< Numbers 26 >
1 Lẹ́yìn àjàkálẹ̀-ààrùn Olúwa sọ fún Mose àti Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà pé,
After the blood of the guilty was shed, the Lord said to Moses, and to Eleazar the son of Aaron the priest:
2 “Ka iye gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọ́n; láti ẹni ogun ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó lè jà lójú ogun ní Israẹli.”
“Number the entire sum of the sons of Israel, from twenty years and above, by their houses and kinships, all who are able to go forth to war.”
3 Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ ti Moabu pẹ̀lú Jordani tí ó kọjá Jeriko, Mose àti Eleasari àlùfáà sọ̀rọ̀ pẹ̀lú wọn ó wí pé,
And so, Moses and Eleazar the priest, who were in the plains of Moab, above the Jordan, opposite Jericho, spoke to those who were
4 “Ka iye àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ọmọ-ogun ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.” Èyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó jáde láti Ejibiti wá.
from twenty years and above, just as the Lord had commanded. And this is their number:
5 Àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli, láti ẹni ti ìdílé Hanoku, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé Hanoku ti jáde wá, láti ìdílé Pallu, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé àwọn ọmọ Pallu ti jáde wá;
Ruben, the firstborn of Israel; his son, Hanoch, from whom is the family of the Hanochites; and Pallu, from whom is the family of the Palluites;
6 ti Hesroni, ìdílé àwọn ọmọ Hesroni; ti Karmi, ìdílé àwọn ọmọ Karmi.
and Hezron, from whom is the family of the Hezronites; and Carmi, from whom is the family of the Carmites.
7 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Reubeni; àwọn tí a sì kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀sán ó dín àádọ́rin.
These are the families of the stock of Ruben, whose number was found to be forty-three thousand and seven hundred thirty.
8 Àwọn ọmọkùnrin Pallu ni Eliabu,
The son of Phallu: Eliab;
9 àwọn ọmọkùnrin Elifelehu ni Nemueli àti Eliabu, Datani àti Abiramu. Èyí ni Datani àti Abiramu náà tí wọ́n ní òkìkí nínú ìjọ tí ó jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ sí Mose àti Aaroni tí ó sì wà lára àwọn ẹgbẹ́ Kora nígbà tí wọ́n bá Olúwa jà.
his sons, Nemuel and Dathan and Abiram. These are Dathan and Abiram, the leaders of the people, who rose up against Moses and Aaron in the sedition at Korah, when they rebelled against the Lord.
10 Ilẹ̀ sì la ẹnu rẹ̀, ó sì gbé wọn mì pọ̀ pẹ̀lú Kora, nígbà tí ẹgbẹ́ rẹ̀ kú níbi tí iná ti run àwọn àádọ́ta lé nígba ọkùnrin. Tí wọ́n sì di àmì ìkìlọ̀.
And the earth, opening its mouth, devoured Korah, with many others dying, when the fire burned two hundred fifty men. And a great miracle was wrought,
11 Àwọn ọmọ Kora, bí ó ti wù kí ó rí, wọn kò kú.
so that, when Korah perished, his sons did not perish.
12 Àwọn ọmọ ìran Simeoni bí ìdílé wọn: ti Nemueli, ìdílé Nemueli; ti Jamini, ìdílé Jamini; ti Jakini, ìdílé Jakini;
The sons of Simeon, by their kinships: Nemuel, from him is the family of the Nemuelites; Jamin, from him is the family of the Jaminites; Jachin, from him is the family of the Jachinites;
13 ti Sera, ìdílé Sera; tí Saulu, ìdílé Saulu.
Sohar, from him is the family of the Soharites; Shaul, from him is the family of the Shaulites.
14 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Simeoni, ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé igba ọkùnrin.
These are the families of the stock of Simeon, whose entire number was twenty-two thousand two hundred.
15 Àwọn ọmọ Gadi bí ìdílé wọn: ti Sefoni, ìdílé Sefoni; ti Haggi, ìdílé Haggi; ti Ṣuni, ìdílé Ṣuni;
The sons of Gad, by their kinships: Zephon, from him is the family of the Zephonites; Haggi, from him is the family of the Haggites; Shuni, from him is the family of the Shunites;
16 ti Osni, ìdílé Osni; ti Eri, ìdílé Eri;
Ozni, from him is the family of the Oznites; Eri, from him is the family of the Erites;
17 ti Arodi, ìdílé Arodi; ti Areli, ìdílé Areli.
