tí ẹ ń gbé, àti èyí tí mo ń gbé, nítorí Èmi Olúwa ń gbé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.’”
Нито един от вас да не осквернява земята, в която живеете, всред която Аз обитавам; защото Аз Иеова обитавам всред израилтяните.

< Numbers 35 >