< Numbers 28 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
Yahweh said this to Moses/me:
2 “Fún àwọn ọmọ Israẹli ní òfin yìí kí o sì wí fún wọn pé: ‘Ẹ rí i wí pé ẹ gbé e wá sí iwájú mi ní àkókò tí a ti yàn, oúnjẹ ọrẹ ẹbọ mi tí a fi iná ṣe sí mi, gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí mi.’
“Tell this to the Israeli people: Bring to me the offerings that will be burned [on the altar]. When they are burned, the smell will be very pleasing to me. And tell them that they must bring them at the proper/right time.
3 Sọ fún wọn, ‘Èyí ní ọrẹ ẹbọ tí a fi iná sun tí ẹ gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa: akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kan aláìlábàwọ́n gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun ní ojoojúmọ́.
Tell them that what they must bring to me each day are two male lambs that are one-year-old. They must have no defects. They must be completely burned [on the altar].
4 Pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn kan ní òwúrọ̀ àti òmíràn ní àfẹ̀mọ́júmọ́.
They should bring one in the morning and the other early in the evening.
5 Pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ tí ó jẹ́ ìdámẹ́wàá efa ìyẹ̀fun dáradára tí a pò mọ́ ìdámẹ́rin hínì òróró tí a yọ lára Olifi.
They must also bring an offering of grain, consisting of two quarts/liters of finely-ground flour, mixed with a quart of [olive] oil.
6 Èyí ni ẹbọ sísun gbogbo ìgbà tí a fi lélẹ̀ ní òkè Sinai gẹ́gẹ́ bí olóòórùn dídùn ẹbọ tí a fi iná sun fún Olúwa pẹ̀lú iná.
That is the offering that they must bring every day. They started to bring those offerings [while you were] at Sinai Mountain. When those offerings are burned [on the altar], the smell will be very pleasing to me.
7 Àfikún ọrẹ ohun mímu rẹ gbọdọ̀ jẹ́ ìdámẹ́rin ti hínì dídé omi mímu tí ó kan pẹ̀lú ọ̀kọ̀ọ̀kan ọ̀dọ́-àgùntàn. Da ẹbọ mímu náà síta sí Olúwa ní ibi mímọ́.
When they burn each lamb, they must also pour on the sacred altar one quart/liter of wine.
8 Pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn kejì ní àfẹ̀mọ́júmọ́, pẹ̀lú oríṣìí ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu èyí tí ó pèsè ní òwúrọ̀, èyí ni ẹbọ tí a fi iná ṣe, olóòórùn dídùn sí Olúwa.
In the evening, when they offer the second lamb, they must also bring the same offerings of grain and wine [as they burned in the morning]. When they are burned, the smell will also be very pleasing to me.”
9 “‘Ní ọjọ́ ìsinmi, pèsè akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kan tí kò lábùkù, pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu àti ẹbọ ohun jíjẹ tí i ṣe ìdá méjì nínú ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun tí a fi òróró pò.
“On each (Sabbath/rest day), [you must bring] two male lambs that have no defects. Also bring a grain offering of four quarts/liters of finely-ground flour mixed with [olive] oil and a wine offering of four quarts/liters of wine.
10 Èyí ni ẹbọ sísun fún gbogbo ọjọ́ ìsinmi kọ̀ọ̀kan, ní àfikún pẹ̀lú ẹbọ sísun àti ẹbọ ohun mímu.
Those are the offerings that are to be burned [on the altar] each (Sabbath/rest day). Those are in addition to the offerings of two lambs and wine that you must bring each day.”
11 “‘Àti ní ọjọ́ tí o bẹ̀rẹ̀ oṣù kọ̀ọ̀kan, kí ẹ̀yin kí ó gbé ẹbọ sísun fún Olúwa pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù méjì, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan, kí gbogbo rẹ̀ sì jẹ́ aláìlábùkù.
“On the first day of each month, you must bring to me an offering of two young bulls, one male sheep, and seven male lambs that are one-year-old. All of these must be without defects. They must all be burned [completely on the altar].
12 Pẹ̀lú akọ màlúù kọ̀ọ̀kan ni kí wọn ó rú ẹbọ ohun jíjẹ ẹbọ ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá ìyẹ̀fun tí a pòpọ̀ pẹ̀lú òróró; pẹ̀lú àgbò, ni kí wọn ó rú ẹbọ ohun jíjẹ tí í ṣe ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun tí a pòpọ̀ mọ́ òróró;
Also bring with each bull an offering of six quarts/liters of finely-ground flour mixed with [olive] oil. With each male sheep make an offering of four quarts of finely-ground flour mixed with [olive] oil.
13 pẹ̀lú ọ̀kọ̀ọ̀kan ọ̀dọ́-àgùntàn, ni kí ẹ rú ẹbọ ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná tí a pò mọ́ òróró. Èyí ni ẹbọ sísun, òórùn dídùn, àti ẹbọ tí a ṣe fún Olúwa pẹ̀lú iná.
Also bring an offering of two quarts/liters of finely-ground flour mixed with [olive] oil with each lamb. When all of these are burned [on the altar], the smell will be very pleasing to me.
14 Kí ẹbọ ohun mímu wọn jẹ́ ààbọ̀ òsùwọ̀n hínì ti ọtí wáìnì, fún akọ màlúù kan, àti ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n hínì fún àgbò kan àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n hínì fún ọ̀dọ́-àgùntàn kan. Èyí ni ẹbọ sísun tí wọn ó máa rú ní oṣù kọ̀ọ̀kan nínú ọdún.
