< Numbers 27 >

1 Ọmọbìnrin Selofehadi ọmọ Heferi, ọmọ Gileadi, ọmọ Makiri ọmọ Manase tó jẹ́ ìdílé Manase, ọmọ Josẹfu wá. Orúkọ àwọn ọmọbìnrin náà ni Mahila, Noa, Hogla, Milka àti Tirsa.
Forsothe the douytris of Salphaat, sone of Epher, sone of Galaad, sone of Machir, sone of Manasses, that was `the sone of Joseph, neiyeden; of whiche douytris these ben the names; Maala, and Noha, and Egla, and Melcha, and Thersa.
2 Wọ́n súnmọ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé wọ́n sì dúró níwájú Mose, àti Eleasari àlùfáà, àti níwájú àwọn olórí àti ìjọ, wọ́n sì wí pé,
And thei stoden bifore Moises, and Eleazar, preest, and alle the princes of the puple, at the dore of tabernacle of boond of pees; and seiden,
3 “Baba wa kú sí aginjù. Kò sí lára àwọn ẹgbẹ́ Kora tí wọ́n kó ara wọn pọ̀ lòdì sí Olúwa, ṣùgbọ́n ó kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kò sì fi ọmọkùnrin sílẹ̀.
Oure fadir was deed in the deseert, nether he was in the rebelte, that was reisid ayens the Lord, vndur Chore, but he was deed in his synne; he hadde no male sones. Whi is `the name of hym takun awei fro his meynee, for he hath no sone? Yif ye possessioun to vs among `the kynesmen of oure fadir.
4 Kín ni ó dé tí orúkọ baba wa yóò parẹ́ nínú ìdílé rẹ̀ nítorí pé kò ní ọmọkùnrin? Fún wa ní ilẹ̀ ìní láàrín àwọn arákùnrin baba wa.”
And Moises telde `the cause of hem to the doom of the Lord;
5 Nígbà náà Mose mú ọ̀rọ̀ wọn wá síwájú Olúwa.
which seide to Moyses, The douytris of Salphaath axen a iust thing; yyue thou possessioun to hem among `the kynnysmen of her fadir,
6 Olúwa sì wí fún un pé,
and be thei successouris to hym in to eritage.
7 “Ohun tí àwọn ọmọbìnrin Selofehadi ń sọ tọ̀nà. O gbọdọ̀ fún wọn ní ogún ìní ti baba wọn.
Forsothe thou schalt speke these thingis to the sons of Israel,
8 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Tí ọkùnrin kan bá kú tí kò sì fi ọmọkùnrin sáyé, ẹ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀.
Whanne a man is deed with out sone, the eritage schal go to his douyter;
9 Tí kò bá ní ọmọbìnrin, fi ohun ìní rẹ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀.
if he hath not a douyter, he schal haue eiris his britheren;
10 Tí kò bá ní arákùnrin, fi ogún ìní rẹ̀ fún arákùnrin baba rẹ̀.
that and if britheren ben not, ye schulen yyue the eritage to `the britheren of his fadir;
11 Tí baba rẹ̀ kò bá ní arákùnrin, fún ará ilé rẹ̀ tí ó bá súnmọ́ jù ní ìdílé rẹ̀ ní ogún ìní rẹ̀, kí ó lè jogún rẹ̀. Èyí gbọdọ̀ jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.’”
forsothe if he hath no britheren of his fadir, the eritage schal be youun to hem that ben next to hym. And this schal be hooli, `that is, stidefast, bi euerlastynge lawe to the sones of Israel, as the Lord comaundide to Moises.
12 Nígbà náà Olúwa sọ fún Mose pé, “Lọ sì orí òkè Abarimu yìí, kí o sì lọ wo ilẹ̀ tí mo fún àwọn ọmọ Israẹli.
Also the Lord seide to Moises, Stie thou in to this hil of Aberym, and biholde thou fro thennus the lond, which Y schal yyue to the sones of Israel.
13 Lẹ́yìn ìgbà tí o bá sì ti rí i, ìwọ náà yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ gẹ́gẹ́ bí Aaroni arákùnrin rẹ ṣe ṣe,
And whanne thou hast seyn it, also thou schalt go to thi puple, as thi brother Aaron yede;
14 nítorí nígbà tí ìlú ṣọ̀tẹ̀ níbi omi ní aginjù Sini, tí gbogbo yín ṣe àìgbọ́ràn sí mi láti yà mí sí mímọ́ níwájú wọn.” (Èyí ni omi Meriba ní Kadeṣi ní aginjù Sini.)
for thou offenddidist me in the deseert of Syn, in the ayen seiyng of the multitude, nether woldist halewe me bifor it, on the watris. These ben the watris of ayen seiyng, in Cades, of the deseert of Syn.
15 Mose sọ fún Olúwa wí pé,
To whom Moises answeryde,
16 “Jẹ́ kí Olúwa, Ọlọ́run ẹ̀mí gbogbo ènìyàn, kí ó yan ọkùnrin kan sí orí ìjọ ènìyàn yìí,
The Lord God of spiritis of al fleisch puruey a man, that be on this multitude,
17 láti máa darí wọn, ẹni tí yóò mú wọn jáde, tí yóò sì mú wọn wọlé, gbogbo ènìyàn Olúwa kí yóò dàbí àgùntàn tí kò ní olùṣọ́.”
and may go out, and entre bifor hem, and lede hem out, and lede hem yn, lest the `puple of the Lord be as scheep with out schepherde.
18 Nígbà náà ní Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú Joṣua ọmọ Nuni, ọkùnrin nínú ẹni tí èmi wà, kí o sì gbé ọwọ́ rẹ lé e.
And the Lord seide to hym, Take thou Josue, the sone of Nun, a man in whom the spyrit of God is, and set thin hond on hym; and he schal stonde bifore Eleazar,
19 Jẹ́ kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti ojú gbogbo àwọn ìjọ ènìyàn Israẹli kí o sì fi àṣẹ fún un ní ojú wọn.
preest, and bifore al the multitude.
20 Kí ìwọ kí ó sì fi nínú ọláńlá rẹ sí i lára, kí gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli kí ó lè gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu.
And thou schalt yyue to hym comaundementis, in the siyt of alle men, and a part of thi glorie, that al the synagoge of the sones of Israel here hym.
21 Kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà, tí yóò gba ìpinnu fún láti béèrè Urimu níwájú Olúwa. Gẹ́gẹ́ bí òfin yìí ni òun pẹ̀lú gbogbo ìjọ ènìyàn Israẹli yóò jáde lọ, pẹ̀lú òfin rẹ̀ sì ni wọn ó wọlé.”
If ony thing schal be worthi to be do for this man, Eleasar, preest, schal counseil the Lord; he schal go out, and schal go yn, at the word of Eleazar; he, and alle the sones of Israel with him, and the tother multitude.
22 Mose sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ fún un. Ó mú Joṣua ó sì mú kí ó dúró níwájú Eleasari àlùfáà àti níwájú gbogbo ìjọ.
Moises dide as the Lord comaundide, and whanne he hadde take Josue, he settide hym bifore Eleazar, preest, and bifore al the multitude of the puple;
23 Nígbà náà ni ó gbé ọwọ́ rẹ̀ le e, ó sì fi àṣẹ fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
and whanne he hadde set hondis on his heed, he reherside alle thingis whiche the Lord comaundide.

< Numbers 27 >