< Numbers 26 >
1 Lẹ́yìn àjàkálẹ̀-ààrùn Olúwa sọ fún Mose àti Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà pé,
And it was after the plague. And he said Yahweh to Moses and to Eleazar [the] son of Aaron the priest saying.
2 “Ka iye gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọ́n; láti ẹni ogun ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó lè jà lójú ogun ní Israẹli.”
Lift up [the] head of - all [the] congregation of [the] people of Israel from a son of twenty year[s] and up-wards to [the] house of ancestors their every [one who] goes forth warfare in Israel.
3 Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ ti Moabu pẹ̀lú Jordani tí ó kọjá Jeriko, Mose àti Eleasari àlùfáà sọ̀rọ̀ pẹ̀lú wọn ó wí pé,
And he spoke Moses and Eleazar the priest with them in [the] plains of Moab at [the] Jordan of Jericho saying.
4 “Ka iye àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ọmọ-ogun ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.” Èyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó jáde láti Ejibiti wá.
From a son of twenty year[s] and up-wards just as he commanded Yahweh Moses and [the] people of Israel who came out from [the] land of Egypt.
5 Àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli, láti ẹni ti ìdílé Hanoku, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé Hanoku ti jáde wá, láti ìdílé Pallu, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé àwọn ọmọ Pallu ti jáde wá;
Reuben [the] firstborn of Israel [the] descendants of Reuben Hanoch [the] clan of the Hanochite[s] of Pallu [the] clan of the Palluite[s].
6 ti Hesroni, ìdílé àwọn ọmọ Hesroni; ti Karmi, ìdílé àwọn ọmọ Karmi.
Of Hezron [the] clan of the Hezronite[s] of Carmi [the] clan of the Carmite[s].
7 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Reubeni; àwọn tí a sì kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀sán ó dín àádọ́rin.
These [were] [the] clans of the Reubenite[s] and they were enrolled [men] their three and forty thousand and seven hundred and thirty.
8 Àwọn ọmọkùnrin Pallu ni Eliabu,
And [the] sons of Pallu Eliab.
9 àwọn ọmọkùnrin Elifelehu ni Nemueli àti Eliabu, Datani àti Abiramu. Èyí ni Datani àti Abiramu náà tí wọ́n ní òkìkí nínú ìjọ tí ó jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ sí Mose àti Aaroni tí ó sì wà lára àwọn ẹgbẹ́ Kora nígbà tí wọ́n bá Olúwa jà.
And [the] sons of Eliab Nemuel and Dathan and Abiram that [was the] Dathan and Abiram ([the] [people] called of *Q(K)*) the congregation who they struggled on Moses and on Aaron in [the] company of Korah when struggled they on Yahweh.
10 Ilẹ̀ sì la ẹnu rẹ̀, ó sì gbé wọn mì pọ̀ pẹ̀lú Kora, nígbà tí ẹgbẹ́ rẹ̀ kú níbi tí iná ti run àwọn àádọ́ta lé nígba ọkùnrin. Tí wọ́n sì di àmì ìkìlọ̀.
And it opened the earth mouth its and it swallowed them and Korah when died the company when consumed the fire fifty and two hundred man and they became a warning sign.
11 Àwọn ọmọ Kora, bí ó ti wù kí ó rí, wọn kò kú.
And [the] sons of Korah not they died.
12 Àwọn ọmọ ìran Simeoni bí ìdílé wọn: ti Nemueli, ìdílé Nemueli; ti Jamini, ìdílé Jamini; ti Jakini, ìdílé Jakini;
[the] descendants of Simeon to clans their of Nemuel [the] clan of the Nemuelite[s] of Jamin [the] clan of the Jaminite[s] of Jakin [the] clan of the Jakinite[s].
13 ti Sera, ìdílé Sera; tí Saulu, ìdílé Saulu.
Of Zerah [the] clan of the Zerahite[s] of Shaul [the] clan of the Shaulite[s].
14 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Simeoni, ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé igba ọkùnrin.
These [were] [the] clans of the Simeonite[s] two and twenty thousand and two hundred.
15 Àwọn ọmọ Gadi bí ìdílé wọn: ti Sefoni, ìdílé Sefoni; ti Haggi, ìdílé Haggi; ti Ṣuni, ìdílé Ṣuni;
[the] descendants of Gad to clans their of Zephon [the] clan of the Zephonite[s] of Haggi [the] clan of the Haggite[s] of Shuni [the] clan of the Shunite[s].
