< Numbers 31 >
Et l'Éternel parla à Moïse en ces termes:
2 “Gbẹ̀san lára àwọn Midiani fún àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn ìgbà náà a ó kó ọ jọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ.”
Venge les enfants d'Israël des Madianites; après quoi tu seras recueilli auprès de ton peuple.
3 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wọ ogun fún àwọn kan nínú yín láti lọ da ojú ìjà kọ àwọn ọmọ Midiani láti gba ẹ̀san Olúwa lára wọn.
Alors Moïse parla au peuple et dit: Équipez militairement des hommes d'entre vous qui marchent contre Madian pour exercer sur Madian les vengeances de l'Éternel;
4 Rán ẹgbẹ̀rún ọmọ-ogun láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan ní Israẹli.”
vous mettrez en campagne mille hommes par Tribu sur toutes les Tribus d'Israël.
5 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yan nínú àwọn ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn Israẹli, ẹgbẹ̀rún ènìyàn láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, ẹgbàá mẹ́fà ènìyàn tí ó wọ ìhámọ́ra ogun.
Alors on tira des groupes d'Israël mille hommes par Tribu, douze mille hommes équipés militairement.
6 Mose rán wọn lọ sí ogun, ẹgbẹ̀rún láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú Finehasi ọmọ Eleasari, ti ó jẹ́ àlùfáà, ti òun ti ohun èlò ibi mímọ́ àti ìpè wọ̀n-ọn-nì ní ọwọ́ rẹ̀.
Et Moïse les mit en campagne, mille par Tribu, eux et Phinées, fils du Prêtre Eléazar, qui portait avec lui les instruments sacrés et les trompettes pour sonner la charge.
7 Wọ́n dojú ìjà kọ Midiani gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, kí wọn sì pa gbogbo wọn.
Et ils firent la campagne de Madian selon l'ordre donné à Moïse par l'Éternel, et ils tuèrent tous les mâles.
8 Wọ́n sì pa àwọn ọba Midiani pẹ̀lú: àwọn ìyókù tí wọ́n pa lára wọn ni Efi, Rekemu, Suri àti Huri, àti Reba: ọba Midiani márùn-ún, wọ́n sì fi idà pa Balaamu ọmọ Beori.
Et ils ajoutèrent à leurs morts les Rois de Madian Evi et Rékem et Tsur et Hur et Reba, cinq rois de Madian; et ils tuèrent avec l'épée Balaam, fils de Behor.
9 Àwọn ọmọ Israẹli sì mú gbogbo obìnrin Midiani ní ìgbèkùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn.
Et les fils d'Israël emmenèrent captives les femmes de Madian et leurs enfants, et prirent comme butin tout leur bétail, et tous leurs troupeaux et tous leurs biens,
10 Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn.
et ils incendièrent toutes leurs villes dans les lieux qu'ils habitaient et tous leurs bourgs.
11 Wọ́n sì kó gbogbo ìní wọn, àti ènìyàn àti ẹran.
Et ils emportèrent tout le butin et toutes les dépouilles en hommes et en bestiaux,
12 Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí wọ́n bàjẹ́ àti ènìyàn àti ẹran wá sọ́dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà, àti sọ́dọ̀ ìjọ àwọn ọmọ Israẹli ní ibùdó àgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani létí Jeriko.
et ils les amenèrent à Moïse et au Prêtre Eléazar et à l'Assemblée des enfants d'Israël, les captifs et les dépouilles et le butin, au camp dans les plaines de Moab sur le Jourdain près de Jéricho.
13 Mose, Eleasari àlùfáà àti gbogbo olórí ìgbèríko lọ láti lọ bá wọn ní ìta ibùdó.
Alors sortirent à leur rencontre Moïse et le Prêtre Eléazar et tous les Princes de l'Assemblée en dehors du camp.
14 Inú bí Mose sí àwọn olórí ọmọ-ogun, pẹ̀lú àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún tí wọ́n ti ogun dé.
Et Moïse s'irrita contre les commandants de l'armée, chefs de mille, et chefs de cent, qui revenaient de l'expédition.
15 Mose sì béèrè wí pé, “Ẹ̀yin ha dá gbogbo àwọn obìnrin sí bí?
Et Moïse leur dit: Vous avez laissé la vie à toutes les femmes!
16 Àwọn ni wọ́n tẹ̀lé ìmọ̀ràn Balaamu, àwọn ní ó ṣe okùnfà yíyí àwọn ọ̀mọ̀ Israẹli padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa nínú èyí tí ó ṣẹlẹ̀ ní Peori, níbi tí àjàkálẹ̀-ààrùn ti kọlu ìjọ Olúwa.
Voici, ce sont elles qui, sur le conseil de Balaam, ont été pour les enfants d'Israël une cause de rébellion contre l'Éternel à l'occasion de Pehor; ce qui attira la plaie sur l'Assemblée de l'Éternel.
