< Numbers 31 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahvé parla à Moïse, et dit:
2 “Gbẹ̀san lára àwọn Midiani fún àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn ìgbà náà a ó kó ọ jọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ.”
« Venge les enfants d'Israël sur les Madianites. Ensuite, vous serez rassemblés auprès de votre peuple. »
3 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wọ ogun fún àwọn kan nínú yín láti lọ da ojú ìjà kọ àwọn ọmọ Midiani láti gba ẹ̀san Olúwa lára wọn.
Moïse parla au peuple, et dit: « Armez des hommes parmi vous pour la guerre, afin qu'ils aillent contre Madian, pour exécuter la vengeance de Yahvé sur Madian.
4 Rán ẹgbẹ̀rún ọmọ-ogun láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan ní Israẹli.”
Vous enverrez mille hommes de chaque tribu, de toutes les tribus d'Israël, à la guerre. »
5 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yan nínú àwọn ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn Israẹli, ẹgbẹ̀rún ènìyàn láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, ẹgbàá mẹ́fà ènìyàn tí ó wọ ìhámọ́ra ogun.
On livra donc, parmi les milliers d'Israël, mille hommes de chaque tribu, soit douze mille hommes armés pour la guerre.
6 Mose rán wọn lọ sí ogun, ẹgbẹ̀rún láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú Finehasi ọmọ Eleasari, ti ó jẹ́ àlùfáà, ti òun ti ohun èlò ibi mímọ́ àti ìpè wọ̀n-ọn-nì ní ọwọ́ rẹ̀.
Moïse les envoya, mille de chaque tribu, à la guerre, avec Phinées, fils du prêtre Éléazar, à la guerre, les ustensiles du sanctuaire et les trompettes d'alarme dans sa main.
7 Wọ́n dojú ìjà kọ Midiani gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, kí wọn sì pa gbogbo wọn.
Ils combattirent contre Madian, comme Yahvé l'avait ordonné à Moïse. Ils tuèrent tous les mâles.
8 Wọ́n sì pa àwọn ọba Midiani pẹ̀lú: àwọn ìyókù tí wọ́n pa lára wọn ni Efi, Rekemu, Suri àti Huri, àti Reba: ọba Midiani márùn-ún, wọ́n sì fi idà pa Balaamu ọmọ Beori.
Ils tuèrent les rois de Madian avec le reste de leurs morts: Evi, Rékem, Tsur, Hur et Réba, les cinq rois de Madian. Ils tuèrent aussi par l'épée Balaam, fils de Beor.
9 Àwọn ọmọ Israẹli sì mú gbogbo obìnrin Midiani ní ìgbèkùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn.
Les enfants d'Israël emmenèrent captives les femmes de Madian et leurs petits enfants, et ils pillèrent tout leur bétail, tous leurs troupeaux et tous leurs biens.
10 Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn.
Ils brûlèrent au feu toutes leurs villes, dans les lieux qu'ils habitaient, et tous leurs campements.
11 Wọ́n sì kó gbogbo ìní wọn, àti ènìyàn àti ẹran.
Ils prirent tous les captifs et tout le butin, tant des hommes que des animaux.
12 Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí wọ́n bàjẹ́ àti ènìyàn àti ẹran wá sọ́dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà, àti sọ́dọ̀ ìjọ àwọn ọmọ Israẹli ní ibùdó àgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani létí Jeriko.
Ils amenèrent les captifs, avec le butin et le pillage, à Moïse, au sacrificateur Éléazar et à l'assemblée des enfants d'Israël, au camp des plaines de Moab, qui sont près du Jourdain, à Jéricho.
13 Mose, Eleasari àlùfáà àti gbogbo olórí ìgbèríko lọ láti lọ bá wọn ní ìta ibùdó.
Moïse et le sacrificateur Éléazar, avec tous les chefs de l'assemblée, sortirent à leur rencontre hors du camp.
14 Inú bí Mose sí àwọn olórí ọmọ-ogun, pẹ̀lú àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún tí wọ́n ti ogun dé.
Moïse se mit en colère contre les officiers de l'armée, les chefs de milliers et les chefs de centaines, qui venaient du service de la guerre.
15 Mose sì béèrè wí pé, “Ẹ̀yin ha dá gbogbo àwọn obìnrin sí bí?
Moïse leur dit: « Avez-vous sauvé toutes les femmes en vie?
16 Àwọn ni wọ́n tẹ̀lé ìmọ̀ràn Balaamu, àwọn ní ó ṣe okùnfà yíyí àwọn ọ̀mọ̀ Israẹli padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa nínú èyí tí ó ṣẹlẹ̀ ní Peori, níbi tí àjàkálẹ̀-ààrùn ti kọlu ìjọ Olúwa.
Voici qu'elles ont poussé les enfants d'Israël, par le conseil de Balaam, à commettre une infidélité à l'égard de l'Éternel dans l'affaire de Péor, et c'est ainsi que la plaie a frappé la congrégation de l'Éternel.
