< Numbers 31 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Mluvil opět Hospodin k Mojžíšovi, řka:
2 “Gbẹ̀san lára àwọn Midiani fún àwọn ọmọ Israẹli. Lẹ́yìn ìgbà náà a ó kó ọ jọ pẹ̀lú àwọn ènìyàn rẹ.”
Pomsti prvé synů Izraelských nad Madianskými, a potom připojen budeš k lidu svému.
3 Mose sì sọ fún àwọn ènìyàn pé, “Ẹ wọ ogun fún àwọn kan nínú yín láti lọ da ojú ìjà kọ àwọn ọmọ Midiani láti gba ẹ̀san Olúwa lára wọn.
Mluvil tedy Mojžíš k lidu, řka: Vypravte některé z sebe k boji, aby šli proti Madianským a vykonali pomstu Hospodinovu nad nimi.
4 Rán ẹgbẹ̀rún ọmọ-ogun láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan ní Israẹli.”
Po tisíci z pokolení, ze všech pokolení Izraelských vyšlete k boji.
5 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì yan nínú àwọn ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn Israẹli, ẹgbẹ̀rún ènìyàn láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, ẹgbàá mẹ́fà ènìyàn tí ó wọ ìhámọ́ra ogun.
I vydáno jest z mnohých tisíců Izraelských po tisíci z každého pokolení, totiž dvanácte tisíců způsobných k boji.
6 Mose rán wọn lọ sí ogun, ẹgbẹ̀rún láti ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan pẹ̀lú Finehasi ọmọ Eleasari, ti ó jẹ́ àlùfáà, ti òun ti ohun èlò ibi mímọ́ àti ìpè wọ̀n-ọn-nì ní ọwọ́ rẹ̀.
I poslal je Mojžíš po tisíci z každého pokolení k boji, a Fínesa syna Eleazara kněze s nimi; a nádoby svaté i trouby k troubení byly v ruce jeho.
7 Wọ́n dojú ìjà kọ Midiani gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, kí wọn sì pa gbogbo wọn.
Tedy bojovali proti Madianským, jakož byl přikázal Hospodin Mojžíšovi, a zbili všecky pohlaví mužského.
8 Wọ́n sì pa àwọn ọba Midiani pẹ̀lú: àwọn ìyókù tí wọ́n pa lára wọn ni Efi, Rekemu, Suri àti Huri, àti Reba: ọba Midiani márùn-ún, wọ́n sì fi idà pa Balaamu ọmọ Beori.
Pobili také krále Madianské mezi jinými, kteréž porazili, totiž Evi, Rekem, Sur, Hur a Rebe, pět králů Madianských; Baláma také, syna Beorova, zabili mečem.
9 Àwọn ọmọ Israẹli sì mú gbogbo obìnrin Midiani ní ìgbèkùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn.
A zajali synové Izraelští ženy Madianské i děti jejich; všecka hovada jejich, i všechny dobytky jejich, a všecka zboží jejich pobrali.
10 Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn.
Všecka také města jejich, v kterýchž svá obydlí měli, i všecky hrady jejich vypálili ohněm.
11 Wọ́n sì kó gbogbo ìní wọn, àti ènìyàn àti ẹran.
A všecku loupež i všecky kořisti pobravše, lidi i hovada,
12 Wọ́n sì kó gbogbo ohun tí wọ́n bàjẹ́ àti ènìyàn àti ẹran wá sọ́dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà, àti sọ́dọ̀ ìjọ àwọn ọmọ Israẹli ní ibùdó àgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu tí ń bẹ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani létí Jeriko.
Vedli je k Mojžíšovi a k Eleazarovi knězi, a ke všemu množství synů Izraelských, i zajaté i kořisti, i loupeže, k vojsku na roviny Moábské, kteréž jsou při Jordánu naproti Jerichu.
13 Mose, Eleasari àlùfáà àti gbogbo olórí ìgbèríko lọ láti lọ bá wọn ní ìta ibùdó.
I vyšli Mojžíš a Eleazar kněz a všecka knížata shromáždění proti nim ven za stany.
14 Inú bí Mose sí àwọn olórí ọmọ-ogun, pẹ̀lú àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún tí wọ́n ti ogun dé.
