< Numbers 32 >

1 Àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, tí wọ́n ní ẹran ọ̀sìn àti ohun ọ̀sìn rí wí pé ilẹ̀ Jaseri àti Gileadi dára fún ohun ọ̀sìn.
Sok nyája volt Rúbén és Gád fiainak, nagyon számos; és látták Jázér földjét, meg Gileád földjét, hogy íme, a hely nyájnak való hely.
2 Àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni sì wá, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà àti sí olórí gbogbo ìlú, wọ́n sì wí pé,
Elmentek tehát Gád fiai és Rúbén fiai és szóltak Mózeshez, meg Eleázárhoz, a paphoz és a község fejedelmeihez, mondván:
3 “Atarotu, Diboni, Jaseri, Nimra, Heṣboni, Eleale, Sebamu, Nebo, àti Beoni.
Átorosz, Divón, Jázér, Nimró, Chesbón és Elolé, Szevom, Nevó és Beón,
4 Ni ilẹ̀ tí Olúwa ti ṣẹ́gun níwájú ìjọ Israẹli tí ó sì dára fún ohun ọ̀sìn, ṣáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ohun ọ̀sìn.”
az ország, melyet levert az Örökkévaló Izrael községe előtt, nyájnak való föld, szolgáidnak pedig van nyája.
5 Wọ́n wí pé, “Tí a bá rí ojúrere rẹ, jẹ́ kí a fi ilẹ̀ yìí fún ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìní. Má ṣe jẹ́ kí a rékọjá odò Jordani.”
És mondták: Ha kegyet találtunk szemeidben, adassék ez az ország szolgáidnak örökségül, ne vigyél át bennünket a Jordánon.
6 Mose sọ fún àwọn ọmọ Gadi àti fún ọmọ Reubeni pé, “Ṣé kí àwọn arákùnrin yín lọ sí ogun, kí ẹ̀yin kí ó sì jókòó sí bí?
És mondta Mózes Gád fiainak és Rúbén fiainak: Vajon testvéreitek menjenek-e a háborúba, ti pedig itt maradjatok?
7 Kí ni ó dé tí o fi mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti lọ sí ibi ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn?
És miért térítenétek el Izrael fiainak szívét, hogy át ne vonuljanak az országba, melyet nekik adott az Örökkévaló.
8 Èyí ni nǹkan tí baba yín ṣe nígbà tí mo rán wọn láti Kadeṣi-Barnea láti lọ wo ilẹ̀ náà.
Így cselekedtek atyáitok, mikor elküldtem őket Kádes-Bárneából, hogy megnézzék az országot.
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n lọ sí àfonífojì Eṣkolu tí wọ́n rí ilẹ̀ náà, wọ́n mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn.
Fölmentek Eskól völgyéig, megnézték az országot és eltérítették Izrael fiai szívét, hogy ne menjenek be az országba, melyet nekik adott az Örökkévaló.
10 Ìbínú Olúwa sì dìde sí wọn ní ọjọ́ náà, ó sì búra, wí pé,
És fölgerjedt az Örökkévaló haragja azon a napon és megesküdött, mondván:
11 ‘Nítorí wọn kò tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin náà tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó gòkè láti Ejibiti ni yóò rí ilẹ̀ tí mo pinnu gẹ́gẹ́ bí ìbúra fún Abrahamu, fún Isaaki àti fún Jakọbu:
Bizony nem fogják látni a férfiak, kik feljöttek Egyiptomból, húsz évestől fölfelé, azt a földet, melyről megesküdtem Ábrahámnak, Izsáknak és Jákobnak, mert nem jártak teljesen utánam;
12 kò sí ẹnìkankan àyàfi Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti àti Joṣua ọmọ Nuni, nítorí wọ́n tẹ̀lé Olúwa tọkàntọkàn.’
kivéve Kálebet, Jefune fiát, a Kenizzit és Józsuát, Nún fiát, mert ők jártak teljesen az Örökkévaló után.
13 Ìbínú Olúwa ru sí àwọn ọmọ Israẹli ó sì mú wọn rìn ní aginjù fún ogójì ọdún, títí tí àwọn ìran tí wọ́n ṣe búburú ní ojú rẹ̀ fi lọ.
És fölgerjedt az Örökkévaló haragja Izrael ellen és vándoroltatta őket a pusztában negyven évig, míg kipusztult az egész nemzedék, mely cselekedte azt, ami rossz az Örökkévaló szemeiben.
14 “Níbí ni ẹ̀yin wà, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀, ẹ̀yin dìde ní ipò baba yín, ẹ sì jẹ́ kí ìbínú gbígbóná Olúwa ru sí Israẹli.
