< Numbers 3 >

1 Ìwọ̀nyí ni ìdílé Aaroni àti Mose ní ìgbà tí Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní òkè Sinai.
Voici l'histoire des générations d'Aaron et de Moïse, au jour où Yahvé parla à Moïse sur la montagne de Sinaï.
2 Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni nìwọ̀nyí, Nadabu ni àkọ́bí, Abihu, Eleasari àti Itamari.
Voici les noms des fils d'Aaron: Nadab, premier-né, Abihu, Éléazar et Ithamar.
3 Orúkọ àwọn ọmọ Aaroni ni ìwọ̀nyí, àwọn àlùfáà tí a fi òróró yàn, àwọn tí a fi joyè àlùfáà láti ṣiṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà.
Voici les noms des fils d'Aaron, les prêtres oints, qu'il consacra pour exercer le sacerdoce.
4 Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu ti kú níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n rú iná àjèjì níwájú Olúwa nínú ijù Sinai, àwọn méjèèjì kò sì ní ọmọ. Báyìí Eleasari àti Itamari ló ṣiṣẹ́ àlùfáà nígbà ayé Aaroni baba wọn.
Nadab et Abihu moururent devant Yahvé lorsqu'ils offrirent du feu étranger devant Yahvé dans le désert du Sinaï, et ils n'eurent pas d'enfants. Eléazar et Ithamar firent le service du sacerdoce en présence d'Aaron, leur père.
5 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahvé parla à Moïse, et dit:
6 “Kó ẹ̀yà Lefi wá, kí o sì fà wọ́n fún Aaroni àlùfáà láti máa ràn án lọ́wọ́.
Fais approcher la tribu de Lévi, et place-la devant le prêtre Aaron, pour qu'elle soit à son service.
7 Wọn yóò máa ṣiṣẹ́ fún un àti fún gbogbo ìjọ ènìyàn ní àgọ́ ìpàdé bí wọ́n ti ń ṣiṣẹ́ ìsìn nínú àgọ́.
Ils veilleront sur ses besoins et sur ceux de toute l'assemblée devant la tente d'assignation, pour faire le service du tabernacle.
8 Wọn yóò máa tọ́jú gbogbo ohun èlò inú àgọ́ ìpàdé, wọn yóò sì máa ṣe ojúṣe àwọn ọmọ Israẹli nípa ṣíṣe iṣẹ́ nínú àgọ́.
Ils garderont tout le mobilier de la Tente d'assignation et les obligations des enfants d'Israël, pour assurer le service de la Tente d'assignation.
9 Fi ẹ̀yà Lefi jì Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, àwọn nìkan ni a fi fún Aaroni nínú gbogbo àwọn ọmọ Israẹli.
Tu donneras les Lévites à Aaron et à ses fils. Ils lui seront entièrement remis au nom des enfants d'Israël.
10 Kí o sì yan Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ láti máa ṣiṣẹ́ àlùfáà; àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ pípa ni kí ẹ pa á.”
Tu désigneras Aaron et ses fils, et ils conserveront leur sacerdoce, mais l'étranger qui s'approchera sera mis à mort. »
11 Olúwa tún sọ fún Mose pé,
Yahvé parla à Moïse et dit:
12 “Báyìí èmi fúnra mi ti mú ẹ̀yà Lefi láàrín àwọn ọmọ Israẹli dípò gbogbo àkọ́bí ọkùnrin àwọn ọmọbìnrin Israẹli. Ti èmi ni àwọn ọmọ Lefi,
« Voici, j'ai pris les Lévites du milieu des enfants d'Israël à la place de tous les premiers-nés qui ouvrent le ventre des enfants d'Israël; et les Lévites seront à moi,
13 nítorí pé ti èmi ni gbogbo àkọ́bí. Ní ọjọ́ tí mo pa gbogbo àkọ́bí ní ilẹ̀ Ejibiti ni mo ti ya gbogbo àkọ́bí sọ́tọ̀ ní Israẹli yálà ti ènìyàn tàbí ti ẹranko. Gbogbo wọn gbọdọ̀ jẹ́ ti èmi. Èmi ni Olúwa.”
car tous les premiers-nés sont à moi. Le jour où j'ai frappé tous les premiers-nés du pays d'Égypte, j'ai consacré à moi tous les premiers-nés d'Israël, hommes et animaux. Ils seront à moi. Je suis Yahvé. »
14 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose ní aginjù Sinai pé,
Yahvé parla à Moïse dans le désert de Sinaï, et dit:
15 “Ka àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè.”
« Compte les enfants de Lévi selon les maisons de leurs pères, selon leurs familles. Tu compteras tous les mâles depuis l'âge d'un mois et au-dessus. »
16 Mose sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.
Moïse les compta selon la parole de Yahvé, comme il en avait reçu l'ordre.
17 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
Voici les fils de Lévi, selon leurs noms: Guershon, Kehath et Merari.
18 Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni: Libni àti Ṣimei.
Voici les noms des fils de Gershon, selon leurs familles: Libni et Shimei.
