< Numbers 31 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
And the Lord spoke unto Moses, saying,
2 “Gbẹ̀san lára àwọn Midiani fún àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn ìgbà náà a ó kó ọ jọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ.”
Execute the vengeance of the children of Israel on the Midianites, after which thou shalt be gathered unto thy people.
3 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wọ ogun fún àwọn kan nínú yín láti lọ da ojú ìjà kọ àwọn ọmọ Midiani láti gba ẹ̀san Olúwa lára wọn.
And Moses spoke unto the people, saying, Arm from yourselves some men for the army, and let them go against the Midianites, to execute the vengeance of the Lord on Midian.
4 Rán ẹgbẹ̀rún ọmọ-ogun láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan ní Israẹli.”
A thousand each for every tribe, of all the tribes of Israel, shall ye send to the army.
5 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yan nínú àwọn ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn Israẹli, ẹgbẹ̀rún ènìyàn láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, ẹgbàá mẹ́fà ènìyàn tí ó wọ ìhámọ́ra ogun.
And there were levied out of the thousands of Israel, a thousand of every tribe, twelve thousand armed for the army.
6 Mose rán wọn lọ sí ogun, ẹgbẹ̀rún láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú Finehasi ọmọ Eleasari, ti ó jẹ́ àlùfáà, ti òun ti ohun èlò ibi mímọ́ àti ìpè wọ̀n-ọn-nì ní ọwọ́ rẹ̀.
And Moses sent them, a thousand of every tribe, to the army; them and Phinehas the son of Elazar the priest, to the army, with the holy vessels, and the trumpets for blowing the alarm in his hand.
7 Wọ́n dojú ìjà kọ Midiani gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, kí wọn sì pa gbogbo wọn.
And they marched out against the Midianites, as the Lord had commanded Moses; and they slew every male.
8 Wọ́n sì pa àwọn ọba Midiani pẹ̀lú: àwọn ìyókù tí wọ́n pa lára wọn ni Efi, Rekemu, Suri àti Huri, àti Reba: ọba Midiani márùn-ún, wọ́n sì fi idà pa Balaamu ọmọ Beori.
And the kings of Midian they slew, besides the rest of their men that were slain; namely, Evi and Rekem, and Zur, and Chur, and Reba, the five kings of Midian; and Bil'am the son of Beor they slew with the sword.
9 Àwọn ọmọ Israẹli sì mú gbogbo obìnrin Midiani ní ìgbèkùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn.
And the children of Israel took captives the women of Midian, and their little ones; and all their cattle, and all their flocks, and all their goods, they took as spoil.
10 Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn.
And all their cities wherein they dwelt, and all their castles they burnt with fire.
11 Wọ́n sì kó gbogbo ìní wọn, àti ènìyàn àti ẹran.
And they took all the spoil, and all the booty, both of men and of cattle.
12 Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí wọ́n bàjẹ́ àti ènìyàn àti ẹran wá sọ́dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà, àti sọ́dọ̀ ìjọ àwọn ọmọ Israẹli ní ibùdó àgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani létí Jeriko.
And they brought unto Moses, and to Elazar the priest, and unto the congregation of the children of Israel, the captives, and the booty, and the spoil, unto the camp, to the plains of Moab, which are by the Jordan opposite Jericho.
13 Mose, Eleasari àlùfáà àti gbogbo olórí ìgbèríko lọ láti lọ bá wọn ní ìta ibùdó.
And Moses, and Elazar the priest, and all the princes of the congregation, went forth to meet them, to without the camp.
14 Inú bí Mose sí àwọn olórí ọmọ-ogun, pẹ̀lú àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún tí wọ́n ti ogun dé.
And Moses was wroth with the officers of the host, the captains over the thousands, and the captains over the hundreds, who had come from the war-campaign.
15 Mose sì béèrè wí pé, “Ẹ̀yin ha dá gbogbo àwọn obìnrin sí bí?
And Moses said unto them, Have ye allowed all the females to live?
16 Àwọn ni wọ́n tẹ̀lé ìmọ̀ràn Balaamu, àwọn ní ó ṣe okùnfà yíyí àwọn ọ̀mọ̀ Israẹli padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa nínú èyí tí ó ṣẹlẹ̀ ní Peori, níbi tí àjàkálẹ̀-ààrùn ti kọlu ìjọ Olúwa.
Behold, these chiefly were the cause unto the children of Israel, through the counsel of Bil'am, to commit the gross trespass against the Lord in the matter of Peor; through which there was the plague among the congregation of the Lord.
17 Nísinsin yìí, pa gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti àwọn obìnrin tí ó ti súnmọ́ ọkùnrin,
And now kill ye every male among the little ones, and every woman that hath known man by lying with him shall ye kill.