És íme föltámadtok ti atyáitok helyett, vétkes emberek fajzata, hogy növeljétek még az Örökkévaló haragjának fölgerjedését Izrael ellen;
15 Tí ẹ̀yin bá yípadà ní ẹ̀yìn rẹ̀ yóò sì fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí sílẹ̀ ní aginjù, ìwọ yóò sì mú un ṣe ìparun.”
mert eltértek tőle, tovább otthagyta őket a pusztában, és így elveszítitek ezt az egész népet.
16 Nígbà náà wọ́n wá sí òkè ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, “Àwa yóò fẹ́ láti kọ́ ilé ẹran níhìn-ín yìí fún ohun ọ̀sìn wa, àti ìlú fún àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa.
És odaléptek hozzá és mondták: Juhaklokat akarunk építeni nyájainknak és városokat gyermekeinknek.
17 Ṣùgbọ́n àwa ṣetán láti dira ogun ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli títí tí a yóò fi mú wọn dé ọ̀dọ̀ wọn lákokò yìí, àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa yóò gbé inú ìlú tí a mọ odi sí fún ìdáàbòbò wọn lọ́wọ́ olùgbé ilẹ̀ náà.
mi pedig fölfegyverkeztünk sietve Izrael fiai előtt, amíg el nem vittük őket helyükre; gyermekeink azonban maradjanak a megerősített városokban az ország lakosai miatt.
18 A kì yóò padà sí ilẹ̀ wa láìṣe pé gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti gba ogún wọn.
Nem térünk vissza házainkba, míg ki nem vette Izrael fiai közül mindenki az ő birtokát.
19 A kì yóò gba ogún kankan pẹ̀lú wọn ní òdìkejì Jordani, nítorí ogún ti wa, ti wá sí ọ̀dọ̀ wa ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani.”
Mert mi nem kapunk birtokot velük a Jordánon túl, miután kijutott nekünk birtokunk a Jordánon innen, kelet felé.
20 Nígbà náà ni Mose sọ fún wọn pé, “Tí ẹ̀yin yóò bá pa ara yín lára, níwájú Olúwa fún ogún.
És mondta nekik Mózes: Ha megteszitek ezt a dolgot, ha kivonultok fölfegyverkezve az Örökkévaló előtt háborúba,
21 Bí gbogbo yín yóò bá lọ sí Jordani ní ìhámọ́ra níwájú Olúwa, títí yóò fi lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ kúrò níwájú rẹ̀.
és átvonul közületek minden fegyveres a Jordánon az Örökkévaló előtt, amíg elűzi az ő ellenségeit maga elől.
22 Tí a ó sì fi ṣe ilẹ̀ náà níwájú Olúwa; ẹ̀yin lè padà tí yóò sì di òmìnira lọ́wọ́ ìdè níwájú Olúwa àti Israẹli. Ilẹ̀ yìí yóò sì jẹ́ tiyín níwájú Olúwa.
és meg lesz hódítva az ország az Örökkévaló előtt, és azután tértek vissza, akkor fel lesztek mentve az Örökkévaló és Izrael által; ez az ország pedig legyen nektek örökségetek az Örökkévaló színe előtt.
23 “Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kọ̀ láti ṣe èyí, ẹ̀yin yóò máa dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa; kí ẹ̀yin kí ó sì mọ̀ dájú pé ẹ̀ṣẹ̀ yín yóò fi yín hàn.
Ha azonban nem tesztek így, íme vétkeztek az Örökkévaló ellen és ismerjétek meg vétkeiteket, mely utol fog érni benneteket.
24 Ẹ kọ́ ilé fún àwọn obìnrin yín àti ọmọ wẹ́wẹ́ yín, àti ilé fún agbo ẹran yín, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin kí ó ṣe ohun tí ẹ ti pinnu.”
Építsetek magatoknak városokat gyermekeiteknek és aklokat juhaitoknak, de ami kijön szátokból azt tegyétek meg.
25 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni sọ fún Mose pé, “Àwa ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti pàṣẹ.
És szóltak Gád fiai, meg Rúben fiai Mózeshez, mondván: Szolgáid cselekedni fognak, amint uram parancsolja.
26 Àwọn ọmọ wa àti ìyàwó wa, àwọn agbo ẹran àti ohun ọ̀sìn wa yóò dúró ní ìlú Gileadi.
Gyermekeink, feleségeink, nyájaink és minden barmunk maradjon ott Gileád városaiban;
27 Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra ogun, yóò rékọjá lọ láti jà níwájú Olúwa; gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti sọ.”
szolgáid pedig átvonulnak, minden hadba való fegyveres, az Örökkévaló előtt, a háborúba, amint uram szólt.
