< Numbers 34 >
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
Manda a los hijos de Israel: Cuando entren en la tierra de Canaán, esta es la tierra que les caerá en herencia, la tierra de Canaán según sus límites.
3 “‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
Su límite del sur irá desde el desierto de Sin hasta la frontera de Edom, y hasta el extremo del mar de la Sal, hacia el oriente.
4 kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
Este límite irá rodeando desde el sur hasta la colina de Acrabim, y pasará hasta Sin. Sus extremos serán desde el sur a Cades Barnea, saldrá a Hasaradar y cruzará hasta Asmón.
5 Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
Rodeará la frontera desde Asmón hasta el torrente de Egipto, y sus límites serán hasta el mar.
6 Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
El mar Grande será la frontera occidental, y su costa será el límite occidental.
7 Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
Esta será la frontera norte: desde el mar Grande trazarán una línea hasta la montaña Hor.
8 àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
Trazarás una frontera desde la montaña Hor hasta la entrada de Hamat, y los extremos de la frontera estarán en Sedad.
9 tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
La frontera llegará a Zifón y terminará en Hasarenán. Esta les será la frontera norte.
10 Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
Para el límite al oriente trazarán una línea desde Hasarenán hasta Sefam.
11 Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
El límite bajará desde Sefam hasta Ribla, al oriente de Ain, y el término descenderá y llegará a la costa oriental del mar de Cineret.
12 Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
Este límite descenderá por el Jordán y terminará en el mar de la Sal. Esta será su tierra, según sus fronteras circundantes.
13 Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
Entonces Moisés ordenó a los hijos de Israel: Esta es la tierra que les repartirán por sorteo, la cual Yavé ordenó que se dé a las nueve tribus y a la media tribu.
14 Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
Pues la tribu de los hijos de Rubén, la tribu de los hijos de Gad y la media tribu de Manasés, cada una ya tomaron su heredad según sus casas paternas.
15 Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
Las dos tribus y media tomaron su heredad a este lado del Jordán, al oriente de Jericó, hacia la salida del sol.
17 “Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
Estos son los nombres de los varones que les repartirán la tierra: El sacerdote Eleazar y Josué, hijo de Nun.
18 Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
Además escogerán un jefe de cada tribu para repartir la tierra.
19 “Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
Aquí están los nombres de los varones: De la tribu de Judá, Caleb, hijo de Jefone.
20 Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
De la tribu de los hijos de Simeón, Samuel, hijo de Amiud.
21 Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
De la tribu de Benjamín, Elidad, hijo de Quislón.
22 Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
De la tribu de los hijos de Dan, el jefe Buqui, hijo de Jogli.
23 Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
En cuanto a los hijos de José, de la tribu de los hijos de Manasés, el jefe Haniel, hijo de Efod.
24 Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
De la tribu de los hijos de Efraín, el jefe Quemuel, hijo de Siftán.
25 Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
De la tribu de los hijos de Zabulón, el jefe Elisafán, hijo de Parnac.
26 Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
De la tribu de los hijos de Isacar, el jefe Paltiel, hijo de Azán.
27 Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
De la tribu de los hijos de Aser, el jefe Ahiud, hijo de Selomi.
28 Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
Y de la tribu de los hijos de Neftalí, el jefe Pedael, hijo de Amiud.
29 Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.
Estos son los que mandó Yavé que repartieran a los hijos de Israel la tierra de Canaán.