< Numbers 34 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
And the Lord spoke unto Moses, saying,
2 “Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
Command the children of Israel, and say unto them, when ye come into the land of Canaan, shall this be the land that shall fall unto you for an inheritance: The land of Canaan according to its boundaries.
3 “‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
And the southern side shall be unto you from the wilderness of Zin along by the boundary of Edom, and your southern border shall commence at the outmost edge of the Salt Sea on its east side.
4 kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
And the border shall turn for you from the south of the ascent of 'Akrabbim, and pass on to Zin; and its terminating points shall be to the south of Kadesh-barnea', and shall go on to Chazar-addar, and pass on to Azmon;
5 Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
And the border shall turn from 'Azmon unto the river of Egypt, and its terminating points shall be at the sea.
6 Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
And as the western border, shall ye have the Great Sea for a border: this shall be your western border.
7 Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
And this shall be unto you the northern border: from the Great Sea shall ye mark out for you [the boundary to] mount Hor;
8 àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
From mount Hor shall ye mark out [the boundary] unto the entrance of Chamath; and the terminations of the border shall be toward Zedad;
9 tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
And the border shall go on to Ziphron, and its terminating points shall be at Chazar'-enan: this shall be unto you the northern border.
10 Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
And ye shall turn yourselves to the eastern border, from Chazar-'enan to Shepham;
11 Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
And the boundary shall go down from Shepham to Riblah, to the eastward of 'Ayin; and the boundary shall descend, and shall touch upon the coast of the sea of Kinnereth, eastward;
12 Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
And the border shall go down to the Jordan, and its terminating points shall be at the Salt Sea: this shall be your land after its boundaries round about.
13 Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
And Moses commanded the children of Israel, saying, This is the land which ye shall divide among yourselves by lot, which the Lord hath commanded to give unto the nine tribes, and to the half tribe.
14 Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
For the tribe of the children of Reuben according to their family divisions, and the tribe of the children of Gad according to their family divisions, have received, —and the half of the tribe of Menasseh have received their inheritance;
15 Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
The two tribes and the half tribe have received their inheritance on this side of the Jordan opposite Jericho eastward, toward the rising of the sun.
16 Olúwa sọ fún Mose pé,
And the Lord spoke unto Moses, saying,
17 “Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
These are the names of the men who shall parcel out unto you the land: Elazar the priest, and Joshua the son of Nun.
18 Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
And one prince each from every tribe shall ye take to parcel out the land.
19 “Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
And these are the names of the men: Of the tribe of Judah, Caleb the son of Yephunneh:
20 Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
And of the tribe of the children of Simeon, Shemuel the son of 'Ammihud;
21 Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
Of the tribe of Benjamin, Elidad the son of Kisslon;
22 Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
And of the tribe of the children of Dan the prince, Bukki the son of Yogli;
23 Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
Of the children of Joseph, for the tribe of the children of Menasseh the prince, Channiel the son of Ephod;
24 Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
And of the tribe of the children of Ephraim the prince, Kemuel the son of Shiphtan;
25 Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
And of the tribe of the children of Zebulun the prince, Elizaphan the son of Parnach;
26 Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
And of the tribe of the children of Issachar the prince, Paltiel the son of 'Azzan;
27 Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
And of the tribe of the children of Asher the prince, Achihud the son of Shelomi;
28 Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
And of the tribe of the children of Naphtali the prince, Pedahel the son of 'Ammihud.
29 Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.
These are they whom the Lord hath commanded to divide out the inheritance unto the children of Israel in the land of Canaan.

< Numbers 34 >