< Numbers 26 >
1 Lẹ́yìn àjàkálẹ̀-ààrùn Olúwa sọ fún Mose àti Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà pé,
Após a peste, Javé falou a Moisés e a Eleazar, filho de Aarão, o sacerdote, dizendo:
2 “Ka iye gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọ́n; láti ẹni ogun ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó lè jà lójú ogun ní Israẹli.”
“Façam um censo de toda a congregação dos filhos de Israel, a partir dos vinte anos de idade, junto às casas de seus pais, todos os que podem sair à guerra em Israel”.
3 Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ ti Moabu pẹ̀lú Jordani tí ó kọjá Jeriko, Mose àti Eleasari àlùfáà sọ̀rọ̀ pẹ̀lú wọn ó wí pé,
Moisés e Eleazar, o sacerdote, falaram com eles nas planícies de Moab, junto ao Jordão em Jericó, dizendo,
4 “Ka iye àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ọmọ-ogun ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.” Èyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó jáde láti Ejibiti wá.
“Façam um censo, a partir de vinte anos, como Javé ordenou a Moisés e aos filhos de Israel”. Estes são aqueles que saíram da terra do Egito.
5 Àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli, láti ẹni ti ìdílé Hanoku, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé Hanoku ti jáde wá, láti ìdílé Pallu, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé àwọn ọmọ Pallu ti jáde wá;
Reuben, o primogênito de Israel; os filhos de Reuben: de Hanoch, a família dos Hanochitas; de Pallu, a família dos Paluítas;
6 ti Hesroni, ìdílé àwọn ọmọ Hesroni; ti Karmi, ìdílé àwọn ọmọ Karmi.
de Hezron, a família dos Hezronitas; de Carmi, a família dos Carmites.
7 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Reubeni; àwọn tí a sì kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀sán ó dín àádọ́rin.
Estas são as famílias dos Rubenitas; e as que foram contadas delas foram quarenta e três mil setecentos e trinta.
8 Àwọn ọmọkùnrin Pallu ni Eliabu,
O filho de Pallu: Eliab.
9 àwọn ọmọkùnrin Elifelehu ni Nemueli àti Eliabu, Datani àti Abiramu. Èyí ni Datani àti Abiramu náà tí wọ́n ní òkìkí nínú ìjọ tí ó jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ sí Mose àti Aaroni tí ó sì wà lára àwọn ẹgbẹ́ Kora nígbà tí wọ́n bá Olúwa jà.
Os filhos de Eliab: Nemuel, Datã, e Abiram. Estes são aqueles Datã e Abirão que foram chamados pela congregação, que se rebelaram contra Moisés e contra Arão na companhia de Coré quando se rebelaram contra Yahweh;
10 Ilẹ̀ sì la ẹnu rẹ̀, ó sì gbé wọn mì pọ̀ pẹ̀lú Kora, nígbà tí ẹgbẹ́ rẹ̀ kú níbi tí iná ti run àwọn àádọ́ta lé nígba ọkùnrin. Tí wọ́n sì di àmì ìkìlọ̀.
e a terra abriu sua boca, e os engoliu junto com Coré quando aquela companhia morreu; na época o fogo devorou duzentos e cinqüenta homens, e eles se tornaram um sinal.
11 Àwọn ọmọ Kora, bí ó ti wù kí ó rí, wọn kò kú.
Notwithstanding, os filhos de Corá não morreram.
12 Àwọn ọmọ ìran Simeoni bí ìdílé wọn: ti Nemueli, ìdílé Nemueli; ti Jamini, ìdílé Jamini; ti Jakini, ìdílé Jakini;
Os filhos de Simeão depois de suas famílias: de Nemuel, a família dos Nemuelitas; de Jamin, a família dos Jaminitas; de Jachin, a família dos Jachinitas;
13 ti Sera, ìdílé Sera; tí Saulu, ìdílé Saulu.
de Zerah, a família dos Zerahitas; de Shaul, a família dos Shaulitas.
14 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Simeoni, ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé igba ọkùnrin.
Estas são as famílias dos Simeonitas, vinte e dois mil e duzentos.
