< Numbers 34 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Nake Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
“Atha andũ a Isiraeli, ũmeere atĩrĩ: ‘Rĩrĩa mũgaatoonya Kaanani-rĩ, bũrũri ũcio mũkaagaĩrwo ũtuĩke igai rĩanyu ũgaakorwo na mĩhaka ĩno:
3 “‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
“‘Mwena wanyu wa gũthini ũkoima Werũ-inĩ wa Zini kũrigania na mũhaka wa Edomu. Mwena wa irathĩro, mũhaka wanyu wa mwena wa gũthini ũkaambĩrĩria mũthia-inĩ wa Iria rĩa Cumbĩ,
4 kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
ũtuĩkanĩirie mwena wa gũthini ũrorete Mwanya wa Akirabimu, ũthiĩte na mbere o nginya Zini, na ũikũrũke na mwena wa gũthini wa Kadeshi-Barinea. Ningĩ ũcooke ũkinye Hazoru-Adari, na uumĩrĩre Azimoni,
5 Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
kũrĩa ũkaarigiicũka, ũnyiitane na karũũĩ ka Misiri, na ũrĩkĩrie Iria-inĩ.
6 Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
“‘Mũhaka wanyu wa mwena wa ithũĩro ũgaakorwo ũrĩ hũgũrũrũ cia Iria rĩrĩa Inene. Ũcio nĩguo ũgaatuĩka mũhaka wanyu wa mwena wa ithũĩro.
7 Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
“‘Naguo mũhaka wanyu wa mwena wa gathigathini uumĩte Iria rĩrĩa Inene ũgaakinya Kĩrĩma-inĩ kĩa Horu,
8 àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
na kuuma Kĩrĩma kĩa Horu ũgaakinya Lebo-Hamathu. Ningĩ mũhaka ũcio ũgaakinya Zedadi,
9 tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
ũthiĩ na mbere nginya Zifironi, na ũgaathirĩra Hazoru-Enani. Ũcio nĩguo ũgaatuĩka mũhaka wanyu wa mwena wa gathigathini.
10 Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
“‘Na rĩrĩ, mũhaka wanyu wa mwena wa irathĩro, ũkoima Hazoru-Enani ũkinye Shefamu.
11 Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
Mũhaka ũcio ũgaaikũrũka kuuma Shefamu nginya Ribila, mwena wa irathĩro wa Aini, na ũthiĩ na mbere ũtwaranĩte na hurũrũka cia mwena wa irathĩro wa Iria rĩrĩa rĩa Kinerethu.
12 Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
Ningĩ mũhaka ũcio ũikũrũkanie na Rũũĩ rwa Jorodani, ũrĩkĩrie Iria-inĩ rĩa Cumbĩ. “‘Ũcio nĩguo ũgaatuĩka bũrũri wanyu, na mĩhaka yaguo mĩena yothe.’”
13 Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
Musa agĩatha andũ a Isiraeli, akĩmeera atĩrĩ: “Mũkaagaya bũrũri ũcio na ũndũ wa kũũcukĩra mĩtĩ ũtuĩke igai rĩanyu Jehova nĩathanĩte akoiga ũkaaheeo mĩhĩrĩga ĩrĩa kenda na nuthu,
14 Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
Tondũ nyũmba cia mũhĩrĩga wa Rubeni, na mũhĩrĩga wa Gadi, na nuthu ya mũhĩrĩga wa Manase nĩmarĩkĩtie kwamũkĩra igai rĩao.
15 Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
Mĩhĩrĩga ĩyo yeerĩ na nuthu nĩĩrĩkĩtie kwamũkĩra magai mayo mwena wa irathĩro wa Rũũĩ rwa Jorodani ya Jeriko, kwerekera irathĩro rĩa riũa.”
16 Olúwa sọ fún Mose pé,
Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ,
17 “Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
“Maya nĩmo marĩĩtwa ma andũ arĩa makaamũgayania bũrũri ũcio ũtuĩke igai rĩanyu: nĩ Eleazaru ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai na Joshua mũrũ wa Nuni.
18 Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
Na ũthuure mũtongoria ũmwe kuuma kũrĩ o mũhĩrĩga nĩgeetha mateithĩrĩrie kũgayania bũrũri ũcio.
19 “Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
Maya nĩmo marĩĩtwa mao: nĩ Kalebu mũrũ wa Jefune, kuuma mũhĩrĩga wa Juda;
20 Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
na Shemueli mũrũ wa Amihudu, kuuma mũhĩrĩga wa Simeoni;
21 Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
na Elidadi mũrũ wa Kisiloni, kuuma mũhĩrĩga wa Benjamini;
22 Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
na Buki mũrũ wa Jogili, ũrĩa mũtongoria kuuma mũhĩrĩga wa Dani;
23 Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
na Hanieli mũrũ wa Efodi, ũrĩa mũtongoria kuuma mũhĩrĩga wa Manase mũrũ wa Jusufu;
24 Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
na Kemueli mũrũ wa Shifitani, ũrĩa mũtongoria kuuma mũhĩrĩga wa Efiraimu mũrũ wa Jusufu;
25 Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
na Elizafani mũrũ wa Paranaki, ũrĩa mũtongoria kuuma mũhĩrĩga wa Zebuluni;
26 Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
na Palitieli mũrũ wa Azani, ũrĩa mũtongoria kuuma mũhĩrĩga wa Isakaru;
27 Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
na Ahihudu mũrũ wa Shelomi, ũrĩa mũtongoria kuuma mũhĩrĩga wa Asheri;
28 Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
na Pedaheli mũrũ wa Amihudu, ũrĩa mũtongoria kuuma mũhĩrĩga wa Nafitali.”
29 Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.
Acio nĩo andũ arĩa Jehova aathanire makaagaĩra andũ a Isiraeli magai mao kũu bũrũri wa Kaanani.

< Numbers 34 >