< Numbers 33 >
1 Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
Estos son los viajes de los hijos de Israel, cuando salieron de la tierra de Egipto en sus ejércitos, bajo la dirección de Moisés y Aarón.
2 Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
Y las etapas de su viaje al salir fueron escritas por Moisés por orden del Señor: estas son las etapas de su viaje y la forma en que se fueron.
3 Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
El decimoquinto día del primer mes salieron de Ramsés; El día después de la Pascua, los hijos de Israel salieron por el poder del Señor ante los ojos de todos los egipcios.
4 Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
Mientras los egipcios colocaban en la tierra los cuerpos de sus hijos a quienes el Señor había enviado destrucción: y sus dioses habían sido juzgados por él.
5 Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
Entonces los hijos de Israel salieron de Ramsés y pusieron sus tiendas en Sucot.
6 Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
Y salieron de Sucot y levantaron sus tiendas en Etam, al borde del desierto.
7 Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
Y desde Etam, volviendo a Pi-hahirot que está antes de Baal-zefón, levantaron sus tiendas antes de Migdol.
8 Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
Y después de haber viajado desde delante de Hahiroth, atravesaron el mar hacia el desierto recorrieron tres días por el desierto de Etam y pusieron sus tiendas en Mara.
9 Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
Y de Mara pasaron a Elim, y en Elim había doce manantiales de agua y setenta palmeras; y allí levantaron sus tiendas.
10 Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
Y salieron de Elim y pusieron sus tiendas junto al Mar Rojo.
11 Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
Luego, desde el Mar Rojo, avanzaron y acamparon en el desierto de sin.
12 Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
Y salieron del desierto de Sin, y pusieron sus tiendas en Dofca.
13 Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
Y salieron de Dofca y pusieron sus tiendas en Alus.
14 Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
Salieron de Alus y pusieron sus tiendas en Refidim, donde no había agua para el pueblo.
15 Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
Y salieron de Refidim, y pusieron sus tiendas en el desierto del Sinaí.
16 Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
Salieron de la tierra baldía de Sinaí y pusieron sus tiendas en Kibrot Hataava.
17 Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
Salieron de Kibrot-hataava y pusieron sus tiendas en Hazerot.
18 Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
Y se fueron de Hazerot, y pusieron sus tiendas en Ritma.
19 Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
Y salieron de Ritma, y pusieron sus tiendas en Rimón -peres.
20 Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
Y salieron de Rimón Peres, y pusieron sus tiendas en Libna.
21 Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
Y se fueron de Libna y pusieron sus tiendas en Rissa.
22 Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
Y se fueron de Rissa y pusieron sus tiendas en Ceelata.
23 Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
Y salieron de Ceelata, y pusieron sus tiendas en el monte Sefer.
24 Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
Salieron del monte Sefer y pusieron sus tiendas en Harada.
25 Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
Salieron de Harada y pusieron sus tiendas en Macelot.
26 Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
Y ellos se fueron de Macelot, y pusieron sus tiendas en Tahat.
27 Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
Y salieron de Tahat y pusieron sus tiendas en Taré.
28 Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
Y se fueron de Taré y pusieron sus tiendas en Mitca.
29 Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
Y salieron de Mitca y pusieron sus tiendas en Hasmona.
30 Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
Y salieron de Hasmona y pusieron sus tiendas en Moserot.
31 Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
Salieron de Moserot y pusieron sus tiendas en Bene-jaacan.
32 Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
Y se fueron de Bene-jaacan, y pusieron sus tiendas en Gidgad.
33 Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
Y se fueron de Gidgad, y pusieron sus tiendas en Jotbata.
34 Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
Y salieron de Jotbata y levantaron sus tiendas en Abrona.
35 Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
Y salieron de Abrona, y pusieron sus tiendas en Ezion-geber.
36 Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
Y salieron de Ezión-geber y levantaron sus tiendas en el desierto de Zin (que es Cades).
37 Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
Y salieron de Cades y levantaron sus tiendas en el monte Hor, en el límite de la tierra de Edom.
38 Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
Entonces el sacerdote Aarón subió al monte por orden del Señor, y murió allí, en el cuadragésimo año después de que los hijos de Israel hubieran salido de la tierra de Egipto, en el quinto mes. El primer día del mes.
39 Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
Aarón tenía ciento veintitrés años cuando murió en el monte Hor.
40 Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
Y llegó la noticia de la venida de los hijos de Israel al rey de Arad, el cananeo, que vivía en el sur de la tierra de Canaán.
41 Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
Y desde el monte Hor siguieron y pusieron sus tiendas en Zalmona.
42 Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
Y salieron de Zalmona, y pusieron sus tiendas en Punón.
43 Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
Y salieron de Punón, y pusieron sus tiendas en Obot.
44 Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
Salieron de Obot y pusieron sus tiendas en Ije-abarim, al borde de Moab.
45 Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
Y salieron de Ije-abarim pusieron sus tiendas en Dibon-gad.
46 Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
Y de Dibón-gad continuaron y pusieron sus tiendas en Almón-diblataim.
47 Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
Y de Almon-diblataim siguieron y levantaron sus tiendas en las montañas de Abarim, delante de Nebo.
48 Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
Salieron de los montes de Abarim y acamparon en las llanuras de Moab, junto al Jordán en Jericó.
49 Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
Plantando sus tiendas al lado del Jordán desde Bet-jesimot hasta Abel-sitim en las tierras bajas de Moab.
50 Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
Y en las llanuras de Moab, junto al Jordán en Jericó, el Señor dijo a Moisés:
51 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
Di a los hijos de Israel: Cuando pases el Jordán a la tierra de Canaán,
52 lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
Mira que todas las personas de la tierra son expulsadas de ti, y destruyen todas sus piedras labradas, todas sus imágenes metálicas y todos sus lugares altos.
53 Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
Y tomen la tierra para ustedes, para su lugar de descanso: porque a ustedes les he dado la tierra como su herencia.
54 Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
Y tomarás tu herencia en la tierra por la decisión del Señor, a cada familia su parte; cuanto mayor sea la familia, mayor será su patrimonio, y cuanto más pequeña sea la familia, menor será su patrimonio; dondequiera que la decisión del Señor dé a cualquier hombre su parte, esa será suya; Las tribus de tus padres te harán la distribución.
55 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
Pero si demoras en expulsar a la gente de la tierra, entonces aquellos de los que todavía están allí serán como puntos de alfiler en tus ojos y como espinas en tus costados, molestándote en la tierra donde estás habitando.
56 Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”
Y sucederá que tal como fue mi propósito hacerles, así te haré a ti.