< Numbers 33 >

1 Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
Oto miejsca postojów synów Izraela, którzy wyszli z ziemi Egiptu ze swymi zastępami pod wodzą Mojżesza i Aarona.
2 Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
Na rozkaz PANA Mojżesz spisał ich wymarsze według etapów. A oto ich wymarsze według etapów:
3 Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
Wyruszyli z Ramses w pierwszym miesiącu, piętnastego dnia tego pierwszego miesiąca; nazajutrz po święcie Paschy synowie Izraela wyszli pod potężną ręką na oczach wszystkich Egipcjan;
4 Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
Podczas gdy Egipcjanie grzebali wszystkich pierworodnych, których PAN zabił wśród nich. Także i nad ich bogami PAN dokonał sądu.
5 Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
Wyruszyli więc synowie Izraela z Ramses i rozbili obóz w Sukkot.
6 Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
Wyruszyli z Sukkot i rozbili obóz w Etam, które leży na skraju pustyni.
7 Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
Wyruszyli z Etam i wrócili do Pi-Hachirot, które leży naprzeciw Baal-Sefon, i rozbili obóz przed Migdol.
8 Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
Wyruszyli z Pi-Hachirot, przeszli przez środek morza na pustyni i po trzech dniach drogi po pustyni Etam rozbili obóz w Mara.
9 Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
Wyruszyli z Mara i przyszli do Elim. A w Elim [było] dwanaście źródeł wody i siedemdziesiąt palm i tam rozbili obóz.
10 Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
Wyruszyli z Elim i rozbili obóz nad Morzem Czerwonym.
11 Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
Wyruszyli znad Morza Czerwonego i rozbili obóz na pustyni Sin.
12 Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
Wyruszyli z pustyni Sin i rozbili obóz w Dofka.
13 Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
Wyruszyli z Dofka i rozbili obóz w Alusz.
14 Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
Wyruszyli z Alusz i rozbili obóz w Refidim, gdzie lud nie miał wody do picia.
15 Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
Wyruszyli z Refidim i rozbili obóz na pustyni Synaj.
16 Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
Wyruszyli z pustyni Synaj i rozbili obóz w Kibrot-Hattaawa.
17 Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
Wyruszyli z Kibrot-Hattaawa i rozbili obóz w Chaserot.
18 Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
Wyruszyli z Chaserot i rozbili obóz w Ritma.
19 Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
Wyruszyli z Ritma i rozbili obóz w Rimmon-Peres.
20 Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
Wyruszyli z Rimmon-Peres i rozbili obóz w Libnie.
21 Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
Wyruszyli z Libny i rozbili obóz w Rissa.
22 Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
Wyruszyli z Rissa i rozbili obóz w Kehelata.
23 Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
Wyruszyli z Kehelata i rozbili obóz na górze Szefer.
24 Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
Wyruszyli z góry Szefer i rozbili obóz w Charada.
25 Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
Wyruszyli z Charada i rozbili obóz w Makhelot.
26 Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
Wyruszyli z Makhelot i rozbili obóz w Tachat.
27 Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
Wyruszyli z Tachat i rozbili obóz w Terach.
28 Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
Wyruszyli z Terach i rozbili obóz w Mitka.
29 Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
Wyruszyli z Mitka i rozbili obóz w Chaszmona.
30 Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
Wyruszyli z Chaszmona i rozbili obóz w Moserot.
31 Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
Wyruszyli z Moserot i rozbili obóz w Bene-Jaakan.
32 Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
Wyruszyli z Bene-Jaakan i rozbili obóz w Chor-Haggidgad.
33 Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
Wyruszyli z Chor-Haggidgad i rozbili obóz w Jotbata.
34 Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
Wyruszyli z Jotbata i rozbili obóz w Abrona.
35 Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
Wyruszyli z Abrona i rozbili obóz w Esjon-Geber.
36 Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
Wyruszyli z Esjon-Geber i rozbili obóz na pustyni Syn, to [jest] w Kadesz.
37 Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
Wyruszyli z Kadesz i rozbili obóz na górze Hor, na granicy ziemi Edomu.
38 Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
Wtedy wstąpił kapłan Aaron na górę Hor na rozkaz PANA i tam umarł w czterdziestym roku po wyjściu synów Izraela z ziemi Egiptu, w pierwszym [dniu] piątego miesiąca.
39 Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
Aaron miał sto dwadzieścia trzy lata, kiedy umarł na górze Hor.
40 Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
A król Aradu, Kananejczyk, który mieszkał na południu w ziemi Kanaan, usłyszał, że nadciągają synowie Izraela.
41 Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
Wyruszyli z góry Hor i rozbili obóz w Salmona.
42 Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
Wyruszyli z Salmona i rozbili obóz w Punon.
43 Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
Wyruszyli z Punon i rozbili obóz w Obot.
44 Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
Wyruszyli z Obot i rozbili obóz w Ijje-Abarim, na granicy Moabu.
45 Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
Wyruszyli z Ijjim i rozbili obóz w Dibon-Gad.
46 Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
Wyruszyli z Dibon-Gad i rozbili obóz w Almon-Diblataim.
47 Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
Wyruszyli z Almon-Diblataim i rozbili obóz na górach Abarim, naprzeciwko Nebo.
48 Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
Wyruszyli z gór Abarim i rozbili obóz na równinach Moabu, nad Jordanem, naprzeciw Jerycha.
49 Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
I rozłożyli się nad Jordanem, od Bet-Jeszimot aż do Abel-Szittim, na równinach Moabu.
50 Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
I PAN przemówił do Mojżesza na równinach Moabu, nad Jordanem, naprzeciw Jerycha, tymi słowy:
51 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
Przemów do synów Izraela i powiedz im: Gdy przeprawicie się przez Jordan do ziemi Kanaan;
52 lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
Wtedy wypędzicie przed sobą wszystkich mieszkańców tej ziemi i zniszczycie wszystkie ich obrazy i wszystkie ich odlane posągi i spustoszycie wszystkie ich wyżyny.
53 Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
A wypędziwszy mieszkańców ziemi, zamieszkacie w niej, gdyż dałem wam tę ziemię w posiadanie.
54 Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
I rozdzielicie tę ziemię przez losowanie jako dziedzictwo, według waszych rodzin. Liczniejszemu dacie większe dziedzictwo, a mniej licznemu dacie mniejsze dziedzictwo. Gdzie komu los przypadnie, to będzie jego; otrzymacie dziedzictwo według pokolenia waszych ojców.
55 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
Jeśli jednak nie wypędzicie przed sobą mieszkańców tej ziemi, wtedy ci, których z nich pozostawicie, będą jak ciernie w waszych oczach i jak kolce dla waszych boków i będą was gnębić w tej ziemi, w której będziecie mieszkać.
56 Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”
Wtedy uczynię wam to, co zamierzałem uczynić im.

< Numbers 33 >