< Numbers 34 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
And the Lord spak to Moises,
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
and seide, Comaunde thou to the sones of Israel, and thou schalt seie to hem, Whanne ye han entrid in to the lond of Canaan, and it bifelde in to possessioun `to you bi lot, it schal be endid bi these endis.
3 “‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
The south part schal bigynne at the wildirnesse of Syn, which is bisidis Edom, and it schal haue termes ayens the eest,
4 kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
the saltiste see, whiche termes schulen cumpasse the south coost bi the `stiynge of Scorpioun, `that is, of an hil clepid Scorpioun, so that tho passe in to Senna, and come to the south, `til to Cades Barne; fro whennus the coostis schulen go out to the town, Abdar bi name, and schulen strecche forth `til to Asemona;
5 Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
and the terme schal go bi cumpas fro Assemona `til to the stronde of Egipt, and it schal be endid bi the brynke of the grete see.
6 Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
Forsothe the west coost schal bigynne at the greet see, and schal be closid bi that ende.
7 Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
Sotheli at the north coost, the termes schulen bigynne at the greet see, and schulen come `til to the hiyeste hil,
8 àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
fro which tho schulen come in to Emath, `til to the termes of Sedada;
9 tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
and the coostis schulen go `til to Ephrona, and the town of Enan. These schulen be the termes in the north part.
10 Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
Fro thennus thei schulen mete coostis ayens the eest coost, fro the town Henan `til to Sephama;
11 Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
and fro Sephama termes schulen go doun in to Reblatha, ayens the welle `of Daphnyn; fro thennus tho schulen come ayens the eest to the se of Cenereth;
12 Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
and tho schulen strecche forth `til to Jordan, and at the laste tho schulen be closid with the salteste see. Ye schulen haue this lond bi hise coostis `in cumpas.
13 Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
And Moises comaundide to the sones of Israel, and seide, This schal be the lond which ye schulen welde bi lot, and which the Lord comaundide to be youun to nyne lynagis and to the half lynage;
14 Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
for the lynage of the sones of Ruben, bi her meynees, and the lynage of the sones of Gad, bi kynrede and noumbre, and half the lynage of Manasses,
15 Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
that is, twey lynagis and an half, han take her part ouer Jordan, ayens Jerico, at the eest coost.
16 Olúwa sọ fún Mose pé,
And the Lord seide to Moises,
17 “Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
These ben the `names of men that schulen departe the lond to you, Eleazar, preest, and Josue, the sone of Nun, and of each lynage, o prynce;
18 Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
of whiche these ben the names, of the lynage of Juda,
19 “Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
Caleph, the sone of Jephone;
20 Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
of the lynage of Symeon, Samuhel, the sone of Amyud;
21 Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
of the lynage of Beniamyn, Heliad, sone of Casselon;
22 Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
of the lynage of the sones of Dan, Bochi, sone of Jogli; of the sones of Joseph,
23 Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
of the lynage of Manasses, Hamyel, sone of Ephoth;
24 Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
of the lynage of Effraym, Camuhel, sone of Septhan;
25 Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
of the lynage of Zabulon, Elisaphan, sone of Pharnat;
26 Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
of the lynage of Isacar, duyk Phaltiel, the sone of Ozan; of the lynage of Azer,
27 Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
Abyud, the sone of Salomy;
28 Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
of the lynage of Neptalym, Fedahel, the sone of Amyud.
29 Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.
These men it ben, to whiche the Lord comaundide, that thei schulden departe to the sones of Israel the lond of Chanaan.

< Numbers 34 >