< Numbers 32 >

1 Àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, tí wọ́n ní ẹran ọ̀sìn àti ohun ọ̀sìn rí wí pé ilẹ̀ Jaseri àti Gileadi dára fún ohun ọ̀sìn.
Liubene fi amola Ga: de fi ilia ohe fofoi da bagohamedafa. Ilia da Ya: isa amola Gilia: de soge da ohe fofomu noga: idafa ba: beba: le,
2 Àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni sì wá, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà àti sí olórí gbogbo ìlú, wọ́n sì wí pé,
ilia da Mousese, Elia: isa amola Isala: ili ouligisu dunu ilima asili, amane sia: i,
3 “Atarotu, Diboni, Jaseri, Nimra, Heṣboni, Eleale, Sebamu, Nebo, àti Beoni.
“Hina Gode da fidibiba: le, Isala: ili dunu da amo soge (moilai A: dalode, Daibone, Ya: isa, Nimila, Hesiabone, Ilia: ile, Sibima, Nibou amola Bione) amo huluane fedelai dagoi. Amola ninia ba: loba amo soge da ohe fofomu noga: idafa ba: sa.
4 Ni ilẹ̀ tí Olúwa ti ṣẹ́gun níwájú ìjọ Israẹli tí ó sì dára fún ohun ọ̀sìn, ṣáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ohun ọ̀sìn.”
5 Wọ́n wí pé, “Tí a bá rí ojúrere rẹ, jẹ́ kí a fi ilẹ̀ yìí fún ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìní. Má ṣe jẹ́ kí a rékọjá odò Jordani.”
Amaiba: le, ninia dilima edegesa. Ninia gaguli fima: ne, amo soge ninima ima. Nini da Yodane Hano degele, na: iyadodili amo lale fima: ne mae sia: ma.”
6 Mose sọ fún àwọn ọmọ Gadi àti fún ọmọ Reubeni pé, “Ṣé kí àwọn arákùnrin yín lọ sí ogun, kí ẹ̀yin kí ó sì jókòó sí bí?
Mousese da bu adole i, “Dilia fidafa Isala: ili dunu da gegena ahoasea, dilia da guiguda: esalumu da defeala: ?
7 Kí ni ó dé tí o fi mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti lọ sí ibi ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn?
Isala: ili dunu da Yodane Hano degele, soge amo Hina Gode da ilima ilegele i, amo ganodini fimu. Dilia da abuliba: le ili dogoa da: i dioma: ne sia: sala: ?
8 Èyí ni nǹkan tí baba yín ṣe nígbà tí mo rán wọn láti Kadeṣi-Barnea láti lọ wo ilẹ̀ náà.
Dilia musa: ada ilia agoane hamoi. Na da Ga: idesie Bania amogawi ili Ga: ina: ne soge hogoma: ne, asunasi.
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n lọ sí àfonífojì Eṣkolu tí wọ́n rí ilẹ̀ náà, wọ́n mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn.
Ilia da asili, soge hogolalu, Esiegole Fago amoga doaga: i. Be ilia da buhagili, Isala: ili dunu da soge amo Hina Gode da ilima i, amo ganodini mae masa: ne, ilia dogo ganodini da: i dioma: ne egane sia: i.
10 Ìbínú Olúwa sì dìde sí wọn ní ọjọ́ náà, ó sì búra, wí pé,
Amo esoga, Hina Gode da ougi ba: i. E da amane ilegele sia: i,
11 ‘Nítorí wọn kò tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin náà tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó gòkè láti Ejibiti ni yóò rí ilẹ̀ tí mo pinnu gẹ́gẹ́ bí ìbúra fún Abrahamu, fún Isaaki àti fún Jakọbu:
‘Na da dafawane ilegele sia: sa. Dunu huluane amo da Idibidi sogega misi amola lalelegesu ode 20 fisiagai amola amo ode idi baligili esala, ilia da soge amo Na da A: ibalaha: me, Aisage amola Ya: igobe ilima ima: ne ilegele sia: i, ilia da amo ganodini hamedafa masunu. Bai ilia da Nama hagai galu.’