15 Àwọn ọmọ Gadi bí ìdílé wọn: ti Sefoni, ìdílé Sefoni; ti Haggi, ìdílé Haggi; ti Ṣuni, ìdílé Ṣuni;
Os filhos de Gad depois de suas famílias: de Zephon, a família dos zefonitas; de Haggi, a família dos Haggitas; de Shuni, a família dos Shunitas;
16 ti Osni, ìdílé Osni; ti Eri, ìdílé Eri;
de Ozni, a família dos Oznitas; de Eri, a família dos Erites;
17 ti Arodi, ìdílé Arodi; ti Areli, ìdílé Areli.
de Arod, a família dos Aroditas; de Areli, a família dos Arelitas.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gadi tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
Estas são as famílias dos filhos de Gad de acordo com aqueles que foram contados deles, quarenta mil e quinhentos.
19 Àwọn ọmọ Juda ni Eri àti Onani, ṣùgbọ́n Eri àti Onani kú ní ilẹ̀ Kenaani.
Os filhos de Judá: Er e Onan. Er e Onan morreram na terra de Canaã.
20 Àti àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣela, ìdílé Ṣela; ti Peresi, ìdílé Peresi; ti Sera, ìdílé Sera.
Os filhos de Judá depois de suas famílias foram: de Selá, a família dos Shelanitas; de Perez, a família dos Perezitas; de Zerah, a família dos Zerahitas.
21 Àwọn ọmọ Peresi: ti Hesroni, ìdílé Hesroni; ti Hamulu, ìdílé Hamulu.
Os filhos de Perez eram: de Hezron, a família dos Hezronitas; de Hamul, a família dos Hamulitas.
22 Wọ̀nyí ni ìdílé Juda; gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógójì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
Estas são as famílias de Judá, segundo aqueles que foram contados deles, setenta e seis mil e quinhentos.
23 Àwọn ọmọ Isakari gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Tola, ìdílé Tola; ti Pufa, ìdílé Pufa;
Os filhos de Issachar após suas famílias: de Tola, a família dos Tolaítas; de Puvah, a família dos Punitas;
24 ti Jaṣubu, ìdílé Jaṣubu; ti Ṣimroni, ìdílé Ṣimroni.
de Jashub, a família dos Jashubitas; de Shimron, a família dos Shimronitas.
25 Wọ̀nyí ni ìdílé Isakari gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
Estas são as famílias de Issachar de acordo com aqueles que foram contados deles, sessenta e quatro mil e trezentos.
26 Àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Seredi, ìdílé Seredi; ti Eloni, ìdílé Eloni; ti Jaleeli, ìdílé Jaleeli.
Os filhos de Zebulom depois de suas famílias: de Sered, a família dos Sereditas; de Elon, a família dos Elonitas; de Jahleel, a família dos Jahleelitas.
27 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
Estas são as famílias dos zebulunitas de acordo com aqueles que foram contados deles, sessenta mil e quinhentos.
28 Àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; Manase àti Efraimu.
Os filhos de José, depois de suas famílias: Manasseh e Efraim.
29 Àwọn ọmọ Manase: ti Makiri, ìdílé Makiri (Makiri sì bí Gileadi); ti Gileadi, ìdílé àwọn ọmọ Gileadi.
Os filhos de Manassés: de Machir, a família dos Machirites; e Machir tornou-se o pai de Gilead; de Gilead, a família dos Gileaditas.
30 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gileadi: ti Ieseri, ìdílé Ieseri; ti Heleki, ìdílé Heleki
Estes são os filhos de Gilead: de Iezer, a família dos Iezeritas; de Helek, a família dos Helekitas;
31 àti ti Asrieli, ìdílé Asrieli; àti ti Ṣekemu, ìdílé Ṣekemu;
e Asriel, a família dos Asrielitas; e Shechem, a família dos Shechemites;
32 àti Ṣemida, ìdílé àwọn ọmọ Ṣemida; àti ti Heferi, ìdílé àwọn ọmọ Heferi.
e Shemida, a família dos Shemidaitas; e Hepher, a família dos Hepheritas.
33 (Selofehadi ọmọ Heferi kò sì ni ọmọkùnrin, bí kò ṣe ọmọbìnrin; orúkọ àwọn ọmọbìnrin ni Mahila, Noa, àti Hogla, Milka àti Tirsa).
Zelophehad, o filho de Hepher, não tinha filhos, mas filhas: e os nomes das filhas de Zelophehad eram Mahlah, Noé, Hoglah, Milcah, e Tirzah.
34 Wọ̀nyí ni ìdílé Manase tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
Estas são as famílias de Manasseh. Os que foram contados deles eram cinqüenta e dois mil e setecentos.
