< Numbers 32 >

1 Àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, tí wọ́n ní ẹran ọ̀sìn àti ohun ọ̀sìn rí wí pé ilẹ̀ Jaseri àti Gileadi dára fún ohun ọ̀sìn.
I mieli synowie Rubenowi, i synowie Gadowi bydła bardzo wiele; a obaczywszy ziemię Jazer i ziemię Galaad, że miejsce ono było sposobne dla bydła,
2 Àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni sì wá, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà àti sí olórí gbogbo ìlú, wọ́n sì wí pé,
Przyszli ciż synowie Gadowi, i synowie Rubenowi, i mówili do Mojżesza i do Eleazara kapłana, i do książąt zgromadzenia, i rzekli:
3 “Atarotu, Diboni, Jaseri, Nimra, Heṣboni, Eleale, Sebamu, Nebo, àti Beoni.
Ziemia Ataret i Dybon, i Jazer, i Nemra, i Hesebon, i Eleale, i Seban, i Nebo, i Beon:
4 Ni ilẹ̀ tí Olúwa ti ṣẹ́gun níwájú ìjọ Israẹli tí ó sì dára fún ohun ọ̀sìn, ṣáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ohun ọ̀sìn.”
Ziemia, którą zwojował Pan przed zgromadzeniem Izraelskiem, jest ziemia sposobna dla bydła, a my słudzy twoi mamy bydła wiele. Przetoż rzekli:
5 Wọ́n wí pé, “Tí a bá rí ojúrere rẹ, jẹ́ kí a fi ilẹ̀ yìí fún ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìní. Má ṣe jẹ́ kí a rékọjá odò Jordani.”
Jeźliśmy znaleźli łaskę przed oczyma twemi, niechże będzie dana ta ziemia sługom twym na osiadłość, a niech nie chodzimy za Jordan.
6 Mose sọ fún àwọn ọmọ Gadi àti fún ọmọ Reubeni pé, “Ṣé kí àwọn arákùnrin yín lọ sí ogun, kí ẹ̀yin kí ó sì jókòó sí bí?
Tedy odpowiedział Mojżesz synom Gadowym, i synom Rubenowym: Więc bracia wasi pójdą na wojnę, a wy tu siedzieć będziecie?
7 Kí ni ó dé tí o fi mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti lọ sí ibi ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn?
Czemuż psujecie serce synom Izraelskim, żeby nie szli do ziemi, którą im dał Pan?
8 Èyí ni nǹkan tí baba yín ṣe nígbà tí mo rán wọn láti Kadeṣi-Barnea láti lọ wo ilẹ̀ náà.
Takci uczynili ojcowie wasi, gdym je był posłał z Kades Barne ku przeszpiegowaniu tej ziemi;
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n lọ sí àfonífojì Eṣkolu tí wọ́n rí ilẹ̀ náà, wọ́n mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn.
Bo gdy przyszli aż do doliny Eschol, obejrzawszy onę ziemię popsowali serce synom Izraelskim, aby nie szli do ziemi, którą im dał Pan;
10 Ìbínú Olúwa sì dìde sí wọn ní ọjọ́ náà, ó sì búra, wí pé,
Skąd zapaliwszy się gniewem Pan, dnia onego przysiągł, mówiąc:
11 ‘Nítorí wọn kò tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin náà tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó gòkè láti Ejibiti ni yóò rí ilẹ̀ tí mo pinnu gẹ́gẹ́ bí ìbúra fún Abrahamu, fún Isaaki àti fún Jakọbu:
Zaiste nie oglądają ludzie ci, którzy wyszli z Egiptu, od dwudziestu lat i wyżej, tej ziemi, o którąm przysiągł Abrahamowi, Izaakowi, i Jakóbowi, przeto iż mię cale nie naśladowali;
12 kò sí ẹnìkankan àyàfi Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti àti Joṣua ọmọ Nuni, nítorí wọ́n tẹ̀lé Olúwa tọkàntọkàn.’
Oprócz Kaleba, syna Jefunowego, Kenezejczyka, i Jozuego, syna Nunowego, ponieważ ci cale naśladowali Pana.
13 Ìbínú Olúwa ru sí àwọn ọmọ Israẹli ó sì mú wọn rìn ní aginjù fún ogójì ọdún, títí tí àwọn ìran tí wọ́n ṣe búburú ní ojú rẹ̀ fi lọ.
I zapalił się gniewem Pan na Izraela, i sprawił, że się tułali po puszczy przez czterdzieści lat, aż poginął wszystek on naród, który czynił źle przed oczyma Pańskimi.
14 “Níbí ni ẹ̀yin wà, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀, ẹ̀yin dìde ní ipò baba yín, ẹ sì jẹ́ kí ìbínú gbígbóná Olúwa ru sí Israẹli.
