< Numbers 33 >

1 Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
These ben the dwellyngis of the sones of Israel, that yeden out of the lond of Egipt, bi her cumpenyes, in the hond of Moises and of Aaron;
2 Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
whiche dwellyngis Moises discriuede bi the places of tentis, that weren chaungid bi comaundement of the Lord.
3 Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
Therfor the sones of Israel yeden forth in `an hiy hond fro Ramesses, in the firste monethe, in the fiftenthe dai of the firste monethe, in the tother dai of pask, while alle Egipcians sien,
4 Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
and birieden the firste gendrid children, whiche the Lord hadde slayn; for the Lord hadde take veniaunce also on the goddis `of hem.
5 Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
`The sones of Israel settiden tentis in Socoth,
6 Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
and fro Sochoth thei camen into Etham, which is in the laste coostis of `the wildirnesse; fro thennus thei yeden out,
7 Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
and camen ayens Phiayroth, whiche biholdith Beelsephon, and settiden tentis bifor Magdalun.
8 Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
And thei yeden forth fro Phiairoth, and passiden bi the myddil see in to the wildirnesse, and thei yeden thre daies bi the deseert of Ethan, and settiden tentis in Mara.
9 Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
And thei yeden forth fro Mara, and camen in to Helym, where weren twelue wellis of watir, and seuenti palm trees; and there thei settiden tentis.
10 Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
But also thei yeden out fro thennus, and settiden tentis on the Reed See. And thei yeden forth fro the Reed See,
11 Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
and settiden tentis in the deseert of Syn,
12 Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
fro whennus thei yeden out, and camen in to Depheca.
13 Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
And thei yeden forth fro Depheca, and settiden tentis in Haluys.
14 Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
And thei yeden forth fro Haluys, and settiden tentis in Raphidyn, where watir failide to `the puple to drinke.
15 Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
And thei yeden forth fro Raphidyn, and settiden tentis in the deseert of Synai.
16 Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
But also thei yeden out of the wildirnesse of Synay, and camen to the Sepulcris of Coueitise.
17 Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
And thei yeden forth fro the Sepulcris of Coueytise, and settiden tentis in Asseroth.
18 Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
And fro Asseroth thei camen in to Rethma.
19 Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
And thei yeden forth fro Rethma, and settiden tentis in Remon Phares;
20 Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
fro whennus thei yeden forth, and camen in to Lemphna.
21 Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
And fro Lemphna thei settiden tentis in Ressa.
22 Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
And thei yeden out fro Ressa, and camen into Celatha;
23 Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
fro whennus thei yeden forth, and settiden tentis in the hil of Sepher.
24 Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
Thei yeden out fro the hil of Sepher, and camen in to Arada;
25 Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
fro thennus thei yeden forth, and settiden tentis in Maceloth.
26 Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
And thei yeden forth fro Maceloth, and camen in to Caath.
27 Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
Fro Caath thei settiden tentis in Thare;
28 Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
fro whennus thei yeden out, and settiden tentis in Methcha.
29 Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
And fro Methcha thei settiden tentis in Esmona.
30 Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
And thei yeden forth fro Asmona, and camen in to Moseroth;
31 Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
and fro Moseroth thei settiden tentis in Benalachan.
32 Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
And thei yeden forth fro Benalachan, and camen in to the hil of Galgad;
33 Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
fro whennus thei yeden forth, and settiden tentis in Jethebacha.
34 Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
And fro Jethebacha thei camen in to Ebrona.
35 Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
And thei yeden out fro Ebrona, and settiden tentis in Asiongaber;
36 Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
fro thennus thei yeden forth, and camen in to deseert of Syn; this is Cades.
37 Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
And thei yeden fro Cades, and thei settiden tentis in the hil of Hor, in the laste coostis of the lond of Edom.
38 Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
And Aaron, the preest, stiede in to the hil of Hor, for the Lord comaundide, and there he was deed, in the fourti yeer of the goyng out of the sones of Israel fro Egipt, in the fyuethe monethe, in the firste dai of the monethe;
39 Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
whanne he was of an hundrid and thre and twenti yeer.
40 Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
And Chanaan, kyng of Arad, that dwellide at the south, in the lond of Canaan, herde that the sones of Israel camen.
41 Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
And thei yeden forth fro the hil of Hor, and settiden tentis in Salmona;
42 Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
fro thennus thei yeden forth, and camen in to Phynon.
43 Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
And thei yeden forth fro Phynon, and settiden tentis in Oboth.
44 Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
And fro Oboth thei camen in to Neabarym, `that is, into the wildirnesse of Abarym, which is in the endis of Moabitis.
45 Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
And thei yeden forth fro Neabarym, and thei settiden tentis in Dibon of Gad;
46 Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
fro whennus thei yeden forth, and settiden tentis in Helmon of Deblathaym.
47 Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
And thei yeden out fro Helmon of Deblathaym, and camen to the hillis of Abarym, ayens Nabo.
48 Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
And thei yeden forth fro the hillis of Abarym, and passiden to the feeldi places of Moab, ouer Jordan, ayens Jericho.
49 Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
And there thei settiden tentis, fro Bethsymon `til to Belsathym, in the pleynere places of Moabitis,
50 Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
where the Lord spak to Moises,
51 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
Comaunde thou to the sones of Israel, and seie thou to hem, Whanne ye han passid Jordan, and han entrid in to the lond of Canaan,
52 lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
distrie ye alle the dwelleris of that cuntrey; breke ye the titlis, `that is, auteris, and dryue ye to poudre the ymagis, and distrie ye alle heiy thingis,
53 Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
and clense ye the lond, and alle men dwellynge thereynne. For Y yaf to
54 Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
you that lond into possessioun whiche ye schulen departe to you bi lot; to mo men ye schulen yyue largere lond, and to fewere men streytere lond, as lot fallith to alle men, so eritage schal be youun; possessioun schal be departid bi lynagis and meynees.
55 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
But if ye nylen sle the dwelleris of the lond, thei, that abiden, schulen be to you as nailes in the iyen, and speris in the sidis, `that is, deedli aduersaries; and thei schulen be aduersaries to you in the lond of youre abitacioun;
56 Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”
and what euer thing Y thouyte to do `to hem, Y schal do to you.

< Numbers 33 >