28 Nígbà náà ni Mose pàṣẹ nípa wọn fún Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni àti sí gbogbo olórí ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
És Mózes parancsot adott rájuk nézve Eleázárnak, a papnak és Józsuának, Nún fiának, meg a törzsek atyai házai fejeinek Izrael fiai között.
29 Mose sì wí fún wọn pé, “Tí àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra fún ogun rékọjá odò Jordani pẹ̀lú níwájú Olúwa, nígbà tí ẹ ṣẹ́gun ilẹ̀ náà níwájú yín, fún wọn ní ilẹ̀ Gileadi gẹ́gẹ́ bí ìní wọn.
És mondta nekik Mózes: Ha átvonulnak Gád fiai és Rúbén fiai veletek a Jordánon, minden fegyveres a háborúba az Örökkévaló előtt, hogy meg lesz hódítva az ország előttetek, akkor adjátok nekik Gileád országát örökségül;
30 Ṣùgbọ́n tí wọn kò bá fẹ́ bá yín rékọjá pẹ̀lú ìhámọ́ra, wọn gbọdọ̀ gba ìní wọn pẹ̀lú yín ní Kenaani.”
ha azonban nem vonulnak át fegyveresen veletek, akkor kapjanak örökséget köztetek Kánaán országában.
31 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe ohun tí Olúwa ti sọ.
Erre feleltek Gád fiai és Rúbén fiai, mondván: Amint az Örökkévaló szólt szolgáidhoz úgy fogunk cselekedni.
32 A máa rékọjá níwájú Olúwa lọ sí Kenaani pẹ̀lú ìhámọ́ra, ṣùgbọ́n ẹrù tí a jogún yóò wà ní ẹ̀bá Jordani.”
Mi átvonulunk fegyveresen az Örökkévaló előtt Kánaán országába, hogy legyen nekünk örök birtokunk a Jordánon innen.
33 Nígbà náà Mose fún àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ọmọ Josẹfu ní ilẹ̀ ọba Sihoni ọba àwọn ọmọ Amori àti ilẹ̀ ọba Ogu ọba Baṣani ní gbogbo ilẹ̀ náà pẹ̀lú ìlú rẹ̀ àti agbègbè tí ó yí i ka.
És Mózes nekik adta, Gád fiainak, Rúbén fiainak és Menassé, József fia féltörzsének, Szichón, az Emóri király birodalmát; és Óg, Boson királya birodalmát; az országot városai szerint, a határokkal együtt, az ország városait köröskörül.
34 Àwọn ará Gadi wọ́n kọ́ Diboni, Atarotu, Aroeri;
És felépítették Gád fiai Divónt, Atorószt és Árórét;
35 pẹ̀lú Atrotu Ṣofani, Jaseri, àti Jogbeha,
Átrósz-Sofont, Jázért és Jogbehot;
36 pẹ̀lú Beti-Nimra, àti Beti-Harani ìlú olódi, àti agbo fún àgùntàn.
Bész-Nimrot és Bész-Horont, megerősített városokat és juhlakokat.
37 Àwọn ọmọ Reubeni sì kọ́ Heṣboni, Eleale, Kiriataimu,
Rúbén fiai pedig felépítették Chesbónt és Elolét, meg Kirjoszimot;
38 pẹ̀lú Nebo pẹ̀lú Baali-Meoni (wọ́n pàrọ̀ orúkọ wọn) àti Sibma. Wọ́n sì sọ ìlú tí wọ́n tún kọ́ ní orúkọ mìíràn.
Nevót, Baál-Meónt, átváltoztatván a neveket és Szivmot; és elnevezték nevekkel a városokat, melyeket építettek.
39 Àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase lọ sí Gileadi, wọ́n sì lé àwọn ọmọ Amori tí ó wà níbẹ̀.
És elmentek Mochir, Menassé fiának fiai Gileádba és elfoglalták azt; és elűzte az Emórit, aki benne volt.
40 Mose sì fi àwọn ọmọ Gileadi fún àwọn ọmọ Makiri àwọn ìran Manase, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
És Mózes adta Gileádot Mochirnak, Menasse fiának és az lakott benne.
41 Jairi, ọmọ Manase gba ibùjókòó wọn, ó sì pè wọ́n ní Haffotu Jairi.
Joir, Menasse fia pedig elment és elfoglalta annak falvait és elnevezte azokat Joir falvainak.
42 Noba gba Kenati àti àwọn ìtẹ̀dó rẹ̀, ó sì pè é ní Noba lẹ́yìn orúkọ ara rẹ̀.
Novách elment és elfoglalta Kenaszot, meg leányvárosait, és elnevezte Nóváchnak az ő nevéről.

< Numbers 32 >