Tedy rozhněval se Mojžíš na vůdce vojska, hejtmany nad tisíci a setníky, kteříž se navraceli z boje,
15 Mose sì béèrè wí pé, “Ẹ̀yin ha dá gbogbo àwọn obìnrin sí bí?
A řekl jim Mojžíš: A což jste zachovali všecky ženy?
16 Àwọn ni wọ́n tẹ̀lé ìmọ̀ràn Balaamu, àwọn ní ó ṣe okùnfà yíyí àwọn ọ̀mọ̀ Israẹli padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa nínú èyí tí ó ṣẹlẹ̀ ní Peori, níbi tí àjàkálẹ̀-ààrùn ti kọlu ìjọ Olúwa.
Ej, onyť jsou hle synům Izraelským, podlé rady Balámovy, daly příčinu k přestoupení proti Hospodinu, při modlářství Fegor, pročež ona rána přišla byla na lid Hospodinův.
17 Nísinsin yìí, pa gbogbo ọ̀dọ́mọkùnrin àti àwọn obìnrin tí ó ti súnmọ́ ọkùnrin,
Protož nyní zmordujte všecky děti pohlaví mužského, a všecky ženy, kteréž poznaly muže.
18 ṣùgbọ́n kí o dá obìnrin tí kò bá tí ì súnmọ́ ọkùnrin sí fún ara yín.
Všecky pak panny, kteréž nepoznaly muže, zachovejte sobě živé.
19 “Ẹnikẹ́ni tí ó bá ti pa ènìyàn tàbí fọwọ́ kan ẹni tí a pa gbọdọ̀ dúró ní ìta ibùdó àgọ́ fún ọjọ́ méje. Ní ọjọ́ kẹta àti ọjọ́ keje ẹ gbọdọ̀ ya ara yín àti ẹni tí ẹ kó lẹ́rú sí mímọ́.
Vy pak zůstaňte vně za stany za sedm dní; všickni, kteřížkoli jste někoho zabili, aneb kteříž jste se zabitého dotkli, očištovati se budete dne třetího a dne sedmého, sebe i zajaté své.
20 Kí ẹ̀yin kí ó ya aṣọ yín sí mímọ́ àti gbogbo ohun tí a fi awọ ṣe àti gbogbo iṣẹ́ irun ewúrẹ́ àti ohun tí a fi igi ṣe.”
Všeliké také roucho a všecky věci kožené, i všelijaké dílo z í kozích, i všelikou nádobu dřevěnou očistíte.
21 Eleasari àlùfáà sì wí fún àwọn olórí ogun náà pé, “Èyí ní ìlànà òfin tí Olúwa fi lélẹ̀ ní àṣẹ fún Mose.
I řekl Eleazar kněz vojákům, kteříž byli šli k boji: Toto jest ustanovení zákona, kteréž byl přikázal Hospodin Mojžíšovi.
22 Kìkì i wúrà, fàdákà, idẹ, irin, idẹ àti òjé.
Zlato však, stříbro, měď, železo, cín a olovo,
23 Ohunkóhun tí ó lè la iná ni kí ẹ̀yin ó mú la iná, nígbà náà ni yóò jẹ́ mímọ́. Ṣùgbọ́n ẹ yóò fi omi ìyàsímímọ́ sọ ọ́ di mímọ́. Àti gbogbo ohun tí kò lè la iná kọjá ni kí a mú la inú omi.
A cožkoli trpí oheň, ohněm přepálíte, a přečištěno bude, však tak, když vodou očišťování obmyto bude; což pak nemůže ohně strpěti, to skrze vodu protáhnete.
24 Ní ọjọ́ keje, ẹ fọ aṣọ yín, ẹ̀yin yóò sì mọ́, nígbà náà ní ẹ̀yin yóò lè wọ inú ibùdó àjọ.”
Zpéřete také roucha svá v den sedmý, a čistí budete; a potom vejdete do stanů.
25 Olúwa sọ fún Mose pé,
Mluvil i to Hospodin k Mojžíšovi, řka:
26 “Ìwọ àti Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí ilé baba ìjọ ni kí o ka iye àwọn ènìyàn àti ẹranko tí a kó ní ìgbèkùn.