A oto, wy powstaliście miasto ojców waszych, plemię ludzi grzesznych, abyście jeszcze przyczynili gniewu zapalczywości Pańskiej przeciwko Izraelowi.
15 Tí ẹ̀yin bá yípadà ní ẹ̀yìn rẹ̀ yóò sì fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí sílẹ̀ ní aginjù, ìwọ yóò sì mú un ṣe ìparun.”
Bo jeźli się odwrócicie od naśladowania jego, tedy on też zaniecha go jeszcze na tej puszczy; a tak wy zgubicie ten wszystek lud.
16 Nígbà náà wọ́n wá sí òkè ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, “Àwa yóò fẹ́ láti kọ́ ilé ẹran níhìn-ín yìí fún ohun ọ̀sìn wa, àti ìlú fún àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa.
Tedy przystąpiwszy do niego rzekli: Obory bydłu i dobytkowi naszemu, i miasta dziatkom naszym tu pobudujemy;
17 Ṣùgbọ́n àwa ṣetán láti dira ogun ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli títí tí a yóò fi mú wọn dé ọ̀dọ̀ wọn lákokò yìí, àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa yóò gbé inú ìlú tí a mọ odi sí fún ìdáàbòbò wọn lọ́wọ́ olùgbé ilẹ̀ náà.
Ale sami zbrojno ochotnie pójdziemy przed syny Izraelskimi, aż je zaprowadzimy na miejsce ich, a dziatki nasze będą mieszkały w mieściech obronnych dla obywateli tej ziemi.
18 A kì yóò padà sí ilẹ̀ wa láìṣe pé gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti gba ogún wọn.
Nie wrócimy się do domów naszych, aż posiądą synowie Izraelscy każdy dziedzictwo swoje;
19 A kì yóò gba ogún kankan pẹ̀lú wọn ní òdìkejì Jordani, nítorí ogún ti wa, ti wá sí ọ̀dọ̀ wa ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani.”
Ani weźmiemy dziedzictwa z nimi za Jordanem i dalej, ponieważ przychodzi dziedzictwo nasze na nas z tej strony Jordanu na wschód słońca.
20 Nígbà náà ni Mose sọ fún wọn pé, “Tí ẹ̀yin yóò bá pa ara yín lára, níwájú Olúwa fún ogún.
I rzekł im Mojżesz: Jeźliż uczynicie, coście rzekli, a pójdziecie zbrojno przed obliczem Pańskiem na wojnę;
21 Bí gbogbo yín yóò bá lọ sí Jordani ní ìhámọ́ra níwájú Olúwa, títí yóò fi lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ kúrò níwájú rẹ̀.
I pójdzie każdy z was zbrojno za Jordan przed oblicznością Pańską, ażby wypędził nieprzyjacioły swoje od oblicza swego;
22 Tí a ó sì fi ṣe ilẹ̀ náà níwájú Olúwa; ẹ̀yin lè padà tí yóò sì di òmìnira lọ́wọ́ ìdè níwájú Olúwa àti Israẹli. Ilẹ̀ yìí yóò sì jẹ́ tiyín níwájú Olúwa.
I aż będzie poddana ziemia ona Panu, a potem się wrócicie, i będziecie bez winy przed Panem i przed Izraelem: tedy wam będzie ta ziemia za osiadłość przed obliczem Pańskiem.
23 “Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kọ̀ láti ṣe èyí, ẹ̀yin yóò máa dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa; kí ẹ̀yin kí ó sì mọ̀ dájú pé ẹ̀ṣẹ̀ yín yóò fi yín hàn.
Ale jeźli tego nie uczynicie, oto zgrzeszycie Panu, a wiedzcie, że grzech wasz znajdzie was.
24 Ẹ kọ́ ilé fún àwọn obìnrin yín àti ọmọ wẹ́wẹ́ yín, àti ilé fún agbo ẹran yín, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin kí ó ṣe ohun tí ẹ ti pinnu.”
Budujcież tedy miasta dziatkom waszym, i obory bydłu waszemu, a co wyszło z ust waszych, uczyńcie.
25 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni sọ fún Mose pé, “Àwa ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti pàṣẹ.
Tedy rzekli synowie Gadowi, i synowie Rubenowi do Mojżesza, mówiąc: Słudzy twoi uczynią, jako pan nasz rozkazuje.
26 Àwọn ọmọ wa àti ìyàwó wa, àwọn agbo ẹran àti ohun ọ̀sìn wa yóò dúró ní ìlú Gileadi.
Dziatki nasze, i żony nasze, stada nasze, i wszystkie bydła nasze, zostaną tu w mieściech Galaadzkich;
27 Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra ogun, yóò rékọjá lọ láti jà níwájú Olúwa; gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti sọ.”
Ale słudzy twoi pójdą wszyscy zbrojno przed Panem na wojnę, jako pan nasz mówi.
