< Numbers 3 >

1 Ìwọ̀nyí ni ìdílé Aaroni àti Mose ní ìgbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní òkè Sinai.
Voici les descendants d'Aaron et de Moïse, au jour où l'Éternel parla à Moïse au mont Sinaï;
2 Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni nìwọ̀nyí, Nadabu ni àkọ́bí, Abihu, Eleasari àti Itamari.
Voici les noms des fils d'Aaron: Nadab, le premier-né, Abihu, Éléazar et Ithamar.
3 Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni ni ìwọ̀nyí, àwọn àlùfáà tí a fi òróró yàn, àwọn tí a fi joyè àlùfáà láti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
Ce sont là les noms des fils d'Aaron, des sacrificateurs qui furent oints, qu'on institua pour exercer le sacerdoce.
4 Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu ti kú níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n rú iná àjèjì níwájú Olúwa nínú ijù Sinai, àwọn méjèèjì kò sì ní ọmọ. Báyìí Eleasari àti Itamari ló ṣiṣẹ́ àlùfáà nígbà ayé Aaroni baba wọn.
Or, Nadab et Abihu moururent devant l'Éternel, lorsqu'ils offrirent un feu étranger devant l'Éternel, au désert de Sinaï. Et ils n'avaient point d'enfants. Mais Éléazar et Ithamar exercèrent la sacrificature, en présence d'Aaron, leur père.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
Alors l'Éternel parla à Moïse, en disant:
6 “Kó ẹ̀yà Lefi wá, kí o sì fà wọ́n fún Aaroni àlùfáà láti máa ràn án lọ́wọ́.
Fais approcher la tribu de Lévi, et fais-la tenir devant Aaron, le sacrificateur, afin qu'ils le servent;
7 Wọn yóò máa ṣiṣẹ́ fún un àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn ní àgọ́ ìpàdé bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú àgọ́.
Et qu'ils soignent tout ce qui est commis à ses soins et aux soins de toute l'assemblée, devant le tabernacle d'assignation, en faisant le service de la Demeure;
8 Wọn yóò máa tọ́jú gbogbo ohun èlò inú àgọ́ ìpàdé, wọn yóò sì máa ṣe ojúṣe àwọn ọmọ Israẹli nípa ṣíṣe iṣẹ́ nínú àgọ́.
Et qu'ils soignent tous les ustensiles du tabernacle d'assignation, et ce qui leur sera confié par les enfants d'Israël, pour faire le service de la Demeure.
9 Fi ẹ̀yà Lefi jì Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn nìkan ni a fi fún Aaroni nínú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli.
Ainsi tu donneras les Lévites à Aaron et à ses fils; ils lui sont complètement donnés d'entre les enfants d'Israël.
10 Kí o sì yan Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ àlùfáà; àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ pípa ni kí ẹ pa á.”
Tu établiras donc Aaron et ses fils, afin qu'ils gardent leur sacerdoce; et l'étranger qui en approchera sera puni de mort.
11 Olúwa tún sọ fún Mose pé,
Et l'Éternel parla à Moïse, en disant:
12 “Báyìí èmi fúnra mi ti mú ẹ̀yà Lefi láàrín àwọn ọmọ Israẹli dípò gbogbo àkọ́bí ọkùnrin àwọn ọmọbìnrin Israẹli. Ti èmi ni àwọn ọmọ Lefi,
Voici, j'ai pris les Lévites, d'entre les enfants d'Israël, à la place de tous les premiers-nés des enfants d'Israël, et les Lévites seront à moi.
13 nítorí pé ti èmi ni gbogbo àkọ́bí. Ní ọjọ́ tí mo pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti ya gbogbo àkọ́bí sọ́tọ̀ ní Israẹli yálà ti ènìyàn tàbí ti ẹranko. Gbogbo wọn gbọdọ̀ jẹ́ ti èmi. Èmi ni Olúwa.”
Car tout premier-né m'appartient; au jour où je frappai tout premier-né dans le pays d'Égypte, je me suis consacré tout premier-né en Israël, depuis les hommes jusqu'aux bêtes; ils seront à moi: je suis l'Éternel.
14 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose ní aginjù Sinai pé,
L'Éternel parla aussi à Moïse, au désert de Sinaï, en disant:
15 “Ka àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè.”
Dénombre les enfants de Lévi, selon les maisons de leurs pères, selon leurs familles, en comptant tous les mâles depuis l'âge d'un mois et au-dessus.
16 Mose sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.
Et Moïse les dénombra, selon le commandement de l'Éternel, ainsi qu'il lui avait été ordonné.
17 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Voici quels sont les fils de Lévi, par leurs noms: Guershon, Kéhath et Mérari.
18 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni: Libni àti Ṣimei.
Et voici les noms des fils de Guershon, selon leurs familles: Libni et Shimeï.
