< Numbers 32 >

1 Àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, tí wọ́n ní ẹran ọ̀sìn àti ohun ọ̀sìn rí wí pé ilẹ̀ Jaseri àti Gileadi dára fún ohun ọ̀sìn.
Фиий луй Рубен ши фиий луй Гад авяу о маре мулциме де вите ши ау вэзут кэ цара луй Иаезер ши цара Галаадулуй ерау ун лок бун пентру вите.
2 Àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni sì wá, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà àti sí olórí gbogbo ìlú, wọ́n sì wí pé,
Атунч, фиий луй Гад ши фиий луй Рубен ау венит ла Мойсе, ла преотул Елеазар ши ла май-марий адунэрий ши ле-ау зис:
3 “Atarotu, Diboni, Jaseri, Nimra, Heṣboni, Eleale, Sebamu, Nebo, àti Beoni.
„Атарот, Дибон, Иаезер, Нимра, Хесбон, Елеале, Себам, Небо ши Беон,
4 Ni ilẹ̀ tí Olúwa ti ṣẹ́gun níwájú ìjọ Israẹli tí ó sì dára fún ohun ọ̀sìn, ṣáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ohun ọ̀sìn.”
цара ачаста пе каре а ловит-о Домнул ынаинтя адунэрий луй Исраел есте ун лок бун пентру вите, ши робий тэй ау вите.”
5 Wọ́n wí pé, “Tí a bá rí ojúrere rẹ, jẹ́ kí a fi ilẹ̀ yìí fún ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìní. Má ṣe jẹ́ kí a rékọjá odò Jordani.”
Апой ау адэугат: „Дакэ ам кэпэтат тречере ынаинтя та, сэ се дя цара ачаста ын стэпыниря робилор тэй ши сэ ну не тречь песте Йордан.”
6 Mose sọ fún àwọn ọmọ Gadi àti fún ọmọ Reubeni pé, “Ṣé kí àwọn arákùnrin yín lọ sí ogun, kí ẹ̀yin kí ó sì jókòó sí bí?
Мойсе а рэспунс фиилор луй Гад ши фиилор луй Рубен: „Фраций воштри сэ мяргэ оаре ла рэзбой, ши вой сэ рэмынець аич?
7 Kí ni ó dé tí o fi mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti lọ sí ibi ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn?
Пентру че воиць сэ ынмуяць инима копиилор луй Исраел ши сэ-й фачець сэ ну трякэ ын цара пе каре ле-о дэ Домнул?
8 Èyí ni nǹkan tí baba yín ṣe nígbà tí mo rán wọn láti Kadeṣi-Barnea láti lọ wo ilẹ̀ náà.
Аша ау фэкут ши пэринций воштри кынд й-ам тримис дин Кадес-Барня сэ искодяскэ цара.
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n lọ sí àfonífojì Eṣkolu tí wọ́n rí ilẹ̀ náà, wọ́n mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn.
С-ау суит пынэ ла валя Ешкол ши, дупэ че ау искодит цара, ау ынмуят инима копиилор луй Исраел ши й-ау фэкут сэ ну интре ын цара пе каре ле-о дэдя Домнул.
10 Ìbínú Olúwa sì dìde sí wọn ní ọjọ́ náà, ó sì búra, wí pé,
Ши Домнул С-а апринс де мыние ын зиуа ачея ши а журат зикынд:
11 ‘Nítorí wọn kò tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin náà tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó gòkè láti Ejibiti ni yóò rí ilẹ̀ tí mo pinnu gẹ́gẹ́ bí ìbúra fún Abrahamu, fún Isaaki àti fún Jakọbu:
‘Оамений ачештя каре с-ау суит дин Еӂипт, де ла вырста де доуэзечь де ань ын сус, ну вор ведя цара пе каре ам журат кэ о вой да луй Авраам, луй Исаак ши луй Иаков, кэч н-ау урмат ын тотул каля Мя,
12 kò sí ẹnìkankan àyàfi Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti àti Joṣua ọmọ Nuni, nítorí wọ́n tẹ̀lé Olúwa tọkàntọkàn.’
афарэ де Калеб, фиул луй Иефуне, Кенизитул, ши Иосуа, фиул луй Нун, каре ау урмат ын тотул каля Домнулуй.’
13 Ìbínú Olúwa ru sí àwọn ọmọ Israẹli ó sì mú wọn rìn ní aginjù fún ogójì ọdún, títí tí àwọn ìran tí wọ́n ṣe búburú ní ojú rẹ̀ fi lọ.
Домнул С-а апринс де мыние ымпотрива луй Исраел ши й-а фэкут сэ рэтэчяскэ ын пустиу тимп де патрузечь де ань, пынэ ла стинӂеря ынтрегулуй лят де оамень каре фэкусерэ рэу ынаинтя Домнулуй.
14 “Níbí ni ẹ̀yin wà, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀, ẹ̀yin dìde ní ipò baba yín, ẹ sì jẹ́ kí ìbínú gbígbóná Olúwa ru sí Israẹli.
Ши ятэ кэ вой луаць локул пэринцилор воштри, ка ниште одрасле де оамень пэкэтошь, ка сэ фачець пе Домнул сэ Се априндэ ши май таре де мыние ымпотрива луй Исраел.