Sečti summu kořistí zajatých, tak z lidí jako z hovad, ty a Eleazar kněz, a přední z čeledi otců v lidu;
27 Pín ohun ìní àti ìkógun náà láàrín àwọn ọmọ-ogun náà tí ó kópa nínú ogun náà àti láàrín gbogbo ìjọ.
A rozdělíš ty kořisti na dva díly, jeden mezi vojáky, kteříž byli vytáhli na vojnu, a druhý mezi všecko shromáždění.
28 Kí o sì gba ìdá ti Olúwa lọ́wọ́ àwọn ológun tí wọn jáde lọ sí ogun náà, ọ̀kan nínú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta nínú àwọn ènìyàn àti nínú màlúù àti nínú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti nínú agbo ẹran.
A vezmeš díl na Hospodina od mužů bojovných, kteříž byli vyšli na vojnu, jednu duši z pěti set, buďto z lidí neb z hovad, neb z oslů, neb z ovcí.
29 Gba ìdá yìí lára ààbọ̀ ìpín tiwọn, kí o sì fún Eleasari àlùfáà, fún ẹbọ ìgbésókè Olúwa.
Z jejich polovice to vezmete, a dáte Eleazarovi knězi obět vzhůru pozdvižení Hospodinu.
30 Lára ààbọ̀ ti Israẹli, yan ọ̀kan kúrò nínú àádọ́ta, yálà ènìyàn, ẹran ọ̀sìn, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àgùntàn, ewúrẹ́ tàbí ẹ̀yà ẹranko mìíràn. Kó wọn fún àwọn Lefi, tí ó dúró fún olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.”
Z polovice pak té, kteráž jest synů Izraelských, vezmeš jedno z padesáti, buďto z lidí neb z volů, neb z oslů, neb z ovcí, a tak ze všelijakých hovad, a dáš to Levítům, držícím stráž příbytku Hospodinova.
31 Nígbà náà Mose àti Eleasari àlùfáà ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
I učinil Mojžíš a Eleazar kněz tak, jakž byl rozkázal Hospodin Mojžíšovi.
32 Èrè tí ó kù lára ìkógun tí àwọn ọmọ-ogun kó jẹ́, ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n ó dín ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn.
A bylo té kořisti z pozůstalé ještě loupeže, kteréž nabral lid válečný, ovec šestkrát sto tisíc, sedmdesáte a pět tisíců;
33 Ẹgbàá méjìléláàádọ́rin màlúù
A volů sedmdesáte a dva tisíce;
34 ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé ẹgbẹ̀rin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,
Oslů šedesáte a jeden tisíců;
35 pẹ̀lú obìnrin ẹgbàá mẹ́rìndínlógún, ni kò ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú ọkùnrin rí.
A panen, kteréž mužů nepoznaly, všech dva a třidceti tisíců.
36 Ìpín ààbọ̀ àwọn tí ó jáde lọ sí ogun sì jẹ́: ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn.
Dostala se pak polovice jedna na díl těm, kteříž byli vytáhli na vojnu, dobytka drobného v počtu třikrát sto tisíc, třidceti a sedm tisíců a pět set,
37 Tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àgùntàn;
A na díl vzatý Hospodinu dobytka drobného šest set, sedmdesáte pět.
38 ẹgbọrọ màlúù jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógún, tí ìdá Olúwa sì jẹ́ méjìléláàádọ́rin;
A z volů šest a třidceti tisíců, z nichž přišlo na díl Hospodinu sedmdesáte a dva.
39 kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta, tí ìdá ti Olúwa sì jẹ́ mọ́kànlélọ́gọ́ta.
Oslů také třidceti tisíc a pět set, z nichž přišlo na díl Hospodinu šedesáte a jeden.
40 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ìdá ti Olúwa sì jẹ́ méjìlélọ́gbọ̀n.
A lidí šestnácte tisíců, z nichž přišlo na díl Hospodinu třidceti a dvě duše.
41 Mose fi ìdá náà fún Eleasari, àlùfáà gẹ́gẹ́ bí ìdá ti Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
Dal tedy Mojžíš díl oddělený Hospodinu Eleazarovi knězi, jakž byl přikázal Hospodin Mojžíšovi.
