< Numbers 33 >
1 Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
He tah Moses neh Aaron kut hmuiah amamih kah caempuei neh Egypt kho lamloh a coe uh vaengkah Israel ca rhoek kah longcaeh ni.
2 Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
Moses loh BOEIPA olka bangla a longpueng kah a pongthohnah te a daek. He rhoek he a longpueng uh vaengkah amih kah pongthohnah ni.
3 Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
A hla lamhmacuek dongkah hla sae hnin hlai nga dongah Raameses lamloh cet uh. Yoom vuen ah Israel ca rhoek te coe uh tih Egypt pum kah mikhmuh ah kut a thueng uh.
4 Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
Te vaengah BOEIPA loh a ngawn Egypt te a up uh. Amih kah caming boeih neh a pathen rhoek soah BOEIPA loh tholhphu a thuung.
5 Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
Israel ca rhoek te Raameses lamloh cet tih Sukkoth ah rhaeh uh.
6 Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
Sukkoth lamloh cet uh tih khosoek hmoi kah Etham ah rhaeh uh.
7 Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
Etham lamloh a caeh uh vaengah Baalzephon rhaldan kah Pihahiroth la mael uh tih Migdol rhaldan ah rhaeh uh.
8 Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
Pihahiroth rhaldan lamloh a caeh uh vaengah tuipuei laklung ah khosoek la kat uh. Etham khosoek ah hnin thum longcaeh te cet uh tih Marah ah rhaeh uh.
9 Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
Marah lamloh cet uh tih Elim la pawk uh. Elim ah tuiphuet tui hlai nit neh rhophoe sawmrhih om tih pahoi rhaeh uh.
10 Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
Elim lamloh cet uh tih carhaek tuipuei ah rhaeh uh.
11 Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
Carhaek tuipuei lamloh cet uh tih Sin khosoek ah rhaeh uh.
12 Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
Sin khosoek lamloh cet uh tih Dophkah ah rhaeh uh.
13 Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
Dophkah lamloh cet uh tih Alush ah rhaeh uh.
14 Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
Alush lamloh cet uh tih Rephidim ah rhaeh uh. Tedae teah te pilnam kah a ok ham tui om pawh.
15 Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
Rephidim lamloh cet uh tih Sinai khosoek ah rhaeh uh.
16 Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
Sinai khosoek lamloh cet uh tih Kiborthhattaavah ah rhaeh uh.
17 Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
Kiborthhattaavah lamloh cet uh tih Hazeroth ah rhaeh uh.
18 Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
Hazeroth lamloh cet uh tih Rithmah ah rhaeh uh.
19 Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
Rithmah lamloh cet uh tih Rimmonperez la rhaeh uh.
20 Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
Rimmonperez lamloh cet uh tih Libnah ah rhaeh uh.
21 Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
Libnah lamloh cet uh tih Rissah ah rhaeh uh.
22 Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
Rissah lamloh cet uh tih Kehelathah ah rhaeh uh.
23 Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
Kehelathah lamloh cet uh tih Shepher tlang ah rhaeh uh.
24 Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
Shepher tlang lamloh cet uh tih Haradah ah rhaeh uh.
25 Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
Haradah lamloh cet uh tih Makheloth ah rhaeh uh.
26 Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
Makheloth lamloh puen uh tih Tahath ah rhaeh uh.
27 Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
Tahath lamloh cet uh tih Terah ah rhaeh uh.
28 Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
Terah lamloh cet uh tih Mithkah ah rhaeh uh.
29 Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
Mithkah lamloh cet uh tih Hashmonah ah rhaeh uh.
30 Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
Hashmonah lamloh cet uh tih Moserah ah rhaeh uh.
31 Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
Moserah lamloh cet uh tih Benejaakan ah rhaeh uh.
32 Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
Benejaakan lamloh cet uh tih Horhagidgad ah rhaeh uh.
33 Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
Horhagidgad lamloh cet uh tih Jobathah ah rhaeh uh.
34 Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
Jobathah lamloh puen uh tih Abronah ah rhaeh uh.
35 Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
Abronah lamloh puen uh tih Eziongeber ah rhaeh uh.
36 Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
Eziongeber lamloh cet uh tih Kadesh kah Zin khosoek ah rhaeh uh.
37 Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
Kadesh lamloh cet uh tih Edom khohmuen bawt kah Hor tlang ah rhaeh uh.
38 Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
Hor tlang ah tah khosoih Aaron khaw BOEIPA kah olka bangla cet coeng tih Egypt kho lamloh Israel ca rhoek a coe uh phoeikah kum likip, hla nga, hlasae cuek vaengah pahoi duek.
39 Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
Aaron he a kum ya pakul pathum a lo ca vaengah Hor tlang ah duek.
40 Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
Te vaengah Kanaan khohmuen ah Israel ca rhoek a pawk te tuithim kah kho aka sa Arad manghai Kanaan loh a yaak.
41 Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
Hor tlang lamloh puen uh tih Zalmonah ah rhaeh uh.
42 Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
Zalmonah lamloh puen uh tih Punon ah rhaeh uh.
43 Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
Punon lamloh puen uh tih Oboth ah rhaeh uh.
44 Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
Oboth lamloh puen uh tih Moab khorhi kah Ijeabarim ah rhaeh uh.
45 Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
Iyim lamloh puen uh tih Gad Dibon ah rhaeh uh.
46 Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
Gad Dibon lamloh puen uh tih Almondiblathaim ah rhaeh uh.
47 Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
Almondiblathaim lamloh puen uh tih Nebo rhaldan kah Abarim tlang ah rhaeh uh.
48 Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
Abarim tlang lamloh puen uh tih Jerikho Jordan kah lo Moab kolken ah rhaeh uh.
49 Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
Jordan kah Moab kolken ah te Bethjeshimoth lamloh Abelshittim duela rhaeh uh.
50 Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
Jerikho Jordan kah Moab kolken ah BOEIPA loh Moses te a voek tih,
51 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
“Israel ca rhoek te voek lamtah amih te thui pah. Nangmih Kanaan khohmuen la Jordan te kat uh.
52 lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
Te vaengah khohmuen kah khosa boeih te na mikhmuh lamloh haek uh. Amih kah ngaihlihnah cungkuem te thup uh lamtah a mueihlawn mueihlip boeih te khaw thup uh. Amih kah hmuensang boeih te khaw tulh uh.
53 Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
Khohmuen te pang uh lamtah a khuiah khosa uh. Khohmuen te pang hamla nangmih taengah kam paek coeng.
54 Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
Khohmuen te hmulung neh tael uh. Nangmih kah koca aka ping ham tah a rho te kum sak lamtah a sii ham tah a rho te sih pah. Amah ham hmulung dongah a naan te tah anih ham om pawn vetih na pa rhoek kah koca tarhing ah pang uh.
55 “‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
Khohmuen kah khosa rhoek te na mikhmuh lamloh na haek uh pawt atah amih lamkah na sueng sak uh te nangmih mik ah miktlaeh banlga, nangmih kaep ah tlaeh la om ni. A khuikah kho na sak nah khohmuen ah nangmih te n'daengdaeh uh ni.
56 Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”
Amih taengah saii ham ka cai vanbangla nangmih taengah khaw ka saii ni,” a ti nah.