< Numbers 34 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
L'Eternel parla aussi à Moïse, en disant:
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
Commande aux enfants d'Israël, et leur dis: Parce que vous allez entrer au pays de Canaan, ce [sera] ici le pays qui vous écherra en héritage, le pays de Canaan selon ses limites.
3 “‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
Votre frontière du côté du Midi sera depuis le désert de Tsin, le long d'Edom; tellement que votre frontière du côté du Midi commencera au bout de la mer Salée vers l'Orient.
4 kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
Et cette frontière tournera du Midi vers la montée de Hakrabbim, et passera jusqu'à Tsin; et elle aboutira du côté du Midi, à Kadès-barné, et sortira aussi en Hatsar-addar, et passera jusqu'à Hatsmon.
5 Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
Et cette frontière tournera depuis Hatsmon jusqu'au torrent d'Egypte; et elle aboutira à la mer.
6 Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
Et quant à la frontière d'Occident, vous aurez la grande mer, et ses limites; ce vous sera la frontière Occidentale.
7 Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
Et ce sera [ici] votre frontière du Septentrion; depuis la grande mer vous marquerez pour vos limites la montagne de Hor.
8 àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
Et de la montagne de Hor vous marquerez pour vos limites l'entrée de Hamath; et cette frontière se rendra vers Tsédad.
9 tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
Et cette frontière passera jusqu'à Ziphron, et elle aboutira à Hatsar-hénan; telle sera votre frontière du Septentrion.
10 Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
Puis vous marquerez pour vos limites vers l'Orient depuis Hatsar-hénan vers Sepham.
11 Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
Et cette frontière descendra de Sepham à Riblat, du côté de l'Orient de Hajin; et cette frontière descendra et s'étendra le long de la mer de Kinnereth vers l'Orient.
12 Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
Et cette frontière descendra au Jourdain, et se rendra à la mer salée; tel sera le pays que vous aurez selon ses limites tout autour.
13 Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
Et Moïse commanda aux enfants d'Israël, en disant: C'est là le pays que vous hériterez par sort, lequel l'Eternel a commandé de donner à neuf Tribus, et à la moitié d'une Tribu.
14 Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
Car la Tribu des enfants de Ruben selon les familles de leurs pères, et la Tribu des enfants de Gad, selon les familles de leurs pères, ont pris leur héritage; [et] la demi-Tribu de Manassé a pris aussi son héritage.
15 Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
Deux tribus, [dis-je], et la moitié d'une Tribu, ont pris leur héritage au deçà du Jourdain de Jéricho, du côté du Levant.
16 Olúwa sọ fún Mose pé,
Et l'Eternel parla à Moïse, en disant:
17 “Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
Ce sont ici les noms des hommes qui vous partageront le pays, Eléazar, le Sacrificateur, et Josué, fils de Nun.
18 Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
Vous prendrez aussi un des principaux de chaque Tribu pour faire le partage du pays.
19 “Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
Et ce sont ici les noms de ces hommes-là. Pour la Tribu de Juda, Caleb, fils de Jéphunné.
20 Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
Pour la Tribu des enfants de Siméon, Samuel, fils de Hammiud.
21 Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
Pour la Tribu de Benjamin, Elidad, fils de Kislon.
22 Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
Pour la Tribu des enfants de Dan, celui qui en est le chef, Bukki, fils de Jogli.
23 Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
Des enfants de Joseph, pour la Tribu des enfants de Manassé, celui qui en est le chef, Hanniel, fils d'Ephod.
24 Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
Pour la Tribu des enfants d'Ephraïm, celui qui en est le chef, Kémuel, fils de Siphthan.
25 Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
Pour la Tribu des enfants de Zabulon, celui qui en est le chef, Elitsaphan, fils de Parnac.
26 Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
Pour la Tribu des enfants d'Issacar, celui qui en est le chef, Paltiel, fils de Hazan.
27 Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
Pour la Tribu des enfants d'Aser, celui qui en est le chef, Ahihud, fils de Sélomi.
28 Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
Et pour la Tribu des enfants de Nephthali, celui qui en est le chef, Pédahel, fils de Hammiud.
29 Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.
Ce sont là ceux auxquels l'Eternel commanda de partager l'héritage aux enfants d'Israël dans le pays de Canaan.

< Numbers 34 >