18 ṣùgbọ́n kí o dá obìnrin tí kò bá tí ì súnmọ́ ọkùnrin sí fún ara yín.
But all among the women-children, that have not known a man by lying with him, keep alive for yourselves.
19 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti pa ènìyàn tàbí fọwọ́ kan ẹni tí a pa gbọdọ̀ dúró ní ìta ibùdó àgọ́ fún ọjọ́ méje. Ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje ẹ gbọdọ̀ ya ara yín àti ẹni tí ẹ kó lẹ́rú sí mímọ́.
But ye, —you must abide without the camp seven days: all ye who have killed any person, and all who have touched any one slain, shall purify yourselves on the third day, and on the seventh day; both you and your captives.
20 Kí ẹ̀yin kí ó ya aṣọ yín sí mímọ́ àti gbogbo ohun tí a fi awọ ṣe àti gbogbo iṣẹ́ irun ewúrẹ́ àti ohun tí a fi igi ṣe.”
And every garment, and whatever is made of skins, and every work of goats' hair, and every vessel made of wood, shall ye purify unto yourselves.
21 Eleasari àlùfáà sì wí fún àwọn olórí ogun náà pé, “Èyí ní ìlànà òfin tí Olúwa fi lélẹ̀ ní àṣẹ fún Mose.
And Elazar the priest said unto the men of the army who had gone to the battle, This is the ordinance of the law which the Lord hath commanded Moses:
22 Kìkì i wúrà, fàdákà, idẹ, irin, idẹ àti òjé.
Nevertheless the gold, and the silver, the copper, the iron, the tin, and the lead,
23 Ohunkóhun tí ó lè la iná ni kí ẹ̀yin ó mú la iná, nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n ẹ yóò fi omi ìyàsímímọ́ sọ ọ́ di mímọ́. Àti gbogbo ohun tí kò lè la iná kọjá ni kí a mú la inú omi.
Every thing that cometh into the fire shall ye make go through the fire, and it shall be clean; only it shall be purified with the waters of sprinkling: and whatsoever doth not come into the fire shall ye cause to go through the water.
24 Ní ọjọ́ keje, ẹ fọ aṣọ yín, ẹ̀yin yóò sì mọ́, nígbà náà ní ẹ̀yin yóò lè wọ inú ibùdó àjọ.”
And ye shall wash your clothes on the seventh day, and ye shall be clean, and after that may ye come into the camp.
25 Olúwa sọ fún Mose pé,
And the Lord said unto Moses, as followeth,
26 “Ìwọ àti Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí ilé baba ìjọ ni kí o ka iye àwọn ènìyàn àti ẹranko tí a kó ní ìgbèkùn.
Take the sum of the booty of the captives, both of man and of cattle, thou, with Elazar the priest, and the chiefs of the families of the congregation:
27 Pín ohun ìní àti ìkógun náà láàrín àwọn ọmọ-ogun náà tí ó kópa nínú ogun náà àti láàrín gbogbo ìjọ.
And thou shalt divide the booty, between those that carried on the war, who went out to the army, and between all the congregation.
28 Kí o sì gba ìdá ti Olúwa lọ́wọ́ àwọn ológun tí wọn jáde lọ sí ogun náà, ọ̀kan nínú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ènìyàn àti nínú màlúù àti nínú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti nínú agbo ẹran.
And thou shalt levy a tribute unto the Lord from the men of war who went out to the army, one individual from every five hundred, of the persons, and of the beef-cattle, and of the asses, and of the sheep;
29 Gba ìdá yìí lára ààbọ̀ ìpín tiwọn, kí o sì fún Eleasari àlùfáà, fún ẹbọ ìgbésókè Olúwa.
From their half shall ye take it; and thou shalt give it unto Elazar the priest, for a heave-offering of the Lord.
30 Lára ààbọ̀ ti Israẹli, yan ọ̀kan kúrò nínú àádọ́ta, yálà ènìyàn, ẹran ọ̀sìn, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, ewúrẹ́ tàbí ẹ̀yà ẹranko mìíràn. Kó wọn fún àwọn Lefi, tí ó dúró fún olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.”
And from the half of the children of Israel, shalt thou take one individual, as it may come, from any fifty, of the persons, of beef-cattle, of the asses, and of the flocks, of all manner of cattle; and thou shalt give the same unto the Levites, who keep the charge of the tabernacle of the Lord.
31 Nígbà náà Mose àti Eleasari àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
And Moses with Elazar the priest did, as the Lord had commanded Moses.
32 Èrè tí ó kù lára ìkógun tí àwọn ọmọ-ogun kó jẹ́, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn.