12 kò sí ẹnìkankan àyàfi Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti àti Joṣua ọmọ Nuni, nítorí wọ́n tẹ̀lé Olúwa tọkàntọkàn.’
Amo da Isala: ili asigilai dunu huluanedafa. Be Ga: ilebe (Yifane, Ginesaide dunu amo egefe) amola Yosiua (Nane egefe) ela fawane da ganodini masunu. Bai ela fawane da Hina Godema hame hagai galu.
13 Ìbínú Olúwa ru sí àwọn ọmọ Israẹli ó sì mú wọn rìn ní aginjù fún ogójì ọdún, títí tí àwọn ìran tí wọ́n ṣe búburú ní ojú rẹ̀ fi lọ.
Hina Gode da Isala: ili dunu ilima ougi galu. Ea hamobeba: le, ilia da wadela: i hafoga: i soge amo ganodini ode 40 agoane udigili lalu. Amalalu, dunu huluanedafa da Ema ougima: ne hamoiba: le, ili da bogogia: i dagoi ba: i.
14 “Níbí ni ẹ̀yin wà, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀, ẹ̀yin dìde ní ipò baba yín, ẹ sì jẹ́ kí ìbínú gbígbóná Olúwa ru sí Israẹli.
Amola wali dilia da ilia sogebi lai dagoi. Dilia da wadela: i fi gaheabolo amola dilia hame nabasu hou hamomuba: le, Hina Gode da bu Isala: ili fi ilima mihanane ougimu.
15 Tí ẹ̀yin bá yípadà ní ẹ̀yìn rẹ̀ yóò sì fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí sílẹ̀ ní aginjù, ìwọ yóò sì mú un ṣe ìparun.”
Dilia Liubene amola Ga: de fi dunu da wali Ema fa: no bobogemu higasea, E da bu Isala: ili dunu huluane wadela: i hafoga: i soge ganodini udigili laloma: ne yolesimu. Amola ilia da gugunufinisi dagoi ba: mu. Bai dilia hamobeba: le.”
16 Nígbà náà wọ́n wá sí òkè ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, “Àwa yóò fẹ́ láti kọ́ ilé ẹran níhìn-ín yìí fún ohun ọ̀sìn wa, àti ìlú fún àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa.
Liubene amola Ga: de dunu da Mousesema misini, amane sia: i, “Ninia bisili ninia sibi gaga: ma: ne, gelega gagoma: ne amola ninia sosogo fi esaloma: ne osobo dogomusa: , logo doasima.
17 Ṣùgbọ́n àwa ṣetán láti dira ogun ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli títí tí a yóò fi mú wọn dé ọ̀dọ̀ wọn lákokò yìí, àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa yóò gbé inú ìlú tí a mọ odi sí fún ìdáàbòbò wọn lọ́wọ́ olùgbé ilẹ̀ náà.
Amasea, ninia da ninia Isala: ili fi eno ilima gilisili gegemusa: masunu. Ninia da ilia doagala: su amo bisili masunu amola mae fisili, ilia da ilia sogedafa amo lale fi dagosea fawane buhagimu. Be ninia da amo gegemusa: ahoasea, ninia uda amola mano da goeguda: gagili sali moilai amo ganodini esalumu. Ilia amogawi fi dunu amoga hahawane gaga: i dagoi ba: mu.
18 A kì yóò padà sí ilẹ̀ wa láìṣe pé gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti gba ogún wọn.
Ninia da ninia diasudafa amoguda: hedolo hame buhagimu. Be Isala: ili dunu oda ilia huluane da ilima ilegei soge amo lai dagobeba: le fawane buhagimu.
19 A kì yóò gba ogún kankan pẹ̀lú wọn ní òdìkejì Jordani, nítorí ogún ti wa, ti wá sí ọ̀dọ̀ wa ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani.”
Ilia da Yodane Hano na: iyadodili soge lasea, ninia da hame lamu. Bai ninia da Yodane Hano eso midadi heda: su gusudili lai dagoi.”
20 Nígbà náà ni Mose sọ fún wọn pé, “Tí ẹ̀yin yóò bá pa ara yín lára, níwájú Olúwa fún ogún.
Mousese da bu adole i, “Dilia adomusa: fawane hanai galea, guiguda: Hina Gode ba: ma: ne, dilia gegena masusa: momagema!