15 Tí ẹ̀yin bá yípadà ní ẹ̀yìn rẹ̀ yóò sì fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí sílẹ̀ ní aginjù, ìwọ yóò sì mú un ṣe ìparun.”
Кэч, дакэ вэ ынтоарчець де ла Ел, Ел ва лэса май департе пе Исраел сэ рэтэчяскэ ын пустиу ши вець адуче пердеря попорулуй ачестуя ынтрег.”
16 Nígbà náà wọ́n wá sí òkè ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, “Àwa yóò fẹ́ láti kọ́ ilé ẹran níhìn-ín yìí fún ohun ọ̀sìn wa, àti ìlú fún àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa.
Ей с-ау апропият де Мойсе ши ау зис: „Вом фаче аич окоале пентру вителе ноастре ши четэць пентру прунчий ноштри,
17 Ṣùgbọ́n àwa ṣetán láti dira ogun ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli títí tí a yóò fi mú wọn dé ọ̀dọ̀ wọn lákokò yìí, àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa yóò gbé inú ìlú tí a mọ odi sí fún ìdáàbòbò wọn lọ́wọ́ olùgbé ilẹ̀ náà.
апой не вом ынарма ын грабэ ши вом мерӂе ынаинтя копиилор луй Исраел, пынэ ый вом дуче ын локул каре ле есте рындуит, ши прунчий ноштри вор локуи ын ачесте четэць ынтэрите, дин причина локуиторилор цэрий ачестея.
18 A kì yóò padà sí ilẹ̀ wa láìṣe pé gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti gba ogún wọn.
Ну не вом ынтоарче ын каселе ноастре май ынаинте ка фиекаре дин копиий луй Исраел сэ фи пус стэпынире пе моштениря луй
19 A kì yóò gba ogún kankan pẹ̀lú wọn ní òdìkejì Jordani, nítorí ogún ti wa, ti wá sí ọ̀dọ̀ wa ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani.”
ши ну вом стэпыни нимик ку ей динколо де Йордан, нич май департе, пентру кэ ной не вом авя моштениря ноастрэ динкоаче де Йордан, ла рэсэрит.”
20 Nígbà náà ni Mose sọ fún wọn pé, “Tí ẹ̀yin yóò bá pa ara yín lára, níwájú Olúwa fún ogún.
Мойсе ле-а зис: „Дакэ фачець аша, дакэ вэ ынармаць ка сэ луптаць ынаинтя Домнулуй,
21 Bí gbogbo yín yóò bá lọ sí Jordani ní ìhámọ́ra níwájú Olúwa, títí yóò fi lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ kúrò níwájú rẹ̀.
дакэ тоць ачея динтре вой каре се вор ынарма трек Йорданул ынаинтя Домнулуй, пынэ че ва изгони пе врэжмаший Луй динаинтя Луй,
22 Tí a ó sì fi ṣe ilẹ̀ náà níwájú Olúwa; ẹ̀yin lè padà tí yóò sì di òmìnira lọ́wọ́ ìdè níwájú Olúwa àti Israẹli. Ilẹ̀ yìí yóò sì jẹ́ tiyín níwájú Olúwa.
ши дакэ вэ вець ынтоарче ынапой нумай дупэ че цара ва фи супусэ ынаинтя Домнулуй, атунч вець фи фэрэ винэ ынаинтя Домнулуй ши ынаинтя луй Исраел, ши цинутул ачеста ва фи мошия воастрэ ынаинтя Домнулуй.
23 “Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kọ̀ láti ṣe èyí, ẹ̀yin yóò máa dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa; kí ẹ̀yin kí ó sì mọ̀ dájú pé ẹ̀ṣẹ̀ yín yóò fi yín hàn.
Дар, дакэ ну фачець аша, пэкэтуиць ымпотрива Домнулуй ши сэ штиць кэ пэкатул востру вэ ва ажунӂе.
24 Ẹ kọ́ ilé fún àwọn obìnrin yín àti ọmọ wẹ́wẹ́ yín, àti ilé fún agbo ẹran yín, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin kí ó ṣe ohun tí ẹ ti pinnu.”
Зидиць четэць пентру прунчий воштри ши окоале пентру вителе воастре ши фачець че аць спус ку гура воастрэ.”
25 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni sọ fún Mose pé, “Àwa ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti pàṣẹ.
Фиий луй Гад ши фиий луй Рубен ау зис луй Мойсе: „Робий тэй вор фаче тот че порунчеште домнул ностру.
26 Àwọn ọmọ wa àti ìyàwó wa, àwọn agbo ẹran àti ohun ọ̀sìn wa yóò dúró ní ìlú Gileadi.
Прунчий ноштри, невестеле, турмеле ноастре ши тоате вителе ноастре вор рэмыне ын четэциле Галаадулуй,
27 Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra ogun, yóò rékọjá lọ láti jà níwájú Olúwa; gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti sọ.”
яр робий тэй, тоць ынармаць пентру рэзбой, вор мерӂе сэ се лупте ынаинтя Домнулуй, кум зиче домнул ностру.”
