< Numbers 33 >
1 Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
Voici l’itinéraire des enfants d’Israël, depuis qu’ils furent sortis du pays d’Egypte, selon leurs légions, sous la conduite de Moïse et d’Aaron.
2 Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
Moïse inscrivit leurs départs et leurs stations sur l’ordre de l’Éternel; voici donc leurs stations et leurs départs:
3 Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
ils partirent de Ramsès dans le premier mois, le quinzième jour du premier mois; le lendemain de la Pâque, les enfants d’Israël sortirent, triomphants, à la vue de toute l’Egypte,
4 Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
tandis que les Egyptiens ensevelissaient ceux que l’Éternel avait frappés parmi eux, tous les premiers-nés, l’Éternel faisant ainsi justice de leurs divinités.
5 Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
Partis de Ramsès, les enfants d’Israël s’arrêtèrent à Soukkot.
6 Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
Ils repartirent de Soukkot et se campèrent à Ethâm, situé sur la lisière du désert.
7 Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
Puis ils partirent d’Ethâm, rebroussèrent vers Pi-Hahirot, qui fait face à Baal-Cefôn, et campèrent devant Migdol.
8 Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
Ils partirent de devant Pi-Hahirot, se dirigèrent, en traversant la mer, vers le désert, et après une marche de trois journées dans le désert d’Ethâm, s’arrêtèrent à Mara.
9 Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
Partis de Mara, ils arrivèrent à Elim. Or, à Elim étaient douze sources d’eau et soixante-dix palmiers, et ils s’y campèrent.
10 Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
Puis ils repartirent d’Elim, et campèrent près de la mer des Joncs.
11 Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
Ils repartirent de la mer des Joncs et campèrent dans le désert de Sîn.
12 Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
Ils repartirent du désert de Sîn, et campèrent à Dofka.
13 Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
Ils repartirent de Dofka, et campèrent à Alouch.
14 Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
Ils repartirent d’Alouch, et campèrent à Rephidîm, où il n’y eut point d’eau à boire pour le peuple.
15 Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
IIs repartirent de Rephidîm, et campèrent dans le désert de Sinaï.
16 Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
Ils repartirent du désert de Sinaï, et campèrent à Kibroth-Hattaava.
17 Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
Ils repartirent de Kibroth-Hattaava, et campèrent à Hacêroth.
18 Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
Ils repartirent de Hacêroth, et campèrent à Rithma.
19 Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
Ils repartirent de Rithma, et campèrent à Rimmôn-Péreç.
20 Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
Ils repartirent de Rimmôn-Péreç, et campèrent à Libna,
21 Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
Ils repartirent de Libna, et campèrent à Rissa.
22 Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
Ils repartirent de Rissa, et campèrent à Kehêlatha.
23 Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
Ils repartirent de Kehêlatha, et campèrent au mont Chéfer.
24 Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
Ils repartirent du mont Chéfer, et campèrent à Harada.
25 Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
Ils repartirent de Harada, et campèrent à Makhêloth.
26 Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
Ils repartirent de Makhêloth, et campèrent à Tahath.
27 Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
Ils repartirent de Tahath, et campèrent à Térah.
28 Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
Ils repartirent de Térah, et campèrent à Mitka.
29 Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
Ils repartirent de Mitka, et campèrent à Haschmona.
30 Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
Ils repartirent de Haschmona, et campèrent à Mossêroth.
31 Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
Ils repartirent de Mossêroth, et campèrent à Benê-Yaakan.
32 Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
Ils repartirent de Benê-Yaakan, et campèrent à Hor-Haghidgad.
33 Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
Ils repartirent de Hor-Haghidgad, et campèrent à Yotbatha.
34 Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
IIs repartirent de Yotbatha, et campèrent à Abrona.
35 Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
Ils repartirent d’Abrona, et campèrent à Asiongaber.
36 Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
Ils repartirent d’Asiongaber, et campèrent au désert de Cîn, c’est-à-dire à Kadêch.
37 Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
Ils repartirent de Kadêch et campèrent à Hor-la-Montagne, à l’extrémité du pays d’Edom.
38 Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
Aaron, le pontife, monta sur cette montagne par ordre de l’Éternel, et y mourut. C’Était la quarantième année du départ des Israélites du pays d’Egypte, le premier jour du cinquième mois.
39 Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
Aaron avait cent vingt-trois ans lorsqu’il mourut à Hor-la-Montagne.
40 Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
C’Est alors que le Cananéen, roi d’Arad, qui habitait au midi du pays de Canaan, apprit l’arrivée des enfants d’Israël.
41 Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
Puis, ils partirent de Hor-la-Montagne, et vinrent camper à Çalmona.
42 Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
Ils repartirent de Çalmona, et campèrent à Pounôn.
43 Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
Ils repartirent de Pounôn, et campèrent à Oboth.
44 Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
Ils repartirent d’Oboth et campèrent à lyyê-Haabarîm, vers les confins de Moab.
45 Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
Ils repartirent d’Iyyîm, et campèrent à Dibôn-Gad.
46 Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
Ils repartirent de Dibôn-Gad, et campèrent à Almôn-Diblathayim.
47 Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
Ils repartirent d’Almôn-Diblathayim et campèrent parmi les monts Abarim, en face de Nébo.
48 Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
Ils repartirent des monts Abarîm et campèrent dans les plaines de Moab, près du Jourdain qui est vers Jéricho.
49 Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
Ils occupaient la rive du Jourdain, depuis Bêth-Hayechimoth jusqu’à Abêl-Hachittîm, dans les plaines de Moab.
50 Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
L’Éternel parla ainsi à Moïse dans les plaines de Moab, près du Jourdain vers Jéricho:
51 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
"Parle aux enfants d’Israël en ces termes: Comme vous allez passer le Jourdain pour atteindre le pays de Canaan,
52 lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
quand vous aurez chassé devant vous tous les habitants de ce pays, vous anéantirez tous leurs symboles, toutes leurs idoles de métal, et ruinerez tous leurs hauts-lieux.
53 Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
Vous conquerrez ainsi le pays et vous vous y établirez; car c’est à vous que je le donne à titre de possession.
54 Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
Vous lotirez ce pays, par la voie du sort, entre vos familles, donnant toutefois aux plus nombreux un plus grand patrimoine et aux moins nombreux un patrimoine moindre, chacun recevant ce que lui aura attribué le sort; c’est dans vos tribus paternelles que vous aurez vos lots respectifs.
55 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
Or, si vous ne dépossédez pas à votre profit tous les habitants de ce pays, ceux que vous aurez épargnés seront comme des épines dans vos yeux et comme des aiguillons à vos flancs: ils vous harcèleront sur le territoire que vous occuperez;
56 Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”
et alors, ce que j’ai résolu de leur faire, je le ferai à vous-mêmes."