16 ti Osni, ìdílé Osni; ti Eri, ìdílé Eri;
Of Ozni [the] clan of the Oznite[s] of Eri [the] clan of the Erite[s].
17 ti Arodi, ìdílé Arodi; ti Areli, ìdílé Areli.
Of Arod [the] clan of the Arodite[s] of Areli [the] clan of the Arelite[s].
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gadi tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
These [were] [the] clans of [the] descendants of Gad to enrolled [men] their forty thousand and five hundred.
19 Àwọn ọmọ Juda ni Eri àti Onani, ṣùgbọ́n Eri àti Onani kú ní ilẹ̀ Kenaani.
[the] sons of Judah [were] Er and Onan and he died Er and Onan in [the] land of Canaan.
20 Àti àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣela, ìdílé Ṣela; ti Peresi, ìdílé Peresi; ti Sera, ìdílé Sera.
And they were [the] descendants of Judah to clans their of Shelah [the] clan of the Shelahite[s] of Perez [the] clan of the Perezite[s] of Zerah [the] clan of the Zerahite[s].
21 Àwọn ọmọ Peresi: ti Hesroni, ìdílé Hesroni; ti Hamulu, ìdílé Hamulu.
And they were [the] descendants of Perez of Hezron [the] clan of the Hezronite[s] of Hamul [the] clan of the Hamulite[s].
22 Wọ̀nyí ni ìdílé Juda; gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógójì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
These [were] [the] clans of Judah to enrolled [men] their six and seventy thousand and five hundred.
23 Àwọn ọmọ Isakari gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Tola, ìdílé Tola; ti Pufa, ìdílé Pufa;
[the] descendants of Issachar to clans their Tola [the] clan of the Tolaite[s] of Puah [the] clan of the Punite[s].
24 ti Jaṣubu, ìdílé Jaṣubu; ti Ṣimroni, ìdílé Ṣimroni.
Of Jashub [the] clan of the Jashubite[s] of Shimron [the] clan of the Shimronite[s].
25 Wọ̀nyí ni ìdílé Isakari gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
These [were] [the] clans of Issachar to enrolled [men] their four and sixty thousand and three hundred.
26 Àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Seredi, ìdílé Seredi; ti Eloni, ìdílé Eloni; ti Jaleeli, ìdílé Jaleeli.
[the] descendants of Zebulun to clans their of Sered [the] clan of the Sardite[s] of Elon [the] clan of the Elonite[s] of Jahleel [the] clan of the Jahleelite[s].
27 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
These [were] [the] clans of the Zebulunite[s] to enrolled [men] their sixty thousand and five hundred.
28 Àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; Manase àti Efraimu.
[the] sons of Joseph to clans their Manasseh and Ephraim.
29 Àwọn ọmọ Manase: ti Makiri, ìdílé Makiri (Makiri sì bí Gileadi); ti Gileadi, ìdílé àwọn ọmọ Gileadi.
[the] descendants of Manasseh of Makir [the] clan of the Makirite[s] and Makir he fathered Gilead of Gilead [the] clan of the Gileadite[s].
30 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gileadi: ti Ieseri, ìdílé Ieseri; ti Heleki, ìdílé Heleki
These [were] [the] descendants of Gilead Iezer [the] clan of the Iezerite[s] of Helek [the] clan of the Helekite[s].
31 àti ti Asrieli, ìdílé Asrieli; àti ti Ṣekemu, ìdílé Ṣekemu;
And Asriel [the] clan of the Asrielite[s] and Shechem [the] clan of the Shechemite[s].
32 àti Ṣemida, ìdílé àwọn ọmọ Ṣemida; àti ti Heferi, ìdílé àwọn ọmọ Heferi.
And Shemida [the] clan of the Shemidaite[s] and Hepher [the] clan of the Hepherite[s].
33 (Selofehadi ọmọ Heferi kò sì ni ọmọkùnrin, bí kò ṣe ọmọbìnrin; orúkọ àwọn ọmọbìnrin ni Mahila, Noa, àti Hogla, Milka àti Tirsa).
And Zelophehad [the] son of Hepher not they belonged to him sons that except daughters and [the] name of [the] daughters of Zelophehad [was] Mahlah and Noah Hoglah Milcah and Tirzah.
34 Wọ̀nyí ni ìdílé Manase tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
These [were] [the] clans of Manasseh and enrolled [men] their [were] two and fifty thousand and seven hundred.
