< Numbers 30 >

1 Mose sì sọ fún olórí àwọn ẹ̀yà ọmọ Israẹli pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ,
Mluvil také Mojžíš knížatům pokolení synů Izraelských, řka: Totoť jest, což přikázal Hospodin:
2 nígbà tí ọkùnrin kan bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ sí Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀ ní ìdè kí òun má bà ba ọ̀rọ̀ rẹ̀ jẹ́ kí ó ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sọ.
Jestliže by muž slib aneb přísahu učinil Hospodinu, závazkem zavazuje duši svou, nezruší slova svého; podlé všeho, což vyšlo z úst jeho, učiní.
3 “Nígbà tí ọmọbìnrin kan bá sì wà ní ilé baba rẹ̀ tó bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa tàbí búra láti fi de ara rẹ̀
Když by pak osoba ženského pohlaví učinila slib Hospodinu, a závazkem zavázala se v domě otce svého v mladosti své,
4 tí baba rẹ̀ bá sì gbọ́ ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí ìdè rẹ̀ tí kò sì sọ nǹkan kan sí i, kí gbogbo ẹ̀jẹ́ rẹ̀ kí ó dúró àti gbogbo ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ yóò sì dúró.
A slyše otec její slib a závazek její, jímž zavázala duši svou, mlčel by k tomu: tedy stálí budou všickni slibové její, i každý závazek, jímž zavázala se, stálý bude.
5 Ṣùgbọ́n tí baba rẹ̀ bá kọ̀ fun un ní ọjọ́ tí ó gbọ́, kò sí ọ̀kan nínú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tàbí nínú ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tí yóò dúró; Olúwa yóò sì tú u sílẹ̀ nítorí baba rẹ̀ kọ̀ fún un.
Jestliže by pak to zrušil otec její toho dne, když slyšel všecky ty sliby a závazky její, jimiž zavázala duši svou, nebudouť stálí; a Hospodin odpustí jí, nebo otec její to zrušil.
6 “Tí ó bá sì ní ọkọ lẹ́yìn ìgbà tí ó jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí lẹ́yìn ìgbà tí ó sọ ọ̀rọ̀ kan láti ẹnu rẹ̀ jáde nínú èyí tí ó fi de ara rẹ̀ ní ìdè,
Pakli by vdaná byla za muže, a měla by slib na sobě, aneb pronesla by ústy svými něco, čímž by se zavázala,
7 tí ọkọ rẹ̀ sì gbọ́ nípa èyí ṣùgbọ́n tí kò sọ nǹkan kan, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó fi de ara rẹ̀ tó dúró.
A slyše muž její, nic by jí neřekl toho dne, kteréhož slyšel: stálí budou slibové její, i závazkové, jimiž zavázala duši svou, stálí budou.
8 Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá kọ̀ nígbà tí ó gbọ́, ǹjẹ́ òun yóò mú ẹ̀jẹ́ rẹ̀ tí ó jẹ́ àti ohun tí ó ti ti ẹnu rẹ̀ jáde, èyí tí ó fi de ara rẹ̀ dasán, Olúwa yóò sì dáríjì í.
Jestliže by pak muž její toho dne, jakž uslyšel, odepřel tomu, a zrušil slib, kterýž na sobě měla, aneb něco rty svými pronesla, čímž by se zavázala, také odpustí jí Hospodin.
9 “Ṣùgbọ́n ẹ̀jẹ́ kí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè kí ìdè tí opó tàbí obìnrin tí a kọ̀sílẹ̀ bá ṣe yóò wà lórí rẹ̀.
Všeliký pak slib vdovy aneb ženy zahnané, jímž by se zavázala, stálý bude.
10 “Bí obìnrin tí ó ń gbé pẹ̀lú ọkọ rẹ̀ bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ tàbí de ara rẹ̀ ní ìdè lábẹ́ ìbúra,
Ale jestliže v domě muže svého slíbila, a závazkem zavázala se s přísahou,
11 tí ọkọ rẹ̀ bá sì gbọ́, ṣùgbọ́n tí kò sọ̀rọ̀, tí kò sì kọ̀, nígbà náà ni ẹ̀jẹ́ rẹ̀ yóò dúró.
A slyše to muž její, mlčel k tomu a neodepřel: tedy stálí budou všickni slibové její, a všickni závazkové, jimiž se zavázala, stálí budou.
12 Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ bá sọ wọ́n dasán, nígbà tí ó gbọ́, nígbà náà kò sí ẹ̀jẹ́ tàbí ìdè tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde tí yóò dúró, ọkọ rẹ̀ ti sọ wọ́n dasán, Olúwa yóò tú u sílẹ̀.
Pakli docela odepřel muž její toho dne, jakž uslyšel, všeliký slib, kterýž vyšel z úst jejích, a závazek, jímž zavázala se, nebude stálý; muž její zrušil to, a Hospodin jí odpustí.
13 Ọkọ rẹ̀ lè ṣe ìwádìí tàbí sọ ọ́ dasán ẹ̀jẹ́ tàbí ìbúra ìdè tí ó ti ṣe láti fi de ara rẹ̀.
Všelikého slibu a každého závazku s přísahou učiněného o trápení života jejího, muž její potvrdí jeho, a muž její zruší jej.
14 Ṣùgbọ́n tí ọkọ rẹ̀ kò bá sọ nǹkan kan sí í nípa rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́, nígbà náà ni ó ṣe ìwádìí nípa ẹ̀jẹ́ àti ìbúra ìdè tí ó dè é. Kí ọkùnrin náà ṣe ìwádìí lórí rẹ̀ láìsọ nípa rẹ̀ si nígbà tí ó gbọ́ nípa rẹ̀.
Pakli by muž její den po dni mlčel, tedy potvrdí všech slibů jejích, a všech závazků jejích, kteréž na sobě má; potvrdilť jest jich, nebo neodepřel jí v den ten, když to uslyšel.
15 Bí ó ti wù kí ó rí, bí ọkùnrin náà bá sọ ọ́ dasán, ní àkókò kan lẹ́yìn tí ó ti gbọ́ wọn, nígbà náà ó jẹ̀bi ọ̀rọ̀ náà.”
Jestliže by pak slyše, potom teprv zrušiti to chtěl, tedy on ponese nepravost její.
16 Èyí ni ìlànà tí Olúwa fún Mose nípa ìbátan láàrín ọkùnrin àti obìnrin àti láàrín baba àti ọ̀dọ́mọbìnrin rẹ̀ tí ó sì ń gbé ní ilé rẹ̀.
Ta jsou ustanovení, kteráž přikázal Hospodin Mojžíšovi, mezi mužem a ženou jeho, mezi otcem a dcerou jeho v mladosti její, dokudž jest v domě otce svého.

< Numbers 30 >