Arod, from him is the family of the Arodites; Areli, from him is the family of the Arelites.
18 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gadi tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
These are the families of Gad, whose entire number was forty thousand five hundred.
19 Àwọn ọmọ Juda ni Eri àti Onani, ṣùgbọ́n Eri àti Onani kú ní ilẹ̀ Kenaani.
The sons of Judah: Er and Onan, who both died in the land of Canaan.
20 Àti àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣela, ìdílé Ṣela; ti Peresi, ìdílé Peresi; ti Sera, ìdílé Sera.
And these were the sons of Judah, by their kinships: Shelah, from whom is the family of the Shelahites; Perez, from whom is the family of the Perezites; Zerah, from whom is the family of the Zerahites.
21 Àwọn ọmọ Peresi: ti Hesroni, ìdílé Hesroni; ti Hamulu, ìdílé Hamulu.
Moreover, the sons of Phares were: Hezron, from whom is the family of the Hezronites; and Hamul, from whom is the family of the Hamulites.
22 Wọ̀nyí ni ìdílé Juda; gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógójì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
These are the families of Judah, whose entire number was seventy-six thousand five hundred.
23 Àwọn ọmọ Isakari gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Tola, ìdílé Tola; ti Pufa, ìdílé Pufa;
The sons of Issachar, by their kinships: Tola from whom is the family of the Tolaites; Puvah, from whom is the family of the Puvahites;
24 ti Jaṣubu, ìdílé Jaṣubu; ti Ṣimroni, ìdílé Ṣimroni.
Jashub, from whom is the family of the Jashubites; Shimron, from whom is the family of the Shimronites.
25 Wọ̀nyí ni ìdílé Isakari gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
These are the kinships of Issachar, whose number was sixty-four thousand three hundred.
26 Àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Seredi, ìdílé Seredi; ti Eloni, ìdílé Eloni; ti Jaleeli, ìdílé Jaleeli.
The sons of Zebulon by their kinships: Sered, from whom is the family of the Seredites; Elon, from whom is the family of the Elonites; Jahleel, from whom is the family of the Jahleelites.
27 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
These are the kinships of Zebulun, whose number was sixty thousand five hundred.
28 Àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; Manase àti Efraimu.
The sons of Joseph by their kinships: Manasseh and Ephraim.
29 Àwọn ọmọ Manase: ti Makiri, ìdílé Makiri (Makiri sì bí Gileadi); ti Gileadi, ìdílé àwọn ọmọ Gileadi.
From Manasseh was born Machir, from whom is the family of the Machirites. Machir conceived Gilead, from whom is the family of the Gileadites.
30 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gileadi: ti Ieseri, ìdílé Ieseri; ti Heleki, ìdílé Heleki
Gilead had sons: Jezer, from whom is the family of the Jezerites; and Helek, from whom is the family of the Helekites;
31 àti ti Asrieli, ìdílé Asrieli; àti ti Ṣekemu, ìdílé Ṣekemu;
and Asriel, from whom is the family of the Asrielites; and Shechem, from whom is the family of the Shechemites;
32 àti Ṣemida, ìdílé àwọn ọmọ Ṣemida; àti ti Heferi, ìdílé àwọn ọmọ Heferi.
and Shemida, from whom is the family of the Shemidaites; and Hepher, from whom is the family of the Hepherites.
33 (Selofehadi ọmọ Heferi kò sì ni ọmọkùnrin, bí kò ṣe ọmọbìnrin; orúkọ àwọn ọmọbìnrin ni Mahila, Noa, àti Hogla, Milka àti Tirsa).
Now Hepher was the father of Zelophehad, who had no sons, but only daughters, whose names are these: Mahlah, and Noa, and Hoglah, and Milcah, and Tirzah.
34 Wọ̀nyí ni ìdílé Manase tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
These are the families of Manasseh, and their number was fifty-two thousand seven hundred.