19 Àwọn ìdílé Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
Et les fils de Kéhath, selon leurs familles: Amram, Jitshar, Hébron et Uziel.
20 Àwọn ìdílé Merari ni: Mahili àti Muṣi. Wọ̀nyí ni ìdílé Lefi gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
Et les fils de Mérari, selon leurs familles: Machli et Mushi. Telles sont les familles de Lévi, selon les maisons de leurs pères.
21 Ti Gerṣoni ni ìdílé Libni àti Ṣimei; àwọn ni ìdílé Gerṣoni.
A Guershon appartient la famille des Libnites, et la famille des Simhites. Telles sont les familles des Guershonites.
22 Iye àwọn ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, jẹ́ ẹgbàata ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
Ceux d'entre eux qui furent dénombrés, en comptant tous les mâles, depuis l'âge d'un mois et au-dessus, étaient sept mille cinq cents.
23 Àwọn ìdílé Gerṣoni yóò pa ibùdó sí ìhà ìwọ̀-oòrùn lẹ́yìn àgọ́.
Les familles des Guershonites campaient derrière la Demeure, vers l'Occident;
24 Olórí àwọn ìdílé Gerṣoni ni Eliasafu ọmọ Láélì.
Et le chef de la maison des pères des Guershonites était Eliasaph, fils de Laël.
25 Iṣẹ́ àwọn ìdílé Gerṣoni nínú àgọ́ ìpàdé ni pé àwọn yóò máa tọ́jú àgọ́, ìbòrí àgọ́, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
Et la charge des enfants de Guershon, quant au tabernacle d'assignation, était la Demeure et le tabernacle, sa couverture, et la tapisserie de l'entrée du tabernacle d'assignation,
26 aṣọ títa ti àgbàlá, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, àwọn okùn rẹ̀ àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
Et les tentures du parvis, et la tapisserie de l'entrée du parvis, qui couvrent la Demeure et l'autel tout autour, et ses cordages pour tout son service.
27 Ti Kohati ní ìdílé Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli, wọ̀nyí ni ìran Kohati.
A Kéhath appartient la famille des Amramites, la famille des Jitseharites, la famille des Hébronites, et la famille des Uziélites. Telles sont les familles des Kéhathites.
28 Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbàá mẹ́rin ó lé ẹgbẹ̀ta, tí yóò máa ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́.
En comptant tous les mâles, depuis l'âge d'un mois et au-dessus, ils étaient huit mille six cents, chargés des soins du sanctuaire.
29 Àwọn ìdílé Kohati yóò pa ibùdó wọn sí ìhà gúúsù ní ẹ̀gbẹ́ àgọ́.
Les familles des enfants de Kéhath campaient sur le côté de la Demeure, vers le Midi;
30 Olórí àwọn ìdílé Kohati ni Elisafani ọmọ Usieli.
Et Elitsaphan, fils d'Uziel, était le chef de la maison des pères des familles des Kéhathites.
31 Àwọn ni yóò máa tọ́jú àpótí ẹ̀rí, tábìlì, ọ̀pá fìtílà, àwọn pẹpẹ, gbogbo ohun èlò ibi mímọ́ tí à ń lò fún iṣẹ́ ìsìn, aṣọ títa àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
Ils avaient en garde l'arche, la table, le chandelier, les autels et les ustensiles du sanctuaire avec lesquels on fait le service, et la tapisserie, et tout son service.
32 Eleasari ọmọ Aaroni àlùfáà ni alákòóso gbogbo àwọn olórí ìdílé Lefi. Òun ni wọ́n yàn lórí gbogbo àwọn tí yóò máa tọ́jú ibi mímọ́.
Et le chef des chefs des Lévites étaient Éléazar, fils d'Aaron, le sacrificateur, qui était préposé à ceux qui étaient chargés des soins du sanctuaire.
33 Ti Merari ni ìran Mahili àti Muṣi, àwọn ni ìran Merari.
A Mérari appartient la famille des Mahlites, et la famille des Mushites. Telles sont les familles de Mérari.
34 Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, èyí tí wọ́n kà jẹ́ igba mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
Ceux d'entre eux qui furent dénombrés, en comptant tous les mâles, depuis l'âge d'un mois et au-dessus, étaient six mille deux cents.
35 Olórí àwọn ìdílé ìran Merari ni Ṣurieli ọmọ Abihaili. Wọn yóò pa ibùdó wọn sí ìhà àríwá àgọ́.
Et Tsuriel, fils d'Abihaïl, était le chef de la maison des pères des familles des Mérarites; ils campaient sur le côté de la Demeure, vers le Nord.
36 Àwọn ìran Merari ni a yàn fún títọ́jú àwọn férémù àgọ́, ọ̀pá ìdábùú rẹ̀, òpó rẹ̀, ihò òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn.
