< Numbers 33 >

1 Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
These, are the departures of the sons of Israel whereby they came forth out of the land of Egypt by their hosts, —in the hand of Moses and Aaron.
2 Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
And Moses wrote their comings forth by their departures, at the bidding of Yahweh, —and these, are their departures by their comings forth.
3 Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
So then they brake up from Rameses in the first month, on the fifteenth day of the first month, on the morrow of the passover, came forth the sons of Israel with an uplifted hand, in the sight of all the Egyptians;
4 Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
when the Egyptians, were burying them whom Yahweh had smitten among them, every firstborn, —when, upon their gods, Yahweh had executed judgments,
5 Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
Thus then the sons of Israel brake up from Rameses, —and encamped in Succoth.
6 Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
And they brake up from Succoth, —and encamped in Etham, which is at the edge of the desert.
7 Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
And they brake up from Etham, and turned upon Pi-hahiroth, which is over against Baal-zephon, —and encamped before Migdol.
8 Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
And they brake up from before Hahiroth, and passed through the midst of the sea towards the desert, —and went their way a journey of three days in the desert of Etham, and encamped in Marah.
9 Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
And they brake up from Marah, and came in towards Elim; there being, in Elim, twelve fountains of water, and seventy palm-trees, so they encamped there.
10 Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
And they brake up from Elim, —and encamped by the Red Sea.
11 Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
And they brake up from the Red Sea, —and encamped in the desert of Sin.
12 Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
And they brake up from the desert of Sin, —and encamped in Dophkah.
13 Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
And they brake up from Dophkah, —and encamped in Alush.
14 Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
And they brake up from Alush, —and encamped in Rephidim, where was no water for the people to drink.
15 Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
And they brake up from Rephidim, —and encamped in the desert of Sinai.
16 Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
And they brake up from the desert of Sinai, —and encamped in Kibroth-hattaavah.
17 Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
And they brake up from Kibroth-hattaavah, —and encamped in Hazeroth.
18 Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
And they brake up from Hazeroth, —and encamped in Rithmah.
19 Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
And they brake up from Rithmah, —and encamped in Rimmon-perez.
20 Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
And they brake up from Rimmon-perez, —and encamped in Libnah.
21 Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
And they brake up from Libnah, —and encamped in Rissah.
22 Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
And they brake up from Rissah, —and encamped in Kehelathah.
23 Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
And they brake up from Kehelathah, —and encamped in Mount Shepher.
24 Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
And they brake up from Mount Shepher, —and encamped in Haradah.
25 Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
And they brake up from Haradah, —and encamped in Makheloth.
26 Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
And they brake up from Makheloth, —and encamped in Tahath.
27 Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
And they brake up from Tahath, —and encamped in Terah.
28 Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
And they brake up from Terah, —and encamped in Mithkah.
29 Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
And they brake up from Mithkah, —and encamped in Hashmonah.
30 Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
And they brake up from Hashmonah, —and encamped in Moseroth.
31 Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
And they brake up from Moseroth, and encamped in Bene-jaakan.
32 Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
And they brake up from Bene-jaakan, and encamped in Hor-haggidgad.
33 Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
And they brake up from Hor-haggidgad, —and encamped in Jotbathah, —
34 Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
And they brake up from Jotbathah, —and encamped in Abronah.
35 Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
And they brake up from Abronah, —and encamped in Eziongeber.
36 Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
And they brake up from Eziongeber, —and encamped in the desert of Zin, the same, is Kadesh.
37 Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
And they brake, up from Kadesh, —and encamped in Mount Hor, on the outskirts of the land of Edom;
38 Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
and Aaron the priest went up into Mount Hor, at the bidding of Yahweh, and died there, in the fortieth year, by the coming forth of the sons of Israel out of the land of Egypt, in the fifth month, on the first of the month.
39 Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
Now, Aaron, was a hundred and twenty-three years old, when he died in Mount Hor.
40 Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
And a Canaanite king of Arad, who was dwelling in the South, in the land of Canaan, heard of the coming in of the sons of Israel.
41 Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
And, they brake up from Mount Hor, —and encamped in Zalmonah.
42 Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
And they brake up from Zalmonah, —and encamped in Punon.
43 Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
And they brake up from Punon, and encamped in Oboth.
44 Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
And they brake up from Oboth, —and encamped in Iye-abarim, within the bounds of Moab.
45 Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
And they brake up from Iyim, —and encamped in Dibon-gad.
46 Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
And they brake up from Dibon-gad, and encamped in Almon-diblathaim.
47 Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
And they brake up from Almon-diblathaim, —and encamped among the mountains of Abarim, before Nebo.
48 Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
And they brake up from the mountains of Abarim, —and encamped in the waste plains of Moab, by Jordan near Jericho.
49 Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
Thus did they encamp by the Jordan from Beth-jeshimoth unto Abel-Shittim [that is, "The acacia—meadows"]—in the waste plains of Moab.
50 Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
And Yahweh spake unto Moses, in the waste plains of Moab, by Jordan near Jericho saying:
51 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
Speak unto the sons of Israel, and thou shalt say unto them, —When ye do pass over the Jordan into the land of Canaan,
52 lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
then shall ye dispossess all the inhabitants of the land from before you, and shall destroy all their figured stones, —all their molten images, also shall ye destroy, and all their high places, shall ye lay waste.
53 Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
So shall ye possess the land, and settle down therein, —for unto you, have I given the land to possess it.
54 Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
And ye shall take your inheritance in the land by lot by your families—for the large one, ye shall make large his inheritance, and for the small one, make small his inheritance, whithersoever the lot cometh out to him, his, shall, it be, by the tribes of your fathers, shall ye take your inheritance.
55 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
But if ye do not dispossess the inhabitants of the land from before you, then shall it be. that they whom ye leave remaining of them will become pricks in your eyes, and thorns in your sides, and will harass you, concerning the land, wherein, ye are settling down.
56 Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”
And it shall be, that as I thought to do unto them, I will do unto you.

< Numbers 33 >