35 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: láti ọ̀dọ̀ Ṣutelahi, ìdílé àwọn ọmọ Ṣutelahi; ti Bekeri, ìdílé àwọn ọmọ Bekeri; ti Tahani, ìdílé àwọn ọmọ Tahani.
Now the sons of Ephraim by their kinships were these: Shuthelah, from whom is the family of the Shuthelahites; Becher, from whom is the family of the Becherites; Tahan, from whom is the family of the Tahanites.
36 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ṣutelahi: ti Erani, ìdílé àwọn ọmọ Erani.
Furthermore, the son of Shuthelah was Eran, from whom is the family of the Eranites.
37 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Efraimu, àwọn tí a kà nínú wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
These are the kinships of the sons of Ephraim, whose number was thirty-two thousand five hundred.
38 Àwọn ọmọ Benjamini gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn nìyìí: tí Bela, ìdílé àwọn ọmọ Bela; ti Aṣbeli, ìdílé àwọn ọmọ Aṣbeli; ti Ahiramu, ìdílé àwọn ọmọ Ahiramu;
These are the sons of Joseph by their families: the sons of Benjamin in their kinships: Bela, from whom is the family of the Belaites; Ashbel, from whom is the family of the Ashbelites; Ahiram, from whom is the family of the Ahiramites;
39 ti Ṣufamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣufamu; ti Hufamu, ìdílé àwọn ọmọ Hufamu.
Shupham, from whom is the family of the Shuphamites; Hupham, from whom is the family of the Huphamites.
40 Àwọn ọmọ Bela ní ipasẹ̀ Ardi àti Naamani nìyìí: ti Ardi, ìdílé àwọn ọmọ Ardi; ti Naamani, ìdílé àwọn ọmọ Naamani.
The sons of Bela: Arad and Naaman. From Arad, the family of the Aradites; from Naaman, the family of the Naamanites.
41 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Benjamini; gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; àti àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé ẹgbẹ̀jọ.
These are the sons of Benjamin by their kinships, whose number was forty-five thousand six hundred.
42 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣuhamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu. Wọ̀nyí ni ìdílé Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
The sons of Dan by their kinships: Shuham, from whom is the family of the Shuhamites. These are the kinships of Dan by their families.
43 Gbogbo ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu, gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
All these were Shuhamites, whose number was sixty-four thousand four hundred.
44 Ti àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Imina, ìdílé àwọn ọmọ Imina; ti Iṣfi, ìdílé àwọn ọmọ Iṣfi; ti Beriah, ìdílé àwọn ọmọ Berii.
The sons of Asher by their kinships: Imnah, from whom is the family of the Imnahites; Ishvi, from whom is the family of the Ishvites; Beriah, from whom is the family of the Beriahites.
45 Ti àwọn ọmọ Beriah: ti Heberi, ìdílé àwọn ọmọ Heberi; ti Malkieli, ìdílé àwọn ọmọ Malkieli.
The sons of Beriah: Heber, from whom is the family of the Heberites; and Malchiel, from whom is the family of the Malchielites.
46 (Orúkọ ọmọ Aṣeri obìnrin nì jẹ́ Sera.)
Now the name of the daughter of Asher was Serah.
47 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
These are the kinships of the sons of Asher, and their number was fifty-three thousand four hundred.
48 Ti àwọn ọmọ Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Jasieli, ìdílé àwọn ọmọ Jaseeli: ti Guni, ìdílé àwọn ọmọ Guni;
The sons of Naphtali by their kinships: Jahzeel, from whom is the family of the Jahzeelites; Guni, from whom is the family of the Gunites;
49 ti Jeseri, ìdílé àwọn ọmọ Jeṣeri; ti Ṣillemu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣillemu.
Jezer, from whom is the family of the Jezerites; Shillem, from whom is the family of the Shillemites.
50 Wọ̀nyí ni ìdílé ti Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé egbèje.
These are the kinships of the sons of Naphtali by their families, whose number was forty-five thousand four hundred.
51 Àpapọ̀ iye tí a kà nínú àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé ẹgbẹ̀sán dín làádọ́rin.
This is the sum of the sons of Israel, who were counted: six hundred thousand and one thousand seven hundred thirty.