42 Ààbọ̀ tí ó jẹ́ ti àwọn ọmọ Israẹli, tí Mose yà sọ́tọ̀ kúrò lára àwọn ọkùnrin tí ó ja ogun.
Z druhé pak polovice synů Izraelských, kterouž vzal Mojžíš od těch mužů, jenž bojovali,
43 Ààbọ̀ tí ìjọ jẹ́ ẹgbàá méjìdínláàádọ́sàn-án ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ àgùntàn,
(A bylo té polovice k shromáždění přináležející z ovec třikrát sto tisíc, třidceti a sedm tisíců a pět set;
44 pẹ̀lú ẹgbàá méjìdínlógún màlúù
Volů třidceti šest tisíců;
45 tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
Oslů třidceti tisíců a pět set;
46 Àwọn ènìyàn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ.
A lidí šestnácte tisíců; )
47 Lára ààbọ̀ ti àwọn ọmọ Israẹli, Mose yan ọ̀kan lára àádọ́ta ènìyàn àti ẹranko gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un. Ó sì fi wọ́n fún àwọn ọmọ Lefi, tí ń ṣe olùtọ́jú àgọ́ Olúwa.
Z té tedy polovice synů Izraelských vzal Mojžíš po jednom zajatém z padesáti, tak z lidí jako z hovad, a dal to Levítům, držícím stráž příbytku Hospodinova, jakž byl přikázal Hospodin Mojžíšovi.
48 Pẹ̀lú àwọn olórí tí ó wà lórí ẹgbẹẹgbẹ̀rin ogun náà, àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wá sọ́dọ̀ Mose.
Tedy přistoupili k Mojžíšovi vývodové vojska, hejtmané nad tisíci a setníci,
49 Wọ́n sì sọ fún un pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ti ka àwọn ọmọ-ogun náà tí ó wà lábẹ́ ìtọ́jú wa, kò sì sí ọ̀kọ̀ọ̀kan tó dín.
A řekli jemu: My služebníci tvoji sečtli jsme počet bojovníků, kteréž jsme měli pod spravou naší, a neubyl ani jeden z nás.
50 Nítorí náà làwa ṣe mú ọrẹ ẹbọ wá fún Olúwa, gbogbo ọrẹ wíwà tí a ní, wúrà, ẹ̀wọ̀n, àti júfù, àti òrùka-àmi, àti òrùka etí, àti ìlẹ̀kẹ̀ láti fi ṣe ètùtù fún ọkàn an wa níwájú Olúwa.”
A protož obětujeme obět Hospodinu, každý z toho, čehož jest dostal, nádobí zlaté, zápony, náramky, prsteny, náušnice a řetízky, aby očištěny byly duše naše před Hospodinem.
51 Mose àti Eleasari àlùfáà, gba wúrà náà lọ́wọ́ wọn pẹ̀lú gbogbo ohun iṣẹ́ ọ̀ṣọ́.
Vzal tedy Mojžíš a Eleazar kněz od nich to zlato všelikého díla řemeslného.
52 Gbogbo wúrà tí àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún mú wá fún Mose àti Eleasari, èyí tí ó jẹ́ ẹbọ ìgbésókè fún Olúwa jẹ́ ẹgbàá mẹ́jọ ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ó lé àádọ́ta ṣékélì.
Bylo pak všeho zlata odděleného, kteréž obětováno Hospodinu, šestnácte tisíců, sedm set a padesáte lotů, od hejtmanů nad tisíci a od setníků.
53 Nítorí ológun kọ̀ọ̀kan ti kó ẹrù fún ara rẹ̀.
(Muži zajisté bojovní, což loupeží vzali, to sobě měli.)
54 Mose àti Eleasari àlùfáà gba wúrà náà lọ́wọ́ àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti lọ́wọ́ balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún wọ́n sì ko wá sínú àgọ́ ìpàdé fún ìrántí àwọn Israẹli níwájú Olúwa.
A vzavše Mojžíš a Eleazar kněz od hejtmanů nad tisíci a setníků to zlato, vnesli je do stánku úmluvy, na památku synů Izraelských před Hospodinem.

< Numbers 31 >