< Numbers 27 >

1 Ọmọbìnrin Selofehadi ọmọ Heferi, ọmọ Gileadi, ọmọ Makiri ọmọ Manase tó jẹ́ ìdílé Manase, ọmọ Josẹfu wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Mahila, Noa, Hogla, Milka àti Tirsa.
Tedy przyszły córki Salfaada, syna Heferowego, syna Galaadowego, syna Machyrowego, syna Manasesowego, z pokolenia Manasesa syna Józefowego; a te są imiona córek jego: Machla, Noa i Hegla, i Melcha i Tersa;
2 Wọ́n súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mose, àti Eleasari àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé,
I stanęły przed Mojżeszem i przed Eleazarem kapłanem i przed książęty i wszystkiem zgromadzeniem u drzwi namiotu zgromadzenia, i rzekły:
3 “Baba wa kú sí aginjù. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kora tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, ṣùgbọ́n ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀.
Ojciec nasz umarł na puszczy, a on nie był w poczcie tych, którzy się byli przeciw Panu zbuntowali w spiknieniu Korego; ale dla grzechu swego umarł, nie mając synów.
4 Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítorí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrín àwọn arákùnrin baba wa.”
Czemuż by zginąć miało imię ojca naszego z domu jego, przeto, że nie miał syna? dajcie nam dziedzictwo między bracią ojca naszego.
5 Nígbà náà Mose mú ọ̀rọ̀ wọn wá síwájú Olúwa.
Tedy odniósł Mojżesz sprawę ich do Pana.
6 Olúwa sì wí fún un pé,
I rzekł Pan do Mojżesza:
7 “Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ń sọ tọ̀nà. O gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.
Dobrze mówią córki Salfaadowe: Daj im koniecznie osiadłość dziedzictwa między bracią ojca ich, a przenieś dziedzictwo ojca ich na nie.
8 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.
Synom także Izraelskim powiedz, mówiąc: Gdyby kto umarł, nie mając syna, tedy przeniesiecie dziedzictwo jego na córkę jego.
9 Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
A jeśliby nie miał i córki, tedy dacie dziedzictwo jego braci jego.
10 Tí kò bá ní arákùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.
A jeśliby i braci nie miał, tedy dacie dziedzictwo jego braci ojca jego.
11 Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.’”
A jeśliby nie było braci ojca jego, tedy dacie dziedzictwo jego pokrewnemu jego, najbliższemu jego z domu jego, aby je odziedziczył. A będzie to synom Izraelskim za ustawę prawną, jako rozkazał Pan Mojżeszowi.
12 Nígbà náà Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sì orí òkè Abarimu yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Israẹli.
Potem rzekł Pan do Mojżesza: Wstąp na tę górę Abarym, a oglądaj ziemię, którąm dał synom Izraelskim.
13 Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Aaroni arákùnrin rẹ ṣe ṣe,
A gdy ją oglądasz, przyłączon będziesz do ludu twego i ty, jako jest przyłączony Aaron, brat twój.
14 nítorí nígbà tí ìlú ṣọ̀tẹ̀ níbi omi ní aginjù Sini, tí gbogbo yín ṣe àìgbọ́ràn sí mi láti yà mí sí mímọ́ níwájú wọn.” (Èyí ni omi Meriba ní Kadeṣi ní aginjù Sini.)
Przeto żeście byli odpornymi słowu mojemu na puszczy Syn, przy poswarku zgromadzenia, i nie poświęciliście mię przy wodach przed oczyma ich. Oneć to są wody poswarku w Kades, na puszczy Syn.
15 Mose sọ fún Olúwa wí pé,
Tedy rzekł Mojżesz do Pana, mówiąc:
16 “Jẹ́ kí Olúwa, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, kí ó yan ọkùnrin kan sí orí ìjọ ènìyàn yìí,
Niech opatrzy Pan, Bóg duchów wszelkiego ciała, mężem godnym to zgromadzenie;
17 láti máa darí wọn, ẹni tí yóò mú wọn jáde, tí yóò sì mú wọn wọlé, gbogbo ènìyàn Olúwa kí yóò dàbí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.”
Któryby wychodził przed nimi, i któryby wchodził przed nimi, i któryby je przywodził, aby nie był lud Pański jako owce, nie mające pasterza.
18 Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú Joṣua ọmọ Nuni, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e.
Tedy rzekł Pan do Mojżesza: Weźmij do siebie Jozuego, syna Nunowego, męża, w którym jest Duch mój, a włóż nań rękę swoję;
19 Jẹ́ kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Israẹli kí o sì fi àṣẹ fún un ní ojú wọn.
I postaw go przed Eleazarem kapłanem, i przed wszystkiem zgromadzeniem, a dasz mu naukę przed oczyma ich;
20 Kí ìwọ kí ó sì fi nínú ọláńlá rẹ sí i lára, kí gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kí ó lè gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
A udzielisz mu zacności swej, aby go słuchało wszystko zgromadzenie synów Izraelskich;
21 Kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Urimu níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”
Który przed twarzą Eleazara kapłana stawać będzie, aby się zań radził sądu Urim przed Panem. Na rozkazanie jego wychodzić będą, on, i wszyscy synowie Izraelscy z nim, i wszystko zgromadzenie.
22 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Joṣua ó sì mú kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ.
Uczynił tedy Mojżesz, jako mu był rozkazał Pan; a wziąwszy Jozuego postawił go przed Eleazarem kapłanem, i przed wszystkiem zgromadzeniem.
23 Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
I włożywszy nań ręce swe, dał mu naukę, jako mówił Pan przez Mojżesza.

< Numbers 27 >