35 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: láti ọ̀dọ̀ Ṣutelahi, ìdílé àwọn ọmọ Ṣutelahi; ti Bekeri, ìdílé àwọn ọmọ Bekeri; ti Tahani, ìdílé àwọn ọmọ Tahani.
Estes são os filhos de Efraim depois de suas famílias: de Shuthelah, a família dos Shuthelahitas; de Becher, a família dos Becheritas; de Tahan, a família dos Tahanitas.
36 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ṣutelahi: ti Erani, ìdílé àwọn ọmọ Erani.
Estes são os filhos de Shuthelah: de Eran, a família dos Eranitas.
37 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Efraimu, àwọn tí a kà nínú wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
Estas são as famílias dos filhos de Efraim, segundo aqueles que foram contados deles, trinta e dois mil e quinhentos. Estes são os filhos de José, depois de suas famílias.
38 Àwọn ọmọ Benjamini gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn nìyìí: tí Bela, ìdílé àwọn ọmọ Bela; ti Aṣbeli, ìdílé àwọn ọmọ Aṣbeli; ti Ahiramu, ìdílé àwọn ọmọ Ahiramu;
Os filhos de Benjamim depois de suas famílias: de Bela, a família dos Belaítas; de Ashbel, a família dos Ashbelitas; de Ahiram, a família dos Ahiramitas;
39 ti Ṣufamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣufamu; ti Hufamu, ìdílé àwọn ọmọ Hufamu.
de Shephupham, a família dos Shuphamitas; de Hupham, a família dos Huphamitas.
40 Àwọn ọmọ Bela ní ipasẹ̀ Ardi àti Naamani nìyìí: ti Ardi, ìdílé àwọn ọmọ Ardi; ti Naamani, ìdílé àwọn ọmọ Naamani.
Os filhos de Bela eram Ard e Naaman: a família dos Arditas; e de Naaman, a família dos naamitas.
41 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Benjamini; gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; àti àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé ẹgbẹ̀jọ.
Estes são os filhos de Benjamin depois de suas famílias; e os que foram contados deles foram quarenta e cinco mil e seiscentos.
42 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣuhamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu. Wọ̀nyí ni ìdílé Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
Estes são os filhos de Dan depois de suas famílias: de Shuham, a família dos Shuhamitas. Estas são as famílias de Dan, depois de suas famílias.
43 Gbogbo ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu, gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
Todas as famílias dos Shuhamitas, segundo aqueles que foram contados deles, eram sessenta e quatro mil e quatrocentos.
44 Ti àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Imina, ìdílé àwọn ọmọ Imina; ti Iṣfi, ìdílé àwọn ọmọ Iṣfi; ti Beriah, ìdílé àwọn ọmọ Berii.
Os filhos de Asher depois de suas famílias: de Imnah, a família dos imnitas; de Ishvi, a família dos Ishvitas; de Beriah, a família dos beritas.
45 Ti àwọn ọmọ Beriah: ti Heberi, ìdílé àwọn ọmọ Heberi; ti Malkieli, ìdílé àwọn ọmọ Malkieli.
Dos filhos de Beriah: de Heber, a família dos Heberitas; de Malchiel, a família dos Malchielitas.
46 (Orúkọ ọmọ Aṣeri obìnrin nì jẹ́ Sera.)
O nome da filha de Asher era Serah.
47 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
Estas são as famílias dos filhos de Asher de acordo com aqueles que foram contados deles, cinqüenta e três mil e quatrocentos.
48 Ti àwọn ọmọ Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Jasieli, ìdílé àwọn ọmọ Jaseeli: ti Guni, ìdílé àwọn ọmọ Guni;
Os filhos de Naftali depois de suas famílias: de Jahzeel, a família dos Jahzeelitas; de Guni, a família dos Gunitas;
49 ti Jeseri, ìdílé àwọn ọmọ Jeṣeri; ti Ṣillemu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣillemu.
de Jezer, a família dos Jezeritas; de Shillem, a família dos Shillemites.
50 Wọ̀nyí ni ìdílé ti Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé egbèje.
Estas são as famílias de Naftali de acordo com suas famílias; e aqueles que foram contados deles eram quarenta e cinco mil e quatrocentos.
51 Àpapọ̀ iye tí a kà nínú àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé ẹgbẹ̀sán dín làádọ́rin.
Estes são os que foram contados dos filhos de Israel, seiscentos e um mil e setecentos e trinta.