35 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: láti ọ̀dọ̀ Ṣutelahi, ìdílé àwọn ọmọ Ṣutelahi; ti Bekeri, ìdílé àwọn ọmọ Bekeri; ti Tahani, ìdílé àwọn ọmọ Tahani.
These [were] [the] descendants of Ephraim to clans their of Shuthelah [the] clan of the Shuthelahite[s] of Beker [the] clan of the Bakrite[s] of Tahan [the] clan of the Tahanite[s].
36 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ṣutelahi: ti Erani, ìdílé àwọn ọmọ Erani.
And these [were] [the] descendants of Shuthelah of Eran [the] clan of the Eranite[s].
37 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Efraimu, àwọn tí a kà nínú wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
These [were] [the] clans of [the] descendants of Ephraim to enrolled [men] their two and thirty thousand and five hundred these [were] [the] descendants of Joseph to clans their.
38 Àwọn ọmọ Benjamini gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn nìyìí: tí Bela, ìdílé àwọn ọmọ Bela; ti Aṣbeli, ìdílé àwọn ọmọ Aṣbeli; ti Ahiramu, ìdílé àwọn ọmọ Ahiramu;
[the] descendants of Benjamin to clans their of Bela [the] clan of the Belaite[s] of Ashbel [the] clan of the Ashbelite[s] of Ahiram [the] clan of the Ahiramite[s].
39 ti Ṣufamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣufamu; ti Hufamu, ìdílé àwọn ọmọ Hufamu.
Of Shupham [the] clan of the Shuphamite[s] of Hupham [the] clan of the Huphamite[s].
40 Àwọn ọmọ Bela ní ipasẹ̀ Ardi àti Naamani nìyìí: ti Ardi, ìdílé àwọn ọmọ Ardi; ti Naamani, ìdílé àwọn ọmọ Naamani.
And they were [the] descendants of Bela Ard and Naaman (to Ard *X*) [the] clan of the Ardite[s] to Naaman [the] clan of the Naamanite[s].
41 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Benjamini; gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; àti àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé ẹgbẹ̀jọ.
These [were] [the] descendants of Benjamin to clans their and enrolled [men] their [were] five and forty thousand and six hundred.
42 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣuhamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu. Wọ̀nyí ni ìdílé Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
These [were] [the] descendants of Dan to clans their of Shuham [the] clan of the Shuhamite[s] these [were] [the] clans of Dan to clans their.
43 Gbogbo ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu, gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
All [the] clans of the Shuhamite[s] to enrolled [men] their [were] four and sixty thousand and four hundred.
44 Ti àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Imina, ìdílé àwọn ọmọ Imina; ti Iṣfi, ìdílé àwọn ọmọ Iṣfi; ti Beriah, ìdílé àwọn ọmọ Berii.
[the] descendants of Asher to clans their of Imnah [the] clan of the Imnahite[s] of Ishvi [the] clan of the Ishvite[s] of Beriah [the] clan of the Beriahite[s].
45 Ti àwọn ọmọ Beriah: ti Heberi, ìdílé àwọn ọmọ Heberi; ti Malkieli, ìdílé àwọn ọmọ Malkieli.
Of [the] descendants of Beriah of Heber [the] clan of the Heberite[s] of Malkiel [the] clan of the Malchielite[s].
46 (Orúkọ ọmọ Aṣeri obìnrin nì jẹ́ Sera.)
And [the] name of [the] daughter of Asher [was] Serah.
47 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
These [were] [the] clans of [the] descendants of Asher to enrolled [men] their three and fifty thousand and four hundred.
48 Ti àwọn ọmọ Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Jasieli, ìdílé àwọn ọmọ Jaseeli: ti Guni, ìdílé àwọn ọmọ Guni;
[the] descendants of Naphtali to clans their of Jahzeel [the] clan of the Jahzeelite[s] of Guni [the] clan of the Gunite[s].
49 ti Jeseri, ìdílé àwọn ọmọ Jeṣeri; ti Ṣillemu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣillemu.
Of Jezer [the] clan of the Jezerite[s] of Shillem [the] clan of the Shillemite[s].
50 Wọ̀nyí ni ìdílé ti Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé egbèje.
These [were] [the] clans of Naphtali to clans their and enrolled [men] their [were] five and forty thousand and four hundred.
51 Àpapọ̀ iye tí a kà nínú àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé ẹgbẹ̀sán dín làádọ́rin.
These [were] [the] enrolled [men] of [the] people of Israel six hundred thousand and one thousand seven hundred and thirty.