And the Lord spoke to Moses, saying:
53 “Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ jẹ́ pínpín fún wọn gẹ́gẹ́ bí ogún wọn gẹ́gẹ́ bí iye orúkọ wọn.
“The land shall be divided to these, as their possessions, according to the number of their names.
54 Fún àwọn ọ̀pọ̀ ni kí ìwọ ó fún ní ogún ìlú púpọ̀ àti fún àwọn tí ó kéré ni kí ìwọ ó fi kékeré fún, ẹnìkọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ gba ogún ìbí tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí a kọ.
To the greater number you shall give a greater portion, and to the lesser number, a lesser portion. To each one, just as they have now been counted, a possession shall be delivered.
55 Rí dájú pé ilẹ̀ yìí gbọdọ̀ jẹ́ fífi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọn sì ti pọ̀ tó. Gẹ́gẹ́ bí orúkọ ẹ̀yà àwọn baba wọn ni kí wọn kí ó ni í.
Yet only in so far as the land is divided by lot to a tribe and to families.
56 Olúkúlùkù ogún ìní ni a gbọdọ̀ fi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti pọ̀ tó láàrín ńlá àti kékeré.”
Whatever the lot will happen to be, it shall be accepted, either by the greater, or by the lesser.
57 Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Lefi tí a kà nínú wọn gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Gerṣoni, ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni; ti Kohati, ìdílé àwọn ọmọ Kohati; ti Merari, ìdílé àwọn ọmọ Merari.
Likewise, this is the number of the sons of Levi by their families: Gershon, from whom is the family of the Gershonites; Kohath, from whom is the family of the Kohathites; Merari, from whom is the family of the Merarites.
58 Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Lefi; ìdílé àwọn ọmọ Libni, ìdílé àwọn ọmọ Hebroni, ìdílé àwọn ọmọ Mahili, ìdílé àwọn ọmọ Muṣi, ìdílé àwọn ọmọ Kora. (Kohati ni baba Amramu,
These are the families of Levi: The family of Libni, the family of Hebroni, the family of Mahli, the family of Mushi, the family of Korah. Yet truly, Kohath conceived Amram,
59 orúkọ aya Amramu sì ń jẹ́ Jokebedi, ọmọbìnrin Lefi, tí ìyá rẹ̀ bí fún Lefi ní Ejibiti. Òun sì bí Aaroni, Mose, àti Miriamu arábìnrin wọn fún Amramu.
who had a wife, Jochebed, the daughter of Levi, who was born to him in Egypt. She bore, to her husband Amram: sons, Aaron and Moses, as well as their sister, Miriam.
60 Aaroni ni baba Nadabu àti Abihu, Eleasari àti Itamari.
From Aaron were born Nadab and Abihu, and Eleazar and Ithamar.
61 Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu kú, nígbà tí wọ́n rú ẹbọ níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n mú iná àjèjì wá.)
Of these, Nadab and Abihu died, when they had offered strange fire before the Lord.
62 Gbogbo àwọn ọmọkùnrin Lefi láti oṣù kan àti ju bẹ́ẹ̀ lọ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀rún. Wọn kò ka wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli tókù nítorí tí wọ́n kò gba ogún ìní lára wọn.
And these were all who were numbered: twenty-three thousand of the male gender, from one month and above. For they were not counted among the sons of Israel, neither was a possession given to them with the others.
63 Àwọn wọ̀nyí ni Mose àti Eleasari àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá odò Jordani létí Jeriko.
This is the number of the sons of Israel, who were enrolled by Moses and by Eleazar the priest, in the plains of Moab, above the Jordan, opposite Jericho.
64 Kò sí ẹnìkan nínú àwọn tí Mose àti Aaroni àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní aginjù Sinai.
Among these, not one of them was numbered before, by Moses and Aaron in the desert of Sinai.
65 Nítorí Olúwa ti sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kíkú ni wọn yóò kú sí aginjù, kò sì sí ẹnìkankan nínú wọn tí kò kú àfi Kalebu ọmọ Jefunne, àti Joṣua ọmọ Nuni.
For the Lord had foretold that all would die in the wilderness. And not one of them remained, except Caleb the son of Jephunneh, and Joshua the son of Nun.