Yahweh falou a Moisés, dizendo:
53 “Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ jẹ́ pínpín fún wọn gẹ́gẹ́ bí ogún wọn gẹ́gẹ́ bí iye orúkọ wọn.
“A estes a terra será dividida para uma herança de acordo com o número de nomes”.
54 Fún àwọn ọ̀pọ̀ ni kí ìwọ ó fún ní ogún ìlú púpọ̀ àti fún àwọn tí ó kéré ni kí ìwọ ó fi kékeré fún, ẹnìkọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ gba ogún ìbí tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí a kọ.
“Quanto mais você der mais herança, e quanto menos você der menos herança. A todos, de acordo com aqueles que foram contados dele, será dada sua herança.
55 Rí dájú pé ilẹ̀ yìí gbọdọ̀ jẹ́ fífi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọn sì ti pọ̀ tó. Gẹ́gẹ́ bí orúkọ ẹ̀yà àwọn baba wọn ni kí wọn kí ó ni í.
Notwithstanding, a terra será dividida por sorteio. De acordo com os nomes das tribos de seus pais, eles herdarão.
56 Olúkúlùkù ogún ìní ni a gbọdọ̀ fi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti pọ̀ tó láàrín ńlá àti kékeré.”
De acordo com o lote, sua herança será dividida entre os mais e os menos”.
57 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Lefi tí a kà nínú wọn gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Gerṣoni, ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni; ti Kohati, ìdílé àwọn ọmọ Kohati; ti Merari, ìdílé àwọn ọmọ Merari.
Estes são aqueles que foram contados dos Levitas depois de suas famílias: de Gershon, a família dos Gershonitas; de Kohath, a família dos Kohathitas; de Merari, a família dos Meraritas.
58 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Lefi; ìdílé àwọn ọmọ Libni, ìdílé àwọn ọmọ Hebroni, ìdílé àwọn ọmọ Mahili, ìdílé àwọn ọmọ Muṣi, ìdílé àwọn ọmọ Kora. (Kohati ni baba Amramu,
Estas são as famílias dos Levi: a família dos Libnitas, a família dos Hebronitas, a família dos Mahlitas, a família dos Mushitas, e a família dos Korahitas. Kohath tornou-se o pai de Amram.
59 orúkọ aya Amramu sì ń jẹ́ Jokebedi, ọmọbìnrin Lefi, tí ìyá rẹ̀ bí fún Lefi ní Ejibiti. Òun sì bí Aaroni, Mose, àti Miriamu arábìnrin wọn fún Amramu.
O nome da esposa de Amram era Jochebed, a filha de Levi, que nasceu a Levi no Egito. Ela deu à luz a Amram Arão e Moisés, e Miriam, sua irmã.
60 Aaroni ni baba Nadabu àti Abihu, Eleasari àti Itamari.
Para Aaron nasceram Nadab e Abihu, Eleazar e Ithamar.
61 Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu kú, nígbà tí wọ́n rú ẹbọ níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n mú iná àjèjì wá.)
Nadab e Abihu morreram quando ofereceram fogo estranho antes de Yahweh.
62 Gbogbo àwọn ọmọkùnrin Lefi láti oṣù kan àti ju bẹ́ẹ̀ lọ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀rún. Wọn kò ka wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli tókù nítorí tí wọ́n kò gba ogún ìní lára wọn.
Os que foram contados entre eles eram vinte e três mil, cada homem de um mês para cima; pois não foram contados entre os filhos de Israel, pois não houve herança dada a eles entre os filhos de Israel.
63 Àwọn wọ̀nyí ni Mose àti Eleasari àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá odò Jordani létí Jeriko.
Estes são os que foram contados por Moisés e Eleazar, o sacerdote, que contavam os filhos de Israel nas planícies de Moabe, junto ao Jordão, em Jericó.
64 Kò sí ẹnìkan nínú àwọn tí Mose àti Aaroni àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní aginjù Sinai.
Mas entre eles não havia um homem que fosse contado por Moisés e Arão, o sacerdote, que contava os filhos de Israel no deserto do Sinai.
65 Nítorí Olúwa ti sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kíkú ni wọn yóò kú sí aginjù, kò sì sí ẹnìkankan nínú wọn tí kò kú àfi Kalebu ọmọ Jefunne, àti Joṣua ọmọ Nuni.
Pois Yahweh havia dito deles: “Certamente morrerão no deserto”. Não sobrou nenhum homem deles, exceto Calebe, filho de Jefoné, e Josué, filho de Freira.