21 Bí gbogbo yín yóò bá lọ sí Jordani ní ìhámọ́ra níwájú Olúwa, títí yóò fi lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ kúrò níwájú rẹ̀.
Dilia gegesu dunu huluane da Yodane Hano degemu. Amasea, Hina Gode da ili ouligimu. Ilia da ilia ha lai amo doagala: le, amola Hina Gode da ili hasalili,
22 Tí a ó sì fi ṣe ilẹ̀ náà níwájú Olúwa; ẹ̀yin lè padà tí yóò sì di òmìnira lọ́wọ́ ìdè níwájú Olúwa àti Israẹli. Ilẹ̀ yìí yóò sì jẹ́ tiyín níwájú Olúwa.
ilia soge huluane lale gagamu. Amalalu, dilia buhagimu da defea. Bai dilia da dia Hina Godema amola dilia Isala: ili fi hamoma: ne ilegei amo hamoi dagoi ba: mu. Amasea, Hina Gode da amo soge Yodane Hano eso midadi heda: su gusudili gala, da dilia sogedafa sia: mu.
23 “Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kọ̀ láti ṣe èyí, ẹ̀yin yóò máa dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa; kí ẹ̀yin kí ó sì mọ̀ dájú pé ẹ̀ṣẹ̀ yín yóò fi yín hàn.
Be na da dilima sisasu olelesa. Dilia da dilia hamomusa: sia: i ilegei amo giadofale hamosea, dilia Hina Godema wadela: le hamoi dagoi ba: mu. Sia: noga: le dawa: ma! Dilia wadela: i hou hamosea, Hina Godema wamolegemu da hamedei ba: mu.
24 Ẹ kọ́ ilé fún àwọn obìnrin yín àti ọmọ wẹ́wẹ́ yín, àti ilé fún agbo ẹran yín, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin kí ó ṣe ohun tí ẹ ti pinnu.”
Amaiba: le, dilia moilai dogoma amola sibi gagoi hamoma. Be dilia hamomusa: ilegele sia: i, amo noga: le hamoma.”
25 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni sọ fún Mose pé, “Àwa ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti pàṣẹ.
Ga: de amola Liubene fi dunu da Mousesema amane sia: i, “Hina! Ninia da dia hamoma: ne sia: i defele hamomu.
26 Àwọn ọmọ wa àti ìyàwó wa, àwọn agbo ẹran àti ohun ọ̀sìn wa yóò dúró ní ìlú Gileadi.
Ninia uda, mano, bulamagau amola sibi da Gilia: de soge moilai goeguda: esaloma: mu.
27 Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra ogun, yóò rékọjá lọ láti jà níwájú Olúwa; gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti sọ.”
Be ninia huluane da Hina Godema fa: no bobogele gegemusa: momageiwane esala. Ninia da dia sia: i defele, Yodane Hano degele, gegena masunu.”
28 Nígbà náà ni Mose pàṣẹ nípa wọn fún Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni àti sí gbogbo olórí ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
Amaiba: le, Mousese da Elia: isa, Yosiua amola eno Isala: ili ouligisu dunu ilima amane hamoma: ne sia: i,
29 Mose sì wí fún wọn pé, “Tí àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra fún ogun rékọjá odò Jordani pẹ̀lú níwájú Olúwa, nígbà tí ẹ ṣẹ́gun ilẹ̀ náà níwájú yín, fún wọn ní ilẹ̀ Gileadi gẹ́gẹ́ bí ìní wọn.
“Ga: de amola Liubene fi dunu da Hina Gode Ea hamoma: ne sia: sea, amola gegemusa: Yodane Hano degesea, amola ilia da dili fidisia, amola Ga: ina: ne soge fi hasalasea, Gilia: de soge amo ilia gagulaligima: ne ilima ima.
30 Ṣùgbọ́n tí wọn kò bá fẹ́ bá yín rékọjá pẹ̀lú ìhámọ́ra, wọn gbọdọ̀ gba ìní wọn pẹ̀lú yín ní Kenaani.”