19 Àwọn ìdílé Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
Fils de Kehath, selon leurs familles: Amram, Izhar, Hebron et Uzziel.
20 Àwọn ìdílé Merari ni: Mahili àti Muṣi. Wọ̀nyí ni ìdílé Lefi gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
Les fils de Merari, selon leurs familles: Mahli et Mushi. Voici les familles des Lévites, selon les maisons de leurs pères.
21 Ti Gerṣoni ni ìdílé Libni àti Ṣimei; àwọn ni ìdílé Gerṣoni.
De Guershon, la famille des Libnites et la famille des Shiméites. Ce sont là les familles des Gershonites.
22 Iye àwọn ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, jẹ́ ẹgbàata ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
Ceux dont on fit le compte, selon le nombre de tous les mâles depuis l'âge d'un mois et au-dessus, ceux dont on fit le compte furent sept mille cinq cents.
23 Àwọn ìdílé Gerṣoni yóò pa ibùdó sí ìhà ìwọ̀-oòrùn lẹ́yìn àgọ́.
Les familles des Guershonites camperont derrière le tabernacle, à l'ouest.
24 Olórí àwọn ìdílé Gerṣoni ni Eliasafu ọmọ Láélì.
Eliasaph, fils de Lael, sera le chef de la maison des pères des Guershonites.
25 Iṣẹ́ àwọn ìdílé Gerṣoni nínú àgọ́ ìpàdé ni pé àwọn yóò máa tọ́jú àgọ́, ìbòrí àgọ́, aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé,
Les fonctions des fils de Gershon dans la Tente d'assignation seront le tabernacle, le chapiteau, sa couverture, le rideau de l'entrée de la Tente d'assignation,
26 aṣọ títa ti àgbàlá, aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà àgbàlá tó yí àgọ́ àti pẹpẹ ká, àwọn okùn rẹ̀ àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
les tentures du parvis, le rideau de l'entrée du parvis qui est près du tabernacle et autour de l'autel, et ses cordons pour tout son service.
27 Ti Kohati ní ìdílé Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli, wọ̀nyí ni ìran Kohati.
De Kehath, la famille des Amramites, la famille des Jitseharites, la famille des Hébronites et la famille des Uzzielites. Telles sont les familles des Kehathites.
28 Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbàá mẹ́rin ó lé ẹgbẹ̀ta, tí yóò máa ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́.
D'après le nombre de tous les mâles, depuis l'âge d'un mois et au-dessus, il y en avait huit mille six cents qui observaient les prescriptions du sanctuaire.
29 Àwọn ìdílé Kohati yóò pa ibùdó wọn sí ìhà gúúsù ní ẹ̀gbẹ́ àgọ́.
Les familles des fils de Kehath camperont au sud du tabernacle.
30 Olórí àwọn ìdílé Kohati ni Elisafani ọmọ Usieli.
Le chef de la maison des pères des familles des Kehathites sera Elizaphan, fils d'Uzziel.
31 Àwọn ni yóò máa tọ́jú àpótí ẹ̀rí, tábìlì, ọ̀pá fìtílà, àwọn pẹpẹ, gbogbo ohun èlò ibi mímọ́ tí à ń lò fún iṣẹ́ ìsìn, aṣọ títa àti gbogbo ohun tó jẹ mọ́ lílò wọn.
Il sera chargé de l'arche, de la table, du chandelier, des autels, des ustensiles du sanctuaire avec lesquels on fait le service, du rideau et de tout son service.
32 Eleasari ọmọ Aaroni àlùfáà ni alákòóso gbogbo àwọn olórí ìdílé Lefi. Òun ni wọ́n yàn lórí gbogbo àwọn tí yóò máa tọ́jú ibi mímọ́.
Éléazar, fils du prêtre Aaron, sera le chef des chefs des lévites, avec la surveillance de ceux qui veillent aux besoins du sanctuaire.
33 Ti Merari ni ìran Mahili àti Muṣi, àwọn ni ìran Merari.
De Merari était la famille des Mahlites et la famille des Mushites. Ce sont là les familles de Merari.
34 Iye gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ oṣù kan ó lé, èyí tí wọ́n kà jẹ́ igba mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
Ceux dont on fit le dénombrement, selon le nombre de tous les mâles depuis l'âge d'un mois et au-dessus, furent six mille deux cents.
35 Olórí àwọn ìdílé ìran Merari ni Ṣurieli ọmọ Abihaili. Wọn yóò pa ibùdó wọn sí ìhà àríwá àgọ́.
Le prince de la maison des pères des familles de Merari était Tsuriel, fils d'Abihail. Ils camperont sur le côté nord de la tente.
36 Àwọn ìran Merari ni a yàn fún títọ́jú àwọn férémù àgọ́, ọ̀pá ìdábùú rẹ̀, òpó rẹ̀, ihò òpó rẹ̀ àti gbogbo ohun èlò tó jẹ mọ́ lílò wọn.
