< Numbers 27 >

1 Ọmọbìnrin Selofehadi ọmọ Heferi, ọmọ Gileadi, ọmọ Makiri ọmọ Manase tó jẹ́ ìdílé Manase, ọmọ Josẹfu wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Mahila, Noa, Hogla, Milka àti Tirsa.
Na rĩrĩ, airĩtu acio a Zelofehadi mũrũ wa Heferi mũrũ wa Gileadi, mũrũ wa Makiru, mũrũ wa Manase maarĩ a mbarĩ cia Manase mũrũ wa Jusufu. Marĩĩtwa ma airĩtu acio maarĩ Mahala, na Noa, na Hogila, na Milika, na Tiriza. Nĩmathiire, magĩkuhĩrĩria
2 Wọ́n súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mose, àti Eleasari àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé,
itoonyero rĩa Hema-ya-Gũtũnganwo, makĩrũgama mbere ya Musa, na Eleazaru ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, na mbere ya atongoria, o na kĩũngano gĩothe gĩa Isiraeli, makiuga atĩrĩ,
3 “Baba wa kú sí aginjù. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kora tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, ṣùgbọ́n ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀.
“Ithe witũ aakuĩrĩire werũ-inĩ. Ndaarĩ ũmwe wa arũmĩrĩri a Kora, arĩa manyiitanire mokĩrĩre Jehova, no aakuire nĩ ũndũ wa mehia make mwene na ndaarĩ na aanake.
4 Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítorí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrín àwọn arákùnrin baba wa.”
Nĩ kĩĩ gĩgũtũma rĩĩtwa rĩa awa rĩniinwo mbarĩ-inĩ yao, nĩ ũndũ atĩ ndaarĩ na mwanake? Tũhei igai hamwe na andũ a nyũmba ya ithe witũ.”
5 Nígbà náà Mose mú ọ̀rọ̀ wọn wá síwájú Olúwa.
Nĩ ũndũ ũcio Musa agĩtwarĩra Jehova ũhoro ũcio wao,
6 Olúwa sì wí fún un pé,
nake Jehova akĩmwĩra atĩrĩ,
7 “Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ń sọ tọ̀nà. O gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.
“Ũguo airĩtu a Zelofehadi maroiga nĩ kĩhooto. Ti-itherũ nĩ wega ũmaheanĩrie igai rĩao na andũ a nyũmba ya ithe wao, o narĩo igai rĩa ithe wao ũmahe.
8 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.
“Ĩra andũ a Isiraeli atĩrĩ, ‘Mũndũ angĩkua na ndatige mwana wa kahĩĩ, mwarĩ nĩaheo igai rĩake.
9 Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
Angĩgakorwo atarĩ na mũirĩtu-rĩ, heagai ariũ a nyina igai rĩake.
10 Tí kò bá ní arákùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.
Angĩgakorwo atarĩ na ariũ a nyina-rĩ, heagai ariũ a nyina na ithe igai rĩake.
11 Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.’”
Angĩkorwo ithe ndaarĩ na ariũ a nyina-rĩ, heagai mũndũ wa mbarĩ yao ũrĩa marĩ a igai rĩake, nĩguo rĩtuĩke rĩake. Ũndũ ũcio ũgũtuĩka watho wa kũrũmagĩrĩrwo nĩ andũ a Isiraeli, o ta ũrĩa Jehova aathire Musa.’”
12 Nígbà náà Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sì orí òkè Abarimu yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Israẹli.
Ningĩ Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Ũkĩra wambate kĩrĩma-inĩ gĩkĩ, kũu rũgongo rwa Abarimu, wĩrorere bũrũri ũrĩa heete andũ a Isiraeli.
13 Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Aaroni arákùnrin rẹ ṣe ṣe,
Warĩkia kũwona, we nĩũgũkua o ta ũrĩa Harũni mũrũ wa nyũkwa aakuire, na ũcookanĩrĩrio na andũ anyu,
14 nítorí nígbà tí ìlú ṣọ̀tẹ̀ níbi omi ní aginjù Sini, tí gbogbo yín ṣe àìgbọ́ràn sí mi láti yà mí sí mímọ́ níwájú wọn.” (Èyí ni omi Meriba ní Kadeṣi ní aginjù Sini.)
nĩgũkorwo rĩrĩa kĩrĩndĩ kĩanemeire hau maaĩ-inĩ ma Werũ wa Zini, wee na Harũni inyuĩ eerĩ mũtiathĩkĩire watho wakwa, nĩmwagire kũndĩĩithia nĩguo muonanie atĩ ndĩ mũtheru mbere ya maitho mao.” (Maaĩ macio nĩ marĩa ma Meriba Kadeshi, Werũ-inĩ wa Zini.)
15 Mose sọ fún Olúwa wí pé,
Musa akĩĩra Jehova atĩrĩ,
16 “Jẹ́ kí Olúwa, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, kí ó yan ọkùnrin kan sí orí ìjọ ènìyàn yìí,
“Jehova-Ngai wa maroho ma andũ othe, nĩagĩthuure mũndũ atuĩke mũrori wa kĩrĩndĩ gĩkĩ,
17 láti máa darí wọn, ẹni tí yóò mú wọn jáde, tí yóò sì mú wọn wọlé, gbogbo ènìyàn Olúwa kí yóò dàbí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.”
atwaranage nakĩo gĩkiumagara na gĩkĩinũka, ũrĩa ũrĩgĩtongoragia gĩgĩthiĩ na gĩgĩcooka, nĩguo kĩrĩndĩ gĩkĩ kĩa Jehova gĩtigatuĩke ta ngʼondu itarĩ na mũrĩithi.”
18 Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú Joṣua ọmọ Nuni, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e.
Nĩ ũndũ ũcio Jehova akĩĩra Musa atĩrĩ, “Oya Joshua mũrũ wa Nuni, mũndũ ũrĩ na roho thĩinĩ wake, na ũmũigĩrĩre guoko gwaku.
19 Jẹ́ kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Israẹli kí o sì fi àṣẹ fún un ní ojú wọn.
Mũrũgamie mbere ya Eleazaru ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai, na mbere ya kĩũngano gĩothe ũmũtue mũtongoria wao hau mbere yao.
20 Kí ìwọ kí ó sì fi nínú ọláńlá rẹ sí i lára, kí gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kí ó lè gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
Ũmũhe ũhoti ũmwe waku, nĩgeetha kĩrĩndĩ gĩothe kĩa andũ a Isiraeli kĩmwathĩkagĩre.
21 Kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Urimu níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”
Nake arũgamage mbere ya Eleazaru ũcio mũthĩnjĩri-Ngai, ũrĩa ũrĩmũtuĩragĩria ũhoro na ũndũ wa kũũria Urimu mbere ya Jehova. Rĩrĩa aathana, hamwe na kĩrĩndĩ gĩothe kĩa andũ a Isiraeli makoimagara, ningĩ aathana rĩngĩ makainũka.”
22 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Joṣua ó sì mú kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ.
Musa agĩĩka o ta ũguo Jehova aamwathĩte. Akĩoya Joshua, na akĩmũrũgamia mbere ya Eleazaru ũrĩa mũthĩnjĩri-Ngai o na mbere ya kĩũngano kĩu gĩothe.
23 Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Ningĩ akĩmũigĩrĩra moko make na akĩmũtua mũtongoria wao o ta ũrĩa Jehova aathĩte Musa.

< Numbers 27 >