17 Nísinsin yìí, pa gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti àwọn obìnrin tí ó ti súnmọ́ ọkùnrin,
Maintenant, tuez tout mâle parmi les petits enfants, et tuez toute femme qui a connu un homme en couchant avec lui.
18 ṣùgbọ́n kí o dá obìnrin tí kò bá tí ì súnmọ́ ọkùnrin sí fún ara yín.
Mais toutes les filles qui n'ont pas connu d'homme en couchant avec lui, gardez-les vivantes pour vous.
19 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti pa ènìyàn tàbí fọwọ́ kan ẹni tí a pa gbọdọ̀ dúró ní ìta ibùdó àgọ́ fún ọjọ́ méje. Ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje ẹ gbọdọ̀ ya ara yín àti ẹni tí ẹ kó lẹ́rú sí mímọ́.
« Campez hors du camp pendant sept jours. Celui qui a tué quelqu'un et celui qui a touché un mort, purifiez-vous le troisième jour et le septième jour, vous et vos captifs.
20 Kí ẹ̀yin kí ó ya aṣọ yín sí mímọ́ àti gbogbo ohun tí a fi awọ ṣe àti gbogbo iṣẹ́ irun ewúrẹ́ àti ohun tí a fi igi ṣe.”
Vous purifierez tout vêtement, tout ce qui est fait en peau, tout ce qui est fait en poil de chèvre et tout ce qui est fait en bois. »
21 Eleasari àlùfáà sì wí fún àwọn olórí ogun náà pé, “Èyí ní ìlànà òfin tí Olúwa fi lélẹ̀ ní àṣẹ fún Mose.
Le sacrificateur Éléazar dit aux hommes de guerre qui allaient au combat: « Voici le règlement de la loi que l'Éternel a prescrite à Moïse.
22 Kìkì i wúrà, fàdákà, idẹ, irin, idẹ àti òjé.
Cependant, l'or, l'argent, l'airain, le fer, l'étain et le plomb,
23 Ohunkóhun tí ó lè la iná ni kí ẹ̀yin ó mú la iná, nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n ẹ yóò fi omi ìyàsímímọ́ sọ ọ́ di mímọ́. Àti gbogbo ohun tí kò lè la iná kọjá ni kí a mú la inú omi.
tout ce qui peut résister au feu, vous le ferez passer par le feu, et il sera pur; néanmoins, il sera purifié avec l'eau pour être impur. Tout ce qui ne résistera pas au feu, vous le ferez passer dans l'eau.
24 Ní ọjọ́ keje, ẹ fọ aṣọ yín, ẹ̀yin yóò sì mọ́, nígbà náà ní ẹ̀yin yóò lè wọ inú ibùdó àjọ.”
Tu laveras tes vêtements le septième jour, et tu seras pur. Ensuite, tu entreras dans le camp. »
25 Olúwa sọ fún Mose pé,
L'Éternel parla à Moïse, et dit:
26 “Ìwọ àti Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí ilé baba ìjọ ni kí o ka iye àwọn ènìyàn àti ẹranko tí a kó ní ìgbèkùn.
Comptez le butin qui a été fait, tant pour les hommes que pour les animaux, vous, le prêtre Éléazar et les chefs de famille de l'assemblée,
27 Pín ohun ìní àti ìkógun náà láàrín àwọn ọmọ-ogun náà tí ó kópa nínú ogun náà àti láàrín gbogbo ìjọ.
et partagez le butin en deux parties: entre les hommes de guerre qui sont allés au combat et toute l'assemblée.
28 Kí o sì gba ìdá ti Olúwa lọ́wọ́ àwọn ológun tí wọn jáde lọ sí ogun náà, ọ̀kan nínú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ènìyàn àti nínú màlúù àti nínú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti nínú agbo ẹran.
Prélève un tribut à l'Éternel sur les hommes de guerre qui sont allés au combat: une âme sur cinq cents, sur les personnes, sur le bétail, sur les ânes et sur les troupeaux.
29 Gba ìdá yìí lára ààbọ̀ ìpín tiwọn, kí o sì fún Eleasari àlùfáà, fún ẹbọ ìgbésókè Olúwa.
Prenez-en la moitié et donnez-la au prêtre Éléazar, pour l'offrande de l'Éternel.
30 Lára ààbọ̀ ti Israẹli, yan ọ̀kan kúrò nínú àádọ́ta, yálà ènìyàn, ẹran ọ̀sìn, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, ewúrẹ́ tàbí ẹ̀yà ẹranko mìíràn. Kó wọn fún àwọn Lefi, tí ó dúró fún olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.”
Sur la moitié des enfants d'Israël, tu prendras une personne tirée sur cinquante, du bétail, des ânes et des troupeaux, de tout le bétail, et tu la donneras aux Lévites, qui font le service de la tente de Yahvé. »
31 Nígbà náà Mose àti Eleasari àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Moïse et le prêtre Éléazar firent ce que l'Éternel avait ordonné à Moïse.
32 Èrè tí ó kù lára ìkógun tí àwọn ọmọ-ogun kó jẹ́, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn.
