< Numbers 33 >

1 Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
Dette var Israels barns vandringer da de drog ut av Egyptens land, hær for hær, under Moses' og Arons førerskap.
2 Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
Efter Herrens befaling skrev Moses op de steder som de drog ut fra på sine vandringer, og dette er deres vandringer efter de steder som de drog ut fra:
3 Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
I den første måned, på den femtende dag i måneden, drog de ut fra Ra'amses; dagen efter påske drog Israels barn ut med løftet hånd for alle egypternes øine,
4 Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
mens egypterne jordet dem som Herren hadde slått ihjel blandt dem, alle sine førstefødte; også over deres guder hadde Herren holdt dom.
5 Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
Så drog da Israels barn fra Ra'amses og leiret sig i Sukkot.
6 Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
Og de drog fra Sukkot og leiret sig i Etam, som ligger ved grensen av ørkenen.
7 Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
Og de drog fra Etam og vendte sa om og tok veien til Pi-Hakirot, som ligger midt imot Ba'al-Sefon, og de leiret sig foran Migdol.
8 Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
Og de drog fra Hakirot og gikk gjennem havet til ørkenen; og de drog tre dagsreiser i Etams ørken og leiret sig i Mara.
9 Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
Og de drog fra Mara og kom til Elim. I Elim var det tolv vannkilder og sytti palmetrær, og de leiret sig der.
10 Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
Og de drog fra Elim og leiret sig ved det Røde Hav.
11 Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
Og de drog fra det Røde Hav og leiret sig i ørkenen Sin.
12 Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
Og de drog fra ørkenen Sin og leiret sig i Dofka.
13 Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
Og de drog fra Dofka og leiret sig i Alus.
14 Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
Og de drog fra Alus og leiret sig i Refidim; der hadde folket ikke vann å drikke.
15 Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
Og de drog fra Refidim og leiret sig i Sinai ørken.
16 Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
Og de drog fra Sinai ørken og leiret sig i Kibrot-Hatta'ava.
17 Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
Og de drog fra Kibrot-Hatta'ava og leiret sig i Haserot.
18 Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
Og de drog fra Haserot og leiret sig i Ritma.
19 Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
Og de drog fra Ritma og leiret sig i Rimmon-Peres.
20 Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
Og de drog fra Rimmon-Peres og leiret sig i Libna.
21 Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
Og de drog fra Libna og leiret sig i Rissa.
22 Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
Og de drog fra Rissa og leiret sig i Kehelata.
23 Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
Og de drog fra Kehelata og leiret sig ved Sefer-fjellet.
24 Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
Og de drog fra Sefer-fjellet og leiret sig i Harada.
25 Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
Og de drog fra Harada og leiret sig i Makhelot.
26 Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
Og de drog fra Makhelot og leiret sig i Tahat.
27 Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
Og de drog fra Tahat og leiret sig i Tarah.
28 Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
Og de drog fra Tarah og leiret sig i Mitka.
29 Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
Og de drog fra Mitka og leiret sig i Hasmona.
30 Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
Og de drog fra Hasmona og leiret sig i Moserot.
31 Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
Og de drog fra Moserot og leiret sig i Bene-Ja'akan.
32 Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
Og de drog fra Bene-Ja'akan og leiret sig i Hor-Hagidgad.
33 Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
Og de drog fra Hor-Hagidgad og leiret sig i Jotbata.
34 Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
Og de drog fra Jotbata og leiret sig i Abrona.
35 Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
Og de drog fra Abrona og leiret sig i Esjon-Geber.
36 Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
Og de drog fra Esjon-Geber og leiet sig i ørkenen Sin, i Kades.
37 Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
Og de drog fra Kades og leiret sig ved fjellet Hor på grensen av Edoms land.
38 Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
Da gikk Aron, presten, efter Herrens befaling op på fjellet Hor, og der døde han i det firtiende år efterat Israels barn var gått ut av Egyptens land, i den femte måned, på den første dag i måneden.
39 Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
Aron var hundre og tre og tyve år gammel da han døde på fjellet Hor.
40 Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
Men den kana'anittiske konge i Arad, som bodde i den sydlige del av Kana'ans land, fikk høre at Israels barn kom.
41 Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
Så drog de fra fjellet Hor og leiret sig i Salmona.
42 Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
og de drog fra Salmona og leiret sig i Punon.
43 Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
Og de drog fra Punon og leiret sig i Obot.
44 Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
Og de drog fra Obot og leiret sig i Ije-Ha'abarim ved Moabs grense.
45 Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
Og de drog fra Ijim og leiret sig i Dibon-Gad.
46 Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
Og de drog fra Dibon-Gad og leiret sig i Almon-Diblataima.
47 Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
Og de drog fra Almon-Diblataima og leiret sig ved Abarim-fjellene, foran Nebo.
48 Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
Og de drog fra Abarim-fjellene og leiret sig på Moabs ødemarker ved Jordan, midt imot Jeriko.
49 Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
Og deres leir ved Jordan strakte sig fra Bet-Hajesimot til Abel-Hassittim på Moabs ødemarker.
50 Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
Og Herren talte til Moses på Moabs ødemarker ved Jordan, midt imot Jeriko, og sa:
51 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
Tal til Israels barn og si til dem: Når I har draget over Jordan inn i Kana'ans land,
52 lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
da skal I drive alle landets innbyggere bort foran eder og tilintetgjøre alle deres stener med innhugne billeder, og I skal tilintetgjøre alle deres støpte billeder og ødelegge alle deres offerhauger.
53 Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
Og I skal ta landet i eie og bo i det; for eder har jeg gitt landet til eiendom.
54 Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
Og I skal skifte landet mellem eder ved loddkasting efter eders ætter; den store ætt skal I gi en stor arv, og den lille ætt skal du gi en liten arv; enhver skal få sin del, efter som loddet faller; efter eders fedrenestammer skal I skifte det mellem eder.
55 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
Men dersom I ikke driver landets innbyggere bort foran eder, da skal de som I lar bli tilbake av dem, bli torner i eders øine og brodder i eders sider, og de skal plage eder i det land som I bor i.
56 Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”
Og det som jeg hadde tenkt å gjøre med dem, det vil jeg da gjøre med eder.

< Numbers 33 >