28 Nígbà náà ni Mose pàṣẹ nípa wọn fún Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni àti sí gbogbo olórí ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
Мойсе а дат порунчь ку привире ла ей преотулуй Елеазар, луй Иосуа, фиул луй Нун, ши капилор де фамилие дин семинцииле копиилор луй Исраел.
29 Mose sì wí fún wọn pé, “Tí àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra fún ogun rékọjá odò Jordani pẹ̀lú níwájú Olúwa, nígbà tí ẹ ṣẹ́gun ilẹ̀ náà níwájú yín, fún wọn ní ilẹ̀ Gileadi gẹ́gẹ́ bí ìní wọn.
Ел ле-а зис: „Дакэ фиий луй Гад ши фиий луй Рубен трек ку вой Йорданул, ынармаць ку тоций ка сэ лупте ынаинтя Домнулуй, дупэ че цара ва фи супусэ ынаинтя воастрэ, сэ ле даць ын стэпынире цинутул Галаадулуй.
30 Ṣùgbọ́n tí wọn kò bá fẹ́ bá yín rékọjá pẹ̀lú ìhámọ́ra, wọn gbọdọ̀ gba ìní wọn pẹ̀lú yín ní Kenaani.”
Дар дакэ ну вор мерӂе ынармаць ымпреунэ ку вой, сэ се ашезе ын мижлокул востру ын цара Канаанулуй.”
31 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe ohun tí Olúwa ti sọ.
Фиий луй Гад ши фиий луй Рубен ау рэспунс: „Вом фаче тот че а спус робилор тэй Домнул.
32 A máa rékọjá níwájú Olúwa lọ sí Kenaani pẹ̀lú ìhámọ́ra, ṣùgbọ́n ẹrù tí a jogún yóò wà ní ẹ̀bá Jordani.”
Вом трече ынармаць ынаинтя Домнулуй ын цара Канаанулуй, дар ной сэ не авем моштениря ноастрэ динкоаче де Йордан.”
33 Nígbà náà Mose fún àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ọmọ Josẹfu ní ilẹ̀ ọba Sihoni ọba àwọn ọmọ Amori àti ilẹ̀ ọba Ogu ọba Baṣani ní gbogbo ilẹ̀ náà pẹ̀lú ìlú rẹ̀ àti agbègbè tí ó yí i ka.
Мойсе а дат фиилор луй Гад ши фиилор луй Рубен ши ла жумэтате дин семинция луй Манасе, фиул луй Иосиф, ымпэрэция луй Сихон, ымпэратул аморицилор, ши ымпэрэция луй Ог, ымпэратул Басанулуй, цара ку четэциле ей, ку цинутуриле четэцилор цэрий де жур ымпрежур.
34 Àwọn ará Gadi wọ́n kọ́ Diboni, Atarotu, Aroeri;
Фиий луй Гад ау зидит Дибонул, Атаротул, Ароерул,
35 pẹ̀lú Atrotu Ṣofani, Jaseri, àti Jogbeha,
Атрот-Шофан, Иаезер, Иогбеха,
36 pẹ̀lú Beti-Nimra, àti Beti-Harani ìlú olódi, àti agbo fún àgùntàn.
Бет-Нимра ши Бет-Харан, четэць ынтэрите, ши ау фэкут стауле пентру турме.
37 Àwọn ọmọ Reubeni sì kọ́ Heṣboni, Eleale, Kiriataimu,
Фиий луй Рубен ау зидит Хесбонул, Елеале, Кириатаим,
38 pẹ̀lú Nebo pẹ̀lú Baali-Meoni (wọ́n pàrọ̀ orúkọ wọn) àti Sibma. Wọ́n sì sọ ìlú tí wọ́n tún kọ́ ní orúkọ mìíràn.
Небо ши Баал-Меон, але кэрор нуме ау фост скимбате, ши Сибма ши ау пус алте нуме четэцилор пе каре ле-ау зидит.
39 Àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase lọ sí Gileadi, wọ́n sì lé àwọn ọmọ Amori tí ó wà níbẹ̀.
Фиий луй Макир, фиул луй Манасе, ау мерс ымпотрива Галаадулуй ши ау пус мына пе ел; ау изгонит пе амориций каре ерау аколо.
40 Mose sì fi àwọn ọmọ Gileadi fún àwọn ọmọ Makiri àwọn ìran Manase, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
Мойсе а дат Галаадул луй Макир, фиул луй Манасе, каре с-а ашезат аколо.
41 Jairi, ọmọ Manase gba ibùjókòó wọn, ó sì pè wọ́n ní Haffotu Jairi.
Иаир, фиул луй Манасе, а порнит ши ел ши а луат тыргуриле, ши ле-а нумит тыргуриле луй Иаир.
42 Noba gba Kenati àti àwọn ìtẹ̀dó rẹ̀, ó sì pè é ní Noba lẹ́yìn orúkọ ara rẹ̀.
Нобах а порнит ши ел ши а луат Кенатул, ымпреунэ ку четэциле каре циняу де ел, ши л-а нумит Нобах, дупэ нумеле луй.

< Numbers 32 >