And the booty, being the rest of the spoil which the men of the army had taken, was of sheep and goats, six hundred thousand and seventy thousand and five thousand,
33 Ẹgbàá méjìléláàádọ́rin màlúù
And of beef-cattle, seventy and two thousand,
34 ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹgbẹ̀rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
And of asses, sixty and one thousand,
35 pẹ̀lú obìnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógún, ni kò ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin rí.
And of human persons, of women that had not known men by lying with him, in all thirty and two thousand.
36 Ìpín ààbọ̀ àwọn tí ó jáde lọ sí ogun sì jẹ́: ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn.
And the half, the portion of those who had gone out in the army, was, in the number of sheep and goats, three hundred thousand and seven and thirty thousand and five hundred.
37 Tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn;
And the tribute unto the Lord of the flocks was six hundred and seventy and five.
38 ẹgbọrọ màlúù jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógún, tí ìdá Olúwa sì jẹ́ méjìléláàádọ́rin;
And the beef-cattle were thirty and six thousand; and the tribute thereof unto the Lord was seventy and two.
39 kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta, tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ mọ́kànlélọ́gọ́ta.
And the asses were thirty thousand and five hundred; and the tribute thereof unto the Lord was sixty and one.
40 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ìdá ti Olúwa sì jẹ́ méjìlélọ́gbọ̀n.
And the human persons were sixteen thousand; and the tribute thereof unto the Lord was thirty and two persons.
41 Mose fi ìdá náà fún Eleasari, àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìdá ti Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
And Moses gave the tribute, the Lord's heave-offering, unto Elazar the priest, as the Lord had commanded Moses.
42 Ààbọ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli, tí Mose yà sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ọkùnrin tí ó ja ogun.
And from the half of the children of Israel, which Moses divided off from the men that had gone forth in the army, —
43 Ààbọ̀ tí ìjọ jẹ́ ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn,
(Now the half of the congregation was, of sheep and goats three hundred thousand and thirty thousand, seven thousand and five hundred.
44 pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún màlúù
And beef-cattle, thirty and six thousand,
45 tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
And asses thirty thousand five hundred,
46 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ.
And human persons sixteen thousand; )
47 Lára ààbọ̀ ti àwọn ọmọ Israẹli, Mose yan ọ̀kan lára àádọ́ta ènìyàn àti ẹranko gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un. Ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ Lefi, tí ń ṣe olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.
And Moses took from this half of the children of Israel, as it came, one from every fifty, of man and of cattle, and gave the same unto the Levites, who kept the charge of the tabernacle of the Lord; as the Lord had commanded Moses.
48 Pẹ̀lú àwọn olórí tí ó wà lórí ẹgbẹẹgbẹ̀rin ogun náà, àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wá sọ́dọ̀ Mose.
And there came near unto Moses the officers who had been over the thousands of the army, the captains of the thousands, and the captains of the hundreds.
49 Wọ́n sì sọ fún un pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti ka àwọn ọmọ-ogun náà tí ó wà lábẹ́ ìtọ́jú wa, kò sì sí ọ̀kọ̀ọ̀kan tó dín.
And they said unto Moses, Thy servants have taken the sum of the men of war who have been under our command, and there lacketh not one man of us.
50 Nítorí náà làwa ṣe mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, gbogbo ọrẹ wíwà tí a ní, wúrà, ẹ̀wọ̀n, àti júfù, àti òrùka-àmi, àti òrùka etí, àti ìlẹ̀kẹ̀ láti fi ṣe ètùtù fún ọkàn an wa níwájú Olúwa.”
We have therefore brought an oblation unto the Lord, each what he hath gotten of vessels of gold, chains, and bracelets, finger-rings, earrings, and tablets, to make an atonement for our souls before the Lord.
51 Mose àti Eleasari àlùfáà, gba wúrà náà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú gbogbo ohun iṣẹ́ ọ̀ṣọ́.
And Moses with Elazar the priest took the gold from them, all kinds of wrought articles.
52 Gbogbo wúrà tí àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún mú wá fún Mose àti Eleasari, èyí tí ó jẹ́ ẹbọ ìgbésókè fún Olúwa jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó lé àádọ́ta ṣékélì.
And all the gold of the offering that they offered up to the Lord, was sixteen thousand seven hundred and fifty shekels, from the captains of the thousands, and from the captains of the hundreds.
53 Nítorí ológun kọ̀ọ̀kan ti kó ẹrù fún ara rẹ̀.
The men of the army had taken spoil, every man for himself.
54 Mose àti Eleasari àlùfáà gba wúrà náà lọ́wọ́ àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti lọ́wọ́ balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wọ́n sì ko wá sínú àgọ́ ìpàdé fún ìrántí àwọn Israẹli níwájú Olúwa.
And Moses and Elazar the priest took the gold from the captains of the thousands and of the hundreds, and they brought it into the tabernacle of the congregation, as a memorial for the children of Israel before the Lord.

< Numbers 31 >