< Numbers 25 >

1 Nígbà tí àwọn Israẹli dúró ní Ṣittimu, àwọn ènìyàn sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin Moabu,
Potem gdy mieszkał Izrael w Syttim, począł lud cudzołożyć z córkami Moabskiemi,
2 tí ó pè wọ́n sí ibi ẹbọ òrìṣà wọn. Àwọn ènìyàn náà jẹun wọ́n sì foríbalẹ̀ níwájú òrìṣà wọn.
Które wzywały ludu ku ofiarom bogów swoich; a jedząc lud kłaniał się bogom ich.
3 Báyìí ni Israẹli ṣe darapọ̀ mọ́ wọn tí wọ́n sì jọ ń sin Baali-Peori. Ìbínú Olúwa sì ru sí wọn.
I przyłączył się Izrael do służby Baal Fegora; skąd się rozgniewał Pan bardzo na Izraela.
4 Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú gbogbo àwọn olórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, pa wọ́n kí o sì fi wọ́n kọ́ sórí igi ní gbangba nínú oòrùn níwájú Olúwa, kí ìbínú Olúwa lè kúrò ní ọ̀dọ̀ Israẹli.”
Rzekł tedy Pan do Mojżesza: Zbierz wszystkie książęta z ludu, a każ im, te przestępce powieszać Panu przed słońcem, aby się odwrócił gniew popędliwości Pańskiej od Izraela.
5 Mose sọ fún àwọn onídàájọ́ Israẹli, “Ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ pa arákùnrin rẹ̀ èyí tí ó darapọ̀ ní fífi orí balẹ̀ fún Baali-Peori.”
Przetoż rzekł Mojżesz do sędziów Izraelskich: Zabijcie każdy z was męże swe, którzy się spospolitowali z Baal Fegorem.
6 Nítòótọ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin Israẹli sì mú obìnrin Midiani wá síwájú ojú Mose àti gbogbo ìjọ ti Israẹli wọ́n sì ń sọkún ní àbáwọlé àgọ́ ìpàdé.
A oto, niektóry z synów Izraelskich przyszedł i przywiódł do braci swej Madyjanitkę przed oczyma Mojżeszowemi, i przed oczyma wszystkiego zgromadzenia synów Izraelskich; a oni płakali przed drzwiami namiotu zgromadzenia.
7 Nígbà tí Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni, àlùfáà, rí èyí, ó fi ìjọ sílẹ̀, pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ní ọwọ́ rẹ̀.
Co gdy ujrzał Finees, syn Eleazara, syna Aarona kapłana, wstawszy z pośrodku zgromadzenia, wziął oszczep w ręce swoje.
8 Ó sì tẹ̀lé arákùnrin Israẹli yìí lọ sínú àgọ́. Ó sì fi ọ̀kọ̀ gún àwọn méjèèjì ní àgúnyọ láti ara ọkùnrin Israẹli àti sí ara obìnrin náà. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn lórí àwọn ọmọ Israẹli sì dúró;
A wszedłszy za onym mężem Izraelskim do namiotu, przebił oboje, męża Izraelskiego, i niewiastę przez żywot jej, i odwrócona była plaga od synów Izraelskich.
9 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn tí ó kú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn náà jẹ́ ẹgbàá méjìlá.
A było tych, co pomarli oną plagą, dwadzieścia i cztery tysiące.
10 Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
Potem rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
11 “Finehasi ọmọ Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà, ti yí ìbínú mi padà kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí tí ó ní ìtara bí èmi náà ti ní ìtara fún iyì mi láàrín wọn, kí ó lè jẹ́ pé èmi ló pa wọ́n run nínú ìtara mi sí wọn.
Finees syn Eleazara, syna Aarona kapłana odwrócił gniew mój od synów Izraelskich, będąc wzruszony zapalczywą miłością ku mnie w pośrodku ich, tak iżem nie wytracił synów Izraelskich w zapalczywości mojej.
12 Nítorí náà sọ fún un pé èmi ṣe májẹ̀mú àlàáfíà mi pẹ̀lú rẹ̀.
Przetoż powiedz mu: Oto, Ja stanowię z nim przymierze moje, przymierze pokoju;
13 Òun àti irú-ọmọ rẹ̀ yóò ní májẹ̀mú láéláé fún iṣẹ́ àlùfáà, nítorí pé ó ní ìtara fún Ọlọ́run rẹ̀ láti fi yẹ́ Ọlọ́run sí, ó sì ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Israẹli.”
I przyjdzie nań, i na nasienie jego po nim, przymierze kapłaństwa wiecznego, że się wzruszył zapalczywością za Boga swego, i oczyścił syny Izraelskie
14 Orúkọ ọmọ Israẹli tí a pa pẹ̀lú obìnrin Midiani náà ni Simri, ọmọ Salu, olórí ilé kan nínú àwọn ọmọ Simeoni.
A imię onego męża Izraelskiego zabitego, który zabity był z Madyjanitką, było Zamry, syn Salów, książę domu ojca swego, z pokolenia Symeonowego.
15 Orúkọ ọmọbìnrin Midiani náà tí a pa ní Kosbi ọmọbìnrin Suri, tí ṣe olóyè àwọn ẹ̀yà kan nínú ìdílé kan ní Midiani.
Imię też niewiasty zabitej Madyjanitki było Kozba, córka Sury, książęcia w narodzie swym, w domu ojczystym między Madyjanity.
16 Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
I rzekł Pan do Mojżesza, mówiąc:
17 “Ka àwọn ará Midiani sí ọ̀tá, kí o sì pa wọ́n,
Staw się nieprzyjacielem Madyjanitom, a pobijcie je,
18 nítorí pé wọ́n ṣe sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá nígbà tí wọ́n tàn yín nípa ìṣẹ̀lẹ̀ Peori, àti arábìnrin wọn Kosbi ọmọbìnrin ìjòyè Midiani kan, obìnrin tí a pa nígbà tí àjàkálẹ̀-ààrùn ṣẹlẹ̀ nítorí Peori.”
Ponieważ i oni stawili się wam nieprzyjaciołmi zdradami swemi, a podeszli was przez Baal Fegora, i przez Kozbę, córkę książęcia Madyjańskiego, siostrę swą, która zabita jest w dzień kaźni dla bałwana Fegor.

< Numbers 25 >