< Numbers 25 >

1 Nígbà tí àwọn Israẹli dúró ní Ṣittimu, àwọn ènìyàn sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ọmọbìnrin Moabu,
Israel kaminawk Shittim ah oh o naah, Moab canunawk hoiah nongpa nongpata zaehaih sak amtong o.
2 tí ó pè wọ́n sí ibi ẹbọ òrìṣà wọn. Àwọn ènìyàn náà jẹun wọ́n sì foríbalẹ̀ níwájú òrìṣà wọn.
To nongpatanawk mah angmacae sithaw angbawnhaih ahmuen ah Israel kaminawk angzoh thai hanah pacae o; to kaminawk loe angbawnhaih buh aan to caak o moe, to ih sithawnawk hma ah akuep o.
3 Báyìí ni Israẹli ṣe darapọ̀ mọ́ wọn tí wọ́n sì jọ ń sin Baali-Peori. Ìbínú Olúwa sì ru sí wọn.
To tiah Israel kaminawk mah Peor ahmuen ah Baal to bok o pongah, Angraeng palungphuihaih Israel kaminawk nuiah phak.
4 Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú gbogbo àwọn olórí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, pa wọ́n kí o sì fi wọ́n kọ́ sórí igi ní gbangba nínú oòrùn níwájú Olúwa, kí ìbínú Olúwa lè kúrò ní ọ̀dọ̀ Israẹli.”
To naah Angraeng mah Mosi khaeah, Hae kami zaehoikungnawk to kawk boih ah loe, zit kathok Angraeng palungphuihaih Israel khae hoi dip thai hanah, nihcae to khodai ah Angraeng hmaa ah qui hoiah bang ah, tiah a naa.
5 Mose sọ fún àwọn onídàájọ́ Israẹli, “Ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbọdọ̀ pa arákùnrin rẹ̀ èyí tí ó darapọ̀ ní fífi orí balẹ̀ fún Baali-Peori.”
To pongah Mosi mah Israel lokcaekkungnawk khaeah, Baal-Peor bokhaih ahmuen ah caeh kaminawk boih to hum oh, tiah a naa.
6 Nítòótọ́ ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin Israẹli sì mú obìnrin Midiani wá síwájú ojú Mose àti gbogbo ìjọ ti Israẹli wọ́n sì ń sọkún ní àbáwọlé àgọ́ ìpàdé.
Khenah, Israel kami maeto mah, Mosi hoi amkhuenghaih kahni im thok taengah kaqah, kamkhueng angmah ih nawkamya Israel kaminawk boih hma ah, Midian nongpata maeto angzoh haih.
7 Nígbà tí Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni, àlùfáà, rí èyí, ó fi ìjọ sílẹ̀, pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ní ọwọ́ rẹ̀.
Qaima Aaron capa Eleazar, Eleazar capa Phinehas mah anih to hnuk naah, anih mah tayae to ban ah sin, kamkhueng kaminawk salak hoiah angthawk moe,
8 Ó sì tẹ̀lé arákùnrin Israẹli yìí lọ sínú àgọ́. Ó sì fi ọ̀kọ̀ gún àwọn méjèèjì ní àgúnyọ láti ara ọkùnrin Israẹli àti sí ara obìnrin náà. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn lórí àwọn ọmọ Israẹli sì dúró;
to tiah zaehaih sah Israel kami ohhaih kahni im khoek to a pangh pacoengah, Israel kami hoi to nongpata to tayae hoiah zok ah takhawh hmaek. To naah Israel salak ih nathaih kasae to dip.
9 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn tí ó kú nínú àjàkálẹ̀-ààrùn náà jẹ́ ẹgbàá méjìlá.
Toe to ih kasae nathaih pongah kami sing hnet, sang palito duek o.
10 Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
Angraeng mah Mosi khaeah,
11 “Finehasi ọmọ Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà, ti yí ìbínú mi padà kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli, nítorí tí ó ní ìtara bí èmi náà ti ní ìtara fún iyì mi láàrín wọn, kí ó lè jẹ́ pé èmi ló pa wọ́n run nínú ìtara mi sí wọn.
Qaima Aaron capa Eleazar, Eleazar capa Phinehas loe, kai pakoehhaih bangah palungthin thacak kami ah oh pongah, Israel kaminawk ka hum han ai ah, Israel nuiah palung ka phuihaih to anih mah dipsak boeh.
12 Nítorí náà sọ fún un pé èmi ṣe májẹ̀mú àlàáfíà mi pẹ̀lú rẹ̀.
To pongah, Khenah, anih khaeah angdaeh lokmaihaih to ka paek boeh;
13 Òun àti irú-ọmọ rẹ̀ yóò ní májẹ̀mú láéláé fún iṣẹ́ àlùfáà, nítorí pé ó ní ìtara fún Ọlọ́run rẹ̀ láti fi yẹ́ Ọlọ́run sí, ó sì ṣe ètùtù fún àwọn ọmọ Israẹli.”
anih loe Sithaw bokhaih bangah palungthin thacak moe, Israel kaminawk zae loih thai hanah, angbawnhaih a sak pongah, angmah hoi a caanawk khoek to dungzan ah qaima toksak hanah lokmaihaih to hnu tih, tiah a thuih pae.
14 Orúkọ ọmọ Israẹli tí a pa pẹ̀lú obìnrin Midiani náà ni Simri, ọmọ Salu, olórí ilé kan nínú àwọn ọmọ Simeoni.
Midian nongpata hoi nawnto hum ih Israel kami ahmin loe, Simeon acaeng zaehoikung ah kaom, Salu ih capa Zimri.
15 Orúkọ ọmọbìnrin Midiani náà tí a pa ní Kosbi ọmọbìnrin Suri, tí ṣe olóyè àwọn ẹ̀yà kan nínú ìdílé kan ní Midiani.
Hum ih Midian nongpata ahmin loe, Midian imthung takoh lu koek ah kaom, Zur canu Gozbi.
16 Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
Angraeng mah Mosi khaeah,
17 “Ka àwọn ará Midiani sí ọ̀tá, kí o sì pa wọ́n,
Midian kaminawk to na misa baktiah poek ah loe hum ah;
18 nítorí pé wọ́n ṣe sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá nígbà tí wọ́n tàn yín nípa ìṣẹ̀lẹ̀ Peori, àti arábìnrin wọn Kosbi ọmọbìnrin ìjòyè Midiani kan, obìnrin tí a pa nígbà tí àjàkálẹ̀-ààrùn ṣẹlẹ̀ nítorí Peori.”
Peor sithaw to bok pongah, nathaih kasae phakhaih niah hum ih, Midian kaminawk zaehoikung ih canu, nihcae ih tanu ah kaom, Gozbi hoi Peor kawng pongah, nangcae to ang ling o boeh, tiah a naa.

< Numbers 25 >