< Numbers 34 >
And Yahweh spake unto Moses, saying:
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
Command the sons of Israel, and thou shalt say unto them, When, ye, are coming into the land of Canaan, this is the land which shall fall unto you, as an inheritance, even the land of Canaan, by the boundaries thereof.
3 “‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
Ye shall therefore have a south corner, from the desert of Zin, on the side of Edom, —so shall ye have a south boundary, from the end of the salt sea, eastward:
4 kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
and the boundary shall go round for you from the south towards the cliffs of Akrabbim, then cross over towards Zin, and the extension thereof shall be from the south to Kadesh-barnea, then shall it reach out to Hazar-addar, and cross over towards Azmon;
5 Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
then shall the boundary turn round from Azmon towards the ravine of Egypt, —and the extension thereof shall be towards the sea.
6 Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
And, for a west boundary, —ye shall have the great sea, even a boundary, this, shall serve you as west boundary.
7 Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
And, this, shall serve you as a north boundary, —From the great sea, ye shall draw a line for you to Mount Hor:
8 àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
From Mount Hor, ye shall draw a line to the entering in of Hamath, —and the extension of the boundary shall be towards Zedad:
9 tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
then shall the boundary reach out towards Ziphron, and the extension thereof, be to Hazar-enan. This, shall serve you as a north, boundary.
10 Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
Then shall ye draw for yourselves a line, for an east boundary, —from Hazar-enan towards Shepham;
11 Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
and the boundary shall go down from Shepham towards Riblah, on the east of Ain—then shall the boundary go down and strike on the side of the Sea of Chinnereth, eastward:
12 Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
then shall the boundary go down towards the Jordan, and the extension thereof be to the salt sea. This shall be your land by the boundaries thereof round about.
13 Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
And Moses commanded the sons of Israel saying, —This, is the land, which ye shall inherit by lot, which Yahweh had commanded to be given to the nine tribes and the half tribe.
14 Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
For the tribe of the sons of the Reubenites by their ancestral house, and the tribe of the sons of Gad, by their ancestral house, have received, and, the half tribe of Manasseh have received, their inheritance:
15 Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
the two tribes, and the half tribe, have received their inheritance—on this side Jordan near Jericho, eastwards, towards sunrise.
Then spake Yahweh unto Moses, saying:
17 “Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
These, are the names of the men who shall receive for you the land, as an inheritance, Eleazar, the priest, and Joshua, son of Nun.
18 Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
Also, one prince from each tribe, shall ye take to receive the land, as an inheritance.
19 “Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
These, therefore, are the names of the men, —For the tribe of Judah, Caleb son of Jephunneh;
20 Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
And, for the tribe of the sons of Simeon, Shemuel son of Ammihud:
21 Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
For the tribe of Benjamin, Elidad son of Chislon;
22 Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
And, for the tribe of the sons of Dan, a prince—Bukki, son of Jogli:
23 Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
For the sons of Joseph, For the tribe of the sons of Manasseh, a prince, —Hanniel son of Ephod;
24 Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
And, for the tribe of the sons of Ephraim, a prince, —Kemuel, son of Shiphtan;
25 Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
And, for the tribe of the sons of Zebulun, a prince, —Elizaphan, son of Parnach;
26 Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
And, for the tribe of the sons of Issachar, a prince, —Paltiel son of Azzan;
27 Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
And, for the tribe of the sons of Asher, a prince, —Ahihud son of Shelomi:
28 Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
And, for the tribe of the sons of Naphtali, a prince, —Pedahel, son of Ammihud.
29 Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.
These, are they whom Yahweh hath commanded to receive for the sons of Israel their inheritance, in the land of Canaan.