28 Nígbà náà ni Mose pàṣẹ nípa wọn fún Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni àti sí gbogbo olórí ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
I przykazał o nich Mojżesz Eleazarowi kapłanowi, i Jozuemu, synowi Nunowemu, i książętom ojców pokoleń synów Izraelskich,
29 Mose sì wí fún wọn pé, “Tí àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra fún ogun rékọjá odò Jordani pẹ̀lú níwájú Olúwa, nígbà tí ẹ ṣẹ́gun ilẹ̀ náà níwájú yín, fún wọn ní ilẹ̀ Gileadi gẹ́gẹ́ bí ìní wọn.
I rzekł im: Jeźli przejdą synowie Gadowi, i synowe Rubenowi z wami za Jordan, wszyscy zbrojno na wojnę przed Panem, a będzie pohołdowana ziemia przed wami, tedy im dacie ziemię Galaad w dziedzictwo;
30 Ṣùgbọ́n tí wọn kò bá fẹ́ bá yín rékọjá pẹ̀lú ìhámọ́ra, wọn gbọdọ̀ gba ìní wọn pẹ̀lú yín ní Kenaani.”
Ale jeźli nie zbrojno z wami przejdą, tedy niech mają dziedzictwo między wami w ziemi Chananejskiej.
31 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe ohun tí Olúwa ti sọ.
I odpowiedzieli synowie Gadowi, i synowie Rubenowi, mówiąc: Co wyrzekł Pan do sług swoich, to uczynimy;
32 A máa rékọjá níwájú Olúwa lọ sí Kenaani pẹ̀lú ìhámọ́ra, ṣùgbọ́n ẹrù tí a jogún yóò wà ní ẹ̀bá Jordani.”
Pójdziemy zbrojno przed Panem do ziemi Chananejskiej, a zostanie przy nas osiadłość dziedzictwa naszego z tej strony Jordanu.
33 Nígbà náà Mose fún àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ọmọ Josẹfu ní ilẹ̀ ọba Sihoni ọba àwọn ọmọ Amori àti ilẹ̀ ọba Ogu ọba Baṣani ní gbogbo ilẹ̀ náà pẹ̀lú ìlú rẹ̀ àti agbègbè tí ó yí i ka.
Dał tedy Mojżesz synom Gadowym, i synom Rubenowym, i połowie pokolenia Manasesa, syna Józefowego, królestwo Sehona, króla Amorejskiego, i królestwo Oga, króla Basańskiego, ziemię z miasty jej, z granicami, i miasta ziemi onej w około.
34 Àwọn ará Gadi wọ́n kọ́ Diboni, Atarotu, Aroeri;
I pobudowali synowie Gadowi Dybon, i Atarot, i Aroer;
35 pẹ̀lú Atrotu Ṣofani, Jaseri, àti Jogbeha,
I Atrot, i Sofan, i Jazer, i Jegba,
36 pẹ̀lú Beti-Nimra, àti Beti-Harani ìlú olódi, àti agbo fún àgùntàn.
I Betnimera, i Betaran, miasta obronne, i obory dla bydła.
37 Àwọn ọmọ Reubeni sì kọ́ Heṣboni, Eleale, Kiriataimu,
Synowie też Rubenowi pobudowali Hesebon, i Eleale, i Karyjataim.
38 pẹ̀lú Nebo pẹ̀lú Baali-Meoni (wọ́n pàrọ̀ orúkọ wọn) àti Sibma. Wọ́n sì sọ ìlú tí wọ́n tún kọ́ ní orúkọ mìíràn.
I Nebo, i Baalmeon, odmieniwszy im imiona, także Sabana; i dali imiona insze onym miastom, które pobudowali.
39 Àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase lọ sí Gileadi, wọ́n sì lé àwọn ọmọ Amori tí ó wà níbẹ̀.
Wtargnęli też synowie Machyra, syna Manasesowego, do Galaad, a wziąwszy je, wygnali Amorejczyka, który tam mieszkał.
40 Mose sì fi àwọn ọmọ Gileadi fún àwọn ọmọ Makiri àwọn ìran Manase, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
I dał Mojżesz Galaad Machyrowi, synowi Manasesowemu, i mieszkał w nim.
41 Jairi, ọmọ Manase gba ibùjókòó wọn, ó sì pè wọ́n ní Haffotu Jairi.
Potem Jair, syn Manasesów, wtargnął, i pobrał wsi ich, które przezwał Chawot Jair.
42 Noba gba Kenati àti àwọn ìtẹ̀dó rẹ̀, ó sì pè é ní Noba lẹ́yìn orúkọ ara rẹ̀.
Także Nobe wtargnął, i wziął Kanat z jego wsiami, i nazwał je Nobe od imienia swego.

< Numbers 32 >