Or le butin, en sus du butin que les hommes de guerre avaient pris, fut de six cent soixante-quinze mille brebis,
33 Ẹgbàá méjìléláàádọ́rin màlúù
soixante-douze mille têtes de bétail,
34 ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹgbẹ̀rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
soixante et un mille ânes,
35 pẹ̀lú obìnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógún, ni kò ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin rí.
et trente-deux mille personnes en tout, des femmes qui n'avaient pas connu d'homme en couchant avec lui.
36 Ìpín ààbọ̀ àwọn tí ó jáde lọ sí ogun sì jẹ́: ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn.
La moitié, qui était la part de ceux qui partaient pour la guerre, était en nombre de trois cent trente-sept mille cinq cents moutons;
37 Tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn;
et le tribut de l'Éternel sur les moutons était de six cent soixante-quinze.
38 ẹgbọrọ màlúù jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógún, tí ìdá Olúwa sì jẹ́ méjìléláàádọ́rin;
Les bovins étaient au nombre de trente-six mille, et le tribut de l'Éternel était de soixante-douze.
39 kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta, tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ mọ́kànlélọ́gọ́ta.
Les ânes étaient au nombre de trente mille cinq cents; le tribut de l'Éternel était de soixante et un.
40 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ìdá ti Olúwa sì jẹ́ méjìlélọ́gbọ̀n.
Les personnes étaient au nombre de seize mille; le tribut de l'Éternel était de trente-deux personnes.
41 Mose fi ìdá náà fún Eleasari, àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìdá ti Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
Moïse remit au sacrificateur Éléazar le tribut, qui était l'ondoiement de l'Éternel, comme l'Éternel l'avait ordonné à Moïse.
42 Ààbọ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli, tí Mose yà sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ọkùnrin tí ó ja ogun.
Sur la moitié des enfants d'Israël, que Moïse sépara des hommes qui avaient combattu
43 Ààbọ̀ tí ìjọ jẹ́ ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn,
(la moitié de l'assemblée était de trois cent trente-sept mille cinq cents moutons,
44 pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún màlúù
trente-six mille têtes de bétail,
45 tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
trente mille cinq cents ânes
46 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ.
et seize mille personnes),
47 Lára ààbọ̀ ti àwọn ọmọ Israẹli, Mose yan ọ̀kan lára àádọ́ta ènìyàn àti ẹranko gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un. Ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ Lefi, tí ń ṣe olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.
sur la moitié des enfants d'Israël, Moïse prit un homme et un animal sur cinquante, et les donna aux Lévites, qui faisaient le service du tabernacle de Yahvé, comme Yahvé l'avait ordonné à Moïse.
48 Pẹ̀lú àwọn olórí tí ó wà lórí ẹgbẹẹgbẹ̀rin ogun náà, àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wá sọ́dọ̀ Mose.
Les officiers qui commandaient les milliers de l'armée, les chefs de milliers et les chefs de centaines, s'approchèrent de Moïse.
49 Wọ́n sì sọ fún un pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti ka àwọn ọmọ-ogun náà tí ó wà lábẹ́ ìtọ́jú wa, kò sì sí ọ̀kọ̀ọ̀kan tó dín.
Ils dirent à Moïse: « Tes serviteurs ont fait le compte des hommes de guerre qui sont sous nos ordres, et il ne manque pas un seul homme parmi nous.
50 Nítorí náà làwa ṣe mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, gbogbo ọrẹ wíwà tí a ní, wúrà, ẹ̀wọ̀n, àti júfù, àti òrùka-àmi, àti òrùka etí, àti ìlẹ̀kẹ̀ láti fi ṣe ètùtù fún ọkàn an wa níwájú Olúwa.”
Nous avons apporté l'offrande de l'Éternel, ce que chacun a trouvé: des ornements en or, des bracelets, des bagues, des anneaux, des boucles d'oreilles et des colliers, pour faire l'expiation de nos âmes devant l'Éternel. »
51 Mose àti Eleasari àlùfáà, gba wúrà náà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú gbogbo ohun iṣẹ́ ọ̀ṣọ́.
Moïse et le sacrificateur Éléazar prirent leur or, tous les bijoux travaillés.
52 Gbogbo wúrà tí àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún mú wá fún Mose àti Eleasari, èyí tí ó jẹ́ ẹbọ ìgbésókè fún Olúwa jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó lé àádọ́ta ṣékélì.
Tout l'or de l'ondoiement qu'ils offrirent à l'Éternel, des chefs de milliers et des chefs de centaines, fut de seize mille sept cent cinquante sicles.
53 Nítorí ológun kọ̀ọ̀kan ti kó ẹrù fún ara rẹ̀.
Les hommes de guerre avaient fait du butin, chacun pour soi.
54 Mose àti Eleasari àlùfáà gba wúrà náà lọ́wọ́ àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti lọ́wọ́ balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wọ́n sì ko wá sínú àgọ́ ìpàdé fún ìrántí àwọn Israẹli níwájú Olúwa.
Moïse et le prêtre Éléazar prirent l'or des chefs de milliers et des chefs de centaines, et l'apportèrent dans la tente d'assignation, comme souvenir pour les enfants d'Israël devant l'Éternel.

< Numbers 31 >