Et les enfants de Mérari avaient la surveillance et le soin des planches de la Demeure, de ses traverses, de ses colonnes, de ses soubassements, de tous ses ustensiles, et de tout son service,
37 Iṣẹ́ wọn tún ni títọ́jú àwọn òpó tó yí àgbàlá ká, ihò òpó rẹ̀, èèkàn àti okùn wọn.
Des colonnes du parvis tout autour, avec leurs soubassements, leurs pieux et leurs cordages.
38 Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn ọmọ yóò pa àgọ́ ní ìdojúkọ ìwọ̀-oòrùn níwájú àgọ́ ìpàdé. Iṣẹ́ wọn ni láti máa mójútó iṣẹ́ ìsìn ibi mímọ́ àti láti máa ṣiṣẹ́ ìsìn fún àwọn ọmọ Israẹli. Àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ yàtọ̀ sí àwọn tí a yàn, pípa ni kí ẹ pa á.
Ceux qui campaient devant la Demeure, vers l'Orient, devant le tabernacle d'assignation, c'était Moïse, et Aaron, et ses fils, chargés du soin du sanctuaire pour les enfants d'Israël; et l'étranger qui en approcherait devait être puni de mort.
39 Àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Lefi tí a kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose àti Aaroni gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, pẹ̀lú gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún.
Tous les Lévites qui furent dénombrés, que Moïse et Aaron dénombrèrent, selon leurs familles, suivant le commandement de l'Éternel, tous les mâles, depuis l'âge d'un mois et au-dessus, étaient vingt-deux mille.
40 Olúwa sọ fún Mose pé, “Ka gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli láti ọmọ oṣù kan ó lé kí o sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
Puis l'Éternel dit à Moïse: Fais le dénombrement de tous les premiers-nés mâles des enfants d'Israël, depuis l'âge d'un mois et au-dessus, et fais le compte de leurs noms.
41 Kí o sì gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì gba gbogbo ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi fún mi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa.”
Tu prendras les Lévites pour moi, l'Éternel, à la place de tous les premiers-nés parmi les enfants d'Israël; et le bétail des Lévites, à la place de tous les premiers-nés du bétail des enfants d'Israël.
42 Mose sì ka gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un.
Moïse dénombra donc, comme l'Éternel le lui avait commandé, tous les premiers-nés parmi les enfants d'Israël;
43 Àpapọ̀ iye àwọn àkọ́bí ọkùnrin láti ọmọ oṣù kan ó lé, ní àkọsílẹ̀ orúkọ wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé ọ̀rìnlúgba ó dín méje.
Et tous les premiers-nés mâles, en comptant par les noms depuis l'âge d'un mois et au-dessus, selon leur dénombrement, furent vingt-deux mille deux cent soixante et treize.
44 Olúwa tún sọ fún Mose pé,
Et l'Éternel parla à Moïse, en disant:
45 “Gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli àti ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi dípò ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Tèmi ni àwọn ọmọ Lefi. Èmi ni Olúwa.
Prends les Lévites à la place de tous les premiers-nés des enfants d'Israël, et le bétail des Lévites à la place de leur bétail; et les Lévites seront à moi: je suis l'Éternel.
46 Nísinsin yìí, láti lè ra ọ̀rìnlúgba dín méje àkọ́bí àwọn Israẹli tó ju iye àwọn ọmọ Lefi lọ,
Quant au rachat des premiers-nés des enfants d'Israël, savoir deux cent soixante et treize qui dépassent le nombre des Lévites,
47 ìwọ yóò gba ṣékélì márùn-ún lórí ẹni kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, èyí tí í ṣe ogún gera.
Tu prendras cinq sicles par tête; tu les prendras selon le sicle du sanctuaire; le sicle est de vingt oboles.
48 Owó tí a fi ra àwọn àkọ́bí ọmọ Israẹli tó lé yìí, ni kí o kó fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀.”
Et tu donneras l'argent à Aaron et à ses fils; c'est le rachat de ceux qu'il y avait en plus.
49 Nígbà náà ni Mose gba owó ìràpadà àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi ti ra àwọn yòókù padà.
Moïse prit donc l'argent du rachat de ceux qu'il y avait en plus, outre les rachetés par les Lévites.
50 Mose sì gba egbèje ṣékélì ó dín márùndínlógójì gẹ́gẹ́ bí iye ṣékélì ibi mímọ́ lọ́wọ́ àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli.
L'argent qu'il prit des premiers-nés des enfants d'Israël, fut de mille trois cent soixante-cinq sicles, selon le sicle du sanctuaire.
51 Mose sì kó owó ìràpadà yìí fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.
Et Moïse donna l'argent du rachat à Aaron et à ses fils, sur l'ordre de l'Éternel, comme l'Éternel l'avait commandé à Moïse.

< Numbers 3 >