17 Nísinsin yìí, pa gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti àwọn obìnrin tí ó ti súnmọ́ ọkùnrin,
Maintenant donc tuez tous les mâles parmi les enfants et tuez toute femme qui aura connu un homme en cohabitation;
18 ṣùgbọ́n kí o dá obìnrin tí kò bá tí ì súnmọ́ ọkùnrin sí fún ara yín.
mais laissez la vie à toutes les filles enfants qui ne connaissent pas la cohabitation d'un homme.
19 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti pa ènìyàn tàbí fọwọ́ kan ẹni tí a pa gbọdọ̀ dúró ní ìta ibùdó àgọ́ fún ọjọ́ méje. Ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje ẹ gbọdọ̀ ya ara yín àti ẹni tí ẹ kó lẹ́rú sí mímọ́.
Quant à vous, campez hors du camp pendant sept jours, vous tous qui avez tué des hommes, ou touché des morts tombés dans le combat; vous ferez votre expiation le troisième jour et le septième, vous et vos prisonniers.
20 Kí ẹ̀yin kí ó ya aṣọ yín sí mímọ́ àti gbogbo ohun tí a fi awọ ṣe àti gbogbo iṣẹ́ irun ewúrẹ́ àti ohun tí a fi igi ṣe.”
Et de tous les vêtements, et de tous les ustensiles de cuir, et de tous les tissus de poil de chèvre et de tout meuble de bois vous ferez l'expiation.
21 Eleasari àlùfáà sì wí fún àwọn olórí ogun náà pé, “Èyí ní ìlànà òfin tí Olúwa fi lélẹ̀ ní àṣẹ fún Mose.
Alors le Prêtre Eléazar dit aux hommes de guerre qui avaient fait la campagne: Voici le texte de la loi que l'Éternel a prescrite à Moïse:
22 Kìkì i wúrà, fàdákà, idẹ, irin, idẹ àti òjé.
Quant à l'or, l'argent, l'airain, le fer, l'étain et le plomb,
23 Ohunkóhun tí ó lè la iná ni kí ẹ̀yin ó mú la iná, nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n ẹ yóò fi omi ìyàsímímọ́ sọ ọ́ di mímọ́. Àti gbogbo ohun tí kò lè la iná kọjá ni kí a mú la inú omi.
tout ce qui va au feu, vous le ferez passer par le feu, pour le rendre pur, et on en fera d'ailleurs l'expiation avec l'eau de purification; seulement tout ce qui ne va pas au feu, vous le passerez dans l'eau.
24 Ní ọjọ́ keje, ẹ fọ aṣọ yín, ẹ̀yin yóò sì mọ́, nígbà náà ní ẹ̀yin yóò lè wọ inú ibùdó àjọ.”
Et lavez vos vêtements le septième jour pour être en état de pureté; puis vous pourrez rentrer au camp.
Et l'Éternel parla à Moïse en ces termes:
26 “Ìwọ àti Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí ilé baba ìjọ ni kí o ka iye àwọn ènìyàn àti ẹranko tí a kó ní ìgbèkùn.
Fais le relevé du butin capturé, en hommes et en bestiaux, toi et le Prêtre Eléazar et les chefs de maisons de l'Assemblée.
27 Pín ohun ìní àti ìkógun náà láàrín àwọn ọmọ-ogun náà tí ó kópa nínú ogun náà àti láàrín gbogbo ìjọ.
Et partage les dépouilles entre les gens de guerre qui ont fait la campagne, et toute l'Assemblée.
28 Kí o sì gba ìdá ti Olúwa lọ́wọ́ àwọn ológun tí wọn jáde lọ sí ogun náà, ọ̀kan nínú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ènìyàn àti nínú màlúù àti nínú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti nínú agbo ẹran.
Et prélève un tribut pour l'Éternel sur les gens de guerre qui ont fait la campagne, un individu sur cinq cents, hommes, bœufs, ânes et menu bétail.
29 Gba ìdá yìí lára ààbọ̀ ìpín tiwọn, kí o sì fún Eleasari àlùfáà, fún ẹbọ ìgbésókè Olúwa.
Vous le prendrez sur leur moitié, et tu le donneras au Prêtre Eléazar pour le présenter à l'Éternel par élévation.
30 Lára ààbọ̀ ti Israẹli, yan ọ̀kan kúrò nínú àádọ́ta, yálà ènìyàn, ẹran ọ̀sìn, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, ewúrẹ́ tàbí ẹ̀yà ẹranko mìíràn. Kó wọn fún àwọn Lefi, tí ó dúró fún olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.”
Et sur la moitié qui ira aux enfants d'Israël, tu prendras un sur cinquante, soit hommes, soit bœufs, soit ânes, soit menu bétail et animaux de toute espèce, et tu en feras don aux Lévites qui ont la garde de la Résidence de l'Éternel.
31 Nígbà náà Mose àti Eleasari àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Et Moïse et Eléazar, le Prêtre, exécutèrent les ordres donnés par l'Éternel à Moïse.
32 Èrè tí ó kù lára ìkógun tí àwọn ọmọ-ogun kó jẹ́, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn.
