< Numbers 33 >

1 Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
These [are] the journeys of the children of Israel, which went forth out of the land of Egypt with their armies under the hand of Moses and Aaron.
2 Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
And Moses wrote their goings out according to their journeys by the commandment of the LORD: and these [are] their journeys according to their goings out.
3 Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
And they departed from Rameses in the first month, on the fifteenth day of the first month; on the morrow after the passover the children of Israel went out with an high hand in the sight of all the Egyptians.
4 Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
For the Egyptians buried all [their] firstborn, which the LORD had smitten among them: upon their gods also the LORD executed judgments.
5 Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
And the children of Israel removed from Rameses, and pitched in Succoth.
6 Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
And they departed from Succoth, and pitched in Etham, which [is] in the edge of the wilderness.
7 Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
And they removed from Etham, and turned again unto Pi-hahiroth, which [is] before Baal-zephon: and they pitched before Migdol.
8 Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
And they departed from before Pi-hahiroth, and passed through the midst of the sea into the wilderness, and went three days’ journey in the wilderness of Etham, and pitched in Marah.
9 Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
And they removed from Marah, and came unto Elim: and in Elim [were] twelve fountains of water, and threescore and ten palm trees; and they pitched there.
10 Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
And they removed from Elim, and encamped by the Red sea.
11 Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
And they removed from the Red sea, and encamped in the wilderness of Sin.
12 Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
And they took their journey out of the wilderness of Sin, and encamped in Dophkah.
13 Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
And they departed from Dophkah, and encamped in Alush.
14 Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
And they removed from Alush, and encamped at Rephidim, where was no water for the people to drink.
15 Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
And they departed from Rephidim, and pitched in the wilderness of Sinai.
16 Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
And they removed from the desert of Sinai, and pitched at Kibroth-hattaavah.
17 Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
And they departed from Kibroth-hattaavah, and encamped at Hazeroth.
18 Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
And they departed from Hazeroth, and pitched in Rithmah.
19 Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
And they departed from Rithmah, and pitched at Rimmon-parez.
20 Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
And they departed from Rimmon-parez, and pitched in Libnah.
21 Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
And they removed from Libnah, and pitched at Rissah.
22 Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
And they journeyed from Rissah, and pitched in Kehelathah.
23 Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
And they went from Kehelathah, and pitched in mount Shapher.
24 Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
And they removed from mount Shapher, and encamped in Haradah.
25 Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
And they removed from Haradah, and pitched in Makheloth.
26 Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
And they removed from Makheloth, and encamped at Tahath.
27 Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
And they departed from Tahath, and pitched at Tarah.
28 Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
And they removed from Tarah, and pitched in Mithcah.
29 Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
And they went from Mithcah, and pitched in Hashmonah.
30 Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
And they departed from Hashmonah, and encamped at Moseroth.
31 Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
And they departed from Moseroth, and pitched in Bene-jaakan.
32 Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
And they removed from Bene-jaakan, and encamped at Hor-hagidgad.
33 Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
And they went from Hor-hagidgad, and pitched in Jotbathah.
34 Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
And they removed from Jotbathah, and encamped at Ebronah.
35 Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
And they departed from Ebronah, and encamped at Ezion-gaber.
36 Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
And they removed from Ezion-gaber, and pitched in the wilderness of Zin, which [is] Kadesh.
37 Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
And they removed from Kadesh, and pitched in mount Hor, in the edge of the land of Edom.
38 Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
And Aaron the priest went up into mount Hor at the commandment of the LORD, and died there, in the fortieth year after the children of Israel were come out of the land of Egypt, in the first [day] of the fifth month.
39 Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
And Aaron [was] an hundred and twenty and three years old when he died in mount Hor.
40 Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
And king Arad the Canaanite, which dwelt in the south in the land of Canaan, heard of the coming of the children of Israel.
41 Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
And they departed from mount Hor, and pitched in Zalmonah.
42 Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
And they departed from Zalmonah, and pitched in Punon.
43 Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
And they departed from Punon, and pitched in Oboth.
44 Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
And they departed from Oboth, and pitched in Ije-abarim, in the border of Moab.
45 Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
And they departed from Iim, and pitched in Dibon-gad.
46 Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
And they removed from Dibon-gad, and encamped in Almon-diblathaim.
47 Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
And they removed from Almon-diblathaim, and pitched in the mountains of Abarim, before Nebo.
48 Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
And they departed from the mountains of Abarim, and pitched in the plains of Moab by Jordan [near] Jericho.
49 Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
And they pitched by Jordan, from Beth-jesimoth [even] unto Abel-shittim in the plains of Moab.
50 Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
And the LORD spake unto Moses in the plains of Moab by Jordan [near] Jericho, saying,
51 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
Speak unto the children of Israel, and say unto them, When ye are passed over Jordan into the land of Canaan;
52 lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
Then ye shall drive out all the inhabitants of the land from before you, and destroy all their pictures, and destroy all their molten images, and quite pluck down all their high places:
53 Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
And ye shall dispossess [the inhabitants] of the land, and dwell therein: for I have given you the land to possess it.
54 Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
And ye shall divide the land by lot for an inheritance among your families: [and] to the more ye shall give the more inheritance, and to the fewer ye shall give the less inheritance: every man’s [inheritance] shall be in the place where his lot falleth; according to the tribes of your fathers ye shall inherit.
55 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
But if ye will not drive out the inhabitants of the land from before you; then it shall come to pass, that those which ye let remain of them [shall be] pricks in your eyes, and thorns in your sides, and shall vex you in the land wherein ye dwell.
56 Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”
Moreover it shall come to pass, [that] I shall do unto you, as I thought to do unto them.

< Numbers 33 >