< Numbers 33 >

1 Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
Stations des enfants d'Israël sortis du pays d'Egypte, formant leurs divisions sous la conduite de Moïse et d'Aaron.
2 Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
Moïse mit par écrit leurs marches selon leurs stations sur l'ordre de l'Éternel, et voici les stations qu'ils firent dans leurs marches.
3 Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
Ils partirent de Raemsès dans le premier mois, le quinzième jour du premier mois; le lendemain de la Pâque, les enfants d'Israël sortirent la main haute, aux yeux de toute l'Egypte,
4 Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
tandis que les Égyptiens donnaient la sépulture à ceux que l'Éternel avait frappés parmi eux, à tous les premiers-nés; et l'Éternel exerçait ses jugements sur leurs dieux.
5 Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
Étant donc partis de Raemsès, ils vinrent camper à Succoth.
6 Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
Et partis de Succoth ils vinrent camper à Etham situé à l'extrémité du désert.
7 Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
Et partis d'Etham ils revinrent sur Pi-Hahiroth située vis-à-vis de Baal-Tsephon et campèrent devant Migdol.
8 Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
Et partis de Hahiroth ils arrivèrent au travers de la mer dans le désert, et firent trois journées de marche dans le désert d'Etham et campèrent à Mara.
9 Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
Et partis de Mara ils parvinrent à Elim, or à Elim il y avait douze sources d'eau et soixante-dix palmiers; et ils y campèrent.
10 Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
Et partis d'Elim ils vinrent camper vers la Mer aux algues.
11 Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
Et partis de la Mer aux algues ils vinrent camper dans le désert de Sin.
12 Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
Et partis du désert de Sin ils vinrent camper à Dophka.
13 Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
Et partis de Dophka ils vinrent camper à Alus.
14 Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
Et partis d'Alus ils vinrent camper à Raphidim; or le peuple n'y trouva point d'eau à boire.
15 Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
Et partis de Raphidim ils vinrent camper dans le désert de Sinaï.
16 Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
Et partis du désert de Sinaï ils vinrent camper aux Tombeaux de la convoitise.
17 Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
Et partis des Tombeaux de la convoitise ils vinrent camper à Hatseroth.
18 Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
Et partis de Hatseroth ils vinrent camper à Rithma.
19 Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
Et partis de Rithma ils vinrent camper à Rimmon-Parets.
20 Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
Et partis de Rimmon-Parets ils vinrent camper à Libna.
21 Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
Et partis de Libna ils vinrent camper à Rissa.
22 Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
Et partis de Rissa ils vinrent camper à Kehelatha.
23 Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
Et partis de Kehelatha ils vinrent camper au mont Sapher.
24 Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
Et partis du mont Sapher ils vinrent camper à Harada.
25 Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
Et partis de Harada ils vinrent camper à Makheloth.
26 Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
Et partis de Makheloth ils vinrent camper à Thahath.
27 Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
Et partis de Thahath ils vinrent camper à Tharach.
28 Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
Et partis de Tharach ils vinrent camper à Mithka.
29 Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
Et partis de Mithka ils vinrent camper à Hasmona.
30 Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
Et partis de Hasmona ils vinrent camper à Moseroth.
31 Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
Et partis de Moseroth ils vinrent camper à Bnei-Jaakan.
32 Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
Et partis de Bnei-Jaakan ils vinrent camper à Hor-Gidgad.
33 Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
Et partis de Hor-Gidgad ils vinrent camper à Jotbatha.
34 Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
Et partis de Jotbatha ils vinrent camper à Abrona.
35 Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
Et partis de Abrona ils vinrent camper à Etsion-Géber.
36 Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
Et partis de Etsion-Géber ils vinrent camper dans le désert de Tsin: c'est Cadès.
37 Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
Et partis de Cadès ils vinrent camper au mont Hor, sur la frontière du pays d'Edom.
38 Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
C'est alors que le Prêtre Aaron monta sur le mont Hor, d'après l'ordre de l'Éternel, et qu'il y mourut la quarantième année après la sortie des enfants d'Israël hors du pays d'Egypte, le cinquième mois, le premier jour du mois;
39 Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
(or Aaron était âgé de cent vingt-trois ans, lorsqu'il mourut sur le mont Hor).
40 Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
Et le Cananéen, Roi de Arad, établi dans le Midi du pays de Canaan entendit parler de l'arrivée des enfants d'Israël.
41 Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
Et étant partis du mont Hor ils vinrent camper à Tsalmona.
42 Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
Et partis de Tsalmona ils vinrent camper à Punon.
43 Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
Et partis de Punon ils vinrent camper à Oboth.
44 Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
Et partis d'Oboth ils vinrent camper à Jiim, à la frontière de Moab.
45 Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
Et partis de Jiim ils vinrent camper à Dibon-Gad.
46 Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
Et partis de Dibon-Gad ils vinrent camper à Almon-Diblathaïm.
47 Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
Et partis de Almon-Diblathaïm ils vinrent camper aux monts Abarim devant le Nébo.
48 Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
Et partis des monts Abarim ils vinrent camper dans les plaines de Moab sur le Jourdain près de Jéricho.
49 Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
Et ils campèrent sur le Jourdain, de Beth-Jesimoth à Abel-Sittim dans les plaines de Moab.
50 Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
Et l'Éternel parla à Moïse dans les plaines de Moab sur le Jourdain près de Jéricho, en ces termes:
51 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
Parle aux enfants d'Israël et dis-leur: Quand après le passage du Jourdain vous serez entrés dans le pays de Canaan,
52 lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
vous chasserez tous les habitants du pays devant vous, détruirez toutes leurs [pierres] figurées et détruirez toutes leurs images de fonte et raserez tous leurs tertres,
53 Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
et vous occuperez le pays et vous y établirez, car je vous ai donné ce pays pour en prendre possession.
54 Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
Et vous vous partagerez le pays au sort selon vos familles; aux plus nombreux vous adjugerez un lot plus étendu; aux moins nombreux, un lot plus restreint; l'emplacement échu par le sort à quelqu'un, c'est ce qu'il aura; vous vous le partagerez d'après vos Tribus patriarcales.
55 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
Mais si vous ne chassez pas devant vous les habitants du pays, ceux d'entre eux que vous laisserez, deviendront des épines pour vos yeux, et des aiguillons dans vos flancs et ils vous mettront à la gêne dans le pays où vous serez établis.
56 Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”
Et il arrivera que ce que j'avais résolu de leur faire, c'est à vous que je le ferai.

< Numbers 33 >