< Numbers 27 >

1 Ọmọbìnrin Selofehadi ọmọ Heferi, ọmọ Gileadi, ọmọ Makiri ọmọ Manase tó jẹ́ ìdílé Manase, ọmọ Josẹfu wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Mahila, Noa, Hogla, Milka àti Tirsa.
Men Selofhads døtre - han var sønn av Hefer, Gileads sønn, som igjen var sønn av Makir, Manasses sønn, av Manasses, Josefs sønns ætt, og hans døtre hette Mahla, Noa og Hogla og Milka og Tirsa -
2 Wọ́n súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mose, àti Eleasari àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé,
de gikk frem for Moses og Eleasar, presten, og høvdingene og hele menigheten ved inngangen til sammenkomstens telt og sa:
3 “Baba wa kú sí aginjù. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kora tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, ṣùgbọ́n ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀.
Vår far døde i ørkenen, og han var ikke med i den flokk som satte sig op mot Herren - i Korahs flokk - men han døde for sin egen synds skyld, og han hadde ingen sønner.
4 Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítorí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrín àwọn arákùnrin baba wa.”
Hvorfor skal vår fars navn gå ut av hans ætt, fordi om han ingen sønn hadde? Gi oss eiendom blandt vår fars brødre!
5 Nígbà náà Mose mú ọ̀rọ̀ wọn wá síwájú Olúwa.
Og Moses førte deres sak frem for Herrens åsyn.
6 Olúwa sì wí fún un pé,
Da sa Herren til Moses:
7 “Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ń sọ tọ̀nà. O gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.
Selofhads døtre har rett i det de sier; du skal gi dem eiendom til arv blandt deres fars brødre og la deres fars arv gå over til dem.
8 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.
Og til Israels barn skal du tale således: Når en mann dør, og han ingen sønn har, da skal I la hans arv gå over til hans datter.
9 Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
Og dersom han ingen datter har, så skal I gi hans brødre hans arv.
10 Tí kò bá ní arákùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.
Og dersom han ingen brødre har, så skal I gi hans fars brødre hans arv.
11 Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.’”
Men dersom hans far ingen brødre har, så skal I gi hans arv til den nærmeste frende i ætten; han skal arve den. Dette skal være gjeldende rett blandt Israels barn, således som Herren har befalt Moses.
12 Nígbà náà Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sì orí òkè Abarimu yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Israẹli.
Siden sa Herren til Moses: Stig op på Abarim-fjellet her og se utover landet som jeg har gitt Israels barn!
13 Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Aaroni arákùnrin rẹ ṣe ṣe,
Og når du har sett det, da skal du og samles til dine fedre likesom din bror Aron blev samlet til sine fedre,
14 nítorí nígbà tí ìlú ṣọ̀tẹ̀ níbi omi ní aginjù Sini, tí gbogbo yín ṣe àìgbọ́ràn sí mi láti yà mí sí mímọ́ níwájú wọn.” (Èyí ni omi Meriba ní Kadeṣi ní aginjù Sini.)
fordi I var. gjenstridige mot mitt ord i ørkenen Sin, dengang menigheten kivedes med mig, og I skulde helliget mig ved å la vann strømme frem for deres øine. Det er Meribas vann ved Kades i ørkenen Sin.
15 Mose sọ fún Olúwa wí pé,
Da talte Moses til Herren og sa:
16 “Jẹ́ kí Olúwa, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, kí ó yan ọkùnrin kan sí orí ìjọ ènìyàn yìí,
Herre, du Gud som råder over livsens ånde i alt kjød, vil du ikke sette en mann over menigheten,
17 láti máa darí wọn, ẹni tí yóò mú wọn jáde, tí yóò sì mú wọn wọlé, gbogbo ènìyàn Olúwa kí yóò dàbí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.”
som kan gå ut og inn foran dem, og som kan føre dem ut og føre dem inn, så Herrens menighet ikke skal være som får uten hyrde!
18 Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú Joṣua ọmọ Nuni, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e.
Og Herren sa til Moses: Ta Josva, Nuns sønn. Han er en mann som det er ånd i. Legg din hånd på ham,
19 Jẹ́ kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Israẹli kí o sì fi àṣẹ fún un ní ojú wọn.
og still ham frem for Eleasar, presten, og for hele menigheten og innsett ham i hans tjeneste for deres øine,
20 Kí ìwọ kí ó sì fi nínú ọláńlá rẹ sí i lára, kí gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kí ó lè gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
og legg noget av din verdighet på ham, så hele Israels barns menighet må lyde ham!
21 Kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Urimu níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”
Og han skal stå frem for Eleasar, presten, og Eleasar skal for Herrens åsyn søke urims dom for ham; efter hans ord skal de gå ut, og efter hans ord skal de gå inn, han selv med alle Israels barn og hele menigheten.
22 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Joṣua ó sì mú kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ.
Så gjorde Moses som Herren hadde befalt ham; han tok Josva og stilte ham frem for Eleasar, presten, og for hele menigheten,
23 Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
og han la sine hender på ham og innsatte ham i hans tjeneste, således som Herren hadde talt ved Moses.

< Numbers 27 >