And he spoke Yahweh to Moses saying.
53 “Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ jẹ́ pínpín fún wọn gẹ́gẹ́ bí ogún wọn gẹ́gẹ́ bí iye orúkọ wọn.
To these it will be divided the land an inheritance by [the] number of names.
54 Fún àwọn ọ̀pọ̀ ni kí ìwọ ó fún ní ogún ìlú púpọ̀ àti fún àwọn tí ó kéré ni kí ìwọ ó fi kékeré fún, ẹnìkọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ gba ogún ìbí tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí a kọ.
For the many you will make great inheritance its and for the few you will make small inheritance its each to [the] mouth of enrolled [men] his it will be given inheritance its.
55 Rí dájú pé ilẹ̀ yìí gbọdọ̀ jẹ́ fífi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọn sì ti pọ̀ tó. Gẹ́gẹ́ bí orúkọ ẹ̀yà àwọn baba wọn ni kí wọn kí ó ni í.
Only by lot it will be divided the land to [the] names of [the] tribes of ancestors their they will inherit.
56 Olúkúlùkù ogún ìní ni a gbọdọ̀ fi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti pọ̀ tó láàrín ńlá àti kékeré.”
On [the] mouth of the lot it will be divided inheritance its between [the] many and [the] few.
57 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Lefi tí a kà nínú wọn gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Gerṣoni, ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni; ti Kohati, ìdílé àwọn ọmọ Kohati; ti Merari, ìdílé àwọn ọmọ Merari.
And these [were] [the] enrolled [men] of the Levite[s] to clans their of Gershon [the] clan of the Gershonite[s] of Kohath [the] clan of the Kohathite[s] of Merari [the] clan of the Merarite[s].
58 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Lefi; ìdílé àwọn ọmọ Libni, ìdílé àwọn ọmọ Hebroni, ìdílé àwọn ọmọ Mahili, ìdílé àwọn ọmọ Muṣi, ìdílé àwọn ọmọ Kora. (Kohati ni baba Amramu,
These - [were] [the] clans of Levi [the] clan of the Libnite[s] [the] clan of the Hebronite[s] [the] clan of the Mahlite[s] [the] clan of the Mushite[s] [the] clan of the Korahite[s] and Kohath he fathered Amram.
59 orúkọ aya Amramu sì ń jẹ́ Jokebedi, ọmọbìnrin Lefi, tí ìyá rẹ̀ bí fún Lefi ní Ejibiti. Òun sì bí Aaroni, Mose, àti Miriamu arábìnrin wọn fún Amramu.
And [the] name of - [the] wife of Amram [was] Jochebed [the] daughter of Levi whom someone bore her to Levi in Egypt and she bore to Amram Aaron and Moses and Miriam sister their.
60 Aaroni ni baba Nadabu àti Abihu, Eleasari àti Itamari.
And it was born to Aaron Nadab and Abihu Eleazar and Ithamar.
61 Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu kú, nígbà tí wọ́n rú ẹbọ níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n mú iná àjèjì wá.)
And he died Nadab and Abihu when brought near they fire strange before Yahweh.
62 Gbogbo àwọn ọmọkùnrin Lefi láti oṣù kan àti ju bẹ́ẹ̀ lọ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀rún. Wọn kò ka wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli tókù nítorí tí wọ́n kò gba ogún ìní lára wọn.
And they were enrolled [men] their three and twenty thousand every male from a son of a month and up-wards for - not they were enrolled in among [the] people of Israel for not it was given to them an inheritance in among [the] people of Israel.
63 Àwọn wọ̀nyí ni Mose àti Eleasari àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá odò Jordani létí Jeriko.
These [were] [the] enrolled [men] of Moses and Eleazar the priest who they enrolled [the] people of Israel in [the] plains of Moab at [the] Jordan of Jericho.
64 Kò sí ẹnìkan nínú àwọn tí Mose àti Aaroni àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní aginjù Sinai.
And among these not he was anyone from [the] enrolled [men] of Moses and Aaron the priest who they had enrolled [the] people of Israel in [the] wilderness of Sinai.
65 Nítorí Olúwa ti sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kíkú ni wọn yóò kú sí aginjù, kò sì sí ẹnìkankan nínú wọn tí kò kú àfi Kalebu ọmọ Jefunne, àti Joṣua ọmọ Nuni.
For he had said Yahweh of them certainly they will die in the wilderness and not he was left of them anyone that except Caleb [the] son of Jephunneh and Joshua [the] son of Nun.