Les fils de Merari seront chargés des planches du tabernacle, de ses barres, de ses piliers, de ses socles, de tous ses instruments, de tout son service,
37 Iṣẹ́ wọn tún ni títọ́jú àwọn òpó tó yí àgbàlá ká, ihò òpó rẹ̀, èèkàn àti okùn wọn.
des piliers du parvis qui l'entourent, de leurs socles, de leurs broches et de leurs cordons.
38 Mose àti Aaroni pẹ̀lú àwọn ọmọ yóò pa àgọ́ ní ìdojúkọ ìwọ̀-oòrùn níwájú àgọ́ ìpàdé. Iṣẹ́ wọn ni láti máa mójútó iṣẹ́ ìsìn ibi mímọ́ àti láti máa ṣiṣẹ́ ìsìn fún àwọn ọmọ Israẹli. Àlejò tó bá súnmọ́ ibi mímọ́ yàtọ̀ sí àwọn tí a yàn, pípa ni kí ẹ pa á.
Ceux qui campent devant le tabernacle, à l'est, devant la tente d'assignation, vers le lever du soleil, seront Moïse, avec Aaron et ses fils, gardant les exigences du sanctuaire pour le devoir des enfants d'Israël. L'étranger qui s'approchera sera mis à mort.
39 Àpapọ̀ iye àwọn ọmọ Lefi tí a kà gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose àti Aaroni gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, pẹ̀lú gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ oṣù kan ó lé jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún.
Tous les Lévites dont Moïse et Aaron firent le compte sur l'ordre de l'Éternel, selon leurs familles, tous les mâles depuis l'âge d'un mois et au-dessus, furent vingt-deux mille.
40 Olúwa sọ fún Mose pé, “Ka gbogbo àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli láti ọmọ oṣù kan ó lé kí o sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
L'Éternel dit à Moïse: « Fais le compte de tous les premiers-nés mâles des enfants d'Israël, depuis l'âge d'un mois et au-dessus, et note le nombre de leurs noms.
41 Kí o sì gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì gba gbogbo ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi fún mi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ẹran ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa.”
Tu prendras les Lévites pour moi - je suis Yahvé - à la place de tous les premiers-nés des enfants d'Israël, et le bétail des Lévites à la place de tous les premiers-nés du bétail des enfants d'Israël. »
42 Mose sì ka gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un.
Moïse compta, comme l'avait ordonné l'Éternel, tous les premiers-nés des enfants d'Israël.
43 Àpapọ̀ iye àwọn àkọ́bí ọkùnrin láti ọmọ oṣù kan ó lé, ní àkọsílẹ̀ orúkọ wọn jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé ọ̀rìnlúgba ó dín méje.
Tous les premiers-nés mâles, selon le nombre des noms, depuis l'âge d'un mois et au-dessus, de ceux qui furent comptés, furent vingt-deux mille deux cent soixante-treize.
44 Olúwa tún sọ fún Mose pé,
Yahvé parla à Moïse, et dit:
45 “Gba àwọn ọmọ Lefi dípò gbogbo àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli àti ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Lefi dípò ohun ọ̀sìn àwọn ọmọ Israẹli. Tèmi ni àwọn ọmọ Lefi. Èmi ni Olúwa.
« Prends les Lévites à la place de tous les premiers-nés des enfants d'Israël, et le bétail des Lévites à la place de leur bétail; et les Lévites seront à moi. Je suis Yahvé.
46 Nísinsin yìí, láti lè ra ọ̀rìnlúgba dín méje àkọ́bí àwọn Israẹli tó ju iye àwọn ọmọ Lefi lọ,
Pour le rachat des deux cent soixante-treize premiers-nés des enfants d'Israël qui dépassent le nombre des Lévites,
47 ìwọ yóò gba ṣékélì márùn-ún lórí ẹni kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí iye owó ibi mímọ́, èyí tí í ṣe ogún gera.
tu prendras cinq sicles pour chacun d'eux; tu les prendras selon le sicle du sanctuaire (le sicle est de vingt gérachs);
48 Owó tí a fi ra àwọn àkọ́bí ọmọ Israẹli tó lé yìí, ni kí o kó fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀.”
et tu donneras l'argent, avec lequel leur reste est racheté, à Aaron et à ses fils. »
49 Nígbà náà ni Mose gba owó ìràpadà àwọn ènìyàn tó ṣẹ́kù lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Lefi ti ra àwọn yòókù padà.
Moïse prit l'argent du rachat de ceux qui dépassaient le nombre des rachetés par les Lévites;
50 Mose sì gba egbèje ṣékélì ó dín márùndínlógójì gẹ́gẹ́ bí iye ṣékélì ibi mímọ́ lọ́wọ́ àkọ́bí àwọn ọmọ Israẹli.
il prit l'argent des premiers-nés des enfants d'Israël, mille trois cent soixante-cinq sicles, selon le sicle du sanctuaire;
51 Mose sì kó owó ìràpadà yìí fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.
et Moïse donna l'argent du rachat à Aaron et à ses fils, selon la parole de Yahvé, comme Yahvé l'avait ordonné à Moïse.

< Numbers 3 >