Et le butin qui resta des captures faites par les gens de guerre, fut: menu bétail, six cent soixante-quinze mille;
33 Ẹgbàá méjìléláàádọ́rin màlúù
bœufs, soixante-douze mille;
34 ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹgbẹ̀rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
ânes, soixante-un mille;
35 pẹ̀lú obìnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógún, ni kò ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin rí.
personnes, parmi les femmes qui n'avaient pas connu la cohabitation d'un homme, total des personnes: trente-deux mille.
36 Ìpín ààbọ̀ àwọn tí ó jáde lọ sí ogun sì jẹ́: ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn.
Et la moitié échue à ceux qui avaient fait la campagne, fut en menu bétail un nombre de trois cent trente-sept mille cinq cents.
37 Tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn;
Et le tribut levé pour l'Éternel fut: en menu bétail, six cent soixante-quinze;
38 ẹgbọrọ màlúù jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógún, tí ìdá Olúwa sì jẹ́ méjìléláàádọ́rin;
et en bœufs (dont il y avait trente-six mille) le tribut pour l'Éternel fut de soixante-douze;
39 kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta, tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ mọ́kànlélọ́gọ́ta.
et en ânes (dont il y avait trente mille cinq cents) le tribut pour l'Éternel fut de soixante-un;
40 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ìdá ti Olúwa sì jẹ́ méjìlélọ́gbọ̀n.
et en personnes (dont il y avait seize mille) le tribut pour l'Éternel fut de trente-deux personnes.
41 Mose fi ìdá náà fún Eleasari, àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìdá ti Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
Et Moïse remit au Prêtre Eléazar le tribut à offrir par élévation à l'Éternel, ainsi que l'Éternel l'avait ordonné à Moïse.
42 Ààbọ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli, tí Mose yà sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ọkùnrin tí ó ja ogun.
Et sur la moitié échue aux enfants d'Israël, que Moïse avait séparée de celle des gens de guerre,
43 Ààbọ̀ tí ìjọ jẹ́ ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn,
(or cette moitié échue à l'Assemblée était de trois cent trente-sept mille cinq cents pièces de menu bétail,
44 pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún màlúù
trente-six mille bœufs,
45 tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
trente mille cinq cents ânes
46 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ.
et seize mille personnes),
47 Lára ààbọ̀ ti àwọn ọmọ Israẹli, Mose yan ọ̀kan lára àádọ́ta ènìyàn àti ẹranko gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un. Ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ Lefi, tí ń ṣe olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.
sur la moitié donc échue aux enfants d'Israël, Moïse préleva un sur cinquante, soit hommes, soit pièces de bétail, qu'il donna aux Lévites chargés de la garde de la Résidence de l'Éternel, ainsi que l'Éternel l'avait prescrit à Moïse.
48 Pẹ̀lú àwọn olórí tí ó wà lórí ẹgbẹẹgbẹ̀rin ogun náà, àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wá sọ́dọ̀ Mose.
Alors s'approchèrent de Moïse les commandants des divisions de l'armée, les chefs de mille et les chefs de cent, et ils dirent à Moïse:
49 Wọ́n sì sọ fún un pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti ka àwọn ọmọ-ogun náà tí ó wà lábẹ́ ìtọ́jú wa, kò sì sí ọ̀kọ̀ọ̀kan tó dín.
Tes serviteurs ont fait le relevé des gens de guerre qui étaient sous notre conduite, et pas un ne fait défaut.
50 Nítorí náà làwa ṣe mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, gbogbo ọrẹ wíwà tí a ní, wúrà, ẹ̀wọ̀n, àti júfù, àti òrùka-àmi, àti òrùka etí, àti ìlẹ̀kẹ̀ láti fi ṣe ètùtù fún ọkàn an wa níwájú Olúwa.”
Et nous apportons chacun comme oblation à l'Éternel ce que nous avons trouvé de joyaux d'or, chaînettes, bracelets, bagues, boucles d'oreilles, globules d'or, pour faire notre propitiation devant l'Éternel.
51 Mose àti Eleasari àlùfáà, gba wúrà náà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú gbogbo ohun iṣẹ́ ọ̀ṣọ́.
Et Moïse et Eléazar, le Prêtre, reçurent d'eux cet or, ouvragé en toutes sortes de joyaux.
52 Gbogbo wúrà tí àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún mú wá fún Mose àti Eleasari, èyí tí ó jẹ́ ẹbọ ìgbésókè fún Olúwa jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó lé àádọ́ta ṣékélì.
Et tout l'or de l'élévation qu'ils offrirent à l'Éternel pesait seize mille sept cent cinquante sicles et venait des chefs de mille et des chefs de cent.
53 Nítorí ológun kọ̀ọ̀kan ti kó ẹrù fún ara rẹ̀.
Les gens de guerre avaient chacun remporté son butin.
54 Mose àti Eleasari àlùfáà gba wúrà náà lọ́wọ́ àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti lọ́wọ́ balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wọ́n sì ko wá sínú àgọ́ ìpàdé fún ìrántí àwọn Israẹli níwájú Olúwa.
Moïse et le Prêtre Eléazar reçurent ainsi cet or des chefs de mille et des chefs de cent, et le portèrent dans la Tente du Rendez-vous comme monument des enfants d'Israël devant l'Éternel.