Be ilia da dili gilisili gegemusa: Yodane Hano hame degesea, defea, ilia da dili defele Ga: ina: ne soge ganodini ilima ilegei soge mogi amo lamu.”
31 Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe ohun tí Olúwa ti sọ.
Ga: de amola Liubene fi dunu da bu adole i, “Hina! Ninia da Hina Gode Ea hamoma: ne sia: i amo defele hamomu.
32 A máa rékọjá níwájú Olúwa lọ sí Kenaani pẹ̀lú ìhámọ́ra, ṣùgbọ́n ẹrù tí a jogún yóò wà ní ẹ̀bá Jordani.”
Ninia da guiguda: Yodane Hano eso midadi heda: su gusudili soge amo gagulaligima: ne, Hina Gode Ea hamoma: ne sia: i amo fa: no bobogele, Yodane Hano degele, Ga: ina: ne soge fi dunuma gegemusa: masunu.”
33 Nígbà náà Mose fún àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ọmọ Josẹfu ní ilẹ̀ ọba Sihoni ọba àwọn ọmọ Amori àti ilẹ̀ ọba Ogu ọba Baṣani ní gbogbo ilẹ̀ náà pẹ̀lú ìlú rẹ̀ àti agbègbè tí ó yí i ka.
Amaiba: le, Mousese da Ga: de amola Liubene fi amola Ma: na: se fi dogoa mogi la: idili, ilima A: moulaide hina bagade Saihone amola Ba: isia: ne hina bagade Oge amo ela soge huluane ilima ilegele i. E da amo soge ea moilai huluane amola soge amoga sisiga: le diala, amo huluane ilima i.
34 Àwọn ará Gadi wọ́n kọ́ Diboni, Atarotu, Aroeri;
Ga: de fi dunu da musa: gagili sali moilai mugului (amo Daibone, A:dalode, Aloua, A:dalodi Sioufa: ne, Ya: isa, Yogebiha, Bede Nimila, amola Bede Ha: ila: ne) amo huluane bu hiougi.
35 pẹ̀lú Atrotu Ṣofani, Jaseri, àti Jogbeha,
36 pẹ̀lú Beti-Nimra, àti Beti-Harani ìlú olódi, àti agbo fún àgùntàn.
37 Àwọn ọmọ Reubeni sì kọ́ Heṣboni, Eleale, Kiriataimu,
Liubene fi dunu da moilai amo Hesiabone, Ilia: ile, Giliada: ime, Nibou, Ba: ile Mione amola Sibima bu gagui. Ilia da moilai huluane amo ilia bu gagui amoma dio gaheabolo asuli.
38 pẹ̀lú Nebo pẹ̀lú Baali-Meoni (wọ́n pàrọ̀ orúkọ wọn) àti Sibma. Wọ́n sì sọ ìlú tí wọ́n tún kọ́ ní orúkọ mìíràn.
39 Àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase lọ sí Gileadi, wọ́n sì lé àwọn ọmọ Amori tí ó wà níbẹ̀.
Ma: ige (Ma: na: se egefe) amo ea fi da Gilia: de soge doagala: le, golili sa: ili, gesowale lai. Ilia da A: moulaide dunu amogawi esalu amo gadili sefasi.
40 Mose sì fi àwọn ọmọ Gileadi fún àwọn ọmọ Makiri àwọn ìran Manase, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
Amaiba: le, Mousese da Gilia: de soge amo Ma: ige fi ilima i. Amola ilia da amogawi esalu.
41 Jairi, ọmọ Manase gba ibùjókòó wọn, ó sì pè wọ́n ní Haffotu Jairi.
Ya: ie (Ma: na: se fi dunu) da moilai mogili doagala: le lai. E da amo moilai amoma ‘Ya: ie ea Moilai’ dio asuli.
42 Noba gba Kenati àti àwọn ìtẹ̀dó rẹ̀, ó sì pè é ní Noba lẹ́yìn orúkọ ara rẹ̀.
Nouba da Gina: de moilai bai bagade amola moilai huluane amoga sisiga: le dialu, amo doagala: le gesowale lai. E da Gina: de moilai amoma hina: dio Nouba amo asuli.

< Numbers 32 >