With each bull, also bring two quarts/liters of wine. With each male sheep, bring (1-1/3 quarts/1.2 liters) of wine. With each lamb, bring one quart/liter of wine. These offerings must be brought on the first day of each month and burned completely [on the altar].
15 Yàtọ̀ sí ẹbọ sísun pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu, ẹ gbọdọ̀ fi akọ ewúrẹ́ kọ̀ọ̀kan fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
In addition to these offerings that you burn, you must bring to me one goat for an offering [to enable me to forgive you for the sins you have committed].”
16 “‘Ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní ni ìrékọjá Olúwa gbọdọ̀ wáyé.
“The Passover Festival must be celebrated to [honor] me [each year] on the fourteenth day of the first month [of each year].
17 Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù yìí ẹ gbọdọ̀ ṣiṣẹ́ àjọ̀dún fún ọjọ́ méje kí ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.
The Festival of Unleavened Bread will start on the next day. For the following seven days, the bread that you eat must be made without yeast.
18 Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; ẹ́yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ agbára kankan.
On the first day of that festival, you must gather together to worship me, and you must not do any work.
19 Ẹ rú ẹbọ sísun sí Olúwa, ẹ rú u pẹ̀lú ọ̀dọ́ màlúù méjì akọ, ẹbọ sísun pẹ̀lú iná àgbò kan àti ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan kí wọn kí ó jẹ́ aláìlábùkù.
On that day, you must bring to me for an offering that will be completely burned [on the altar] two young bulls, one male sheep, and seven male lambs that are one-year-old. They must all have no defects.
20 Pẹ̀lú akọ màlúù kọ̀ọ̀kan ni kí ẹ pèsè ẹbọ ohun mímu pẹ̀lú ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi òróró pò; pẹ̀lú àgbò, ìdá méjì nínú mẹ́wàá;
With each of these bulls, bring a grain offering of grain, consisting of six quarts/liters of finely-ground flour mixed with [olive] oil. With the male sheep, bring an offering of grain consisting of four quarts/liters of finely-ground flour mixed with [olive] oil.
21 pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan ìdákan nínú mẹ́wàá.
With each of the seven lambs, bring an offering of two quarts/liters of finely-ground flour mixed with [olive] oil.
22 Pẹ̀lú òbúkọ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣètùtù fún un yín.
Also bring one goat for a sacrifice to cause you to be forgiven for your sin.
23 Ṣe eléyìí ní àfikún sí ẹbọ sísun àràárọ̀.
Bring these offerings in addition to the offerings that you bring each morning.
24 Báyìí ní kí ẹ̀yin rúbọ ní ọjọọjọ́, jálẹ̀ ní ọjọ́ méjèèje, oúnjẹ ẹbọ tí a fi iná ṣe, tí olóòórùn dídùn sí Olúwa; ó rú u pẹ̀lú ẹbọ sísun ìgbà gbogbo, àti ẹbọ ohun mímu.
The smell of the grain that is burned [on the altar] each day for seven days will be very pleasing to me. Bring the grain in addition to the animals and the wine that you burn [on the altar].
25 Ní ọjọ́ keje kí ẹ̀yin kí ó ní àpéjọ mímọ́, ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan.
On the seventh day of that festival, you must [again] gather together to worship me, and you must not do any work.”
26 “‘Ní ọjọ́ àkọ́so pẹ̀lú, nígbà tí ẹ̀yin bá mú ẹbọ ohun jíjẹ tuntun wá fún Olúwa lẹ́yìn àsìkò àjọ̀dún, kí ẹ̀yin kí ó ní àpéjọ mímọ́, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan.
“On the day of the Harvest Festival, when you bring to me the first grain that you have harvested, you must gather together to worship me. Do not do any work on that day.
27 Kí ẹ mú ẹbọ sísun ẹgbọrọ màlúù méjì, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kan gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn fún Olúwa.
Bring to me two young bulls, one male sheep, and seven male lambs that are one-year-old. When they are completely burned [on the altar], the smell will be very pleasing to me.
28 Pẹ̀lú ọ̀kọ̀ọ̀kan akọ màlúù ní kí ẹ rú ẹbọ ohun mímu ìdámẹ́ta pẹ̀lú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi òróró pò pẹ̀lú àgbò kan.
Also bring a grain offering of nice flour mixed with [olive] oil. For each bull, bring six quarts/liters, and with each male sheep, bring four quarts/liters,
29 Àti pẹ̀lú ọ̀kọ̀ọ̀kan ọ̀dọ́-àgùntàn méje, kí ó jẹ́ ìdákan nínú mẹ́wàá.
and with each of the lambs bring two quarts/liters.
30 Ẹ fi òbúkọ kan ṣe ètùtù fún ara yín.
Also sacrifice one male goat to cause you to be forgiven for your sins.
31 Kí ẹ̀yin kí ó rú wọn pẹ̀lú ẹbọ sísun ìgbà gbogbo, àti ẹbọ ohun mímu yín àti ẹbọ ohun jíjẹ yín. Kí ẹ sì ri dájú pé àwọn ẹranko náà jẹ́ aláìlábùkù.
Bring these offerings and the offering of wine in addition to the animals and grain that you burn [on the altar] each day. [And remember that] the animals that you sacrifice must have no defects.”

< Numbers 28 >